-
Mọ Irú Ẹni Tí Ẹlẹ́dàá Rẹ Jẹ́Ilé Ìṣọ́—1999 | June 15
-
-
yìí, Jésù ti fi agbára tí ó ní láti láti sọ òkú di alààyè hàn. (Lúùkù 7:11-17; 8:40-56) Ṣùgbọ́n, báwo ló ṣe ṣe nígbà tó rí Màríà, arábìnrin Lásárù, tó ń ṣọ̀fọ̀? Jésù “kérora nínú ẹ̀mí, ó sì dààmú.” Kò ṣe bí ẹni tọ́ràn náà ò kàn rárá, kó sọ pé òun fẹ́ ṣe bí ọkùnrin; ṣùgbọ́n ó “bẹ̀rẹ̀ sí da omijé.” (Jòhánù 11:33-35) Èyí kì í ṣe ojú ayé lásán. A sún Jésù láti hùwà rere—ó jí Lásárù dìde. O lè ronú nípa bí èyí ṣe ran àwọn àpọ́sítélì lọ́wọ́ láti lóye ìmọ̀lára Ẹlẹ́dàá àti àwọn ìwà rẹ̀. Ó yẹ kí ó ràn àwa pẹ̀lú lọ́wọ́ àti àwọn ẹlòmíràn láti mọ ìwà àti àwọn ọ̀nà Ẹlẹ́dàá.
18. Ojú ìwòye wo ló yẹ káwọn èèyàn ní nípa kíkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì?
18 Kò sídìí kankan tí a fi ní láti máa tijú kíkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì àti kíkọ́ nípa Ẹlẹ́dàá wa. Bíbélì kì í ṣe ìwé tí kò bá ìgbà mu mọ́. Jòhánù jẹ́ ẹnì kan tó kẹ́kọ̀ọ́ nínú rẹ̀, tí ó sì di alábàáṣiṣẹ́ Jésù. Ó kọ̀wé lẹ́yìn ìgbà náà pé: “A mọ̀ pé Ọmọ Ọlọ́run ti wá, ó sì ti fún wa ní agbára ìmòye kí a lè jèrè ìmọ̀ nípa ẹni tòótọ́ náà. A sì wà ní ìrẹ́pọ̀ pẹ̀lú ẹni tòótọ́ náà, nípasẹ̀ Ọmọ rẹ̀ Jésù Kristi. Èyí ni Ọlọ́run tòótọ́ náà àti ìyè àìnípẹ̀kun.” (1 Jòhánù 5:20) Ṣàkíyèsí pé lílo “agbára ìmòye” láti jèrè ìmọ̀ nípa “ẹni tòótọ́ náà,” ìyẹn ni Ẹlẹ́dàá, lè yọrí sí “ìyè àìnípẹ̀kun.”
Báwo Lo Ṣe Lè Ran Àwọn Ẹlòmíràn Lọ́wọ́ Láti Kẹ́kọ̀ọ́ Nípa Rẹ̀?
19. Ìgbésẹ̀ wo la ti gbé láti ran àwọn oníyèméjì lọ́wọ́?
19 Ó ń béèrè iṣẹ́ takuntakun kí àwọn kan tó lè gbà gbọ́ pé Ẹlẹ́dàá oníyọ̀ọ́nú kan ń bẹ, ẹni tó bìkítà nípa wa, ó sì tún ń béèrè irú iṣẹ́ bẹ́ẹ̀ kí wọ́n tó lè mọ irú ẹni tó jẹ́. Àràádọ́ta ọ̀kẹ́ lọ́nà àràádọ́ta ọ̀kẹ́ ló ṣì wà tí wọ́n ń ṣiyè méjì nípa Ẹlẹ́dàá tàbí tí ojú ìwòye wọn nípa rẹ̀ kò bá ohun tó wà nínú Bíbélì mu. Báwo lo ṣe lè ràn wọ́n lọ́wọ́? Nígbà àpéjọpọ̀ àgbègbè àti ti àgbáyé tí Àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe lọ́dún 1998 sí 1999, a mú irin iṣẹ́ tuntun kan tó gbéṣẹ́ jáde ní ọ̀pọ̀ èdè—ìyẹn ni ìwé náà, Is There a Creator Who Cares About You?
