ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Ìlú Ńlá Náà Pa Run
    Ìṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
    • Wáìnì Tí Ń Ru Ìfẹ́ Ìgbónára Sókè

      13. (a) Báwo ni áńgẹ́lì alágbára ńlá náà ṣe pe àfiyèsí sí bí ìwà aṣẹ́wó Bábílónì Ńlá ṣe gbòòrò tó? (b) Ìwà ìṣekúṣe wo ló wọ́pọ̀ ní Bábílónì ìgbàanì tá a tún rí nínú Bábílónì Ńlá?

      13 Lẹ́yìn èyíinì, áńgẹ́lì alágbára ńlá náà pe àfiyèsí sí bí ìwà aṣẹ́wó Bábílónì Ńlá ṣe gbòòrò tó, ó pòkìkí pé: “Nítorí pé tìtorí wáìnì tí ń ru ìfẹ́ ìgbónára àgbèrè rẹ̀ sókè,a gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè ti di ẹran-ìjẹ, àwọn ọba ilẹ̀ ayé sì bá a ṣe àgbèrè, àwọn olówò arìnrìn-àjò ilẹ̀ ayé sì di ọlọ́rọ̀ nítorí agbára fàájì aláìnítìjú rẹ̀.” (Ìṣípayá 18:3) Bábílónì Ńlá ti fi àwọn ohun àṣà àìmọ́ tó wà nínú ìsìn rẹ̀ kọ́ gbogbo orílẹ̀-èdè ayé. Gẹ́gẹ́ bí Herodotus òpìtàn Gíríìkì ti wí, ní Bábílónì ìgbàanì, wọ́n fi dandan lé e pé kí gbogbo omidan fi ipò wúńdíá rẹ̀ ṣe iṣẹ́ aṣẹ́wó nínú ìjọsìn tí wọ́n ń ṣe nínú tẹ́ńpìlì wọn. Dòní olónìí, ìwà ìṣekúṣe tí ń ríni lára ni àwọn ère gbígbẹ́ tí ogun ti bà jẹ́ tó wà ní Angkor Wat lórílẹ̀-èdè Kampuchea ń gbé lárugẹ, bẹ́ẹ̀ náà sì ni àwọn ère tó wà nínú tẹ́ńpìlì tó wà ní Khajuraho, nílẹ̀ Íńdíà. Àwọn ère náà fi ọlọ́run Vishnu hàn láàárín àwọn àwòrán rírínilára tó ń mú kí ọkàn fà sí ìṣekúṣe. Lórílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà, àṣírí ìwà ìṣekúṣe àwọn ajíhìnrere orí tẹlifíṣọ̀n tú síta lọ́dún 1987 àti lọ́dún 1988, èyí tó fì wọ́n làkàlàkà. Bákan náà, àṣírí àwọn òjíṣẹ́ ìsìn tó ń bá ẹ̀yà kan náà lò pọ̀ tú. Gbogbo ìṣẹ̀lẹ̀ wọ̀nyí fi hàn pé àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì pàápàá fàyè gba ìwà àgbèrè lọ́nà tó pabanbarì. Àmọ́, gbogbo orílẹ̀-èdè ti kó sínú páńpẹ́ oríṣi ìwà àgbèrè mìíràn tó burú jáì.

      14-16. (a) Àjọṣe tí kò bófin mu wo ló wà láàárín ìsìn àti ìṣèlú nílẹ̀ Ítálì tí ìjọba Oníkùmọ̀ ń ṣàkóso? (b) Nígbà tí Ítálì gbógun ti ilẹ̀ Abisíníà, kí làwọn bíṣọ́ọ̀bù Ṣọ́ọ̀ṣì Kátólíìkì sọ?

