ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Kí Ni Ọjọ́ Ìdájọ́?
    Kí Ni Bíbélì Fi Kọ́ni Gan-an?
    • náà. Nípa bẹ́ẹ̀, ohun táwọn èèyàn bá ṣe lákòókò Ọjọ́ Ìdájọ́ ni Ọlọ́run máa wò ṣèdájọ́ wọn.

      Ọjọ́ Ìdájọ́ ló máa jẹ́ ìgbà àkọ́kọ́ tí ọ̀kẹ́ àìmọye èèyàn yóò láǹfààní láti kẹ́kọ̀ọ́ kí wọ́n lè mọ ohun tí Ọlọ́run fẹ́ kí wọ́n sì ṣe é. Èyí fi hàn pé ètò ìkọ́nilẹ́kọ̀ọ́ tó pabanbarì yóò wáyé lákòókò náà. Dájúdájú, “òdodo ni àwọn olùgbé ilẹ̀ eléso yóò kọ́.” (Aísáyà 26:9) Àmọ́ lákòókò náà, kì í ṣe gbogbo èèyàn ní yóò fẹ́ láti máa ṣe ohun tí Ọlọ́run bá fẹ́. Aísáyà 26:10 sọ pé: “Bí a tilẹ̀ fi ojú rere hàn sí ẹni burúkú, kò kúkú ní kọ́ òdodo. Ní ilẹ̀ ìfòtítọ́-hùwà ni yóò ti máa hùwà lọ́nà tí kò bá ìdájọ́ òdodo mu, kì yóò sì rí ọlá ògo Jèhófà.” Lákòókò Ọjọ́ Ìdájọ́, Ọlọ́run yóò pa àwọn ẹni burúkú bẹ́ẹ̀ run láéláé.—Aísáyà 65:20.

      Ní òpin Ọjọ́ Ìdájọ́ náà, àwọn tó bá là á já yóò ti “wá sí ìyè” lẹ́kùn-únrẹ́rẹ́ gẹ́gẹ́ bí èèyàn pípé. (Ìṣípayá 20:5) Nípa bẹ́ẹ̀, àkókò Ọjọ́ Ìdájọ́ ni Ọlọ́run máa mú aráyé bọ̀ sípò ìjẹ́pípé tó dá èèyàn sí níbẹ̀rẹ̀. (1 Kọ́ríńtì 15:24-28) Lẹ́yìn náà ni ìdánwò àṣekágbá yóò wáyé. Ọlọ́run yóò dá Sátánì sílẹ̀ lẹ́wọ̀n yóò sì fún un láyè láti ṣi aráyé lọ́nà lẹ́ẹ̀kan sí i, èyí tó máa jẹ́ àṣemọ rẹ̀. (Ìṣípayá 20:3, 7-10) Ìlérí tí Bíbélì ṣe yóò wá ṣẹ lẹ́kùn-únrẹ́rẹ́ sára àwọn tí kò bá jẹ́ kí Sátánì ṣi àwọn lọ́nà. Ìlérí ọ̀hún ni pé: “Àwọn olódodo ni yóò ni ilẹ̀ ayé, wọn yóò sì máa gbé títí láé lórí rẹ̀.” (Sáàmù 37:29) Dájúdájú, ìbùkún ni Ọjọ́ Ìdájọ́ yóò jẹ́ fún gbogbo èèyàn tó bá jẹ́ onígbọràn!

  • Ọdún 1914—Ọdún Pàtàkì Nínú Àsọtẹ́lẹ̀ Bíbélì
    Kí Ni Bíbélì Fi Kọ́ni Gan-an?
    • ÀFIKÚN

      Ọdún 1914—Ọdún Pàtàkì Nínú Àsọtẹ́lẹ̀ Bíbélì

      NǸKAN bí ogójì ọdún ṣáájú ọdún 1914 làwọn akẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì ti ń kéde pé àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ gbankọgbì yóò wáyé ní ọdún 1914. Kí làwọn ìṣẹ̀lẹ̀ ọ̀hún, ẹ̀rí wo ló sì fi hàn pé ọdún 1914 jẹ́ ọdún pàtàkì?

