-
Fífi Ìtẹnumọ́ Yíyẹ Ka Ìwé Mímọ́Jàǹfààní Nínú Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run
-
-
Ẹ̀KỌ́ 21
Fífi Ìtẹnumọ́ Yíyẹ Ka Ìwé Mímọ́
NÍGBÀ tó o bá ń bá àwọn èèyàn sọ̀rọ̀ nípa ète Ọlọ́run, yálà nínú ilé ni o, tàbí látorí pèpéle, ohun tó wà nínú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ló yẹ kó o gbé ọ̀rọ̀ rẹ kà. Èyí sábà máa ń wé mọ́ kíka ẹsẹ Bíbélì, ó sì yẹ kí a kà á dáadáa.
Ìtẹnumọ́ Yíyẹ Wé Mọ́ Fífi Bí Ọ̀rọ̀ Ṣe Rí Lára Hàn. Ńṣe ni kí o ka Ìwé Mímọ́ lọ́nà tó fi bí ọ̀rọ̀ ṣe rí lára hàn. Gbé àwọn àpẹẹrẹ kan yẹ̀ wò. Tó o bá ń ka Sáàmù 37:11 sókè, ó yẹ kí ohùn rẹ dún lọ́nà tó fi hàn pé tayọ̀tayọ̀ lo fi ń retí àlàáfíà tí ẹsẹ yẹn ṣèlérí. Tó o bá ń ka Ìṣípayá 21:4, tó sọ̀rọ̀ nípa bí ìjìyà àti ikú yóò ṣe dópin, ó yẹ kí ohùn rẹ gbé ìmọrírì àtinúwá yọ nítorí ìtura ńláǹlà tí àsọtẹ́lẹ̀ ibẹ̀ ń sọ. Ohùn kánjúkánjú ló yẹ kí o fi ka Ìṣípayá 18:2, 4, 5, tó ń rọ àwọn èèyàn pé kí wọ́n jáde kúrò nínú “Bábílónì Ńlá” tí ẹ̀ṣẹ̀ ti wọ̀ lọ́rùn. Àmọ́ ṣá, ńṣe ló yẹ kí o fi bí ọ̀rọ̀ yìí ṣe rí lára hàn látọkànwá, kí o má sì ṣe é láṣejù. Ẹsẹ náà fúnra rẹ̀ àti bí o ṣe fẹ́ lò ó ló máa pinnu bí o ṣe máa fi bí ọ̀rọ̀ ṣe rí lára hàn tó nígbà tí o bá ń kà á.
Tẹnu Mọ́ Àwọn Ọ̀rọ̀ Tó Yẹ. Bó bá jẹ́ apá kan ẹsẹ Bíbélì kan lo kàn fẹ́ ṣàlàyé, apá yẹn ló yẹ kó o tẹnu mọ́ nígbà tó o bá ń ka ẹsẹ náà. Fún àpẹẹrẹ, tó o bá ń ka Mátíù 6:33, o ò ní tẹnu mọ́ “òdodo Rẹ̀” tàbí “gbogbo nǹkan mìíràn wọ̀nyí” bó bá jẹ́ pé ohun tí “wíwá ìjọba náà . . . lákọ̀ọ́kọ́” túmọ̀ sí lo fẹ́ ṣàlàyé.
Bóyá o ń ronú láti ka Mátíù 28:19 nínú ọ̀rọ̀ kan tó o ní nínú Ìpàdé Iṣẹ́ Ìsìn. Àwọn ọ̀rọ̀ wo lo máa tẹnu mọ́? Bó bá jẹ́ pé ńṣe lo fẹ́ rọ àwọn ará láti jẹ́ aláápọn nínú bíbẹ̀rẹ̀ ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì inú ilé, tẹnu mọ́ “máa sọ àwọn ènìyàn . . . di ọmọ ẹ̀yìn.” Àmọ́, bó bá jẹ́ ojúṣe Kristẹni láti wàásù òtítọ́ Bíbélì fún àwọn àjèjì tó ṣí wá sílùú lo fẹ́ sọ̀rọ̀ lé lórí, tàbí kẹ̀, bóyá o fẹ́ fún àwọn akéde kan níṣìírí láti lọ sìn níbi tí àìní gbé pọ̀, o lè tẹnu mọ́ “àwọn ènìyàn gbogbo orílẹ̀-èdè.”
Ọ̀pọ̀ ìgbà la máa ń fi ẹsẹ Ìwé Mímọ́ kan dáhùn ìbéèrè tàbí ká fi ti kókó kan táwọn kan kà sí àríyànjiyàn lẹ́yìn. Bó bá jẹ́ gbogbo ọ̀rọ̀ tó wà nínú ẹsẹ yẹn la tẹnu mọ́ lọ́nà kan náà, àwùjọ lè máà rí bí ẹsẹ Ìwé Mímọ́ ọ̀hún ṣe tan mọ́ ọ̀rọ̀ tó wà nílẹ̀. Kókó náà lè yé ọ, ṣùgbọ́n ó lè máà yé wọn.
Bí àpẹẹrẹ, tó o bá ń ka Sáàmù 83:18 nínú Bíbélì kan tó ní orúkọ Ọlọ́run nínú, bó bá jẹ́ gbólóhùn náà “Ẹni Gíga Jù Lọ” nìkan lo tẹnu mọ́, onílé lè máà rí òtítọ́ náà tí ìwọ rí kedere pé Ọlọ́run ní orúkọ tirẹ̀. Orúkọ náà “Jèhófà” ló yẹ kó o tẹnu mọ́. Ṣùgbọ́n o, tó o bá ń fi ẹsẹ kan náà ṣàlàyé ipò ọba aláṣẹ Jèhófà, gbólóhùn náà “Ẹni Gíga Jù Lọ” ló yẹ kó o dìídì tẹnu mọ́. Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́, tó o bá ń lo Jákọ́bù 2:24 láti fi hàn pé ó ṣe pàtàkì láti fi iṣẹ́ kún ìgbàgbọ́, tó o sì wá lọ ń tẹnu mọ́ “polongo . . . ní olódodo” dípò títẹnumọ́ “àwọn iṣẹ́,” èyí lè dojú ọ̀rọ̀ rú lọ́kàn àwọn olùgbọ́ rẹ.
