ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Jẹ́ Kí Àwọn Èèyàn Mọ Òtítọ́ Nípa Jésù
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba—2002 | November
    • Jẹ́ Kí Àwọn Èèyàn Mọ Òtítọ́ Nípa Jésù

      1 Àwọn Kristẹni ẹni àmì òróró, pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ àwọn àgùntàn mìíràn tó jẹ́ alábàákẹ́gbẹ́ wọn, “ní iṣẹ́ jíjẹ́rìí Jésù.” (Ìṣí. 12:17) Iṣẹ́ tá a gbé fún wọn yìí ṣe pàtàkì gan-an ni, níwọ̀n bó ti jẹ́ pé nípasẹ̀ Jésù nìkan ni ìgbàlà fi lè ṣeé ṣe.—Jòh. 17:3; Ìṣe 4:12.

      2 ‘Ọ̀nà, Òtítọ́, àti Ìyè’: Jésù sọ pé: “Èmi ni ọ̀nà àti òtítọ́ àti ìyè. Kò sí ẹni tí ń wá sọ́dọ̀ Baba bí kò ṣe nípasẹ̀ mi.” (Jòh. 14:6) Àyàfi nípasẹ̀ Jésù nìkan, ẹni tí í ṣe “ọ̀nà,” la fi lè tọ Ọlọ́run lọ nínú àdúrà ká sì ní àjọṣe tó ní ìtẹ́wọ́gbà pẹ̀lú Rẹ̀. (Jòh. 15:16) Jésù ni “òtítọ́” nítorí pé òun ni àwọn àsọtẹ́lẹ̀ àti òjìji àwọn nǹkan tí ń bọ̀ tó wà nínú Ìwé Mímọ́ Lédè Hébérù nímùúṣẹ sí lára. (Jòh. 1:17; Kól. 2:16, 17) Ní ti gidi, lájorí ète tí àsọtẹ́lẹ̀ tòótọ́ wà fún ni láti túbọ̀ tànmọ́lẹ̀ sí ipa pàtàkì tí Jésù kó nínú mímú ète Ọlọ́run ṣẹ. (Ìṣí. 19:10) Síwájú sí i, Jésù ni “ìyè.” Láti rí ẹ̀bùn ìyè àìnípẹ̀kun gbà, gbogbo wa gbọ́dọ̀ lo ìgbàgbọ́ nínú ẹbọ ìràpadà rẹ̀.—Jòh. 3:16, 36; Héb. 2:9.

      3 Olórí àti Ọba Tí Ń Jọba: Àwọn èèyàn tún gbọ́dọ̀ mọ bí ọlá àṣẹ àti agbára ńlá tí Jèhófà fi síkàáwọ́ Ọmọ rẹ̀ ṣe gbòòrò tó. A ti fi Jésù jẹ Ọba Ìjọba Ọlọ́run—‘òun sì ni ìgbọràn àwọn ènìyàn jẹ́ tirẹ̀.’ (Jẹ́n. 49:10) Láfikún sí i, Jèhófà ti yàn án sípò gẹ́gẹ́ bí Orí ìjọ. (Éfé. 1:22, 23) Ó ṣe pàtàkì pé ká ran àwọn akẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì wa lọ́wọ́ láti lóye ọ̀nà tí Jésù ń gbà darí ìjọ àti bó ṣe ń lo “ẹrú olóòótọ́ àti olóye” náà láti pèsè “oúnjẹ [tẹ̀mí] ní àkókò tí ó bẹ́tọ̀ọ́ mu.”—Mát. 24:45-47.

      4 Àlùfáà Àgbà Tó Láàánú: Nítorí pé Jésù ti fojú winá àdánwò tó sì ti jìyà gẹ́gẹ́ bí ẹ̀dá èèyàn, “ó lè wá ṣe àrànṣe fún àwọn tí a ń dán wò.” (Héb. 2:17, 18) Ẹ ò rí i pé ohun tó ń mọ́kàn yọ̀ ló jẹ́ fún àwọn ẹ̀dá èèyàn aláìpé láti mọ̀ pé Jésù ń bá wọn kẹ́dùn nítorí àwọn àìlera wọn àti pé ó ń fi tàánútàánú bẹ̀bẹ̀ fún wọn! (Róòmù 8:34) Lórí ìpìlẹ̀ ẹbọ ìràpadà Jésù àtàwọn ohun tó ń ṣe gẹ́gẹ́ bí Àlùfáà Àgbà, a lè tọ Jèhófà lọ “pẹ̀lú òmìnira ọ̀rọ̀ sísọ,” kó lè ṣeé ṣe fún wa láti rí “ìrànlọ́wọ́ [gbà] ní àkókò tí ó tọ́.”—Héb. 4:15, 16.

