ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Ìlú Ńlá Náà Pa Run
    Ìṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
    • 22. (a) Kí ni ohùn kan láti ọ̀run wí? (b) Kí ló máyọ̀ wá fún àwọn èèyàn Ọlọ́run lọ́dún 537 ṣááju Sànmánì Kristẹni àti lọ́dún 1919?

      22 Ọ̀rọ̀ tí Jòhánù sọ tẹ̀ lé e tún tọ́ka sí ìmúṣẹ àsọtẹ́lẹ̀, ó ní: “Mo sì gbọ́ tí ohùn mìíràn láti ọ̀run wá wí pé: ‘Ẹ jáde kúrò nínú rẹ̀, ẹ̀yin ènìyàn mi, bí ẹ kò bá fẹ́ ṣàjọpín pẹ̀lú rẹ̀ nínú àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, bí ẹ kò bá sì fẹ́ gbà lára àwọn ìyọnu àjàkálẹ̀ rẹ̀.’” (Ìṣípayá 18:4) Nínú Ìwé Mímọ́, ara ohun tí àwọn àsọtẹ́lẹ̀ nípa ìṣubú Bábílónì ayé ọjọ́un máa ń sọ ni àṣẹ tí Jèhófà pa fáwọn èèyàn rẹ̀ pé: “Ẹ fẹsẹ̀ fẹ kúrò ní àárín Bábílónì.” (Jeremáyà 50:8, 13) Lọ́nà kan náà, nítorí pé Bábílónì Ńlá máa dahoro, àwọn èèyàn Ọlọ́run là ń rọ̀ láti sá àsálà nísinsìnyí. Lọ́dún 537 ṣááju Sànmánì Kristẹni, inú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì olóòótọ́ dùn púpọ̀ nígbà tí wọ́n láǹfààní láti sá kúrò ní ìlú Bábílónì. Lọ́nà kan náà, inú àwọn èèyàn Ọlọ́run dùn nígbà tí wọ́n rí ìtúsílẹ̀ kúrò nínú ìgbèkùn Bábílónì lọ́dún 1919. (Ìṣípayá 11:11, 12) Látìgbà yẹn, ọ̀kẹ́ àìmọye àwọn mìíràn ti ṣe ìgbọràn sí àṣẹ náà láti sá kúrò nínú Bábílónì Ńlá.

  • Ìlú Ńlá Náà Pa Run
    Ìṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
    • 24. (a) Àwọn èèyàn Ọlọ́run gbọ́dọ̀ sá kúrò nínú Bábílónì Ńlá láti yẹra fún kí ni? (b) Ẹ̀ṣẹ̀ wo làwọn tí wọ́n ò sá kúrò nínú Bábílónì Ńlá ń ṣàjọpín pẹ̀lú rẹ̀?

      24 Ẹ ò rí i pé àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí lágbára! Nítorí náà, ó yẹ kéèyàn ṣe ohun tó yẹ ní ṣíṣe. Jeremáyà rọ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ní ọjọ́ rẹ̀ láti ṣe ohun tó yẹ, ó ní: “Ẹ sá lọ kúrò nínú Bábílónì, . . . nítorí ó jẹ́ àkókò ẹ̀san tí ó jẹ́ ti Jèhófà. Ìlòsíni kan wà tí yóò san padà fún un. Ẹ jáde kúrò nínú rẹ̀, ẹ̀yin ènìyàn mi, kí olúkúlùkù yín sì pèsè àsálà fún ọkàn rẹ̀ lọ́wọ́ jíjófòfò ìbínú Jèhófà.” (Jeremáyà 51:6, 45) Lọ́nà kan náà, ohùn tó wá láti ọ̀run náà ń kìlọ̀ fáwọn èèyàn Ọlọ́run lónìí láti sá kúrò nínú Bábílónì Ńlá kí ìyọnu tó máa dé bá a má bàa kàn wọ́n. Nísinsìnyí, à ń pòkìkí ìdájọ́ Jèhófà lórí ayé yìí, títí kan Bábílónì Ńlá, ìdájọ́ náà yóò sì dà bí ìyọnu ńláǹlà. (Ìṣípayá 8:1–9:21; 16:1-21) Àwọn èèyàn Ọlọ́run ní láti ya ara wọn sọ́tọ̀ kúrò nínú ìsìn èké bí wọn ò bá fẹ́ kí ìdájọ́ Jèhófà tó dà bí ìyọnu ńláǹlà yẹn kàn wọ́n kí wọ́n sì pa run pọ̀ mọ́ ìsìn èké. Yàtọ̀ síyẹn, bí wọn ò bá kúrò nínú ètò ìsìn èké, wọn yóò pín nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀. Bíi ti Bábílónì Ńlá wọn yóò jẹ̀bi ìwà panṣágà nípa tẹ̀mí àti ìtàjẹ̀sílẹ̀ “gbogbo àwọn tí a ti fikú pa lórí ilẹ̀ ayé.”—Ìṣípayá 18:24; fi wé Éfésù 5:11; 1 Tímótì 5:22.