Àpẹẹrẹ mìíràn tó lè ràn wá lọ́wọ́ wà nínú Róòmù 15:7-13. Èyí jẹ́ apá kan lẹ́tà tí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù kọ sí ìjọ kan tí àwọn Kèfèrí àtàwọn Júù àbínibí jọ wà. Àlàyé tí àpọ́sítélì náà ń ṣe níbí ni pé, kì í ṣe kìkì àwọn Júù tó dádọ̀dọ́ nìkan ni iṣẹ́ òjíṣẹ́ tí Kristi ṣe ṣàǹfààní fún, ó tún ṣe àwọn èèyàn orílẹ̀-èdè láǹfààní pẹ̀lú, kí “àwọn orílẹ̀-èdè bàa lè yin Ọlọ́run lógo fún àánú rẹ̀.” Nígbà náà ni Pọ́ọ̀lù wá fa ọ̀rọ̀ yọ látinú ẹsẹ Ìwé Mímọ́ mẹ́rin, láti pe àfiyèsí sí àǹfààní táwọn orílẹ̀-èdè ní yẹn. Báwo ló ṣe yẹ kó o ka ọ̀rọ̀ tó fà yọ wọ̀nyẹn, kí o lè tẹnu mọ́ kókó tí Pọ́ọ̀lù ní lọ́kàn? Bó o bá ń sàmì sí àwọn gbólóhùn tó o fẹ́ tẹnu mọ́, o lè sàmì sí “àwọn orílẹ̀-èdè” Ró 15 ní ẹsẹ kẹsàn-án, “ẹ̀yin orílẹ̀-èdè” ní Ró 15 ẹsẹ kẹwàá, “gbogbo ẹ̀yin orílẹ̀-èdè” àti “gbogbo àwọn ènìyàn” ní Ró 15 ẹsẹ kọkànlá, àti “àwọn orílẹ̀-èdè” ní Ró 15 ẹsẹ kejìlá. Wá gbìyànjú láti ka Róòmù 15:7-13, kó o sì tẹnu mọ́ gbólóhùn wọ̀nyẹn. Bó o ti ń kà á bẹ́ẹ̀, gbogbo àlàyé Pọ́ọ̀lù á wá ṣe kedere, á sì rọrùn láti lóye.
Onírúurú Ọ̀nà Tó O Lè Gbà Tẹnu Mọ́ Ọ̀rọ̀. Oríṣiríṣi ọ̀nà lo lè gbà tẹnu mọ́ ọ̀rọ̀ tí ń gbé èrò yọ tó o fẹ́ kó dún ketekete. Ó yẹ kí ọ̀nà tó o fẹ́ lò wà níbàámu pẹ̀lú ẹsẹ náà àti bó o ṣe fẹ́ gbé ọ̀rọ̀ kalẹ̀. Àbá mélòó kan rèé.
Fífi ohùn gbé ìtẹnumọ́ ọ̀rọ̀ yọ. Ó wé mọ́ yíyí ohùn padà láti lè jẹ́ kí àwọn ọ̀rọ̀ tí ń gbé èrò yọ dún yàtọ̀ sí ìyókù gbólóhùn náà. A lè ṣe ìtẹnumọ́ yìí nípa gbígbóhùn sókè tàbí rírẹ ohùn sílẹ̀. Nínú ọ̀pọ̀ èdè, yíyí ìró ohùn padà máa ń gbé ìtẹnumọ́ ọ̀rọ̀ yọ. Àmọ́ nínú àwọn èdè kan, ìyẹn lè yí ìtumọ̀ ọ̀rọ̀ padà pátápátá. Fífẹ̀sọ̀ pe àwọn gbólóhùn pàtàkì máa ń jẹ́ kí wọ́n túbọ̀ tẹ̀wọ̀n lọ́kàn olùgbọ́. Nínú àwọn èdè tí ìlò ohùn kì í ti í ṣiṣẹ́ fún títẹnumọ́ àwọn ọ̀rọ̀ kan, yóò pọn dandan láti lo ọ̀nà èyíkéyìí tí wọ́n bá ń lò nínú èdè yẹn láti fi tẹnu mọ́ ọ̀rọ̀.
Dídánudúró. A lè ṣe èyí ṣáájú tàbí lẹ́yìn kíka apá pàtàkì nínú ẹsẹ Bíbélì kan, tàbí ká tiẹ̀ ṣe é nígbà méjèèjì. Dídánudúró ní kété ṣáájú kí o tó ka kókó pàtàkì kan ń mú káwọn èèyàn kẹ́ etí sílẹ̀; dídánudúró lẹ́yìn kíkà á ń jẹ́ kó túbọ̀ wọni lọ́kàn ṣinṣin. Àmọ́ bí ìdánudúró bá wá pọ̀ jù, nǹkan kan ò ní dún yàtọ̀ mọ́ o.
Àsọtúnsọ. O lè tẹnu mọ́ kókó kan pàtó nípa dídá ara rẹ padà sẹ́yìn, kí o sì tún ọ̀rọ̀ yẹn tàbí gbólóhùn yẹn kà. Ọ̀nà kan tó máa ń dára jù ni láti kọ́kọ́ ka ẹsẹ náà tán, kí o tó wá padà tún gbólóhùn pàtàkì náà kà.
