-
Pípa Bábílónì Ńlá RunÌṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
-
-
1. Báwo ni áńgẹ́lì náà ṣe ṣàlàyé ẹranko ẹhànnà aláwọ̀ rírẹ̀dòdò yẹn, irú ọgbọ́n wo la sì nílò láti lóye àwọn ohun ìṣàpẹẹrẹ inú Ìṣípayá?
ÁŃGẸ́LÌ náà tún ṣàlàyé síwájú sí i fún Jòhánù nípa ẹranko ẹhànnà aláwọ̀ rírẹ̀dòdò tí Ìṣípayá 17:3 sọ náà, ó ní: “Níhìn-ín ni ibi tí làákàyè tí ó ní ọgbọ́n ti wọlé: Orí méje náà túmọ̀ sí òkè ńlá méje, níbi tí obìnrin náà jókòó lé. Ọba méje ni ó sì ń bẹ: márùn-ún ti ṣubú, ọ̀kan wà, ọ̀kan tí ó kù kò tí ì dé, ṣùgbọ́n nígbà tí ó bá dé, yóò dúró fún ìgbà kúkúrú.” (Ìṣípayá 17:9, 10) Ọgbọ́n tó wá látòkè ni áńgẹ́lì yìí ń sọ, ìyẹn ọgbọ́n kan ṣoṣo tó lè mú wa lóye àwọn ohun ìṣàpẹẹrẹ inú ìwé Ìṣípayá. (Jákọ́bù 3:17) Ọgbọ́n yìí ló ń mú kí ẹgbẹ́ Jòhánù àtàwọn alábàákẹ́gbẹ́ rẹ̀ lóye bí àkókò tá à ń gbé yìí ti ṣe pàtàkì tó. Ó ń jẹ́ káwọn tó ń fi gbogbo ọkàn sin Jèhófà mọrírì àwọn ìdájọ́ Jèhófà tó máa wáyé láìpẹ́, ó sì ń jẹ́ ká mọ bá a ṣe lè bẹ̀rù Jèhófà lọ́nà tó yẹ. Gẹ́gẹ́ bí Òwe 9:10 ṣe wí: “Ìbẹ̀rù Jèhófà ni ìbẹ̀rẹ̀ ọgbọ́n, ìmọ̀ Ẹni Mímọ́ Jù Lọ sì ni ohun tí òye jẹ́.” Kí ni ọgbọ́n Ọlọ́run ṣí payá fún wa nípa ẹranko ẹhànnà yìí?
2. Kí ni ìtumọ̀ orí méje ẹranko ẹhànnà aláwọ̀ rírẹ̀dòdò náà, báwo ló sì ṣe jẹ́ pé “márùn-ún ti ṣubú, [tí] ọ̀kan [sì] wà”?
2 Orí méje ẹranko tó rorò yẹn túmọ̀ sí “òkè ńlá” méje, tàbí “ọba” méje. Ìwé Mímọ́ lo èdè méjèèjì náà láti tọ́ka sí agbára ìṣàkóso. (Jeremáyà 51:24, 25; Dáníẹ́lì 2:34, 35, 44, 45) Bíbélì mẹ́nu kan agbára ayé mẹ́fà tí wọ́n ti ní ipa kan tàbí òmíràn lórí ìgbòkègbodò àwọn èèyàn Ọlọ́run. Àwọn agbára ayé náà ni: Íjíbítì, Ásíríà, Bábílónì, Mídíà òun Páṣíà, Gíríìsì, àti Róòmù. Lákòókò tí Jòhánù rí ìran Ìṣípayá yìí, márùn-ún lára àwọn agbára ayé náà ò sí mọ́, Róòmù ló wà nípò gẹ́gẹ́ bí agbára ayé nígbà náà. Èyí bá gbólóhùn náà mu pé, “márùn-ún ti ṣubú, ọ̀kan wà.” Ṣùgbọ́n èwo ni “ọ̀kan tí ó kù” tí ò tíì dé?
-
-
Pípa Bábílónì Ńlá RunÌṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
-
-
6. Àwọn orílẹ̀-èdè wo tó fẹ́ máa ṣàkóso gbogbo ayé ló bọ́ sójútáyé, èwo ló sì kẹ́sẹ járí jù lọ nínú wọn?
