ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Àṣírí Mímọ́ ti Ọlọ́run—Ọ̀nà Ológo Tó Gbà Parí!
    Ìṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
    • 8. (a) Ìyọrísí wo ni fífun kàkàkí keje ní lórí àwọn orílẹ̀-èdè? (b) Ta làwọn orílẹ̀-èdè ń bínú sí?

      8 Àmọ́ ṣá o, fífun kàkàkí keje kò mú ìdùnnú kankan wá fún àwọn orílẹ̀-èdè. Àkókò ti tó fún wọn láti rí ìbínú Jèhófà. Gẹ́gẹ́ bí Jòhánù ṣe sọ: “Ṣùgbọ́n àwọn orílẹ̀-èdè kún fún ìrunú, ìrunú tìrẹ sì dé, àti àkókò tí a yàn kalẹ̀ láti ṣèdájọ́ àwọn òkú, àti láti fi èrè wọn fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ wòlíì àti fún àwọn ẹni mímọ́ àti fún àwọn tí ń bẹ̀rù orúkọ rẹ, ẹni kékeré àti ẹni ńlá, àti láti run àwọn tí ń run ilẹ̀ ayé.” (Ìṣípayá 11:18) Látọdún 1914 wá làwọn orílẹ̀-èdè ayé ti ń bínú kíkankíkan sí ara wọn, sí Ìjọba Ọlọ́run àti pàápàá jù lọ sáwọn ẹlẹ́rìí méjì ti Jèhófà.—Ìṣípayá 11:3.

      9. Báwo làwọn orílẹ̀-èdè ṣe ń pa ilẹ̀ ayé run, kí sì ni Ọlọ́run ti pinnu láti ṣe nípa rẹ̀?

      9 Látìgbà ìwáṣẹ̀ làwọn orílẹ̀-èdè ti ń run ilẹ̀ ayé nítorí ogun tí wọ́n ń jà nígbà gbogbo àti nítorí ọ̀nà tí kò bójú mu tí wọ́n ń gbà bójú tó àwọn nǹkan. Ṣùgbọ́n láti ọdún 1914, bí wọ́n ṣe ń ba ilẹ̀ ayé jẹ́ yìí ti wá le sí i débi tó fi ń kó ìdààmú báni. Ìwọra àti ìwà ìbàjẹ́ ti mú kí ọ̀pọ̀ ilẹ̀ túbọ̀ máa di aṣálẹ̀ tí àwọn ilẹ̀ tó lè mú oúnjẹ jáde sì ń pòórá lọ́nà tó kàmàmà. Omi òjò tó ní èròjà olóró nínú ti ba ọ̀pọ̀lọpọ̀ àgbègbè jẹ́. Ọ̀pọ̀ ibi ti oúnjẹ ti ń wá làwọn èèyàn ti sọ di eléèérí. Atẹ́gùn tá à ń mí sínú àti omi tá à ń mu sì ti di eléèérí. Àwọn ìdọ̀tí tó ń wá látinú àwọn ilé iṣẹ́ ńláńlá fẹ́ fòpin sí ìwàláàyè àwọn nǹkan tó ń gbé lórí ilẹ̀ àti nínú òkun. Àwọn orílẹ̀-èdè tó jẹ́ alágbára láyé tiẹ̀ fẹ́ pa ayé run pátápátá nígbà kan nípa fífi ohun ìjà runlérùnnà pa ìran èèyàn run yán-ányán-án. Àmọ́ a láyọ̀ pé, Jèhófà yóò “run àwọn tí ń run ilẹ̀ ayé.” Yóò mú ìdájọ́ wá sórí àwọn agbéraga èèyàn tí wọn ò bẹ̀rù Ọlọ́run wọ̀nyẹn, tí wọ́n mú kí ilẹ̀ ayé wà ní ipò burúkú tó wà. (Diutarónómì 32:5, 6; Sáàmù 14:1-3) Ìdí nìyí tí Jèhófà fi ṣe ṣètò fún ègbé kẹta, kó lè mú kí àwọn oníwà àìtọ́ yìí dáhùn fún àwọn ohun tí wọ́n ṣe.—Ìṣípayá 11:14.

      Ègbé Ni Fáwọn Tó Ń Ba Ilẹ̀ Ayé Jẹ́!

      10. (a) Kí ni ègbé kẹta? (b) Ọ̀nà wo ni ègbé kẹta gbà mú ohun tó ju ìdálóró lọ wá?