      25. Báwo làwọn èèyàn Ọlọ́run ṣe jáde kúrò nínú Bábílónì ìgbàanì?

      25 Ṣùgbọ́n, báwo làwọn èèyàn Ọlọ́run ṣe ń jáde kúrò nínú Bábílónì Ńlá? Lákọ̀ọ́kọ́ ná, báwo làwọn èèyàn Ọlọ́run ṣe jáde kúrò nínú Bábílónì ayé ọjọ́un? Wọ́n jáde kúrò nínú Bábílónì ayé ọjọ́un nípa rírin ìrìn àjò kúrò níbẹ̀ padà sí iyàn-níyàn Ilẹ̀ Ìlérí. Àmọ́ ó ṣì tún ku ohun mìíràn tí wọ́n máa ṣe. Aísáyà sọ àsọtẹ́lẹ̀ èyí fáwọn ọmọ Ísírẹ́lì pé: “Ẹ yí padà, ẹ yí padà, ẹ jáde kúrò níbẹ̀, ẹ má fọwọ́ kan ohun àìmọ́ kankan; ẹ jáde kúrò ní àárín rẹ̀, ẹ wẹ ara yín mọ́, ẹ̀yin tí ń gbé àwọn nǹkan èlò Jèhófà.” (Aísáyà 52:11) Bẹ́ẹ̀ ni, wọ́n ní láti pa gbogbo ìwà àìmọ́ ti ìsìn Bábílónì tì, èyí tó lè ta àbààwọ́n sí ìjọsìn tí wọ́n ń ṣe sí Jèhófà.

      26. Báwo làwọn Kristẹni ará Kọ́ríńtì ṣe ṣègbọràn sí ọ̀rọ̀ náà pé, ‘Ẹ jáde kúrò láàárín wọn, kí ẹ sì jáwọ́ nínú fífọwọ́ kan ohun àìmọ́’?

      26 Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù fa ọ̀rọ̀ Aísáyà yọ nínú lẹ́tà rẹ̀ tó kọ sáwọn ará Kọ́ríńtì, ó ní: “Ẹ má ṣe fi àìdọ́gba so pọ̀ pẹ̀lú àwọn aláìgbàgbọ́. Nítorí àjọṣe wo ni òdodo àti ìwà àìlófin ní? Tàbí àjọpín wo ni ìmọ́lẹ̀ ní pẹ̀lú òkùnkùn? . . . ‘Nítorí náà, ẹ jáde kúrò láàárín wọn, kí ẹ sì ya ara yín sọ́tọ̀,’ ni Jèhófà wí, ‘kí ẹ sì jáwọ́ nínú fífọwọ́kan ohun àìmọ́.’” Kò di dandan pé káwọn Kristẹni ní Kọ́ríńtì fi Kọ́ríńtì sílẹ̀ kí wọ́n tó lè ṣègbọràn sí àṣẹ yẹn. Ńṣe ni wọ́n ní láti yẹra fún àwọn tẹ́ńpìlì àìmọ́ táwọn èèyàn ti ń ṣe ìsìn èké, wọn ò sì gbọ́dọ̀ kọ́ ìṣe àìmọ́ àwọn abọ̀rìṣà wọ̀nyẹn. Lọ́dún 1919, àwọn èèyàn Ọlọ́run bẹ̀rẹ̀ sí í sá kúrò nínú Bábílónì Ńlá lọ́nà yìí, wọ́n wẹ ara wọn mọ́ kúrò nínú àwọn ẹ̀kọ́ èké àtàwọn àṣà àìmọ́ èyíkéyìí. Nípa bẹ́ẹ̀, ó ṣeé ṣe fún wọn láti sin Ọlọ́run gẹ́gẹ́ bí àwọn èèyàn rẹ̀ tá a ti wẹ̀ mọ́.—2 Kọ́ríńtì 6:14-17; 1 Jòhánù 3:3.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́