Ìfaraṣàpèjúwe. Lílo ara àti ojú sábà máa ń jẹ́ kí ọ̀rọ̀ tàbí gbólóhùn kan túbọ̀ fi bí ọ̀rọ̀ ṣe rí lára hàn.
Ìró ohùn. Nínú àwọn èdè kan, nígbà mìíràn a máa ń tipa ohùn tá a fi ka ọ̀rọ̀ kan fún un nítumọ̀ ọ̀tọ̀, kí á sì tipa bẹ́ẹ̀ pàfiyèsí sí i. Èyí pẹ̀lú gba ọgbọ́n, pàápàá bí a bá fẹ́ fi bẹnu àtẹ́ lu nǹkan kan.
Tó Bá Jẹ́ Ẹlòmíràn Ló Kà Á. Tó bá jẹ́ onílé ló ka ẹsẹ Ìwé Mímọ́, ó lè tẹnu mọ́ ọ̀rọ̀ tí kò yẹ kó tẹnu mọ́, tàbí kí ó má tiẹ̀ tẹnu mọ́ ọ̀rọ̀ kankan. Kí wá ni o lè ṣe? Ó sábà máa ń dára jù lọ láti mú kí ìtumọ̀ rẹ̀ ṣe kedere nípa ṣíṣàlàyé ẹsẹ náà. Lẹ́yìn àlàyé rẹ, o lè wá pe àfiyèsí pàtàkì sí àwọn ọ̀rọ̀ tó ń gbé èrò yọ nínú ẹsẹ Bíbélì náà.
-
-
Lílo Ìwé Mímọ́ Bí Ó Ti YẹJàǹfààní Nínú Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run
-
-
Ẹ̀KỌ́ 22
Lílo Ìwé Mímọ́ Bí Ó Ti Yẹ
NÍGBÀ tá a bá ń kọ́ àwọn èèyàn lẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì, ohun tó yẹ ká ṣe ju ká kàn ṣáà ti ka àwọn ẹsẹ kan látinú Bíbélì. Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù kọ̀wé sí Tímótì alábàákẹ́gbẹ́ rẹ̀ pé: “Sa gbogbo ipá rẹ láti fi ara rẹ hàn fún Ọlọ́run ní ẹni tí a tẹ́wọ́ gbà, aṣiṣẹ́ tí kò ní ohun kankan láti tì í lójú, tí ń fi ọwọ́ títọ̀nà mú ọ̀rọ̀ òtítọ́.”—2 Tím. 2:15.
Láti ṣe èyí túmọ̀ sí pé bí a ṣe ń ṣàlàyé àwọn ẹsẹ Ìwé Mímọ́ gbọ́dọ̀ bá ohun tí Bíbélì alára fi kọ́ni mu. Èyí ń béèrè pé ká gbé ìdí tí ọ̀rọ̀ yẹn fi wáyé níbẹ̀ yẹ̀ wò, dípò tí a ó kàn fi fa àwọn gbólóhùn tó kàn wù wá níbẹ̀ yọ, kí á sì wá fi èrò tara wa kún un. Jèhófà gbẹnu Jeremáyà kìlọ̀ fáwọn wòlíì tó sọ pé ẹnu Jèhófà làwọn ti gbọ́ ọ̀rọ̀ táwọn ń sọ, nígbà tó jẹ́ pé “ìran ọkàn-àyà tiwọn” ni wọ́n ń sọ ní ti gidi. (Jer. 23:16) Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù kìlọ̀ fáwọn Kristẹni pé kí wọ́n má ṣe fi ìmọ̀ ọgbọ́n orí ènìyàn ta àbààwọ́n sí Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run nígbà tó kọ̀wé pé: “Àwa ti kọ àwọn ohun má-jẹ̀ẹ́-á-gbọ́ tí ń tini lójú sílẹ̀ ní àkọ̀tán, a kò rin ìrìn àlùmọ̀kọ́rọ́yí, bẹ́ẹ̀ ni a kò ṣe àbùlà ọ̀rọ̀ Ọlọ́run.” Láyé ìgbà yẹn, àwọn onímàgòmágó tí ń ta wáìnì máa ń fomi lú wáìnì wọn kí ó lè pọ̀ sí i, kí owó lè túbọ̀ wọlé fún wọn. Àwa kì í ṣe àbùlà Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run nípa dída ọgbọ́n orí ènìyàn pọ̀ mọ́ ọ̀rọ̀ náà. Pọ́ọ̀lù sọ pé: “Àwa kì í ṣe akirità ọ̀rọ̀ Ọlọ́run gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ ènìyàn ti jẹ́, ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí pẹ̀lú òtítọ́ inú, bẹ́ẹ̀ ni, gẹ́gẹ́ bí a ti rán wa láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run, ní iwájú Ọlọ́run, ní ìbákẹ́gbẹ́pọ̀ pẹ̀lú Kristi, ni àwa ń sọ̀rọ̀.”—2 Kọ́r. 2:17; 4:2.
Nígbà mìíràn, o lè lo ẹsẹ Bíbélì kan láti fi gbé ìlànà kan yọ. Bíbélì kún fún àwọn ìlànà tó ń fún wa ní ìtọ́sọ́nà yíyèkooro láti kojú onírúurú ipò. (2 Tím. 3:16, 17) Ṣùgbọ́n, o gbọ́dọ̀ rí i dájú pé o lo ẹsẹ Bíbélì lọ́nà pípéye, láìlọ́ ọ lọ́rùn, láìmú kí ó máa sọ ohun tí ìwọ bá fẹ́. (Sm. 91:11, 12; Mát. 4:5, 6) Bí o ṣe lò ó gbọ́dọ̀ bá ète Jèhófà àti Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run mu látòkèdélẹ̀.
