ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Àwọn Ẹlẹ́ṣin Mẹ́rin Tí Ń Sáré Kútúpà Kútúpà!
    Ìṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
    • 14. Ẹṣin àti ẹlẹ́ṣin wo ni Jòhánù tún rí, kí sì ni ìran yìí ṣàpẹẹrẹ?

      14 Ọ̀nà wo ni wọ́n wá gbà dáhùn ìkésíni kejì náà “Máa bọ̀!”? Ó jẹ́ lọ́nà yìí: “Òmíràn sì jáde wá, ẹṣin aláwọ̀ iná; ẹni tí ó jókòó lórí rẹ̀ ni a sì yọ̀ǹda fún láti mú àlàáfíà kúrò ní ilẹ̀ ayé kí wọ́n lè máa fikú pa ara wọn lẹ́nì kìíní-kejì; a sì fún un ní idà ńlá kan.” (Ìṣípayá 6:4) Ìran tó burú jáì gan-an ni ní tòótọ́! Kò sì sí iyèméjì rárá ní ti ohun tó ṣàpẹẹrẹ: ogun ni! Kì í ṣe ogun òdodo, ìyẹn ogun àjàṣẹ́gun tí Ọba aṣẹ́gun tí Jèhófà yàn ń jà, àmọ́ ó jẹ́ ogun oníkà, táwọn èèyàn dá sílẹ̀ láàárín àwọn orílẹ̀-èdè, èyí tó kún fún ìtàjẹ̀sílẹ̀ àti ìrora aláìnídìí. Ó bá a mu gan-an ni pé ẹṣin apọ́n-bí-iná ni ẹlẹ́ṣin yìí gùn!

      15. Kí nìdí tí kò fi yẹ ká ní àjọṣe kankan pẹ̀lú ẹlẹ́ṣin kejì?

      15 Dájúdájú, Jòhánù kò ní fẹ́ ní àjọṣe kankan pẹ̀lú ẹlẹ́ṣin yìí àti gígùn tó ń gun ẹṣin lọ gbuurugbu, nítorí Bíbélì ti sọ tẹ́lẹ̀ nípa àwọn èèyàn Ọlọ́run pé: “Wọn kì yóò kọ́ṣẹ́ ogun mọ́.” (Aísáyà 2:4) Bó tilẹ̀ jẹ́ pé Jòhánù, “wà ní ayé” nígbà náà, tí ẹgbẹ́ Jòhánù àti ogunlọ́gọ̀ ńlá sì “wà ní ayé” lónìí, síbẹ̀, wọn “kì í ṣe apá kan” ètò àwọn nǹkan inú ayé tí ẹ̀jẹ̀ ti rin gbingbin yìí. Ohun ìjà tẹ̀mí la ní, ìyẹn ohun ìjà “alágbára láti ọwọ́ Ọlọ́run” tó ń jẹ́ ká lè fi aápọn pòkìkí òtítọ́, dípò tá a ó fi máa ja ogun nípa ti ara.—Jòhánù 17:11, 14; 2 Kọ́ríńtì 10:3, 4.

      16. Ìgbà wo ni a fún ẹlẹ́ṣin pupa náà ní “idà ńlá kan,” báwo la sì ṣe fún un?

      16 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ogun ti wà ṣáájú ọdún 1914 tí Ẹni tó gun ẹṣin funfun náà gba adé rẹ̀. Ṣùgbọ́n “idà ńlá kan” ni wọ́n fún ẹni tó gun ẹṣin pupa nísinsìnyí. Kí ni èyí túmọ̀ sí? Láti ìgbà tí Ogun Àgbáyé Kìíní ti bẹ́ sílẹ̀, ogun ẹ̀dá èèyàn ti túbọ̀ di èyí tí ẹ̀jẹ̀ rin gbingbin, tó sì túbọ̀ ń ṣèparun ju ti tẹ́lẹ̀ lọ. Ní àárín ọdún 1914 sí 1918 táwọn èèyàn para wọn nípakúpa, àwọn ọkọ̀ afọ́nta, afẹ́fẹ́ májèlé, ọkọ̀ òfuurufú, ọkọ̀ ogun abẹ́ omi, ìbọn arọ̀jò ọta, àtàwọn ohun ìjà alágbára ni wọ́n lò, yálà kí wọ́n lò ó fún ìgbà àkọ́kọ́ tàbí kí wọ́n lò ó lọ́nà tí wọn ò gbà lò ó rí. Ní orílẹ̀-èdè tó tó méjìdínlọ́gbọ̀n ni wọ́n ti fi ipá mú gbogbo ará ìlú láti lọ́wọ́ sí ọ̀rọ̀ ogun jíjà, tí wọn kò fi ọ̀rọ̀ ìjà ogun náà mọ sí kìkì àwọn tí ń fi ogun ṣiṣẹ́ ṣe. Iye ẹ̀mí tó ṣòfò bani lẹ́rù. Ó ju mílíọ̀nù mẹ́sàn-án àwọn jagunjagun tí wọ́n pa, àwọn ará ìlú tó kú pọ̀ lọ jàra. Àní lẹ́yìn tí ogun náà parí pàápàá, orí ilẹ̀ ayé ò padà ní àlàáfíà gidi kankan títí di báyìí. Ní ohun tó ju àádọ́ta ọdún lọ lẹ́yìn ogun yẹn, òṣèlú ará Jámánì náà Konrad Adenauer sọ pé: “Àìléwu àti ìparọ́rọ́ ti pòórá nínú ìgbésí ayé ọmọ ẹ̀dá látọdún 1914.” A yọ̀ǹda fún ẹni tó gẹṣin aláwọ̀ iná náà láti mú àlàáfíà kúrò ní ilẹ̀ ayé ní tòótọ́!