      14 Tẹ́lẹ̀tẹ́lẹ̀ a ti ṣàgbéyẹ̀wò àjọṣe aláìbófinmu tó wà láàárín ìsìn àti ìṣèlú, èyí tó gbé Hitler dé ipò olórí ìjọba Násì nílẹ̀ Jámánì. Àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn pẹ̀lú jìyà nítorí títì tí ìsìn tojú bọ àwọn ohun tó ń lọ nínú ayé. Bí àpẹẹrẹ: Nílẹ̀ Ítálì tí ìjọba aláṣẹ oníkùmọ̀ ti ń ṣàkóso, ní ọjọ́ kọkànlá oṣù February, ọdún 1929, Mussolini àti Kádínà Gasparri fọwọ́ sí Àdéhùn Lateran tó sọ Ìlú Vatican di ìpínlẹ̀ olómìnira tí ń ṣe ìjọba lórí ara rẹ̀. Póòpù Pius Kọkànlá sọ pé òun ti “dá Ítálì padà fún Ọlọ́run, àti Ọlọ́run padà fún Ítálì.” Àmọ́, ṣé òótọ́ ni? Ó dáa, ẹ jẹ́ ká wo ohun tó ṣẹlẹ̀ ní ọdún mẹ́fà lẹ́yìn náà. Ní ọjọ́ kẹta oṣù October, ọdún 1935, Ítálì gbógun ti ilẹ̀ Abisíníà, ó sọ pé Abisíníà jẹ́ “ilẹ̀ oníwà òǹrorò tó ṣì ń ṣe òwò ẹrú.” Àmọ́ ká sọ̀rọ̀ síbi tọ́rọ̀ wà, ta ni òǹrorò nínú àwọn méjèèjì? Ǹjẹ́ Ṣọ́ọ̀ṣì Kátólíìkì dẹ́bi fún ìwà ìkà tí Mussolini hù? Nígbà tí póòpù ń sọ̀rọ̀, ọ̀rọ̀ tí ò lè tètè yé èèyàn ló lò, àmọ́ àwọn bíṣọ́ọ̀bù rẹ̀ ò ṣẹ́ ọ̀rọ̀ kù sábẹ́ ahọ́n nígbà tí wọ́n ń gbàdúrà fún àwọn ọmọ ogun Ítálì “ilẹ̀ baba” wọn. Nínú ìwé náà, The Vatican in the Age of the Dictators, Anthony Rhodes ròyìn pé:

      15 “Nínú Lẹ́tà Olùṣọ́ Àgùntàn rẹ̀ ti ọjọ́ kọkàndínlógún oṣù October ọdún [1935], Bíṣọ́ọ̀bù ìlú Udine [ní Ítálì] kọ̀wé pé, ‘Kò bákòókò mu bẹ́ẹ̀ sì ni kò yẹ ká sọ̀rọ̀ nípa bóyá ohun tá à ń ṣe náà dára tàbí kò dára. Bó ṣe jẹ́ pé ọmọ ilẹ̀ Ítálì ni wá, pàápàá jù lọ tá a tún jẹ́ Kristẹni, ojúṣe wa ni láti ṣe ipa tiwa nínú bí àwọn ohun ìjà ilẹ̀ wa á ṣe ṣàṣeyọrí.’ Ní ọjọ́ kọkànlélógún oṣù October, Bíṣọ́ọ̀bù ìlú Padua kọ̀wé pé, ‘Ní àkókò lílekoko tá a wà yìí, a rọ̀ yín pé kẹ́ ẹ nígbàgbọ́ nínú àwọn olóṣèlú wa àtàwọn ọmọ ogun wa.’ Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù October, Bíṣọ́ọ̀bù ìlú Cremona ya àwọn àsíá ẹgbẹ́ ọmọ ogun sí mímọ́ ó sì sọ pé: ‘Kí ìbùkún Ọlọ́run wà lórí àwọn ọmọ ogun wa wọ̀nyí tí wọn yóò lọ sí Áfíríkà láti ṣẹ́gun àwọn ilẹ̀ ọlọ́ràá fún Ítálì àgbà orílẹ̀-èdè, tí wọ́n á sì tipa bẹ́ẹ̀ mú kí wọ́n gba àṣà ilẹ̀ Róòmù àti ti ẹ̀sìn Kristẹni. Ǹjẹ́ kí Ítálì tún ṣe ojúṣe rẹ̀ lẹ́ẹ̀kan sí i gẹ́gẹ́ bí orílẹ̀-èdè tó ń fi ẹ̀sìn Kristẹni kọ́ gbogbo ayé.’”

      16 Àwọn àlùfáà Ṣọ́ọ̀ṣì Kátólíìkì ló gbàdúrà fáwọn ọmọ ogun tó gbógun ja ilẹ̀ Abisíníà. Lọ́nàkọnà, ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni nínú àwọn wọ̀nyí lè sọ pé àwọ́n dà bí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù tí ‘ọrùn rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ẹ̀jẹ̀ èèyàn gbogbo’?—Ìṣe 20:26.