‘Fífi ọwọ́ títọ̀nà mú ọ̀rọ̀ òtítọ́’ tún wé mọ́ lílóye èrò tí Bíbélì ń gbìn síni lọ́kàn. Kì í ṣe “kóńdó” tí a fi ń halẹ̀ mọ́ àwọn èèyàn. Àwọn olùkọ́ni inú ìsìn tí wọ́n tako Jésù Kristi fa ọ̀rọ̀ yọ látinú Ìwé Mímọ́, àmọ́ wọn ò náání àwọn ohun pàtàkì tí Ọlọ́run ń béèrè, ìyẹn àwọn ohun tó ní í ṣe pẹ̀lú ìdájọ́ òdodo àti àánú àti ìṣòtítọ́. (Mát. 22:23, 24; 23:23, 24) Jésù a máa gbé ànímọ́ Bàbá rẹ̀ yọ nígbà tó bá ń kọ́ni ní Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run. Bí Jésù ṣe ní ìtara fún òtítọ́, bẹ́ẹ̀ náà ló ní ìfẹ́ jíjinlẹ̀ fáwọn èèyàn tó ń kọ́ lẹ́kọ̀ọ́. A gbọ́dọ̀ sapá láti tẹ̀ lé àpẹẹrẹ rẹ̀.—Mát. 11:28.
Báwo la ṣe lè rí i dájú pé a ò ṣi Ìwé Mímọ́ lò? Kíka Bíbélì déédéé yóò ràn wá lọ́wọ́. Ó tún yẹ ká mọyì “ẹrú olóòótọ́ àti olóye” tí Jèhófà ń lò, ìyẹn ẹgbẹ́ Kristẹni ẹni àmì òróró tí Jèhófà ń tipasẹ̀ rẹ̀ pèsè oúnjẹ tẹ̀mí fún agboolé ìgbàgbọ́. (Mát. 24:45) Ìdákẹ́kọ̀ọ́ àti lílọ sí àwọn ìpàdé ìjọ déédéé àti kíkópa nínú wọn yóò ràn wá lọ́wọ́ láti jàǹfààní nínú ìtọ́ni tí ẹgbẹ́ ẹrú olóòótọ́ àti olóye náà ń pèsè.
Bí ìwé Reasoning From the Scriptures bá wà lédè rẹ, tí o sì mọ̀ ọ́n lò dáadáa, kò ní nira fún ọ rárá láti mọ ọ̀nà tó tọ́ láti gbà lo ọgọ́rọ̀ọ̀rún ẹsẹ Ìwé Mímọ́ tá a sábà máa ń lò lóde ẹ̀rí. Bó o bá fẹ́ lo ẹsẹ kan tí o kò fi bẹ́ẹ̀ mọ̀, ìwà ìrẹ̀lẹ̀ yóò sún ọ láti ṣe ìwádìí yíyẹ, kí o bàa lè fi ọwọ́ títọ̀nà mú ọ̀rọ̀ òtítọ́ nígbà tó o bá ń sọ̀rọ̀.—Òwe 11:2.
Jẹ́ Kí Ìlò Ẹsẹ Ìwé Mímọ́ Ṣe Kedere. Nígbà tó o bá ń kọ́ àwọn ẹlòmíràn, rí i dájú pé wọ́n lóye bí ẹsẹ tó o lò ṣe tan mọ́ kókó tí ò ń sọ̀rọ̀ lé lórí. Bó bá jẹ́ ìbéèrè lo fi nasẹ̀ Ìwé Mímọ́ náà, ó yẹ káwọn olùgbọ́ rẹ rí i bí ẹsẹ náà ṣe dáhùn ìbéèrè ọ̀hún. Bó bá jẹ́ pé ò ń fi ẹsẹ náà ti gbólóhùn kan lẹ́yìn ni, rí i dájú pé akẹ́kọ̀ọ́ náà lóye bí ẹsẹ náà ṣe ṣàlàyé kókó náà.
Wíwulẹ̀ ka ẹsẹ náà, àní kéèyàn kà á pẹ̀lú ìtẹnumọ́ pàápàá, kì í sábàá tó. Rántí pé ọ̀pọ̀ èèyàn ni kò mọ ohun tó wà nínú Bíbélì, tó sì jẹ́ pé kíkà á lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo péré lè máà tó láti mú kí wọ́n lóye kókó tí ò ń sọ. Pe àfiyèsí sí apá ibi tó tan mọ́ kókó tí ẹ̀ ń sọ̀rọ̀ lé lórí gan-an nínú ẹsẹ náà.
Èyí sábà máa ń béèrè pé kí o mú àwọn ọ̀rọ̀ pàtàkì-pàtàkì ibẹ̀ jáde, ìyẹn àwọn ọ̀rọ̀ tí kókó tí ẹ̀ ń sọ dá lé lórí gan-an. Ọ̀nà tó rọrùn jù lọ ni pé kó o tún àwọn ọ̀rọ̀ tí ń lani lóye wọ̀nyẹn sọ. Bó bá jẹ́ ẹnì kan lò ń bá sọ̀rọ̀, o lè béèrè àwọn ìbéèrè tó máa jẹ́ kó rí ọ̀rọ̀ pàtàkì wọ̀nyẹn. Nígbà tí àwọn olùbánisọ̀rọ̀ kan bá ń bá àwùjọ sọ̀rọ̀, wọ́n máa ń yàn láti lo àwọn ọ̀rọ̀ mìíràn tó ní ìtumọ̀ kan náà tàbí kí wọ́n tún àlàyé náà ṣe kí àwùjọ lè lóye wọn dáadáa. Àmọ́ tó o bá yàn láti ṣe èyí, ṣọ́ra, kí ọ̀rọ̀ rẹ má bàa rú àwùjọ lójú, tí wọn ò fi ní rí bí kókó tó ò ń sọ̀rọ̀ lé lórí ṣe tan mọ́ ọ̀rọ̀ inú ẹsẹ Ìwé Mímọ́ náà.
