ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • “Ta Ni Ó Yẹ Láti Ṣí Àkájọ Ìwé Náà?”
    Ìṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
    • Orin Ìyìn

      14. (a) Kí ni ẹ̀dá alààyè mẹ́rẹ̀ẹ̀rin wọnnì àti alàgbà mẹ́rìnlélógún ṣe nígbà tí Jésù gba àkájọ ìwé náà? (b) Báwo ni ìsọfúnni tí Jòhánù rí gbà nípa alàgbà mẹ́rìnlélógún náà ṣe túbọ̀ jẹ́ ká mọ àwọn àti ipò wọn dájú?

      14 Kí ni àwọn yòókù tó wà níwájú ìtẹ́ Jèhófà wá ṣe? “Nígbà tí ó sì gba àkájọ ìwé náà, àwọn ẹ̀dá alààyè mẹ́rin àti àwọn alàgbà mẹ́rìnlélógún náà wólẹ̀ níwájú Ọ̀dọ́ Àgùntàn náà, olúkúlùkù wọn ní háàpù kan lọ́wọ́ àti àwokòtò wúrà tí ó kún fún tùràrí, tùràrí náà sì túmọ̀ sí àdúrà àwọn ẹni mímọ́.” (Ìṣípayá 5:8) Bí àwọn ẹ̀dá alààyè mẹ́rẹ̀ẹ̀rin tó jẹ́ kérúbù tó wà níwájú ìtẹ́ Ọlọ́run ṣe tẹrí ba náà làwọn alàgbà mẹ́rìnlélógún náà ṣe tẹrí ba fún Jésù láti fi hàn pé wọ́n bọ̀wọ̀ fún ọlá àṣẹ rẹ̀. Ṣùgbọ́n àwọn alàgbà wọ̀nyí nìkan ni wọ́n ní háàpù àti àwokòtò tùràrí.a Àwọn nìkan sì ni wọ́n ń kọrin tuntun kan nísinsìnyí. (Ìṣípayá 5:9) Nípa báyìí wọ́n jọ ọ̀kẹ́ méje ó lé ẹgbàajì [144,000] ti “Ísírẹ́lì Ọlọ́run” tí wọ́n jẹ́ mímọ́, táwọn pẹ̀lú ní háàpù tí wọ́n sì ń kọrin tuntun kan. (Gálátíà 6:16; Kólósè 1:12; Ìṣípayá 7:3-8; 14:1-4) Síwájú sí i, alàgbà mẹ́rìnlélógún náà ni a fi hàn pé wọ́n ń ṣe iṣẹ́ kan ní ọ̀run, ìyẹn iṣẹ́ àlùfáà. Àpẹẹrẹ tiwọn ni iṣẹ́ àwọn àlùfáà tí wọ́n ń sun tùràrí fún Jèhófà nínú àgọ́ ìjọsìn ní Ísírẹ́lì ìgbàanì jẹ́, èyí tó ti dópin lórí ilẹ̀ ayé nígbà tí Ọlọ́run mú Òfin Mósè kúrò ní ojú ọ̀nà, tó kàn án mọ́ igi oró Jésù. (Kólósè 2:14) Kí la rí fà yọ nínú gbogbo èyí? Òun ni pé ńṣe ni ibí yìí ń jẹ́ ká rí àwọn ẹni àmì òróró aṣẹ́gun bí wọ́n ṣe wà lẹ́nu iṣẹ́ wọn gíga jù lọ, tí í ṣe ‘àlùfáà Ọlọ́run àti ti Kristi, tí wọ́n ń ṣàkóso gẹ́gẹ́ bí ọba pẹ̀lú rẹ̀ fún ẹgbẹ̀rún ọdún.’—Ìṣípayá 20:6.

      15. (a) Ní Ísírẹ́lì, ta ni ẹnì kan ṣoṣo tó láǹfààní láti wọ ibi Mímọ́ Jù Lọ tó wà nínú àgọ́ ìjọsìn? (b) Kí nìdí tí àlùfáà àgbà fi gbọ́dọ̀ sun tùràrí kó tó wọnú ibi Mímọ́ Jù Lọ nítorí ẹ̀mí rẹ̀?

      15 Ní Ísírẹ́lì ìgbàanì, àlùfáà àgbà nìkan ló lè wọ ibi Mímọ́ Jù Lọ láti wá síwájú ibi tó ń ṣàpẹẹrẹ ibi tí Jèhófà wà. Tí àlùfáà àgbà yìí kò bá fẹ́ pàdánù ẹ̀mí rẹ̀, ó gbọ́dọ̀ gbé tùràrí dání wá síbẹ̀. Òfin Jèhófà sọ pé: “Kí [Áárónì] mú ìkóná tí ó kún fún ẹyín iná tí ń jó láti orí pẹpẹ níwájú Jèhófà, kí ìtẹkòtò ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì sì kún fún àtàtà tùràrí onílọ́fínńdà, kí ó sì mú wọn wá sínú aṣọ ìkélé. Kí ó sì fi tùràrí sínú iná níwájú Jèhófà, kí ìṣúdùdù èéfín tùràrí sì bo ìbòrí Àpótí, tí ó wà lórí Gbólóhùn Ẹ̀rí, kí ó má bàa kú.” (Léfítíkù 16:12, 13) Àlùfáà àgbà ò lè rí inú ibi Mímọ́ Jù Lọ wọ̀ láàyè àyàfi tó bá sun tùràrí.

      16. (a) Lábẹ́ ètò àwọn nǹkan ti Kristẹni, àwọn wo ló wọnú Ibi Mímọ́ Jù Lọ lọ́run, èyí tí ibi mímọ́ jù lọ tó wà nínú àgọ́ ìjọsìn ń ṣàpẹẹrẹ rẹ̀? (b) Kí nìdí táwọn Kristẹni ẹni àmì òróró fi ní láti ‘sun tùràrí’?

      16 Nínú ètò àwọn nǹkan ti Kristẹni, Jésù Kristi, Àlùfáà Àgbà táwọn àlùfáà àgbà ìṣáájú jẹ́ àpẹẹrẹ rẹ̀, nìkan kọ́ ló wọnú Ibi Mímọ́ Jù Lọ, ìyẹn ibi tí Jèhófà wà ní ọ̀run, èyí tí ibi mímọ́ jù lọ tó wà nínú àgọ́ ìjọsìn ń ṣàpẹẹrẹ rẹ̀. Olúkúlùkù ọ̀kẹ́ méje ó lé ẹgbàajì [144,000] tí wọ́n jẹ́ àlùfáà lábẹ́ Jésù náà wọ̀ ọ́ níkẹyìn. (Hébérù 10:19-23) Àwọn àlùfáà yìí, táwọn alàgbà mẹ́rìnlélógún náà ń ṣàpẹẹrẹ, kò lè wọnú Ibi Mímọ́ Jù Lọ náà àyàfi bí wọ́n bá ‘sun tùràrí,’ ìyẹn ni pé kí wọ́n máa gbàdúrà kí wọ́n sì máa rawọ́ ẹ̀bẹ̀ sí Jèhófà nígbà gbogbo.—Hébérù 5:7; Júúdà 20, 21; fi wé Sáàmù 141:2.

  • “Ta Ni Ó Yẹ Láti Ṣí Àkájọ Ìwé Náà?”
    Ìṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
    • [Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 86]

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́