      Nínú Lúùkù 21:24, Jésù sọ pé: “Àwọn orílẹ̀-èdè yóò sì tẹ Jerúsálẹ́mù mọ́lẹ̀, títí àwọn àkókò tí a yàn kalẹ̀ fún àwọn orílẹ̀-èdè [akoko awọn Keferi, Bibeli Mimọ] yóò fi pé.” Jerúsálẹ́mù ti fìgbà kan rí jẹ́ olú ìlú orílẹ̀-èdè àwọn Júù, ibẹ̀ ni àwọn ọba tó jẹ́ àtọmọdọ́mọ Ọba Dáfídì ti ṣàkóso. (Sáàmù 48:1, 2) Àmọ́, àwọn ọba tó jẹ ní Jerúsálẹ́mù kì í ṣẹgbẹ́ àwọn ọba àwọn orílẹ̀-èdè tó kù. Ìdí ni pé orí “ìtẹ́ Jèhófà” ni wọ́n jókòó sí gẹ́gẹ́ bí aṣojú Ọlọ́run. (1 Kíróníkà 29:23) Nípa bẹ́ẹ̀, Jerúsálẹ́mù ṣàpẹẹrẹ ìṣàkóso Jèhófà.

      Àmọ́, báwo ni ‘àwọn orílẹ̀-èdè ṣe tẹ ìṣàkóso Ọlọ́run mọ́lẹ̀,’ ìgbà wo sì nìyẹn wáyé? Ó wáyé ní ọdún 607 ṣáájú Sànmánì Kristẹni (Ṣ.S.K.), nígbà tí àwọn ará Bábílónì pa Jerúsálẹ́mù run. Kò sẹ́ni tí yóò jókòó lórí “ìtẹ́ Jèhófà” mọ́ nítorí pé àwọn ará Bábílónì ti fòpin sí ìlà ìdílé àwọn ọba tó jẹ́ àtọmọdọ́mọ Dáfídì. (2 Àwọn Ọba 25:1-26) Ṣé ‘ìtẹ̀mọ́lẹ̀’ yìí kò ní dópin ni? Rárá, ó máa dópin. Ìdí ni pé wòlíì Ìsíkíẹ́lì sọ nípa Sedekáyà, ọba tó jẹ gbẹ̀yìn ní Jerúsálẹ́mù pé: “Mú láwàní kúrò, sì ṣí adé kúrò. . . . Kì yóò jẹ́ ti ẹnì kankan títí di ìgbà tí ẹni tí ó ní ẹ̀tọ́ lọ́nà òfin yóò fi dé, èmi yóò sì fi í fún un.” (Ìsíkíẹ́lì 21:26, 27) Jésù Kristi ni ẹni tó ní ẹ̀tọ́ lọ́nà òfin sí adé ọba ní ìlà ìdílé Dáfídì. (Lúùkù 1:32, 33) Nítorí náà, ìgbà tí Jésù bá di Ọba ni ‘ìtẹ̀mọ́lẹ̀’ náà yóò dópin.

      Ìgbà wo wá ni ìṣẹ̀lẹ̀ pàtàkì yìí máa wáyé? Jésù fi hàn pé àwọn Kèfèrí yóò ṣàkóso fún àkókò kan pàtó. Àkọsílẹ̀ ìwé Dáníẹ́lì orí 4 jẹ́ ká mọ bí àkókò náà ṣe máa gùn tó. Ó sọ nípa àlá kan tó jẹ́ àsọtẹ́lẹ̀ tí Nebukadinésárì Ọba Bábílónì lá. Ọba náà rí i tí wọn gé igi ńlá kan tó ga fíofío lulẹ̀. Kùkùté igi yìí ò sì lè rúwé nítorí pé wọ́n fi ọ̀já irin àti bàbà dì í. Áńgẹ́lì kan wá kéde pé: “Kí ìgbà méje sì kọjá lórí rẹ̀.”—Dáníẹ́lì 4:10-16.

      Nígbà mìíràn, Bíbélì máa ń fi igi ṣàpèjúwe ìṣàkóso. (Ìsíkíẹ́lì 17:22-24; 31:2-5) Nítorí náà, gígé tí wọ́n bá gé igi ìṣàpẹẹrẹ náà lulẹ̀ ló máa dúró fún bí wọ́n ṣe máa fòpin sí ìṣàkóso Ọlọ́run tí àwọn ọba tó ń jẹ ní Jerúsálẹ́mù jẹ́ aṣojú rẹ̀. Àmọ́ ìran náà sọ pé ìgbà díẹ̀ ni wọ́n yóò fi “tẹ Jerúsálẹ́mù mọ́lẹ̀,” ó pè é ní “ìgbà méje.” Báwo ni ìgbà méje yìí yóò ṣe gùn tó?

      Ìṣípayá 12:6, 14 fi hàn pé àkókò mẹ́ta àti ààbọ̀ jẹ́ “ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀fà [1,260] ọjọ́.” Nípa bẹ́ẹ̀, “ìgbà méje” yóò jẹ́ ìlọ́po méjì ìyẹn, ó sì jẹ́, ẹgbẹ̀rún méjì, ọgọ́rùn-ún márùn-ún ó lé ogún [2,520] ọjọ́. Àmọ́ àwọn orílẹ̀-èdè Kèfèrí kò dẹ́kun ‘ìtẹ̀mọ́lẹ̀’ náà ní ẹgbẹ̀rún méjì, ọgọ́rùn-ún márùn-ún ó lé ogún ọjọ́ péré lẹ́yìn tí wọ́n pa Jerúsálẹ́mù run. Èyí fi hàn pé àkókò ‘ìtẹ̀mọ́lẹ̀’ náà máa gùn jù bẹ́ẹ̀ lọ. Tá a bá wá mú “ọjọ́ kan fún ọdún kan” gẹ́gẹ́ bí ìlànà tó wà nínú Númérì 14:34 àti Ìsíkíẹ́lì 4:6, “ìgbà méje” yìí yóò jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjì, ọgọ́rùn-ún márùn-ún ó lé ogún ọdún.

      Oṣù October ọdún 607 Ṣ.S.K. ni àwọn ará Bábílónì pa Jerúsálẹ́mù run tí wọ́n sì mú ọba tó ń jẹ ní ìlà ìdílé Dáfídì kúrò lórí ìtẹ́. Ìgbà yẹn ni ẹgbẹ̀rún méjì, ọgọ́rùn-ún márùn-ún ó lé ogún ọdún bẹ̀rẹ̀, ó sì parí ní oṣù October ọdún 1914. Ìgbà yìí ni “àwọn àkókò tí a yàn kalẹ̀ fún àwọn orílẹ̀-èdè” dópin, tí Ọlọ́run sì sọ Jésù Kristi di Ọba Ìjọba Ọlọ́run ní ọ̀run.a—Sáàmù 2:1-6; Dáníẹ́lì 7:13, 14.

      Jésù sọ tẹ́lẹ̀ pé àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ gbankọgbì yóò máa ṣẹlẹ̀ nígbà “wíwà níhìn-ín” òun gẹ́gẹ́ bí Ọba ní ọ̀run. Àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ ọ̀hún sì ń ṣẹlẹ̀ lóòótọ́, bí ogun, ìyàn, ìmìtìtì ilẹ̀ àti àjàkálẹ̀ àrùn. (Mátíù 24:3-8; Lúùkù 21:11) Àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ wọ̀nyí jẹ́ ẹ̀rí tí kò ṣeé já ní koro pé ọdún 1914 ni Ìjọba Ọlọ́run bẹ̀rẹ̀ sí í ṣàkóso ní ọ̀run tí “àwọn ọjọ́ ìkẹyìn” ètò àwọn nǹkan búburú yìí sì bẹ̀rẹ̀.—2 Tímótì 3:1-5.

      Àtẹ: Ìṣírò ìgbà méje tàbí àkókò àwọn Kèfèrí, bẹ̀rẹ̀ láti ìgbà tí Jerúsálẹ́mù pa run sí ìgbà tí 2,520 ọdún dópin ní October 1914