Tó o bá lè mú kí àwọn kókó ọ̀rọ̀ ṣe kedere, o ti fi ìpìlẹ̀ rere lélẹ̀ nìyẹn. Ohun tó kàn ni pé kí o wá ṣàlàyé síwájú sí i. Ṣé o jẹ́ kí ìdí tó o fi fẹ́ ka Ìwé Mímọ́ náà ṣe kedere nígbà tó ò ń nasẹ̀ rẹ̀? Bí o bá ṣe bẹ́ẹ̀, ṣàlàyé ọ̀nà tí àwọn ọ̀rọ̀ tí o tẹnu mọ́ gbà tan mọ́ ohun tó o fọkàn àwùjọ sí pé kí wọ́n máa retí. Ṣàlàyé yékéyéké nípa bí wọ́n ṣe tan mọ́ra. Ká tiẹ̀ wá sọ pé o kò lo irú ìnasẹ̀ ọ̀rọ̀ tó ṣe kedere bẹ́ẹ̀, ó ṣì yẹ kó o ṣàlàyé síwájú sí i.
Àwọn Farisí bi Jésù ní ìbéèrè kan tí wọ́n rò pé ó le koko bí ojú ẹja, wọ́n ní: “Ó ha bófin mu fún ọkùnrin láti kọ aya rẹ̀ sílẹ̀ lórí onírúurú ìdí gbogbo?” Jésù gbé èsì rẹ̀ ka Jẹ́nẹ́sísì 2:24. Ṣàkíyèsí pé apá kan nínú ẹsẹ yẹn ló darí àfiyèsí sí, ó sì wá lò ó bó ṣe yẹ. Lẹ́yìn tó tọ́ka sí i pé ọkùnrin náà àti aya rẹ̀ di “ara kan,” Jésù wá kan ọ̀rọ̀ rẹ̀ nìṣó pé: “Nítorí náà, ohun tí Ọlọ́run ti so pọ̀, kí ènìyàn kankan má ṣe yà á sọ́tọ̀.”—Mát. 19:3-6.
Báwo ló ṣe yẹ kí àlàyé rẹ gùn tó, kí ọ̀nà tó o gbà lo Ìwé Mímọ́ lè ṣe kedere? Àwùjọ rẹ àti bí kókó tó ò ń sọ̀rọ̀ lé lórí ti ṣe pàtàkì sí ló yẹ kó pinnu ìyẹn. Ohun tó yẹ kó o máa lépa ni bí ọ̀rọ̀ rẹ á ṣe tètè yéni àti bí o ṣe máa sọ ojú abẹ níkòó.
Máa Fèrò Wérò Látinú Ìwé Mímọ́. Ìwé Ìṣe 17:2, 3 sọ fún wa pé àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù “fèrò-wérò láti inú Ìwé Mímọ́” nígbà iṣẹ́ òjíṣẹ́ rẹ̀ ní Tẹsalóníkà. Gbogbo ìránṣẹ́ Jèhófà ló yẹ kó sapá láti ní ànímọ́ yìí. Bí àpẹẹrẹ, Pọ́ọ̀lù sọ̀rọ̀ nípa ìgbésí ayé àti iṣẹ́ òjíṣẹ́ Jésù, ó fi hàn pé a ti sọ nǹkan wọ̀nyí tẹ́lẹ̀ nínú Ìwé Mímọ́ Lédè Hébérù, lẹ́yìn náà ló wá là á mọ́lẹ̀ pé: “Èyí ni Kristi náà, Jésù yìí tí mo ń kéde fún yín.”
Nígbà tí Pọ́ọ̀lù ń kọ̀wé sí àwọn Hébérù, ọ̀pọ̀ ìgbà ló fa ọ̀rọ̀ yọ látinú Ìwé Mímọ́ Lédè Hébérù. Láti tẹnu mọ́ kókó kan tàbí láti mú un ṣe kedere, ó máa ń fa ẹyọ ọ̀rọ̀ kan tàbí gbólóhùn kúkúrú kan yọ, á sì wá sọ bí ó ṣe ṣe pàtàkì tó. (Héb. 12:26, 27) Nígbà tí Pọ́ọ̀lù ń sọ ìtàn tó wà nínú Hébérù orí kẹta, ó fa ọ̀rọ̀ yọ látinú Sáàmù 95:7-11. Ṣàkíyèsí pé ó wá ṣàlàyé lórí apá mẹ́ta lára rẹ̀: (1) ó ṣàlàyé lórí ọkàn-àyà (Héb. 3:8-12), (2) ó ṣàlàyé ìjẹ́pàtàkì ọ̀rọ̀ náà “Lónìí” (Héb. 3:7, 13-15; 4:6-11), (3) ó sì ṣàlàyé ìtumọ̀ gbólóhùn náà: “Wọn kì yóò wọ ibi ìsinmi mi” (Héb. 3:11, 18, 19; 4:1-11). Sapá láti tẹ̀ lé àpẹẹrẹ yẹn nínú bó o ṣe ń lo ẹsẹ Ìwé Mímọ́ kọ̀ọ̀kan.
Ṣàkíyèsí ọ̀nà tó múná dóko tí Jésù gbà fèrò wérò látinú Ìwé Mímọ́ nínú ìtàn tó wà ní Lúùkù 10:25-37. Ọkùnrin kan tó jẹ́ ògbóǹkangí nínú Òfin béèrè pé: “Olùkọ́, nípa ṣíṣe kí ni èmi yóò fi jogún ìyè àìnípẹ̀kun?” Nígbà tí Jésù máa fèsì, ó kọ́kọ́ ní kí ọkùnrin náà sọ èrò rẹ̀ lórí ọ̀ràn náà. Lẹ́yìn náà ni Jésù wá tẹnu mọ́ bí ó ṣe ṣe pàtàkì tó láti ṣe ohun tí Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run wí. Nígbà tó wá hàn kedere pé òye ọ̀rọ̀ náà kò tíì yé ọkùnrin yìí, Jésù wá ṣe ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ àlàyé lórí ẹyọ ọ̀rọ̀ kan ṣoṣo nínú ẹsẹ náà, èyíinì ni “aládùúgbò.” Dípò kí ó kàn sọ ìtumọ̀ rẹ̀, ńṣe ló lo àpèjúwe kan tó ran ọkùnrin náà lọ́wọ́ láti fúnra rẹ̀ parí ọ̀rọ̀ náà síbi tó tọ́.