20, 21. (a) Báwo ni a ṣe lè lo ìwé náà, Creator, lọ́nà tí yóò kẹ́sẹ járí? (b) Sọ ìrírí nípa bí ìwé Creator ti ṣe jẹ́ ìwé to gbéṣẹ́.
20 Ó jẹ́ ìwé kan tí yóò gbé ìgbàgbọ́ rẹ ró nínú Ẹlẹ́dàá wa, tí yóò sì jẹ́ kí o túbọ̀ mọ ìwà àti àwọn ọ̀nà rẹ̀. Èé ṣe tí èyí fi dá wa lójú? Nítorí pé, ète bẹ́ẹ̀ la ní lọ́kàn táa fi ṣe ìwé náà, Is There a Creator Who Cares About You? jáde. Kókó kan tó jẹ yọ jálẹ̀ ìwé náà ni, “Kí ló lè túbọ̀ jẹ́ kí ìgbésí ayé rẹ̀ nítumọ̀?” A gbé àwọn kókó inú rẹ̀ kalẹ̀ lọ́nà tó jẹ́ pé àwọn èèyàn tí wọ́n kàwé púpọ̀ pàápàá lè gbádùn ẹ̀. Síbẹ̀, ó sọ̀rọ̀ lórí àwọn nǹkan tí púpọ̀ nínú wa ń yán hànhàn láti mọ̀. Ọ̀rọ̀ tó lè fa àwọn tó ń kọminú nípa pé Ẹlẹ́dàá ń bẹ mọ́ra wà nínú rẹ̀, wọ́n á gbádùn ẹ̀, ó sì lè yí èrò wọn padà. Ìwé náà kò wulẹ̀ gbà pé òǹkàwé náà ti gbà gbọ́ pé Ẹlẹ́dàá ń bẹ. Ọ̀nà táa gbà jíròrò àwọn àwárí àti èròǹgbà ìmọ̀ sáyẹ́ǹsì lọ́ọ́lọ́ọ́ yóò fa àwọn oníyèméjì lọ́kàn mọ́ra. Irú àwọn kókó bẹ́ẹ̀ pàápàá yóò fún ìgbàgbọ́ àwọn tó gba Ọlọ́run gbọ́ pàápàá lókun.
21 Nígbà tóo bá ń kẹ́kọ̀ọ́ ìwé tuntun yìí, wàá rí i pé àwọn apá kan nínú rẹ̀ ṣàlàyé àkópọ̀ ìtàn Bíbélì lọ́nà tó gbé àwọn ìwà Ọlọ́run yọ, èyí tó lè ran àwọn òǹkàwé lọ́wọ́ láti mọ Ọlọ́run dunjú. Ọ̀pọ̀ àwọn tí wọ́n ti kà á ló ti sọ nípa bí kókó yẹn ṣe jóòótọ́ tó nínú ìgbésí ayé wọn. (Wo àpilẹ̀kọ tó tẹ̀ lé e, ní ojú ìwé 25 sí 26.) Ǹjẹ́ kí ọ̀ràn tìrẹ náà rí bẹ́ẹ̀ bóo ti ń ka ìwé náà, tí o sì n lò ó láti ran àwọn ẹlòmíràn lọ́wọ́ láti mọ Ẹlẹ́dàá wọn lámọ̀dunjú.
-
-
‘Iná Ẹ̀mí Ìtọpinpin Ń Jó Lọ́kàn Mi’Ilé Ìṣọ́—1999 | June 15
-
-
‘Iná Ẹ̀mí Ìtọpinpin Ń Jó Lọ́kàn Mi’
“N kò lè sọ bínú mi ti dùn tó àti bí ara mi ti yá gágá tó nígbà tí mò ń ka ìwé yìí, Is There a Creator Who Cares About You? Ìwé yìí ò ṣeé gbé sílẹ̀ o, àfi kéèyàn ṣáà warí mọ́ ọn tó fi máa kà á tán. Ẹ mà ṣeun o, torí ẹ̀yin lẹ tanná ran ẹ̀mí ìtọpinpin lọ́kàn mi.”
BÍ Ọ̀KAN lára Àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà tó wá láti Àríwá Carolina, ní Orílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà ṣe sọ nípa ìwé náà tí Watch Tower Society mú jáde ní Àpéjọpọ̀ Àgbègbè “Ọ̀nà Ìgbésí Ayé Tí Ọlọ́run Fẹ́” tó wáyé lọ́dún 1998 sí 1999 nìyẹn. Ká ní oò tilẹ̀ ní ẹ̀dà ìwé náà, gbọ́ nǹkan táwọn ẹlòmí-ìn sọ.
