-
Ṣíṣèdájọ́ Aṣẹ́wó Burúkú NáàÌṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
-
-
13. Ìran tí ń ṣeni ní kàyéfì wo ni Jòhánù rí nígbà tí áńgẹ́lì náà fi agbára ẹ̀mí gbé e lọ sínú aginjù?
13 Kí ló tún kù tí àsọtẹ́lẹ̀ náà ṣí payá nípa aṣẹ́wó ńlá náà àtohun tó máa ṣẹlẹ̀ sí i? Gẹ́gẹ́ bí Jòhánù ti sọ nísinsìnyí, ìran mìíràn tó hàn ketekete tún wá sí ojútáyé òun ni pé: “Ó [ìyẹn áńgẹ́lì náà] sì gbé mi nínú agbára ẹ̀mí lọ sínú aginjù kan. Mo sì tajú kán rí obìnrin kan tí ó jókòó lórí ẹranko ẹhànnà aláwọ̀ rírẹ̀dòdò tí ó kún fún àwọn orúkọ ọ̀rọ̀ òdì, tí ó sì ní orí méje àti ìwo mẹ́wàá.”—Ìṣípayá 17:3.
-
-
Ṣíṣèdájọ́ Aṣẹ́wó Burúkú NáàÌṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
-
-
15. Àwọn ìyàtọ̀ wo ló wà láàárín ẹranko ẹhànnà ti Ìṣípayá 13:1 àti ti Ìṣípayá 17:3?
15 Ẹranko ẹhànnà yìí ní orí méje àti ìwo mẹ́wàá. Àmọ́, ṣé ọ̀kan náà ni pẹ̀lú ẹranko ẹhànnà tí Jòhánù kọ́kọ́ rí, èyí tí òun pẹ̀lú ní orí méje àti ìwo mẹ́wàá? (Ìṣípayá 13:1) Bẹ́ẹ̀ kọ́, ìyàtọ̀ wà láàárín wọn. Ẹranko ẹhànnà kejì yìí jẹ́ aláwọ̀ rírẹ̀dòdò, àti pé, láìdà bí ẹranko ẹhànnà ìṣáájú, Jòhánù kò sọ pé ó ní adé dáyádémà. Orí ẹ̀ méjèèje nìkan kọ́ làwọn orúkọ ọ̀rọ̀ òdì wà, kàkà bẹ́ẹ̀, ńṣe ni gbogbo ara rẹ̀ “kún fún àwọn orúkọ ọ̀rọ̀ òdì.” Àmọ́ láìka èyí sí, nǹkan kan gbọ́dọ̀ da ẹranko ẹhànnà tuntun yìí àti ti àkọ́kọ́ pọ̀; ìjọra tó wà láàárín wọn pọ̀ débi pé kò lè jẹ́ pé wọ́n ṣèèṣì jọra ni.
16. Kí lohun tí ẹranko ẹhànnà aláwọ̀ rírẹ̀dòdò náà jẹ́, kí sì nìdí tí wọ́n sọ pé wọ́n fi dá a sílẹ̀?
16 Kí wá ni ẹranko ẹhànnà aláwọ̀ rírẹ̀dòdò tuntun yìí? Ó ní láti jẹ́ pé òun ni ère ẹranko ẹhànnà tí wọ́n mú jáde látàrí ìsapá ẹranko ẹhànnà tó ní ìwo méjì bí ọ̀dọ́ àgùntàn, èyí tó dúró fún agbára ayé Gẹ̀ẹ́sì òun Amẹ́ríkà. Lẹ́yìn tí wọ́n ti ṣe ère náà, ẹranko ẹhànnà oníwo méjì yẹn ni a yọ̀ǹda fún láti fi èémí fún ère ẹranko ẹhànnà náà. (Ìṣípayá 13:14, 15) Nísinsìnyí Jòhánù wá rí ère tó wà lóòyẹ̀, tí ń mí. Ó ṣàpẹẹrẹ àjọ Ìmùlẹ̀ Àwọn Orílẹ̀-Èdè tí ẹranko ẹhànnà oníwo méjì náà mú wá sí ìyè lọ́dún 1920. Ààrẹ orílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà náà, Wilson, ti fọkàn yàwòrán pé àjọ Ìmùlẹ̀ náà “yóò jẹ́ ibi ìjíròrò fún mímú kí wọ́n máa ṣe ẹ̀tọ́ fún gbogbo èèyàn, yóò sì fòpin sí ogun títí láé.” Nígbà tí wọ́n jí àjọ náà dìde lẹ́yìn Ogun Àgbáyé Kejì gẹ́gẹ́ bí Ìparapọ̀ Àwọn Orílẹ̀-Èdè, ìdí tí wọ́n fi dá a sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bó ṣe wà nínú ìwé àṣẹ ìdásílẹ̀ ni “láti rí i pé àlàáfíà àti ààbò wà lágbàáyé.”
-