Ó ṣe kedere pé nígbà tí Jésù bá ń dáhùn ìbéèrè, kì í fa àwọn ẹsẹ Bíbélì tó dáhùn ìbéèrè náà yọ ní tààràtà lásán. Ńṣe ló máa ń fọ́ ohun tí ẹsẹ wọ̀nyí sọ sí wẹ́wẹ́, tí á sì wá fi bí ẹsẹ náà ṣe dáhùn ìbéèrè tó wà nílẹ̀ hàn.
Nígbà táwọn Sadusí ń tako ìrètí àjíǹde, apá kan pàtó nínú Ẹ́kísódù 3:6 ni Jésù pe àfiyèsí sí. Ṣùgbọ́n kò fi mọ sórí kíka ẹsẹ yẹn nìkan. Ó fèrò wérò lórí rẹ̀ láti fi hàn kedere pé àjíǹde jẹ́ ara ète Ọlọ́run.—Máàkù 12:24-27.
Mímọ bá a ṣe ń fèrò wérò lọ́nà tí ó tọ́, tí ó sì múná dóko nínú Ìwé Mímọ́ ṣe pàtàkì gan-an kí o tó lè di olùkọ́ tó pegedé.
-
-
Jẹ́ Kí Àwùjọ Rí Bí Ọ̀rọ̀ Rẹ Ṣe WúlòJàǹfààní Nínú Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run
-
-
Ẹ̀KỌ́ 23
Jẹ́ Kí Àwùjọ Rí Bí Ọ̀rọ̀ Rẹ Ṣe Wúlò
YÁLÀ ẹnì kan ṣoṣo lò ń bá sọ̀rọ̀ ni o tàbí àwùjọ ńlá, kò bọ́gbọ́n mu láti kàn gbà pé kókó tí ò ń sọ̀rọ̀ lé lórí yóò wu olùgbọ́ rẹ, tàbí àwùjọ náà, kìkì nítorí pé ó ti wu ìwọ alára. Ohun tó o fẹ́ sọ ṣe pàtàkì, àmọ́ bí o kò bá fi bí ó ṣe wúlò hàn kedere, ó lè máà pẹ́ tí ọ̀kan àwùjọ yóò fi kúrò lórí ohun tí ò ń bá wọn sọ.
Kódà, ó máa ń ṣẹlẹ̀ sí àwùjọ inú Gbọ̀ngàn Ìjọba pàápàá. Wọ́n lè máa fọkàn bá ọ lọ bí o bá ń sọ àpèjúwe kan tàbí ìrírí kan tí wọn kò gbọ́ rí. Ṣùgbọ́n ó ṣeé ṣe kí wọ́n má fọkàn sí ọ̀rọ̀ rẹ bó bá jẹ́ ohun tí wọ́n ti mọ̀ tẹ́lẹ̀ ni, pàápàá bí o kò bá fi ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ àlàyé gbé e jókòó. O ní láti ràn wọ́n lọ́wọ́ láti rí ìdí tí ohun tí ò ń sọ yóò fi ṣe wọ́n ní àǹfààní gidi àti ọ̀nà tí yóò gbà ṣe wọ́n láǹfààní.
Bíbélì rọ̀ wá pé kí á máa ronú lọ́nà tó gbéṣẹ́, tó sì ṣeé mú lò. (Òwe 3:21) Jèhófà lo Jòhánù Olùbatisí láti darí àwọn èèyàn sí “ọgbọ́n tí ó gbéṣẹ́ ti àwọn olódodo.” (Lúùkù 1:17) Ọgbọ́n yìí jẹ́ èyí tó pilẹ̀ látinú ojúlówó ìbẹ̀rù fún Jèhófà. (Sm. 111:10) Àwọn tó mọrírì ọgbọ́n yìí ń rí ìrànlọ́wọ́ gbà láti lè rí ọgbọ́n ta sí ọ̀ràn ìgbésí ayé ìsinsìnyí, kí ọwọ́ wọn sì tún tẹ ìyè tòótọ́, ìyẹn ìyè ayérayé tí ń bọ̀.—1 Tím. 4:8; 6:19.
Bí O Ṣe Lè Sọ̀rọ̀ Lọ́nà Tó Ṣeé Mú Lò. Bí ọ̀rọ̀ rẹ yóò bá ṣeé mú lò, kì í ṣe ọ̀rọ̀ yẹn nìkan lo máa ronú sí dáadáa, wàá tún ronú nípa àwọn olùgbọ́ rẹ pẹ̀lú. Má kàn kó wọn pọ̀ gẹ́gẹ́ bí àwùjọ nígbà tó o bá ń ronú nípa wọn. Ẹnì kọ̀ọ̀kan àti ìdílé kọ̀ọ̀kan ló para pọ̀ sínú àwùjọ yẹn. Àwọn ọmọdé, ọ̀dọ́, àgbà, àtàwọn tó jẹ́ arúgbó lè wà níbẹ̀. Àwọn ẹni tuntun lè wà níbẹ̀ àtàwọn tó tiẹ̀ ti ń sin Jèhófà kí wọ́n tó bí ọ pàápàá. Àwọn kan lè dàgbà dénú nípa tẹ̀mí; bẹ́ẹ̀ ni ìwà àti ìṣe ayé ṣì lè wà lọ́kàn àwọn kan digbí. Bi ara rẹ léèrè pé: ‘Báwo ni ohun tí mo fẹ́ sọ̀rọ̀ lé lórí yóò ṣe ṣe àwùjọ yìí láǹfààní? Báwo ni mo ṣe lè mú kí kókó ọ̀rọ̀ mi yé wọn?’ O lè yàn láti fún ọ̀kan tàbí méjì péré nínú àwọn olùgbọ́ tí a mẹ́nu kàn níhìn-ín láfiyèsí ní pàtàkì. Àmọ́ ṣá, máà gbàgbé àwọn tó kù o.