Lẹ́yìn ọjọ́ díẹ̀ tí ọkùnrin kan gba ẹ̀dà tirẹ̀ ní àpéjọpọ̀ tí wọ́n ṣe ní San Diego, California, ní Orílẹ̀-Èdè Amẹ́ríkà, ó kọ̀wé pé: “Ìwé yìí mà fún ìgbàgbọ́ lókun o. Ó mú kí ń kún fún ìmọrírì jíjinlẹ̀ fún àwọn iṣẹ́ ọwọ́ Jèhófà. Ojú ìwé kejìdínlọ́gọ́rùn-ún ni mo wà báyìí, ó sì ń ṣe mí bí ẹnì pé kó máà tán, kí n ṣáà máa kà á lọ ṣáá! Ayọ̀ ọ̀hún pọ̀ jọjọ.”
Obìnrin kan láti Ìlà Oòrùn Ayé kọ̀wé pé: “Olùbánisọ̀rọ̀ ní àpéjọpọ̀ náà lo gbólóhùn náà, ‘ìwé àrà ọ̀tọ̀,’ bẹ́ẹ̀ gan-an nìwé náà jẹ́. Ohun kan tó tún tayọ nínú ìwé náà ni pé kò fipá mú òǹkàwé láti gbà pé Ọlọ́run ń bẹ, síbẹ̀ ó sọ ojú abẹ níkòó.”
Àwọn ohun tó jẹ́ apà kan òkodoro ọ̀rọ̀ náà ni àwọn àwárí ìmọ̀ sáyẹ́ǹsì tó fani mọ́ra nípa àgbáálá ayé wa, ìwàláàyè àti àwa fúnra wa. Èyí wú ọ̀pọ̀lọpọ̀ lórí. Obìnrin kan láti California kọ̀wé pé: “N kò tiẹ̀ mọ ohun tí màá sọ nípa bí ìwé kékeré yìí ti nípa lórí mi tó. N kò lè gbé ìwé náà sílẹ̀ rárá torí pé ojú ìwé kọ̀ọ̀kan ló ń ṣàpèjúwe ọ̀pọ̀ nǹkan tí a ṣàwárí nípa àgbáálá ayé wa àti ìwàláàyè fúnra rẹ̀. Ọ̀rọ̀ ki sínú ẹ̀! Ṣe ni n óò máa gbé ìwé kékeré yìí gẹ̀gẹ̀, tí n óò sì máa ṣàjọpín rẹ̀ pẹ̀lú ọ̀pọ̀ ènìyàn bí ó bá ti lè ṣeé ṣe tó.”
Ohun kan tó tún mú inú ọ̀pọ̀ dùn ni bí ìwé náà ṣe ṣàkópọ̀ Bíbélì, tó sì ṣàgbéyọ àwọn ìwà Ẹlẹ́dàá náà. Ohun tí ẹnì kan sọ nípa ìwé náà rèé: “Kò tí ì síwèé tí mo kà tó ṣàkópọ̀ Bíbélì tó bí apá tó gbẹ̀yìn ìwé yìí ti ṣe.” Kété lẹ́yìn àpéjọpọ̀ kan tí a kọ́kọ́ ṣe ní New York, ní Orílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà, ẹlòmíràn kọ̀wé pé: “Ìwé tẹ́ẹ ṣẹ̀ṣẹ̀ tẹ̀ jáde yìí ló jẹ́ ìwé tó gbàfiyèsí ẹni jù lọ tí ẹ tí ì tẹ̀ jáde. Àwọn ẹ̀rí ìmọ̀ sáyẹ́ǹsì tó fi hàn pé Ẹlẹ́dàá ń bẹ wọ̀ mí lọ́kàn ṣinṣin. Àkópọ̀ rẹ́gí tó ṣe nípa Bíbélì ti tó lọ́tọ̀ láti ṣàlàyé àwọn kókó tó wà nínú rẹ̀ àti láti jẹ́ kí òǹkàwé náà fẹ́ mọ púpọ̀ sí i.”
