-
Bá A Ṣe Lè Di Orúkọ Jésù Mú ṢinṣinÌṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
-
-
‘Mánà Tó Wà Nípamọ́ àti Òkúta Róbótó Funfun Kan’
17. Èrè wo ló ń dúró de àwọn Kristẹni ẹni àmì òróró tí wọ́n bá “ṣẹ́gun,” kí sì ló pọn dandan fáwọn Kristẹni ní Págámù láti ṣẹ́pá rẹ̀?
17 Èrè tí ò láfiwé ló ń dúró de gbogbo àwọn tí wọ́n bá gbà ìmọ̀ràn tí Jésù fúnni nípasẹ̀ ìdarí ẹ̀mí mímọ́ Jèhófà. Fetí sílẹ̀! “Kí ẹni tí ó bá ní etí gbọ́ ohun tí ẹ̀mí ń sọ fún àwọn ìjọ: Ẹni tí ó bá ṣẹ́gun ni èmi yóò fún ní díẹ̀ nínú mánà tí a fi pa mọ́, èmi yóò sì fún un ní òkúta róbótó funfun kan, àti lára òkúta róbótó náà orúkọ tuntun tí a kọ, èyí tí ẹnì kankan kò mọ̀ àyàfi ẹni tí ó rí i gbà.” (Ìṣípayá 2:17) Nípa báyìí, ó gbà àwọn Kristẹni tó wà ní Págámù níyànjú láti “ṣẹ́gun” bíi tàwọn Kristẹni tó wà ní Símínà. Báwọn tó wà ní Págámù, níbi tí ìtẹ́ Sátánì wà bá máa kẹ́sẹ járí, wọ́n gbọ́dọ̀ jáwọ́ nínú ìbọ̀rìṣà. Wọ́n gbọ́dọ̀ ṣẹ́pá ìṣekúṣe, ẹ̀ya ìsìn, àti ìpẹ̀yìndà tó jọra pẹ̀lú ti Bálákì, Báláámù, àti ẹ̀ya ìsìn Níkóláọ́sì. Nípa ṣíṣe bẹ́ẹ̀, àwọn Kristẹni ẹni àmì òróró wọ̀nyẹn á rí ìkésíni gbà láti jẹ nínú “mánà tí a fi pa mọ́” náà. Kí lèyí túmọ̀ sí?
18, 19. (a) Kí ni mánà tí Jèhófà pèsè fáwọn ọmọ Ísírẹ́lì? (b) Mánà wo ló wà nípamọ́? (d) Kí ni jíjẹ mánà tó wà nípamọ́ náà ṣàpẹẹrẹ?
18 Nígbà ayé Mósè, Jèhófà pèsè mánà láti gbé ẹ̀mí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ró lákòókò ìrìn àjò wọn nínú aginjù. Mánà yẹn ò fara sin, nítorí láràárọ̀—àfi ọjọ́ Sábáàtì nìkan—ṣe ló máa ń fara hàn lọ́nà ìyanu, bí ìrì dídì wínníwínní tó bo ilẹ̀. Ohun tí Ọlọ́run pèsè kí ebi má bàa pa àwọn ọmọ Ísírẹ́lì kú ni. Gẹ́gẹ́ bí ohun ìrántí, Jèhófà pàṣẹ fún Mósè láti tọ́jú díẹ̀ nínú “oúnjẹ” yìí sínú ìṣà wúrà tí ń bẹ nínú àpótí ọlọ́wọ̀ ti májẹ̀mú “jálẹ̀ ìran-ìran [ọmọ Ísírẹ́lì].”—Ẹ́kísódù 16:14, 15, 23, 26, 33; Hébérù 9:3, 4.
19 Àpẹẹrẹ náà mà bá a mu rẹ́gí o! Ọlọ́run tọ́jú mánà yìí sínú iyàrá ìkélé Mímọ́ Jù Lọ ti àgọ́ ìsìn, níbi tí iná ìyanu tó rà bàbà lórí ìdérí Àpótí ti ṣàpẹẹrẹ wíwà tí Jèhófà wà ńbẹ̀. (Ẹ́kísódù 26:34) Kò sí ẹnì kankan tó lè wọnú ibi ọlọ́wọ̀ yẹn láti jẹ mánà tó fara sin náà. Bó ti wù kó rí, Jésù sọ pé àwọn ẹni àmì òróró ọmọlẹ́yìn òun tí wọ́n ṣẹ́gun yóò jẹ “mánà tí a fi pa mọ́” náà. Bí Kristi ti ṣe ṣáájú wọn, ó ṣeé ṣe fún wọn láti wọlé, “[kì í ṣe] sí ibi mímọ́ tí a fi ọwọ́ ṣe, tí ó jẹ́ ẹ̀dà ti òtítọ́, bí kò ṣe sí ọ̀run.” (Hébérù 9:12, 24) Bí wọ́n bá ṣe ń jí dìde, wọ́n ń gbé àìdibàjẹ́ àti àìleèkú wọ̀—ìpèsè aláìláfiwé láti ọ̀dọ̀ Jèhófà, tó ṣàpẹẹrẹ fífún tí wọ́n fún wọn ní “mánà tí a fi pa mọ́” èyí tí ò lè bà jẹ́. Àǹfààní tí àwùjọ kékeré tó ṣẹ́gun yìí ní mà ga o!—1 Kọ́ríńtì 15:53-57.
20, 21. (a) Kí ni fífún àwọn Kristẹni ẹni àmì òróró ní òkúta róbótó funfun ṣàpẹẹrẹ? (b) Níwọ̀n bó ti jẹ́ pé kìkì ọ̀kẹ́ méje ó lé ẹgbàajì òkúta róbótó funfun ló wà, ìrètí wo ló wà fáwọn ogunlọ́gọ̀ ńlá?
20 Àwọn èèyàn yìí tún gba “òkúta róbótó funfun.” Láwọn ilé ẹjọ́ Róòmù, wọ́n máa ń lo òkúta róbótó láti fi ṣèdájọ́.b Òkúta róbótó funfun túmọ̀ sí ìdásílẹ̀, nígbà tí òkúta róbótó dúdú túmọ̀ sí ìdálẹ́bi, ìyẹn sì máa ń jẹ́ ikú lọ́pọ̀ ìgbà. Fífún tí Jésù fáwọn Kristẹni ní Págámù ní “òkúta róbótó funfun” fi hàn pé ó kà wọ́n sí aláìmọwọ́mẹsẹ̀, aláìlábààwọ́n tó mọ́ tónítóní. Ṣùgbọ́n àwọn ọ̀rọ̀ Jésù lè ní ìtumọ̀ míì. Láyé ìgbà tí Róòmù ṣì ń jẹ́ Róòmù, wọ́n máa ń lo òkúta róbótó bíi tíkẹ́ẹ̀tì láti lè wọlé sáwọn ibi ìṣẹ̀lẹ̀ pàtàkì. Nítorí náà, òkúta róbótó funfun náà lè tọ́ka sí ohun kan tó jẹ́ àkànṣe gan-an fún Kristẹni ẹni àmì òróró náà tó ṣẹ́gun, ìyẹn gbígbà tí wọ́n gbà á wọlé síbi ọlọ́lá ní ọ̀run níbi ìgbéyàwó Ọ̀dọ́ Àgùntàn náà. Gbogbo irú òkúta róbótó bẹ́ẹ̀ tó wà ò ju ọ̀kẹ́ méje ó lé ẹgbàajì [144,000] lọ.—Ìṣípayá 14:1; 19:7-9.
21 Ṣé èyí wá túmọ̀ sí pé Ọlọ́run ò kà ọ́ sí bó o bá jẹ́ ọ̀kan lára ogunlọ́gọ̀ ńlá tó ń jọ́sìn ní ìfẹ̀gbẹ́kẹ̀gbẹ́ pẹ̀lú wọn? Kò rí bẹ́ẹ̀ rárá! Bó ò tiẹ̀ sí lára àwọn tó máa gba òkúta róbótó funfun tó o lè fi wọlé sí ọ̀run, wà á la ìpọ́njú ńlá já, wà á sì kópa nínú iṣẹ́ aláyọ̀ ti mímú Párádísè orí ilẹ̀ ayé padà bọ̀ sípò, ìyẹn bó o bá fara dà á. Àwọn tó tún máa bá ọ nípìn-ín nínú èyí làwọn olùṣòtítọ́ tí wọ́n gbé ayé kí ìsìn Kristẹni tó bẹ̀rẹ̀ tí wọ́n á jí dìde àtàwọn tí wọ́n jẹ́ àgùntàn mìíràn tó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé ṣe ni wọ́n ṣẹ̀ṣẹ̀ kú. Nígbẹ̀yìn gbẹ́yín, gbogbo àwọn òkú yòókù tá a tún rà padà ló máa rí àjíǹde sí ìyè nínú Párádísè lórí ilẹ̀ ayé.—Sáàmù 45:16; Jòhánù 10:16; Ìṣípayá 7:9, 14.
22, 23. Kí ni ìjẹ́pàtàkì orúkọ tó wà lára òkúta róbótó náà fáwọn Kristẹni ẹni àmì òróró, ìṣírí wo ló sì yẹ kéyìí fún wa?
22 Kí lórúkọ tuntun tó wà lára òkúta róbótó náà? Orúkọ jẹ́ ọ̀nà kan láti dá ẹnì kan mọ̀ láti lè fìyàtọ̀ sáàárín ẹni náà àtàwọn mìíràn. Àwọn Kristẹni ẹni àmì òróró wọ̀nyí gba òkúta róbótó náà lẹ́yìn tí wọ́n ti parí iṣẹ́ wọn ti orí ilẹ̀ ayé gẹ́gẹ́ bí aṣẹ́gun. Lọ́nà tó ṣe kedere, nígbà náà, orúkọ tó wà lára òkúta róbótó náà ní í ṣe pẹ̀lú àǹfààní wíwà ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú Jésù lọ́run—ipò tó máa jẹ́ kí wọ́n sún mọ́ Jésù jù lọ bí wọ́n ti ń ṣiṣẹ́ ìsìn wọn pẹ̀lú ìmọrírì gẹ́gẹ́ bí ọmọ aládé, èyí tó wà fún kìkì àwọn tí wọ́n jogún Ìjọba ọ̀run. Fún ìdí yìí, ó jẹ́ orúkọ kan, tàbí ipò, “èyí tí ẹnì kankan kò mọ̀ àyàfi ẹni tí ó rí i gbà.”—Fi wé Ìṣípayá 3:12.
23 Ìṣírí gbáà lèyí jẹ́ fún ẹgbẹ́ Jòhánù láti “gbọ́ ohun tí ẹ̀mí ń sọ fún àwọn ìjọ” kí wọn sì fi ṣèwà hù! Ìyànjú kékeré kọ́ lèyí máa jẹ́ fáwọn alábàákẹ́gbẹ́ wọn, ogunlọ́gọ̀ ńlá, bí wọ́n ṣe ń fi ìṣòtítọ́ sìn pẹ̀lú wọn nígbà tí wọ́n ṣì wà pẹ̀lú wọn níhìn-ín lórí ilẹ̀ ayé láti mú kí Ìjọba Jèhófà di mímọ̀!
-
-
Bá A Ṣe Lè Di Orúkọ Jésù Mú ṢinṣinÌṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
-
-
[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 45]
Wọ́n fi mánà díẹ̀ pa mọ́ sínú àpótí májẹ̀mú. Fífún tí Jésù fún ẹni àmì òróró tó ṣẹ́gun ní mánà ìṣàpẹẹrẹ tó wà nípamọ́ túmọ̀ sí pé ẹni náà rí àìleèkú gbà
[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 45]
Àwọn tó bá máa wọlé síbi ìgbéyàwó Ọ̀dọ́ Àgùntàn ni òkúta róbótó funfun náà wà fún
-