-
Ògo Ìtẹ́ Jèhófà ní Ọ̀runÌṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
-
-
Mànàmáná, Ohùn, àti Ààrá
12. Kí ni Jòhánù rí tó sì gbọ́ lẹ́yìn èyí, kí sì ni “mànàmáná àti ohùn àti ààrá” mú wa rántí?
12 Kí ni Jòhánù rí tí ó sì gbọ́ lẹ́yìn èyí? Ó ní: “Mànàmáná àti ohùn àti ààrá sì ń jáde wá láti inú ìtẹ́ náà.” (Ìṣípayá 4:5a) Èyí múni rántí àwọn ọ̀nà àgbàyanu míì tí Jèhófà ti gbà fi agbára rẹ̀ hàn gan-an ni! Bí àpẹẹrẹ, nígbà tí Jèhófà “sọ̀ kalẹ̀” sórí Òkè Sínáì, Mósè ròyìn pé: “Ní ọjọ́ kẹta, nígbà tí ó di òwúrọ̀, ó sì ṣẹlẹ̀ pé ààrá sán, mànàmáná sì bẹ̀rẹ̀ sí kọ, àti àwọsánmà ṣíṣú dùdù lórí òkè ńlá náà àti ìró ìwo adúnròkè lálá. . . . Nígbà tí ìró ìwo náà túbọ̀ ń dún kíkankíkan láìdáwọ́ dúró, Mósè bẹ̀rẹ̀ sí sọ̀rọ̀, Ọlọ́run tòótọ́ sì bẹ̀rẹ̀ sí fi ohùn dá a lóhùn.”—Ẹ́kísódù 19:16-19.
13. Kí ni mànàmáná tí ń ti ibi ìtẹ́ Jèhófà jáde dúró fún?
13 Ní ọjọ́ Olúwa, Jèhófà ń fi agbára rẹ̀ àti wíwà tó wà nítòsí hàn lọ́nà ológo tó ga lọ́lá. Àmọ́ kì í ṣe nípa lílo mànàmáná gidi, nítorí àmì làwọn ohun tí Jòhánù rí jẹ́. Kí wá ni mànàmáná náà dúró fún? Ó dára, ìbùyẹ̀rì mànàmáná lè fúnni ní ìmọ́lẹ̀, ó sì tún lè pani. Fún ìdí yìí, mànàmáná tí ń bù yẹ̀rì jáde láti ibi ìtẹ́ Jèhófà jẹ́ àpẹẹrẹ àwọn ìbùyẹ̀rì ìlàlóye àti ní pàtàkì jù lọ, àwọn ìhìn nípa ìdájọ́ amú-bí-iná tí Ọlọ́run ń bá a lọ láti fún àwọn èèyàn rẹ̀ láìdáwọ́dúró.—Fi wé Sáàmù 18:14; 144:5, 6; Mátíù 4:14-17; 24:27.
14. Báwo ni ohùn ṣe ń dún jáde lónìí?
14 Àwọn ohùn náà ńkọ́? Lákòókò tí Jèhófà sọ̀ kalẹ̀ sórí Òkè Sínáì, ohùn kan bá Mósè sọ̀rọ̀. (Ẹ́kísódù 19:19) Àwọn ohùn láti ọ̀run ló sọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun tó jẹ́ àṣẹ àti ìpòkìkí inú ìwé Ìṣípayá. (Ìṣípayá 4:1; 10:4, 8; 11:12; 12:10; 14:13; 16:1, 17; 18:4; 19:5; 21:3) Lónìí Jèhófà pẹ̀lú ti sọ àwọn ohun tó jẹ́ àṣẹ àti àwọn ìpòkìkí kan fáwọn èèyàn rẹ̀, ní títan ìmọ́lẹ̀ sí òye wọn nípa àwọn àsọtẹ́lẹ̀ àti àwọn ìlànà Bíbélì. A sábà máa ń gbọ́ àwọn ìsọfúnni tó ń lani lóye láwọn àpéjọ àgbègbè, irú àwọn òtítọ́ Bíbélì bẹ́ẹ̀ ni a sì ti pòkìkí kárí ayé lẹ́yìn náà. Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù sọ nípa àwọn olóòótọ́ oníwàásù ìhìn rere pé: “Họ́wù, ní ti tòótọ́, ‘ìró wọ́n jáde lọ sí gbogbo ilẹ̀ ayé, àsọjáde wọn sì jáde lọ sí àwọn ìkángun ilẹ̀ ayé tí a ń gbé.’”—Róòmù 10:18.