Sáyẹ́ǹsì Tó Yéni Yéké
Ìsọfúnni lórí ìmọ̀ sáyẹ́ǹsì ní àwọn òrí tó ṣáájú lè dà bí pé ó le díẹ̀, ṣùgbọ́n ohun táwọn kan sọ nípa rẹ̀ nìyí:
Ọkùnrin ará Kánádà kan kọ̀wé pé: “Èyí yàtọ̀ pátápátá sáwọn ìwé ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ mìíràn, tí àwọn tó kọ wọ́n máa ń fẹ́ fi ọ̀rọ̀ kàǹkà-kàǹkà wọn fani mọ́ra. Ìmọ̀ tẹ́ẹ ní lórí àwọn ẹ̀kọ́ bíi físíìsì, kẹ́mísìrì, èròjà DNA, àwọn èròjà apilẹ̀ àbùdá, àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ, kọyọyọ, yékéyéké làlàyé yìn yé wa. Ì bá ti lọ wà jù, ká lẹ́yìn lẹ kọ àwọn ìwé tí mo kà ní yunifásítì lọ́dún mélòó kan sẹ́yìn!”
Ọ̀jọ̀gbọ́n yunifásítì kan nínú ìmọ̀ físíìsì kọ̀wé pé: “[Ìwé náà] gbé àwọn kókó ọ̀ràn náà kalẹ̀ láìkówọnú àwọn kúlẹ̀kúlẹ̀ tó jẹ mọ́ ti ìmọ̀ ìjìnlẹ̀. Ìwé náà fèrò wérò pẹ̀lú òǹkàwé, ó sì fa ọ̀rọ̀ ọ̀pọ̀ onímọ̀ sáyẹ́ǹsì yọ. Èyí jẹ́ ‘ìwé pàtàkì’ fún gbogbo ẹni tó bá nífẹ̀ẹ́ nínú ìpilẹ̀ṣẹ̀ àgbáálá ayé àti ìwàláàyè, ì báà jẹ́ onímọ̀ sáyẹ́ǹsì tàbí ọ̀gbẹ̀rì nínú ìmọ̀ sáyẹ́ǹsì.”
Obìnrin kan tí ń kọ́ṣẹ́ nọ́ọ̀sì lọ́wọ́ sọ pé: “Ìyàlẹ́nu ńlá ló jẹ́ fún mi nígbà tí mo ṣí ìwé náà sí àkòrí kẹrin, tí mo sì ka àyọkà kan níbẹ̀, tí ó wá láti inú ìwé tí à ń lò gan-an ní kíláàsì! Mo fún ọ̀jọ̀gbọ́n wa ní ìwé náà, mo sì sọ fún un pé mo mọ̀ dájú pé ìsọfúnni inú ìwé náà yóò tù ú lára. Mo fi ojú ìwé kẹrìnléláàádọ́ta tó sọ nípa ọpọlọ hàn án. Ó kà á sínú, ó sì wí pé: ‘Èyí mà ga o! Màá kà á dáadáa.’”
Ẹni kan tó jẹ́ ọmọ ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin àgbà ní Belgium kọ̀wé pé: “Ohun tó yà mí lẹ́nu, tó sì jẹ́ kó gba àfiyèsí mi pátápátá ni àwọn àlàyé lórí ìmọ̀ sáyẹ́ǹsì tó fi hàn pé dípò tí ìmọ̀ sáyẹ́ǹsì òde òní fi máa tako ẹ̀kọ́ náà pé Ọlọ́run ń bẹ, èyí tí Bíbélì fi kọ́ni, ṣe ló fara mọ́ ẹ̀kọ́ náà. Ojú ìwòye tó múná dóko lèyí jẹ́.”
Mímọ Ẹlẹ́dàá Náà Dunjú
Ìwé náà ran àwọn èèyàn ní ọ̀pọ̀ ilẹ̀ lọ́wọ́ láti mọ Ọlọ́run dunjú, kí wọ́n sì sún mọ́ ọn pẹ́kípẹ́kí. Òǹkàwé kan ní Fukuoka City, Japan, sọ pé: “Ṣe ló dà bíi pé fún ìgbà àkọ́kọ́ a darí àfiyèsí sí Jèhófà. Ìwé náà yíni lérò padà lọ́nà tó yani lẹ́nu. Ó jẹ́ kí n mọ Jèhófà lọ́nà tí ń kò ronú nípa rẹ̀ rí.” Ará El Salvador kan kọ̀wé pé: “Ẹ ṣàlàyé kúnnákúnná nípa bí Ọlọ́run ṣe jẹ́ aláàánú, olóore ọ̀fẹ́, ẹni tí ń lọ́ra láti bínú, tó sì pọ̀ ní ìṣeun ìfẹ́ tó. Lóòótọ́, ohun tí a nílò gan-an nìyí táa bá fẹ́ sún mọ́ Ọlọ́run àti Ọmọ rẹ̀. Èyí ni ìwé tó kọ́kọ́ ṣàlàyé ìmọ̀lára Jèhófà àti ẹ̀mí ìgbatẹnirò tí Ọmọ rẹ̀, Jésù, ní.” Ẹnì kan tó ka ìwé náà ní Zambia sọ pé: “Èrò mi nípa Jèhófà yí padà pátápátá.”
