-
Ìlú Ńlá Náà Pa RunÌṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
-
-
23. Báwo ni ohùn tó wá láti ọ̀run ṣe tẹnu mọ́ ọn pé ó jẹ́ kánjúkánjú láti sá kúrò nínú Bábílónì Ńlá?
23 Ṣé bẹ́ẹ̀ náà ló ṣe jẹ́ kánjúkánjú tó ni pé kéèyàn sá kúrò nínú Bábílónì Ńlá, kéèyàn yọwọ́yọsẹ̀ kúrò nínú jíjẹ́ ara ìsìn ayé kéèyàn sì ya ara rẹ̀ sọ́tọ̀ pátápátá? Bẹ́ẹ̀ ni o, nítorí pé ojú tí Ọlọ́run fi ń wo Bábílónì Ńlá tó jẹ́ abàmì ìsìn àtọdúnmọ́dún làwa náà ní láti fi wò ó. Ọlọ́run ò fọ̀rọ̀ sábẹ́ ahọ́n sọ, ó pè é ní aṣẹ́wó ńlá. Nítorí náà, ohùn láti ọ̀run wá sọ fún Jòhánù síwájú sí i nípa aṣẹ́wó yìí pé: “Nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ ti wọ́ jọpọ̀ títí dé ọ̀run, Ọlọ́run sì ti mú àwọn ìṣe àìṣèdájọ́ òdodo rẹ̀ wá sí ìrántí. Ẹ ṣe sí i, àní gẹ́gẹ́ bí òun fúnra rẹ̀ ti ṣe síni, ẹ sì ṣe sí i ní ìlọ́po méjì, bẹ́ẹ̀ ni, ìlọ́po méjì iye ohun tí ó ṣe; nínú ife tí ó fi àdàlù kan sí, ẹ fi ìlọ́po méjì àdàlù náà sí i fún un. Dé àyè tí ó ṣe ara rẹ̀ lógo, tí ó sì gbé nínú fàájì aláìnítìjú, dé àyè yẹn ni kí ẹ fún un ní ìjoró àti ọ̀fọ̀. Nítorí pé nínú ọkàn-àyà rẹ̀, ó ń wí ṣáá pé, ‘Mo jókòó bí ọbabìnrin, èmi kì í sì í ṣe opó, èmi kì yóò sì rí ọ̀fọ̀ láé.’ Ìdí nìyẹn tí àwọn ìyọnu àjàkálẹ̀ rẹ̀, ikú àti ọ̀fọ̀ àti ìyàn, yóò fi dé ní ọjọ́ kan ṣoṣo, a ó sì fi iná sun ún pátápátá, nítorí pé Jèhófà Ọlọ́run, ẹni tí ó ṣèdájọ́ rẹ̀, jẹ́ alágbára.”—Ìṣípayá 18:5-8.
-
-
Ìlú Ńlá Náà Pa RunÌṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
-
-
27. Àwọn ìbáradọ́gba wo ní ń bẹ láàárín ìdájọ́ lórí Bábílónì ìgbàanì àti lórí Bábílónì Ńlá?
27 Ìṣubú Bábílónì ìgbàanì àti ahoro tó dà nígbẹ̀yìngbẹ́yín ni ìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀. “Nítorí títí dé ọ̀run ni ìdájọ́ rẹ̀.” (Jeremáyà 51:9) Lọ́nà kan náà, ẹ̀ṣẹ̀ Bábílónì Ńlá ti “wọ́ jọpọ̀ títí dé ọ̀run,” tí Jèhófà fúnra rẹ̀ fi kíyè sí i. Ó ti jẹ̀bi àìṣèdájọ́ òdodo, ìbọ̀rìṣà, ìṣekúṣe, ìninilára, ìfipájalè, àti ìṣìkàpànìyàn. Ìṣubú Bábílónì ìgbàanì jẹ́ ara ẹ̀san tó rí gbà fún ohun tó ti ṣe fún tẹ́ńpìlì Jèhófà àtàwọn olùjọsìn tòótọ́ rẹ̀. (Jeremáyà 50:8, 14; 51:11, 35, 36) Ìṣubú Bábílónì Ńlá àti ìparun rẹ̀ nígbẹ̀yìngbẹ́yín lọ́nà kan náà jẹ́ ìgbẹ̀san fún ohun tó ti ṣe sí àwọn olùjọsìn tòótọ́ láti ọgọ́rọ̀ọ̀rún ọdún wá. Kódà, ìparun rẹ̀ ìkẹyìn ló máa jẹ́ ìbẹ̀rẹ̀ ‘ọjọ́ ẹ̀san látọwọ́ Ọlọ́run wa.’—Aísáyà 34:8-10; 61:2; Jeremáyà 50:28.
28. Ìlànà ìdájọ́ òdodo wo ni Jèhófà máa lò fún Bábílónì Ńlá, kí sì nìdí?
28 Lábẹ́ Òfin Mósè, bí ọmọ Ísírẹ́lì kan bá ja ará ìlú ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ lólè, ó ní láti san án padà ó kéré tán ní ìlọ́po méjì. (Ẹ́kísódù 22:1, 4, 7, 9) Nígbà ìparun Bábílónì Ńlá tí ń bọ̀, Jèhófà yóò lo ìlànà ìdájọ́ òdodo tó fara jọ ọ́. Bábílónì Ńlá yóò gba ìlọ́po méjì ohun tó fi fúnni. Kì yóò rí àánú gbà nítorí pé òun náà kò fi àánú kankan hàn sáwọn tó kó nígbèkùn. Ó ń jẹ lára àwọn èèyàn ilẹ̀ ayé kó lè máa wà nínú “fàájì aláìnítìjú” lọ. Ìyà yóò jẹ òun náà á sì ṣọ̀fọ̀. Bábílónì ìgbàanì rò pé òun wà níbi ààbò tí mìmì kan ò ti lè mi òun, ó ń ṣògo pé: “Èmi kì yóò jókòó gẹ́gẹ́ bí opó, èmi kì yóò sì mọ àdánù àwọn ọmọ.” (Aísáyà 47:8, 9, 11) Bábílónì Ńlá pẹ̀lú sọ pé mìmì kan ò lè mi òun. Ṣùgbọ́n ìparun rẹ̀ tí Jèhófà tó “jẹ́ alágbára” ti pàṣẹ rẹ̀, yóò ṣẹlẹ̀ lójijì, bí ẹni pé “ní ọjọ́ kan ṣoṣo”!
-