6 Ṣùgbọ́n, nígbà tó di ọ̀rúndún kẹẹ̀ẹ́dógún, àwọn orílẹ̀-èdè kan bẹ̀rẹ̀ sí í wá ọ̀nà àtidá àwọn ilẹ̀ ọba tuntun sílẹ̀. Bó tilẹ̀ jẹ́ pé ara àwọn ibi tí Ilẹ̀ Ọba Róòmù ń ṣàkóso nígbà kan rí ni díẹ̀ lára àwọn orílẹ̀-èdè tó ń gbèrò àtidi ilẹ̀ ọba wọ̀nyí, ìṣàkóso wọn yàtọ̀ sí ti Róòmù pátápátá. Ilẹ̀ Potogí, Sípéènì, Faransé àti Holland wá ń gbókèèrè ṣàkóso àwọn ilẹ̀ mìíràn. Ṣùgbọ́n Ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì ló kẹ́sẹ járí jù lọ nítorí pé ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè ló ń ṣàkóso lé lórí tó sì tipa bẹ́ẹ̀ jẹ́ ilẹ̀ ọba gbígbòòrò kan tó jẹ́ pé bí oòrùn bá ṣe ń wọ̀ ní apá kan ilẹ̀ ọba rẹ̀ ni yóò máa yọ ní ibòmíràn. Díẹ̀díẹ̀ ni àkóso ilẹ̀ ọba yìí ń tàn títí tó fi dé ọ̀pọ̀ lára àwọn orílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà ti Àríwá, Áfíríkà, Íńdíà, àti Ìlà Oòrùn Éṣíà tó fi mọ́ àwọn Gúúsù Pàsífíìkì tó lọ salalu.
7. Báwo ló ṣe di pé orílẹ̀-èdè méjì para pọ̀ di agbára ayé, báwo sì ni Jòhánù ṣe sọ pé ‘orí’ keje, tàbí agbára ayé keje, ṣe máa pẹ́ tó?
7 Nígbà tó fi máa di ọ̀rúndún kọkàndínlógún, díẹ̀ lára àwọn ibi tí Ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì ń gbókèèrè ṣàkóso lé lórí ní Amẹ́ríkà ti Àríwá ti kúrò lábẹ́ Ìjọba Ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì tí wọ́n sì para pọ̀ di Orílẹ̀-Èdè Amẹ́ríkà. Àmọ́ rògbòdìyàn òṣèlú ṣì ń bá a lọ láàárín orílẹ̀-èdè tuntun náà àti Ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì tó ń ṣàkóso rẹ̀ tẹ́lẹ̀. Ṣùgbọ́n Ogun Àgbáyé Kìíní jẹ́ kí orílẹ̀-èdè méjèèjì rí ìdí tó fi yẹ kí wọ́n jọ fìmọ̀ ṣọ̀kan, ni wọ́n bá jọ wọnú àjọṣe tó jinlẹ̀. Bí orílẹ̀-èdè méjèèjì, ìyẹn Orílẹ̀-Èdè Amẹ́ríkà tó jẹ́ orílẹ̀-èdè tó lọ́rọ̀ jù lọ báyìí àti Ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì tó ń ṣàkóso ibi tó pọ̀ jù lọ ṣe para pọ̀ di agbára ayé nìyẹn, tí wọ́n jọ ń ṣàkóso gbogbo ayé. Ìṣàkóso tá à ń sọ yìí ni ‘orí’ keje, tàbí agbára ayé keje, èyí tó ṣì wà lójú ọpọ́n ní àkókò òpin yìí, tó sì ń ṣàkóso àgbègbè táwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà òde òní kọ́kọ́ fìdí múlẹ̀ sí. Bá a bá fi ìwọ̀n àkókò tí orí keje fi ṣàkóso wé èyí tí orí kẹfà fi ṣàkóso, “ìgbà kúkúrú” ni orí keje fi máa wà títí dìgbà tí Ìjọba Ọlọ́run fi máa pa gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tó kù run.
-