      a October 607 Ṣ.S.K. sí October 1 Ṣ.S.K jẹ́ ọgọ́rùn-ún mẹ́fà ó lé mẹ́fà [606] ọdún. Níwọ̀n bí òǹkà kò ti bẹ̀rẹ̀ látorí òdo, tó jẹ́ pé orí oókan ló ti bẹ̀rẹ̀, October 1 Ṣ.S.K. sí October 1914 Sànmánì Kristẹni (S.K.) yóò jẹ́ ẹgbẹ̀rún kan, ọgọ́rùn-ún mẹ́sàn-án ó lé mẹ́rìnlá [1,914] ọdún. Tá a bá wá ro ọgọ́rùn-ún mẹ́fà ó lé mẹ́fà ọdún pọ̀ mọ́ ẹgbẹ̀rún kan, ọgọ́rùn-ún mẹ́sàn-án ó lé mẹ́rìnlá ọdún, yóò jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjì, ọgọ́rùn-ún márùn-ún ó lé ogún [2,520] ọdún. Wo àlàyé nípa bí Jerúsálẹ́mù ṣe pa run nínú ìwé Insight on the Scriptures, lábẹ́ àkọlé tá a pè ní “Chronology” (Ìṣirò Ọjọ́ Àwọn Ìṣẹ̀lẹ̀). Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà la ṣe ìwé yìí.]

  • Ta Ni Máíkẹ́lì Olú-Áńgẹ́lì?
    Kí Ni Bíbélì Fi Kọ́ni Gan-an?
    • ÀFIKÚN

      Ta Ni Máíkẹ́lì Olú-Áńgẹ́lì?

      IYE ìgbà díẹ̀ ni Bíbélì mẹ́nu kan Máíkẹ́lì tó jẹ́ orúkọ ẹ̀dá ẹ̀mí kan. Àmọ́ ní iye ìgbà díẹ̀ tí Bíbélì mẹ́nu kàn án ọ̀hún, akọ iṣẹ́ ló ń ṣe. Nínú ìwé Dáníẹ́lì, Máíkẹ́lì bá àwọn áńgẹ́lì búburú wọ̀yá ìjà; nínú lẹ́tà Júdà, ó bá Sátánì ṣawuyewuye; nínú ìwé Ìṣípayá sì rèé, ó bá Èṣù àtàwọn ẹ̀mí èṣù rẹ̀ jagun. Bí Máíkẹ́lì ṣe ń gbè sẹ́yìn ìṣàkóso Jèhófà tó sì ń bá àwọn ọ̀tá Ọlọ́run jà, orúkọ rẹ̀ ló ń rò ó, èyí tó túmọ̀ sí, “Ta Ní Dà Bí Ọlọ́run?” Àmọ́, ta ni Máíkẹ́lì yìí?

      Àìmọye èèyàn ló jẹ́ pé orúkọ kan ṣoṣo kọ́ ni wọ́n ń jẹ́. Bí àpẹẹrẹ, Jékọ́bù baba ńlá tún ń jẹ́ Ísírẹ́lì, àpọ́sítélì Pétérù sì tún ń jẹ́ Símónì. (Jẹ́nẹ́sísì 49:1, 2; Mátíù 10:2) Lọ́nà kan náà, Bíbélì fi hàn pé Máíkẹ́lì jẹ́ orúkọ mìíràn tí Jésù Kristi ń jẹ́ kó tó wá sórí ilẹ̀ ayé àti lẹ́yìn tó kúrò lórí ilẹ̀ ayé. Jẹ́ ká wo ìdí tá a fi gbà bẹ́ẹ̀ nínú Ìwé Mímọ́.

      Olú-Áńgẹ́lì. Bíbélì sọ̀rọ̀ nípa Máíkẹ́lì tó jẹ́ “olú-áńgẹ́lì.” (Júúdà 9) “Olú-áńgẹ́lì” túmọ̀ sí “olórí àwọn áńgẹ́lì.” Kíyè sí i pé olú-áńgẹ́lì la pe Máíkẹ́lì. Èyí fi hàn pé méjì irú áńgẹ́lì bẹ́ẹ̀ ò sí. Bákan náà, ní gbogbo ibi tí Bíbélì ti sọ̀rọ̀ nípa “olú-áńgẹ́lì,” ẹnì kan ṣoṣo ló pè bẹ́ẹ̀, kì í ṣe ẹni méjì. Yàtọ̀ síyẹn, Jésù ni Bíbélì sábà máa ń fi sí ipò olú-áńgẹ́lì. Ìwé Tẹsalóníkà Kìíní 4:16 sọ nípa Jésù tó ti jíǹde pé: “Olúwa fúnra rẹ̀ yóò sọ̀ kalẹ̀ láti ọ̀run wá pẹ̀lú ìpè àṣẹ, pẹ̀lú ohùn olú-áńgẹ́lì.” Ẹsẹ Bíbélì yìí fi hàn pé ohùn Jésù jẹ́ ohùn

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́