-
Ọba Ajagun Náà Ṣẹ́gun ní Amágẹ́dọ́nìÌṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
-
-
22. Báwo ni Jòhánù ṣe ṣàkópọ̀ bí ogun àjàkẹ́yìn náà yóò ṣe rí?
22 Jòhánù ṣe àkópọ̀ bí ogun àjàkẹ́yìn náà yóò ṣe rí, ó ní: “Mo sì rí ẹranko ẹhànnà náà àti àwọn ọba ilẹ̀ ayé àti àwọn ẹgbẹ́ ọmọ ogun wọn tí wọ́n kóra jọpọ̀ láti bá ẹni tí ó jókòó sórí ẹṣin àti ẹgbẹ́ ọmọ ogun rẹ̀ ja ogun. A sì mú ẹranko ẹhànnà náà, àti pa pọ̀ pẹ̀lú rẹ̀, wòlíì èké tí ó ṣe àwọn iṣẹ́ àmì níwájú rẹ̀, èyí tí ó fi ṣi àwọn tí ó gba àmì ẹranko ẹhànnà náà lọ́nà àti àwọn tí ó ṣe ìjọsìn fún ère rẹ̀. Nígbà tí wọ́n ṣì wà láàyè, àwọn méjèèjì ni a fi sọ̀kò sínú adágún iná tí ń fi imí ọjọ́ jó. Ṣùgbọ́n àwọn ìyókù ni a fi idà gígùn ẹni tí ó jókòó sórí ẹṣin pa tán, idà tí ó ti ẹnu rẹ̀ jáde. Gbogbo àwọn ẹyẹ sì jẹ àwọn ibi kìkìdá ẹran ara wọn ní àjẹyó.”—Ìṣípayá 19:19-21.
-
-
Ọba Ajagun Náà Ṣẹ́gun ní Amágẹ́dọ́nìÌṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
-
-
24. (a) Ìdájọ́ wo la mú wá sórí ẹranko ẹhànnà náà àti wòlíì èké náà, kí ló sì túmọ̀ sí pé wọ́n “ṣì wà láàyè”? (b) Kí nìdí tí “adágún iná” náà fi ní láti jẹ́ ìṣàpẹẹrẹ?
24 Ẹranko ẹhànnà tó tinú òkun wá tó ní orí méje, ìwo mẹ́wàá, tó ṣàpẹẹrẹ ètò ìṣèlú Sátánì, ti dìgbàgbé, bẹ́ẹ̀ sì ni wòlíì èké náà, ìyẹn agbára ayé keje, tún bá a lọ pẹ̀lú. (Ìṣípayá 13:1, 11-13; 16:13) Nígbà tí wọ́n ṣì wà “láàyè,” tàbí tí wọ́n ṣì jọ ń ta ko àwọn èèyàn Ọlọ́run lórí ilẹ̀ ayé, a jù wọ́n sínú “adágún iná.” Ṣé adágún iná gidi lèyí? Rárá, nítorí ẹranko ẹhànnà náà àti wòlíì èké náà kì í ṣe ẹranko gidi. Kàkà bẹ́ẹ̀, adágún iná náà ṣàpẹẹrẹ ìparun pátápátá, ìparun ìkẹyìn, ibi àrèmabọ̀. Nígbà tó bá yá, ibẹ̀ yẹn lá máa fi ikú àti Hédíìsì, àti Èṣù fúnra rẹ̀, sọ̀kò sí. (Ìṣípayá 20:10, 14) Dájúdájú, kì í ṣe ibi tí wọ́n ti ń dá àwọn ẹni búburú lóró títí ayérayé, kì í ṣe ibi tó gbóná bí ajere, nítorí èrò pé irú ibi bẹ́ẹ̀ wà jẹ́ ohun ìríra lójú Jèhófà.—Jeremáyà 19:5; 32:35; 1 Jòhánù 4:8, 16.
-