15. Ààrá wo ló ti sán jáde láti orí ìtẹ́ náà ní apá tá a wà yìí nínú ọjọ́ Olúwa?
15 Ààrá sábà máa ń tẹ̀ lé mànàmáná. Dáfídì tọ́ka sí ààrá gidi gẹ́gẹ́ bí “ohùn Jèhófà.” (Sáàmù 29:3, 4) Nígbà tí Jèhófà bá àwọn ọ̀tá jà fún Dáfídì, ààrá ni Bíbélì sọ pe Ó rán sí wọn. (2 Sámúẹ́lì 22:14; Sáàmù 18:13) Élíhù sọ fún Jóòbù pé ohùn Jèhófà dún bí ààrá, bí Ó ti ń ṣe “àwọn ohun ńlá ti a kò lè mọ̀.” (Jóòbù 37:4, 5) Ní apá tá a wà yìí nínú ọjọ́ Olúwa, Jèhófà ti ‘sán ààrá,’ ní kíkìlọ̀ nípa àwọn ohun ńláǹlà tí òun yóò ṣe sí àwọn ọ̀tá rẹ̀. Ìró àwọn ààrá ìṣàpẹẹrẹ wọ̀nyí ti dún àdúntúndún jákèjádò ilẹ̀ ayé. Ayọ̀ ńbẹ fún ọ o, tó o bá ń fiyè sí ìpòkìkí adún-bí-ààrá wọ̀nyí tó o sì ń lo ahọ́n rẹ lọ́nà tó bọ́gbọ́n mu láti fi kún ìró wọn!—Aísáyà 50:4, 5; 61:1, 2.
Àwọn Fìtílà Iná àti Òkun Bí Gíláàsì
16. Kí ni “fìtílà iná méje” náà túmọ̀ sí?
16 Kí ni Jòhánù rí síwájú sí i? Ohun tí ó rí nìyí: “Fìtílà iná méje sì wà tí ń jó níwájú ìtẹ́ náà, ìwọ̀nyí sì túmọ̀ sí ẹ̀mí méje ti Ọlọ́run. Àti níwájú ìtẹ́ náà ni ohun tí a lè pè ní òkun bí gíláàsì, tí ó dà bí kírísítálì wà.” (Ìṣípayá 4:5b, 6a) Jòhánù fúnra rẹ̀ sọ ohun tí fìtílà méje náà dúró fún pé: “Ìwọ̀nyí sì túmọ̀ sí ẹ̀mí méje ti Ọlọ́run.” Iye náà, méje, ṣàpẹẹrẹ ìpépérépéré nínú àwọn ohun ti Ọlọ́run; fún ìdí yìí, fìtílà méje náà ní láti dúró fún ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ agbára ìlanilóye ti ẹ̀mí mímọ́. Ẹ wo bí ẹgbẹ́ Jòhánù náà ti kún fún ìmoore tó lónìí pé a ti fi ìlàlóye yìí sí ìkáwọ́ rẹ̀, tó sì tún jẹ́ ojúṣe rẹ̀ láti rí i dájú pé ìlàlóye yìí dé ọ̀dọ̀ àwọn tí ebi ń pa nípa tẹ̀mí nínú ayé! Inú wa sì dùn gan-an ni pé lọ́dọọdún ọgọ́rọ̀ọ̀rún mílíọ̀nù ẹ̀dà ìwé ìròyìn Ilé Ìṣọ́ ń bá a lọ láti máa tan ìmọ́lẹ̀ yìí jáde ní nǹkan bí igba [200] èdè!—Sáàmù 43:3.
-
-
Ògo Ìtẹ́ Jèhófà ní Ọ̀runÌṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
-
-
[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 78]
-