ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Ṣíṣèdájọ́ Aṣẹ́wó Burúkú Náà
    Ìṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
    • 25. (a) Kí làwọn ohun tó wà nínú “ife wúrà kan tí ó kún fún àwọn ohun ìríra” ṣàpẹẹrẹ? (b) Kí ni mímu tí aṣẹ́wó ìṣàpẹẹrẹ náà mu àmupara túmọ̀ sí?

      25 Nísinsìnyí, wá wo ohun tó wà lọ́wọ́ aṣẹ́wó náà. Ẹ̀rù ti gbọ́dọ̀ ba Jòhánù bó ṣe rí ohun kan, ìyẹn ni ife wúrà kan tó “kún fún àwọn ohun ìríra àtàwọn ohun àìmọ́ àgbèrè rẹ̀”! Èyí ni ife tí “wáìnì ìbínú àgbèrè rẹ̀” wà nínú rẹ̀, èyí tó fi mú kí gbogbo orílẹ̀-èdè mu àmupara. (Ìṣípayá 14:8; 17:4) Ife náà fara hàn bí ohun tó dára lóde, ṣùgbọ́n àwọn ohun ìríra, ohun aláìmọ́ ló wà nínú rẹ̀. (Fi wé Mátíù 23:25, 26.) Gbogbo àwọn àṣà ẹlẹ́gbin àti irọ́ tí aṣẹ́wó ńlá náà ti lò láti yí àwọn orílẹ̀-èdè lérò padà àti láti mú wọn wá sábẹ́ agbára rẹ̀ ló wà nínú ife náà. Èyí tó tiẹ̀ túbọ̀ wá ríni lára ni pé, Jòhánù rí i pé aṣẹ́wó náà fúnra rẹ̀ ti yó kẹ́ri, ó ti mu ẹ̀jẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ Ọlọ́run ní àmupara! Àní, ohun tí Bíbélì tún sọ níwájú ni pé “nínú rẹ̀ ni a ti rí ẹ̀jẹ̀ àwọn wòlíì àti ti àwọn ẹni mímọ́ àti ti gbogbo àwọn tí a ti fikú pa lórí ilẹ̀ ayé.” (Ìṣípayá 18:24) Ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ yìí mà pọ̀ o!

      26. Ẹ̀rí wo ló wà pé Bábílónì Ńlá jẹ̀bi ẹ̀jẹ̀?

      26 Láti ọ̀pọ̀ ọ̀rúndún sẹ́yìn ni ilẹ̀ ọba ìsìn èké àgbáyé ti ń ta ọ̀pọ̀ ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀. Bí àpẹẹrẹ, lórílẹ̀-èdè Japan nígbà ojú dúdú, wọ́n sọ àwọn tẹ́ńpìlì ìlú Kyoto di ibi odi agbára, àwọn àlùfáà ajẹ́jẹ̀ẹ́ ìnìkàngbé tí wọ́n jẹ́ jagunjagun, tí wọ́n ń gbàdúrà ní “orúkọ mímọ́ Búdà,” sì ń bá ara wọn jà lẹ́nì kìíní-kejì títí àwọn ojú pópó fi pọ́n dẹ̀dẹ̀ fún ẹ̀jẹ̀. Ní ọ̀rúndún ogún, àwọn àlùfáà ṣọ́ọ̀ṣì yan pẹ̀lú àwọn ọmọ ogun orílẹ̀-èdè wọn, àwọn ọmọ ogun yìí sì ń pa ara wọn nípakúpa, pẹ̀lú àdánù ẹ̀mí tó tó àádọ́ta ọ̀kẹ́ lọ́nà ọgọ́rùn-ún [100,000,000], ó kéré tán. Ní October 1987, ààrẹ orílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà tẹ́lẹ̀ rí Nixon sọ pé: “Ọ̀rúndún ogún yìí ni wọ́n tíì ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀ jù lọ rí. Àwọn èèyàn tó bógun lọ ní ọ̀rúndún yìí pọ̀ ju àwọn tó kú nínú gbogbo ogun tí wọ́n ti jà kí ọ̀rúndún yìí tó bẹ̀rẹ̀.” Ọlọ́run yóò dá àwọn ìsìn ayé lẹ́jọ́ nítorí ipa tí wọ́n kó nínú gbogbo èyí; Jèhófà kórìíra “ọwọ́ tí ń ta ẹ̀jẹ̀ aláìmọwọ́-mẹsẹ̀ sílẹ̀.” (Òwe 6:16, 17) Ṣáájú èyí, Jòhánù ti gbọ́ igbe kan láti ibi pẹpẹ: “Títí di ìgbà wo, Olúwa Ọba Aláṣẹ mímọ́ àti olóòótọ́, ni ìwọ ń fà sẹ́yìn kúrò nínú ṣíṣèdájọ́ àti gbígbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ wa lára àwọn tí ń gbé lórí ilẹ̀ ayé?” (Ìṣípayá 6:10) Nígbà tí àkókò náà bá dé láti dáhùn ìbéèrè yẹn, ọ̀rọ̀ náà á kan Bábílónì Ńlá, ìyá àwọn aṣẹ́wó àtàwọn ohun ìríra ilẹ̀ ayé gbọ̀ngbọ̀n.

  • A Rí Ojútùú Ohun Ìjìnlẹ̀ Kan Tó Ṣeni Ní Kàyéfì
    Ìṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
    • 1. (a) Kí ló ṣe Jòhánù nígbà tó rí aṣẹ́wó ńlá náà àti ẹranko ẹlẹ́rùjẹ̀jẹ̀ tó ń gùn, kí sì nìdí? (b) Kí ló ṣe ẹgbẹ́ Jòhánù lóde òní bí àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ tó ń mú ìran alásọtẹ́lẹ̀ náà ṣẹ ṣe ń ṣẹlẹ̀?

      KÍ LÓ ṣe Jòhánù nígbà tó rí aṣẹ́wó ńlá náà àti ẹranko ẹlẹ́rùjẹ̀jẹ̀ tó ń gùn? Òun fúnra rẹ̀ sọ pé: “Tóò, ní títajúkán rí i, kàyéfì ńlá ṣe mí.” (Ìṣípayá 17:6b) Ẹ̀dá èèyàn ò lè dá ronú kan irú ohun abàmì bẹ́ẹ̀ rárá. Síbẹ̀, ohun abàmì yìí ṣẹlẹ̀ nínú aginjù lọ́hùn-ún. Aṣẹ́wó oníwàkiwà kan ń gun abàmì ẹranko ẹhànnà kan tó ní àwọ̀ rírẹ̀dòdò! (Ìṣípayá 17:3) Kàyéfì ńlá ṣe ẹgbẹ́ Jòhánù lóde òní pẹ̀lú bí àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ tó ń mú ìran alásọtẹ́lẹ̀ náà ṣẹ ṣe ń ṣẹlẹ̀. Ká ní àwọn èèyàn ayé lè rí i ni, wọn ì bá kígbe pé, ‘Èèmọ̀ rè é!,’ àwọn olùṣàkóso ayé ì bá sì sọ pé, ‘Áà, kí rèé!’ Ṣùgbọ́n ìran tó ṣeni ní kàyéfì yìí ń nímùúṣẹ lóòótọ́ lákòókò wa yìí. Àwọn èèyàn Ọlọ́run ti kópa tó pọ̀ nínú ìmúṣẹ ìran náà, èyí sì jẹ́ kó dá wọn lójú pé àsọtẹ́lẹ̀ ìran náà yóò ní ìmúṣẹ rẹ̀ yíyanilẹ́nu tó kẹ́yìn.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́