Ká ní ọ̀kan lára àwọn ẹ̀kọ́ Bíbélì téèyàn máa ń kọ́kọ́ mọ̀ ni a yàn fún ọ láti sọ̀rọ̀ lé lórí ńkọ́? Báwo ni wàá ṣe sọ ọ̀rọ̀ yẹn fún àwùjọ tó ti gba ẹ̀kọ́ yẹn gbọ́ tẹ́lẹ̀ kí ó sì ṣe wọ́n láǹfààní? Ńṣe ni kó o gbìyànjú láti mú kí ìgbàgbọ́ wọn nípa rẹ̀ túbọ̀ lágbára sí i. Lọ́nà wo? Nípa ṣíṣàlàyé àwọn ẹ̀rí Ìwé Mímọ́ tó tì í lẹ́yìn ni. O tún lè mú kí wọ́n túbọ̀ mọyì ẹ̀kọ́ Bíbélì yẹn sí i. O lè ṣe èyí nípa fífihàn bí ẹ̀kọ́ yẹn ṣe bá àwọn òtítọ́ Bíbélì yòókù mu, àti bí ó ṣe bá ànímọ́ Jèhófà alára mu. Lo àwọn àpẹẹrẹ, bóyá kí o sọ ìrírí pàápàá, nípa bí lílóye ẹ̀kọ́ tí ò ń sọ yìí ti ṣe àwọn èèyàn láǹfààní, tó sì ti nípa lórí irú ojú tí wọ́n fi ń wo ọjọ́ ọ̀la.
Má ṣe dúró dìgbà àlàyé kúkúrú tí o máa ṣe níparí ọ̀rọ̀ rẹ kí o tó máa sọ ọ̀nà tí wọ́n lè gbà lo ohun tó ò ń sọ. Láti ìbẹ̀rẹ̀ ló yẹ kí olúkúlùkù ẹni tó wà nínú àwùjọ rẹ ti mọ̀ ọ́n lára pé “ọ̀rọ̀ yìí kàn mí o.” Bí o bá sì ti wá fi ìpìlẹ̀ yẹn lélẹ̀, ńṣe ni kí o máa bá a nìṣó láti sọ bí àwùjọ náà ṣe lè lo àwọn kókó pàtàkì inú ọ̀rọ̀ rẹ bí o ṣe ń ṣàlàyé wọn lọ́kọ̀ọ̀kan kí o sì tún sọ àwọn kókó pàtàkì yẹn níparí ọ̀rọ̀ rẹ pẹ̀lú.
Nígbà tó o bá ń sọ bí wọ́n ṣe lè lo ọ̀rọ̀ rẹ, rí i dájú pé o sọ ọ́ lọ́nà tó bá àwọn ìlànà Bíbélì mu. Kí nìyẹn túmọ̀ sí? Ó túmọ̀ sí pé kí o sọ ọ́ tìfẹ́tìfẹ́ lọ́nà tí yóò fi hàn pé o gba tẹni rò. (1 Pét. 3:8; 1 Jòh. 4:8) Kódà nígbà tí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù ń gbìyànjú láti yanjú àwọn ìṣòro tó ta kókó ní Tẹsalóníkà, ó ṣì rí i dájú pé òun mẹ́nu kan àwọn ìhà tí àwọn Kristẹni arákùnrin àti arábìnrin rẹ̀ tó wà níbẹ̀ ti ń tẹ̀ síwájú dáadáa nípa tẹ̀mí. Ó tún fi hàn pé òun fọkàn tán wọn pé wọ́n á fẹ́ láti ṣe ohun tó tọ́ nínú ohun tí òun ń bá wọn sọ̀rọ̀ lé lórí. (1 Tẹs. 4:1-12) Àpẹẹrẹ tó dára gan-an nìyẹn fún wa láti tẹ̀ lé!
Ṣé wọ́n fẹ́ kó o fi ọ̀rọ̀ rẹ gba àwọn èèyàn níyànjú láti túbọ̀ jí gìrì sí iṣẹ́ wíwàásù àti kíkọ́ni ní ìhìn rere ni? Ńṣe ni kí o mú kí ìtara àti ìmọrírì tí àwọn èèyàn ní fún àǹfààní yìí túbọ̀ pọ̀ sí i. Àmọ́ bí o ṣe ń ṣe èyí, fi í sọ́kàn pé ìwọ̀n tí oníkálùkù lè ṣe lẹ́nu iṣẹ́ yìí yàtọ̀ síra, Bíbélì sì fi ìyẹn hàn bẹ́ẹ̀. (Mát. 13:23) Má ṣe sọ òkò ọ̀rọ̀ lu àwọn arákùnrin rẹ láti mú wọn kárí sọ, pé àwọn ti dẹ́ṣẹ̀ jìnnàjìnnà. Ohun tí Hébérù 10:24 rọ̀ wá láti ṣe ni pé kí á “ru ara wa sókè sí ìfẹ́ àti sí àwọn iṣẹ́ àtàtà.” Bí a bá gbin ẹ̀mí ìfẹ́ sí àwọn èèyàn lọ́kàn, wọ́n á lẹ́mìí àtiṣe iṣẹ́ látọkànwá. Dípò tí wàá fi máa gbìyànjú láti pàṣẹ pé dandan ni kí iṣẹ́ tẹ́nì kan ṣe bá tẹnì kejì dọ́gba, mọ̀ pé ohun tí Jèhófà ń fẹ́ ni pé kí á jẹ́ kí “ìgbàgbọ́” sún àwọn èèyàn láti ṣe “ìgbọràn.” (Róòmù 16:26) Bí á bá fi ìyẹn sọ́kàn, ńṣe la óò máa wá ọ̀nà láti máa fún ìgbàgbọ́ tiwa àti tàwọn arákùnrin wa lókun.