      10 Ègbé kẹta ọ̀hún nìyí. Ó sì ń bọ̀ kíákíá! Òun ni Jèhófà yóò lò láti mú ìparun wá sórí àwọn tí ń ba “àpótí ìtìsẹ̀” rẹ̀ jẹ́, ìyẹn ilẹ̀ ayé tó lẹ́wà tí à ń gbé yìí. (Aísáyà 66:1) Ìjọba Mèsáyà, tó jẹ́ àṣírí ọlọ́wọ̀ ti Ọlọ́run ló mú egbé yìí wá. Ègbé méjì àkọ́kọ́ ti dá àwọn ọ̀tá Ọlọ́run lóró, pàápàá àwọn aṣáájú ìsìn ṣọ́ọ̀ṣì. Ìdálóró yìí sì wá ní pàtàkì látinú ìyọnu eéṣú àti agbo àwọn agẹṣinjagun. Ṣùgbọ́n ohun tó máa jẹ́ àbájáde ègbé kẹta tó ti ọwọ́ Ìjọba Jèhófà fúnra rẹ̀ wá yóò ju ìdálóró lọ. (Ìṣípayá 9:3-19) Yóò fa ọgbẹ́ ikú ní ti pé á lé àwùjọ ẹ̀dá èèyàn tí ń ṣèparun àtàwọn olùṣàkóso rẹ̀ jáde. Èyí ni Jèhófà yóò fi ṣe àṣekágbá ìdájọ́ rẹ̀ ní Amágẹ́dọ́nì. Bí Dáníẹ́lì ṣe sọ tẹ́lẹ̀ gẹ́lẹ́ ló rí pé: “Ní ọjọ́ àwọn ọba wọ̀nyẹn [àwọn alákòóso tí ń pa ilẹ̀ ayé run], Ọlọ́run ọ̀run yóò gbé ìjọba kan kalẹ̀ èyí tí a kì yóò run láé. Ìjọba náà ni a kì yóò sì gbé fún àwọn ènìyàn èyíkéyìí mìíràn. Yóò fọ́ ìjọba wọ̀nyí túútúú, yóò sì fi òpin sí gbogbo wọn, òun fúnra rẹ̀ yóò sì dúró fún àkókò tí ó lọ kánrin.” Bí òkè títóbi kan, Ìjọba Ọlọ́run yóò ṣe àkóso lé ayé lórí, ìyẹn ilẹ̀ ayé tí a ó sọ di ológo, yóò sì fi hàn pé Jèhófà ni ọba aláṣẹ, bẹ́ẹ̀ ni yóò sì mú ìdùnnú ayérayé wá fún aráyé.—Dáníẹ́lì 2:35, 44; Aísáyà 11:9; 60:13.

      11. (a) Àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ aláyọ̀ tó ń ṣẹlẹ̀ lọ́wọ́lọ́wọ́ wo ni àsọtẹ́lẹ̀ náà sọ nípa rẹ̀? (b) Inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí wo la máa rí gbà, ọ̀nà wo la ó fi rí i gbà, ta ló sì fi fúnni?

      11 Àwọn nǹkan aláyọ̀ tó ń ṣẹlẹ̀ báyìí tí yóò sì máa ṣẹlẹ̀ nìṣó ní ṣísẹ̀-n-tẹ̀lé jálẹ̀ ọjọ́ Olúwa, ń bá ègbé kẹta rìn. Ó jẹ́ àkókò ‘fún ṣíṣèdájọ́ àwọn òkú, àti fún Ọlọ́run láti fi èrè fún àwọn ẹrú rẹ̀ wòlíì àti fún àwọn ẹni mímọ́ àti fún àwọn tí ń bẹ̀rù orúkọ rẹ̀.’ Àjíǹde kúrò nínú ikú lèyí túmọ̀ sí o! Ní ti àwọn ẹni àmì òróró tó jẹ́ ẹni mímọ́ tí wọ́n ti sùn nínú ikú, èyí ṣẹlẹ̀ ní ìbẹ̀rẹ̀ ọjọ́ Olúwa. (1 Tẹsalóníkà 4:15-17) Bí àkókò ti ń lọ, àwọn ẹni mímọ́ tí wọ́n ṣẹ́ kù ń dara pọ̀ mọ́ àwọn wọ̀nyí nípasẹ̀ àjíǹde ojú ẹsẹ̀. Àwọn yòókù pẹ̀lú ni a ó san èrè fún, títí kan àwọn ẹrú Ọlọ́run tí wọ́n jẹ́ wòlíì láyé ìgbàanì àti gbogbo àwọn yòókù lára aráyé tí wọ́n bẹ̀rù orúkọ Jèhófà. Yálà wọ́n jẹ́ ara ogunlọ́gọ̀ ńlá tí yóò la ìpọ́njú ńlá já tàbí wọ́n jẹ́ ara “àwọn òkú, ẹni ńlá àti ẹni kékeré,” tí yóò jí dìde sí ìyè nígbà Ẹgbẹ̀rún ọdún Ìjọba Kristi. Níwọ̀n bí Mèsáyà Ọlọ́run tó jẹ́ Ọba ti ní kọ́kọ́rọ́ ikú àti ti Hédíìsì lọ́wọ́, Ìjọba rẹ̀ á mú kó ṣeé ṣe fún un láti fi ìyè àìnípẹ̀kun fún gbogbo àwọn tó sapá láti gba ìpèsè tó ṣeyebíye yẹn. (Ìṣípayá 1:18; 7:9, 14; 20:12, 13; Róòmù 6:22; Jòhánù 5:28, 29) Yálà ìyè àìleèkú ní ọ̀run tàbí ìyè ayérayé lórí ilẹ̀ ayé ló jẹ́ ti ẹnì kan, inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí látọ̀dọ̀ Jèhófà ni ẹ̀bùn ìyè yìí jẹ́, èyí tí ẹnì kọ̀ọ̀kan tó bá rí i gbà ní láti máa dúpẹ́ lọ́wọ́ Jèhófà fún títí láé!—Hébérù 2:9.

  • Àṣírí Mímọ́ ti Ọlọ́run—Ọ̀nà Ológo Tó Gbà Parí!
    Ìṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
    • [Àpótí tó wà ní ojú ìwé 175]

      Rírun Ilẹ̀ Ayé

      “Ní gbogbo ìṣẹ́jú àáyá mẹ́ta ni wọ́n ń pa igbó ẹgàn tó tóbi tó pápá ìṣeré bọ́ọ̀lù àfẹsẹ̀gbá run. . . . Pípa àwọn igbó ẹgàn run ń mú kí ẹgbẹẹgbẹ̀rún ọ̀wọ́ àwọn ewéko àti ẹran pa run.”—Illustrated Atlas of the World (Rand McNally).

      “Láàárín ọ̀rúndún méjì táwọn èèyàn fi gbé àgbègbè [àwọn adágún omi tá à ń pè ní Great Lakes], wọ́n di adágún omi tó lẹ́gbin jù lọ lágbàáyé.”—The Globe and Mail (Kánádà).

      Ní April 1986 ìbúgbàù àti iná tó wáyé nílé iṣẹ́ ẹ̀rọ kan tí wọ́n ti ń ṣe ohun ìjà runlé-rùnnà ní Chernobyl, lórílẹ̀-èdè Soviet Union tẹ́lẹ̀ rí, “ni ìṣẹ̀lẹ̀ runlé-rùnnà tó kàmàmà jù lọ . . . bá a bá yọwọ́ àdó olóró tí wọ́n jù sí ìlú Hiroshima àti Nagasaki.” Ìdí ni pé, ìṣẹ̀lẹ̀ náà tú “kẹ́míkà olóró tí kò tán bọ̀rọ̀ sínú atẹ́gùn, ilẹ̀ àti omi ayé, èyí sì tó gbogbo àdó olóró tí wọ́n ti jù gẹ́gẹ́ bí ìdánrawò.”—JAMA; The New York Times.

      Ní Minamata, Japan, ilé iṣẹ́ kan tó ń ṣe egbòogi tú èròjà olóró methylmercury sínú odò kan tó ya láti ara òkun. Nígbà táwọn èèyàn sì jẹ ẹja àti edé tó ti ní èròjà náà lára, ó fa àrùn Minamata (MD), ìyẹn “akọ àrùn ọpọlọ. . . . Títí di àkókò yìí [1985], ẹgbẹ̀jọ dín méjìlélógún [2,578] èèyàn jákèjádò Japan làwọn dókítà ti rí i pé wọ́n ní àrùn Minamata.”—International Journal of Epidemiology.

      [Àpótí tó wà ní ojú ìwé 176]

      Àwọn ìkéde rírinlẹ̀ tó wà nínú Ìṣípayá 11:15-19 jẹ́ ìṣẹ̀lẹ̀ tó ń sọ nípa àwọn ìran tó tẹ̀ lé e. Ìṣípayá orí Kejìlá jẹ́ àtúnyẹ̀wò tó ṣe ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ àlàyé lórí àwọn ìkéde àgbàyanu inú Ìṣípayá 11:15, 17. Orí Kẹtàlá fúnni ní ìsọfúnni tí ń lani lóye nípa orí Kọkànlá ẹsẹ kejìdínlógún, nítorí ó sọ ọ̀nà tí ètò ìṣèlú Sátánì tó ti mú ìparun wá sórí ilẹ̀ ayé gbà pilẹ̀ṣẹ̀ tó sì gbèrú. Orí Kẹrìnlá àti Ìkarùndínlógún ṣe ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ àlàyé síwájú sí i nípa àwọn ìdájọ́ Ìjọba Ọlọ́run, èyí tó ní í ṣe pẹ̀lú fífun kàkàkí keje àti ègbé kẹta.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́