      17. Lẹ́yìn Ogun Àgbáyé Kìíní, báwo ni ẹlẹ́ṣin pupa náà ṣe ti ń lo “idà ńlá”?

      17 Ẹlẹ́ṣin pupa yìí gbẹ̀mí ọ̀kẹ́ àìmọye yẹn tán tàìgbà á tán báyìí ló tún bẹ́ gìjà sínú Ogun Àgbáyé Kejì. Wọ́n wá lo àwọn ohun èlò ìpakúpa tó túbọ̀ burú jáì ju ti tẹ́lẹ̀ lọ, iye àwọn tó sì kú ju ìlọ́po mẹ́rin àwọn tó kú nínú Ogun Àgbáyé Kìíní. Ní 1945 bọ́ǹbù runlé-rùnnà méjì bú gbàù sórí Japan, tí ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn sì pa ẹgbẹẹgbẹ̀rún èèyàn run ráúráú ká tó pajú pẹ́ẹ́. Lákòókò Ogun Àgbáyé Kejì, ẹlẹ́ṣin pupa náà gbẹ̀mí àwọn tó lé ní mílíọ̀nù márùndínlọ́gọ́ta [55], kódà ìyẹn pàápàá kò tẹ́ ẹ lọ́rùn. Ìròyìn kan tó ṣeé gbára lé sọ pé láti ìgbà Ogun Àgbáyé Kejì “idà ńlá” náà ti gbẹ̀mí àwọn tó ju ogun [20] mílíọ̀nù lọ dáadáa.

      18, 19. (a) Kàkà kí ìpakúpa tó ń wáyé láti ìgbà Ogun Àgbáyé Kejì jẹ́ ẹ̀rí pé ìmọ̀ ẹ̀rọ àwọn ológun ti ní ìtẹ̀síwájú tó dára, ẹ̀rí kí ni ó jẹ́? (b) Ewu ńlá wo ni ó dojú kọ aráyé, ṣùgbọ́n kí ni Ẹni tó gẹṣin funfun náà yóò ṣe láti mú un kúrò?

      18 Ṣé èyí wá ń fi hàn pé ìmọ̀ ẹ̀rọ àwọn ológun ti ní ìtẹ̀síwájú tó dára ni? Rárá o. Kàkà bẹ́ẹ̀, ńṣe ló jẹ́ ẹ̀rí pé ẹṣin pupa aláìláàánú náà ń bá eré rẹ̀ lọ kútúpà kútúpà. Ibo sì ni yóò parí eré sísá náà sí? Àwọn onímọ̀ ìjìnlẹ̀ kan sọ pé yàtọ̀ sí pé àwọn èèyàn lè dìídì dá ogun tí wọ́n á ti lo ohun ìjà runlé-rùnnà tó lágbára gan-an sílẹ̀, ogun tí wọ́n á ti lo bọ́ǹbù runlé-rùnnà tiẹ̀ lè ṣèèṣì bẹ́ sílẹ̀ lójijì! Ṣùgbọ́n ó dùn mọ́ni pé èrò ti ajagunṣẹ́gun tó gun ẹṣin funfun náà yàtọ̀ síyẹn.

      19 Níwọ̀n ìgbà tó bá ti jẹ́ pé ẹ̀mí ìfẹ́ orílẹ̀-èdè onígbèéraga àti ìkórìíra làwọn èèyàn fi ń ṣe gbogbo nǹkan, inú ewu ńláǹlà laráyé wà. Nítorí pé ìgbàkigbà ni ogun tí wọ́n á ti lo bọ́ǹbù runlé-rùnnà lè bẹ́ sílẹ̀. Kódà bí àwọn orílẹ̀-èdè bá tiẹ̀ fi ìbẹ̀rù kó gbogbo ohun ìjà runlé-rùnnà wọn dà nù, wọ́n á ṣì mọ̀ ọ́n ṣe. Kò ní pẹ́ sí wọn lọ́wọ́ láti tún ṣe gbogbo ohun ìjà náà padà tí wọ́n bá ní kí wọ́n ṣe é; fún ìdí yìí, ogun èyíkéyìí tí wọ́n bá ń fi àwọn ohun ìjà pẹ́ẹ́pẹ̀ẹ̀pẹ́ jà lè padà di ogun tí wọ́n á ti lo ohun ìjà runlé-rùnnà. Ẹ̀mí ìgbéraga àti ìkórìíra tó gbòde kan láàárín àwọn orílẹ̀-èdè lónìí máa sún aráyé láti para wọn rún pátápátá ni, àyàfi bí Ẹni tó gẹṣin funfun náà bá wá nǹkan ṣe sí àgbáàràgbá eré ti ẹṣin aláwọ̀ iná náà ń sá. Ẹ jẹ́ ká ní ìgbẹ́kẹ̀lé pé Kristi Ọba yóò gẹṣin rẹ̀ débi tí yóò fi parí ìṣẹ́gun rẹ̀ lórí ayé tí Sátánì ń darí, tí yóò sì tún fìdí ilẹ̀ ayé tuntun tí ìfẹ́ yóò ti jọba múlẹ̀, ìyẹn ìfẹ́ fún Ọlọ́run àti fún ọmọnìkejì ẹni, èyí tó máa ń jẹ́ kí àlàáfíà jọba, tó ga jìnnàjìnnà ju àlàáfíà tipátipá táwọn orílẹ̀-èdè ń fẹ́, tí wọ́n ń tìtorí ẹ̀ fi ohun ìjà runlé-rùnnà halẹ̀ mọ́ni lóde òní táwọn èèyàn ń hùwà bí asínwín.—Sáàmù 37:9-11; Máàkù 12:29-31; Ìṣípayá 21:1-5.

  • Àwọn Ẹlẹ́ṣin Mẹ́rin Tí Ń Sáré Kútúpà Kútúpà!
    Ìṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
    • [Àpótí tó wà ní ojú ìwé 94]

      ‘A Yọ̀ǹda fún Un Láti Mú Àlàáfíà Kúrò ní Ilẹ̀ Ayé’

      Ibo ni ìmọ̀ ẹ̀rọ ń sin ayé yìí lọ? Ní January 22, 1987, ìwé ìròyìn The Globe and Mail ti Tòróńtò, Kánádà, ròyìn nǹkan wọ̀nyí láti inú ọ̀rọ̀ kan tí Ivan L. Head, ààrẹ Ibùdó Ìwádìí Lórí Ìdàgbàsókè Àwọn Orílẹ̀-Èdè sọ:

      “Lọ́nà tó ṣeé gbára lé, a díwọ̀n rẹ̀ pé ọ̀kan nínú mẹ́rin gbogbo àwọn onímọ̀ ìjìnlẹ̀ àti onímọ̀ ẹ̀rọ nínú ayé tí wọ́n ń lọ́wọ́ nínú ìwádìí àti ìdàgbàsókè ní ń ṣiṣẹ́ lórí àwọn ohun ìjà. . . . Ní ìdíwọ̀n ti ọdún 1986, owó tí wọ́n ń ná lórí nǹkan wọ̀nyí ju mílíọ̀nù kan ààbọ̀ dọ́là lọ ní ìṣẹ́jú kọ̀ọ̀kan. . . . Ǹjẹ́ gbogbo kìràkìtà lórí ìmọ̀ ẹ̀rọ yìí ń fi hàn pé ààbò túbọ̀ wà fún gbogbo wa? Àkójọ ohun ìjà runlé-rùnnà tí àwọn orílẹ̀-èdè mélòó kan tó jẹ́ alágbára ní lọ́wọ́ báyìí lágbára ju àpapọ̀ gbogbo ohun ọlọ́ṣẹ́ tí àwọn jagunjagun lò nínú Ogun Àgbáyé Kejì lọ lọ́nà ẹgbẹ̀rún mẹ́fà [6,000]. Ìyẹn jẹ́ ẹgbẹ̀rún mẹ́fà Ogun Àgbáyé Kejì. Láti 1945 wá, ọ̀sẹ̀ méje péré ni ìgbòkègbodò ológun kò fi ṣẹlẹ̀ láyé. Ó lé ní àádọ́jọ [150] ogun láàárín àwọn orílẹ̀-èdè tàbí ogun abẹ́lé táwọn èèyàn ti jà, èyí tí a díwọ̀n rẹ̀ pé ó ti mú ẹ̀mí tó ju ogún [20] mílíọ̀nù lọ. Ohun tó sì jẹ́ kí wọ́n lè gbẹ̀mí ọ̀pọ̀ jù lọ èèyàn yìí ni ìmọ̀ ẹ̀rọ tuntun tó gbéṣẹ́ tó wà lóde báyìí lákòókò Ìparapọ̀ Àwọn Orílẹ̀-Èdè tá a wà yìí.”

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́