Jíjẹ́ Kí Àwọn Èèyàn Rí Bí Ọ̀rọ̀ Náà Ṣe Wúlò. Bí o ṣe ń wàásù fún àwọn èèyàn, má ṣe kùnà láti mẹ́nu kan bí ìhìn rere ṣe wúlò fún wọn. Bí o bá fẹ́ ṣe bẹ́ẹ̀, ó gba pé kí o mọ ohun tí ń bẹ lọ́kàn àwọn tó wà ní ìpínlẹ̀ rẹ. Báwo lo ṣe lè mọ̀ ọ́n? Máa tẹ́tí sí ìròyìn orí rédíò àti tẹlifíṣọ̀n. Máa wo ojú ewé àkọ́kọ́ nínú ìwé ìròyìn. Bákan náà, máa gbìyànjú láti fa àwọn èèyàn wọnú ìfọ̀rọ̀wérọ̀, kí o sì tẹ́tí gbọ́ wọn bí wọ́n bá ń sọ̀rọ̀. O lè wá rí i pé wọ́n ní àwọn ìṣòro tí wọ́n ń bá yí, bóyá iṣẹ́ bọ́ lọ́wọ́ wọn ni, àìrí owó ilé san ni, àìsàn ni, ẹbí wọn kan kú ni, ewu ìwà ọ̀daràn ni, ẹni tí wọ́n fi ọwọ́ ọlá gbá lójú ni, ìdílé wọn dà rú ni, ọ̀nà tí yóò gbà kápá àwọn ọmọ ni, àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ. Ǹjẹ́ Bíbélì lè ràn wọ́n lọ́wọ́? Ó dájú pé ó lè ṣe bẹ́ẹ̀.
Nígbà tó o bá fẹ́ bẹ̀rẹ̀ ìfọ̀rọ̀wérọ̀, ó ṣeé ṣe kí kókó kan ti wà lọ́kàn rẹ tó o fẹ́ sọ̀rọ̀ lé lórí. Àmọ́, tí ẹni yẹn bá fi hàn pé nǹkan mìíràn wà tó jẹ òun lógún ní lọ́ọ́lọ́ọ́, má ṣe lọ́tìkọ̀ láti kọ́kọ́ bá a sọ̀rọ̀ lórí ìyẹn ná bí o bá mọ ohun tó o lè sọ, tàbí kí o sọ fún un pé wàá padà wá bá a sọ ohun tó lè ràn án lọ́wọ́. Lóòótọ́, a kò ní máa ‘tojú bọ ohun tí kò kàn wá,’ ṣùgbọ́n tayọ̀tayọ̀ la ó fi mẹ́nu kan àwọn ìmọ̀ràn wíwúlò tó wà nínú Bíbélì fún àwọn èèyàn. (2 Tẹs. 3:11) Dájúdájú, ohun tó máa wú àwọn èèyàn lórí jù lọ ni pé kí wọ́n rí ìmọ̀ràn inú Bíbélì tó kan ọ̀ràn ìgbésí ayé tiwọn fúnra wọn.
Bí àwọn èèyàn ò bá rí ọ̀nà tí ohun tí à ń bá wọn sọ gbà kàn wọ́n, wọ́n lè dá ìfọ̀rọ̀wérọ̀ yẹn dúró kíákíá. Bí wọ́n bá sì tiẹ̀ jẹ́ ká sọ̀rọ̀, sísọ tí a kò sọ bí wọ́n ṣe lè lo ọ̀rọ̀ tí a bá wọn sọ lè mú kí ọ̀rọ̀ wa má fi bẹ́ẹ̀ yí ìgbésí ayé wọn padà. Ṣùgbọ́n, bí a bá mú kí ọ̀nà tí wọ́n lè gbà lo ohun tí a bá wọn sọ yé wọn kedere, ìgbésí ayé wọn lè bẹ̀rẹ̀ sí yí padà látorí ohun tí a bá wọn sọ wẹ́rẹ́ yẹn.
Nígbà tí o bá ń kọ́ni lẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì, máa sọ fún wọn bí wọn yóò ṣe mú ọ̀rọ̀ ibẹ̀ lò. (Òwe 4:7) Mú kí àwọn akẹ́kọ̀ọ́ lóye ìmọ̀ràn, àwọn ìlànà, àti àpẹẹrẹ inú Ìwé Mímọ́ tó fi bí èèyàn ṣe lè máa rìn ní àwọn ọ̀nà Jèhófà hàn. Tẹnu mọ́ àwọn àǹfààní téèyàn máa jẹ bí ó bá ń ṣe bẹ́ẹ̀. (Aísá. 48:17, 18) Èyí á sún àwọn akẹ́kọ̀ọ́ láti ṣe àyípadà tó yẹ nínú ìgbésí ayé wọn. Kọ́ wọn ní bí wọ́n ṣe lè máa fẹ́ràn Jèhófà kí wọ́n sì fẹ́ láti máa ṣe ohun tó wù ú, kí o sì wá jẹ́ kí ọkàn àwọn fúnra wọn sún wọn láti fi ìmọ̀ràn inú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run sílò.
-