      17. Báwo ni ìyà ṣe jẹ́ orílẹ̀-èdè Sípéènì nítorí pé àwọn àlùfáà rẹ̀ kò “fi idà wọn rọ abẹ ohun ìtúlẹ̀”?

      17 Yàtọ̀ sí Jámánì, Ítálì àti Abisíníà, Sípéènì ni orílẹ̀-èdè mìíràn tójú rẹ̀ rí màbo látàrí ìwà àgbèrè Bábílónì Ńlá. Ohun tí ìjọba dẹmọ ṣe láti dín agbára ńlá tí Ṣọ́ọ̀ṣì Kátólíìkì ní kù wà lára ohun tó mú kí Ogun Abẹ́lé wáyé nílẹ̀ Sípéènì lọ́dún 1936 sí 1939. Nígbà tí ogun abẹ́lé náà bẹ̀rẹ̀, Franco onísìn Kátólíìkì, tó jẹ́ olórí ìjọba aláṣẹ oníkùmọ̀ àti aṣáájú àwọn ọmọ ogun aṣọ̀tẹ̀-síjọba, sọ pé òun jẹ́ “Olórí Ogun Mímọ́ Tí Ìsìn Kristẹni Ń Jà,” ó sì pa oyè yẹn tì nígbà tó yá. Ẹgbẹẹgbẹ̀rún àwọn ará Sípéènì ló kú nínú ogun abẹ́lé náà. Yàtọ̀ sí èyí, iye kan tí wọ́n bù kéré fi hàn pé, àwọn Aṣọ̀tẹ̀-síjọba ọmọlẹ́yìn Franco pa ẹgbẹ̀rún lọ́nà ogójì [40,000] àwọn ọmọ ẹgbẹ́ òṣèlú Popular Front, ẹgbẹ́ òṣèlú Popular Front pẹ̀lú sì pa ẹgbẹ̀rún mẹ́jọ [8,000] àwọn abẹnugan nínú ìsìn, ìyẹn àwọn ọkùnrin ajẹ́jẹ̀ẹ́ ìnìkàngbé, àwọn àlùfáà, àwọn obìnrin ajẹ́jẹ̀ẹ́ ìnìkàngbé, àtàwọn tó ń múra àtidi obìnrin ajẹ́jẹ̀ẹ́ ìnìkàngbé. Ìpayà àti àdánù tí ogun abẹ́lé yẹn fà kàmàmà, ó sì fi hàn pé ìwà ọgbọ́n ni kéèyàn ṣègbọràn sí ọ̀rọ̀ tí Jésù sọ, pé: “Dá idà rẹ padà sí àyè rẹ̀, nítorí gbogbo àwọn tí wọ́n bá ń mú idà yóò ṣègbé nípasẹ̀ idà.” (Mátíù 26:52) Ẹ wo bó ti ń kóni nírìíra tó pé àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì lọ́wọ́ nínú ìtàjẹ̀sílẹ̀ tó burú jáì yìí! Dájúdájú, àwọn àlùfáà wọn ò “fi idà wọn rọ abẹ ohun ìtúlẹ̀” rárá!—Aísáyà 2:4.

  • Ìlú Ńlá Náà Pa Run
    Ìṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
    • [Àpótí tó wà ní ojú ìwé 263]

      “Àwọn Ọba . . . Bá A Ṣe Àgbèrè”

      Ní apá ìbẹ̀rẹ̀ ọ̀rúndún tó bẹ̀rẹ̀ ní ọdún 1800, àwọn olówò ará Yúróòpù ń ṣe fàyàwọ́ oògùn olóró opium púpọ̀ gan-an wọ ilẹ̀ Ṣáínà. Ní oṣù March ọdún 1839 àwọn aláṣẹ ará Ṣáínà gbìyànjú láti dáwọ́ òwò aláìbófinmu náà dúró nípa fífi ipá gba ọ̀kẹ́ kan [20,000] àpótí oògùn olóró náà lọ́wọ́ àwọn oníṣòwò ará Ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì. Èyí yọrí sí gbọ́nmi-sí-omi-ò-tó láàárín Ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì àti Ṣáínà. Bí àjọṣe tó wà láàárín orílẹ̀-èdè méjèèjì yẹn ṣe ń bà jẹ́ sí i, àwọn míṣọ́nárì ìjọ Pùròtẹ́sítáǹtì kan rọ Ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì láti sọ ọ́ di ogun, wọ́n sọ gbólóhùn bíi:

      “Gbọ́nmi-si-omi-ò-to yìí mú inú mi dùn nítorí pé mo rò pé ó lè mú kí ìjọba Ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì bínú, Ọlọ́run nínú agbára rẹ̀ sì lè lo ìyẹn láti fi wó ògiri ìdènà tí kò jẹ́ kí ìhìn rere nípa Kristi wọ ilẹ̀ Ṣáínà.”—Ẹni tó sọ bẹ́ẹ̀ ni Henrietta Shuck, tó jẹ́ míṣọ́nárì ìjọ Southern Baptist.

      Níkẹyìn, ogun bẹ́ sílẹ̀, ìyẹn ogun tá a mọ̀ lónìí sí Ogun Opium. Gbogbo ọkàn làwọn míṣọ́nárì ṣọ́ọ̀ṣì fi fún Ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì níṣìírí láti jà nípa sísọ àwọn ọ̀rọ̀ bí ìwọ̀nyí:

      “Mo rí i pé mi ò gbọ́dọ̀ wo ohun tó ń ṣẹlẹ̀ yìí gẹ́gẹ́ bí Ogun Opium tàbí ogun Ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì, kàkà bẹ́ẹ̀, mo rí i pé Ọlọ́run ló ń lo ìwà ibi èèyàn láti fi fọ́ ohun ìdènà tí kò jẹ́ kí àánú rẹ̀ ráyè wọ ilẹ̀ Ṣáínà.”—Ẹni tó sọ bẹ́ẹ̀ ni Peter Parker, tó jẹ́ míṣọ́nárì ìjọ Congregational.

      Ọ̀gbẹ́ni Samuel W. Williams, tóun náà jẹ́ míṣọ́nárì ìjọ Congregational fi kún un pé: “Ó hàn gbangba pé ọwọ́ Ọlọ́run wà nínú gbogbo ohun tó ṣẹlẹ̀ yìí, a kò sì ṣiyè méjì pé Ẹni tó sọ pé Òun wá láti mú idà wá sórí ayé ti dé láti yára pa àwọn ọ̀tá Rẹ̀ run kó sì bẹ̀rẹ̀ ìjọba Rẹ̀. Yóò máa sojú wọn dé nìṣó títí yóò fi fìdí Ọmọ Aládé Àlàáfíà náà múlẹ̀.”

      Míṣọ́nárì tórúkọ rẹ̀ ń jẹ́ J. Lewis Shuck kọ̀wé nípa bí wọ́n ṣe pa àwọn ọmọ ilẹ̀ Ṣáínà nípakúpa, ó ní: “Mo ka irú nǹkan bẹ́ẹ̀ . . . sí ohun èlò tí Olúwa lò láti fi gbá àwọn pàǹtírí tí ń dènà ìlọsíwájú Ẹ̀kọ́ Òtítọ́ Ọlọ́run dà nù.”

      Míṣọ́nárì ìjọ Congregational kan tórúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Elijah C. Bridgman fi kún un pé: “Ọ̀pọ̀ ìgbà ni Ọlọ́run ti lo agbára èèyàn láti fi lànà sílẹ̀ fún ìjọba Rẹ̀ . . . Irinṣẹ́ lásán lèèyàn kàn jẹ́ nínú ṣíṣẹ ohun pàtàkì yìí; Ọlọ́run gan-an lẹni tó ń fi agbára rẹ̀ darí wọn. Gómìnà ńlá gbogbo orílẹ̀-èdè ló lo Ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì láti fìyà jẹ ilẹ̀ Ṣáínà àti láti rẹ̀ ẹ́ wálẹ̀.”—A mú ọ̀rọ̀ yìí látinú àpilẹ̀kọ náà, “Ends and Means,” tí Stuart Creighton Miller kọ lọ́dún 1974 tí wọ́n sì tẹ̀ jáde nínú ìwé The Missionary Enterprise in China and America (Ìwádìí tí Harvard ṣe tí John K. Fairbank sì ṣàtúntẹ̀ rẹ̀).

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́