Ó wá yéni kedere, ìdí tí Àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà fi ń fi tayọ̀tayọ̀ fi ìwé náà, Is There a Creator Who Cares About You? lọ àwọn ẹlómíràn. Ẹnì kan sọ pé: “Bí mo ti ń parí orí kẹwàá [“Bí Ẹlẹ́dàá Bá Bíkítà, Èé Ṣe Tí Ìyà Fi Pọ̀ Tó Bẹ́ẹ̀?”], ohun tó jáde lẹ́nu mi ni pé, ‘Ìwé táa nílò ní Japan gan-an nìyí!’ Màá fẹ́ láti lè rántí ohun tí mo kà nínú àkòrí yìí, kí n bàa lè lò ó nínú iṣẹ́ ìsìn pápá léraléra.” Obìnrin kan ń bá ọmọdébìnrin kan kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì, inú tẹ́ńpìlì àwọn ẹlẹ́sìn Búdà tí baba ọmọdébìnrin náà ti ń ṣiṣẹ́ àlùfáà ni a sì ti tọ́ ọmọ náà dàgbà. “Ó nira fún un láti tẹ́wọ́ gba ojú ìwòye náà pé Ẹlẹ́dàá ń bẹ. Kò sí ohun kan tó fipá múni nínú àlàyé ti ìwé yìí ṣe, ṣùgbọ́n àwọn òótọ́ ọ̀rọ̀ ń bẹ níbẹ̀, nítorí náà mo gbà pé àwọn ẹlẹ́sìn Búdà pàápàá lè ka ìwé yìí láìkọminú rárá. Ó tún jẹ́ ká túbọ̀ mọ̀ pé Jèhófà nífẹ̀ẹ́ wa.”
Àgbéyẹ̀wò yìí wá láti ìlú England: “Mo ṣẹ̀ṣẹ̀ ka ìwé Creator tán ni o, mo tún fẹ́ bẹ̀rẹ̀ sí í tún un kà. Ìwé nìwé yìí o jàre! Kò sí béèyàn ò ṣe ní nífẹ̀ẹ́ Jèhófà tó bá ń kà á. Mo ti fún aládùúgbò mi ní ẹ̀dà rẹ̀ kan, lẹ́yìn tó sì ka àkòrí méjì péré tán, ó wí pé, ‘Mi ò lè gbéwèé náà sílẹ̀, ó ti lọ wà jù.’ Ó dá mi lójú pé èyí yóò ran àwọn èèyàn lọ́wọ́ láti mọ Ẹlẹ́dàá wa Atóbilọ́lá dunjú.”
Ọkùnrin kan ní Maryland, Orílẹ̀-Èdè Amẹ́ríkà, sọ pé: “Ẹ wò ó, ọ̀rọ̀ ẹ̀ wọ̀ mí lákínyẹmí ará! Mo ti wéwèé pé gbogbo àwọn tí a jọ ń ṣòwò ni màá fún ní ẹ̀dà kọ̀ọ̀kan. Nígbà mìíràn, ó máa ń ṣòro fún mi láti bẹ̀rẹ̀ sí wàásù fún irú àwọn èèyàn bẹ́ẹ̀ tọ́wọ́ wọn máa ń dí, tí wọ́n sì jẹ́ ọ̀mọ̀wé. Àmọ́ báyìí o, ìwé yìí yóò ràn mí lọ́wọ́ láti rí ọ̀nà tó fani mọ́ra, tó sì gbéṣẹ́ láti bẹ̀rẹ̀ ọ̀rọ̀ mi.”
Ó dájú pé, ìwé náà, Is There a Creator Who Cares About You?, yóò nípa tó dáa lórí àwọn èèyàn jákèjádò ayé.
-