      5 A gbàdúrà pé kí àwọn ìsapá wa láti sọ òtítọ́ nípa Jésù fún àwọn ẹlòmíràn sún wọn láti ṣègbọràn sí i àti láti sìn ín pa pọ̀ pẹ̀lú wa.—Jòh. 14:15, 21.

  • Ṣètìlẹ́yìn fún Alábòójútó Ìkẹ́kọ̀ọ́ Ìwé Ìjọ Rẹ
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba—2002 | November
    • Ṣètìlẹ́yìn fún Alábòójútó Ìkẹ́kọ̀ọ́ Ìwé Ìjọ Rẹ

      1 Gbogbo wa lẹ́nì kọ̀ọ̀kan ló ń jàǹfààní tó pọ̀ látinú Ìkẹ́kọ̀ọ́ Ìwé Ìjọ. Lóṣù tó kọjá, a jíròrò ọ̀nà tí alábòójútó Ìkẹ́kọ̀ọ́ Ìwé Ìjọ ń gbà bójú tó iṣẹ́ tá a yàn fún un. Àmọ́ ìtìlẹ́yìn wo la lè ṣe fún un ká sì tipa bẹ́ẹ̀ ṣe ara wa àtàwọn mìíràn láǹfààní?

      2 Máa Pésẹ̀ Lọ́sọ̀ọ̀sẹ̀: Níwọ̀n bí àwùjọ Ìkẹ́kọ̀ọ́ Ìwé Ìjọ ti máa ń mọ níwọ̀nba, ó ṣe pàtàkì kó o máa wà níbẹ̀. Fi sọ́kàn pé wàá máa pésẹ̀ lọ́sọ̀ọ̀sẹ̀. Ìtìlẹ́yìn mìíràn tó o tún lè ṣe ni pé kí o máa tètè dé, nítorí ìyẹn á mú kó ṣeé ṣe fún alábòójútó ìkẹ́kọ̀ọ́ láti bẹ̀rẹ̀ ìpàdé náà lọ́nà tó wà létòlétò.—1 Kọ́r. 14:40.

      3 Àwọn Ìdáhùn Tó Ń Gbéni Ró: Ọ̀nà mìíràn tó o tún lè gbà ṣètìlẹ́yìn ni nípa mímúra sílẹ̀ dáadáa àti nípa dídáhùn lọ́nà tó ń gbéni ró. Àwọn ìdáhùn tó dá lórí kókó kan ṣoṣo ló sábà máa ń dára jù lọ, èyí sì tún máa ń fún àwọn mìíràn níṣìírí láti dáhùn. Má ṣe máa gbìyànjú láti dáhùn gbogbo kókó tó wà nínú ìpínrọ̀ kan. Bí kókó kan nínú ìkẹ́kọ̀ọ́ náà bá wọ̀ ọ́ lọ́kàn gan-an, ṣàjọpín ohun tó wà lọ́kàn rẹ náà pẹ̀lú àwọn ará nínú ìdáhùn rẹ láti mú kí ìjíròrò náà túbọ̀ lárinrin.—1 Pét. 4:10.

      4 Bó o bá ní àǹfààní láti ka àwọn ìpínrọ̀ fún àǹfààní àwùjọ náà, sapá láti rí i pé ò ń ṣe iṣẹ́ tá a yàn fún ọ yìí dáadáa. Kíkàwé lọ́nà tó dára á mú kí ìpàdé náà túbọ̀ gbádùn mọ́ni.—1 Tím. 4:13.

      5 Ìjẹ́rìí Àjẹ́pọ̀: A máa ń ṣe ìpàdé fún iṣẹ́ ìsìn pápá ní ọ̀pọ̀ ibi tá a ti ń ṣe Ìkẹ́kọ̀ọ́ Ìwé Ìjọ, ìtìlẹ́yìn tí ò ń ṣe fún àwọn ètò wọ̀nyí yóò ran alábòójútó náà lọ́wọ́ bó ti ń mú ipò iwájú nínú iṣẹ́ wíwàásù ìhìn rere náà. Máa wo àwọn ìṣètò wọ̀nyí gẹ́gