-
Ègbé Àkọ́kọ́—Àwọn EéṣúÌṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
-
-
13. Báwo làwọn eéṣú yẹn ṣe rí?
13 Ìrísí àwọn eéṣú yẹn mà pabanbarì o! Jòhánù ṣàpèjúwe ìrísí wọn pé: “Ìrí àwọn eéṣú náà sì jọ àwọn ẹṣin tí a múra sílẹ̀ fún ìjà ogun; àti ní orí wọn ni ohun tí ó rí bí adé tí ó dà bí wúrà wà, ojú wọn sì dà bí ojú ènìyàn, ṣùgbọ́n wọ́n ní irun bí irun obìnrin. Eyín wọn sì dà bí ti kìnnìún; wọ́n sì ní àwo ìgbàyà bí àwo ìgbàyà irin. Ìró ìyẹ́ apá wọn sì dà bí ìró àwọn kẹ̀kẹ́ ẹṣin ti ọ̀pọ̀ ẹṣin tí ń sáré lọ sínú ìjà ogun.”—Ìṣípayá 9:7-9.
-
-
Ègbé Àkọ́kọ́—Àwọn EéṣúÌṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
-
-
15. Ní tàwọn eéṣú náà, kí ni ìwọ̀nyí tọ́ka sí (a) àwo ìgbàyà irin? (b) ojú bíi ti èèyàn? (d) irun bíi tobìnrin? (e) eyín bíi ti kìnnìún? (ẹ) pípa ọ̀pọ̀ ariwo?
15 Nínú ìran náà, àwọn eéṣú náà ní àwo ìgbàyà onírin, tó ń ṣàpẹẹrẹ ìwà òdodo tí kò lè fọ́. (Éfésù 6:14-18) Pẹ̀lúpẹ̀lù wọ́n ní ojú èèyàn, èyí ń tọ́ka sí ànímọ́ ìfẹ́, níwọ̀n bí Ọlọ́run, ẹni tí ó jẹ́ ìfẹ́, ti ṣe èèyàn ní àwòrán rẹ̀. (Jẹ́nẹ́sísì 1:26; 1 Jòhánù 4:16) Irun wọn gùn bíi tobìnrin, èyí tó jẹ́ àpẹẹrẹ pé wọ́n ń tẹrí ba fún Ọba wọn, tí í ṣe áńgẹ́lì ọ̀gbun àìnísàlẹ̀ náà. Eyín wọn sì jọ eyín kìnnìún. Kìnnìún máa ń fi eyín ẹ̀ fa ẹran ya. Látọdún 1919 wá, ẹgbẹ́ Jòhánù tún ti gba agbára láti jẹ oúnjẹ líle látinú ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, pàápàá àwọn òtítọ́ nípa Ìjọba Ọlọ́run tí “Kìnnìún tí ó jẹ́ ti ẹ̀yà Júdà,” Jésù Kristi, ń ṣàkóso. Bí kìnnìún ti ṣàpẹẹrẹ ìgboyà gẹ́lẹ́, ìgboyà ńlá ló gbà láti lóye ọ̀rọ̀ ìkéde yìí, ká sì tẹ́ ẹ̀ jáde ká tó wá pín in káàkiri ilẹ̀ ayé. Àwọn eéṣú ìṣàpẹẹrẹ yìí ti pa ariwo púpọ̀, bí “ìró àwọn kẹ̀kẹ́ ẹṣin ti ọ̀pọ̀ ẹṣin tí ń sáré lọ sínú ìjà ogun.” Gẹ́gẹ́ bí àpẹẹrẹ àwọn Kristẹni ọ̀rúndún kìíní tí wọ́n ń tẹ̀ lé, wọn ò ní in lọ́kàn láti dákẹ́ jẹ́ẹ́.—1 Kọ́ríńtì 11:7-15; Ìṣípayá 5:5.
-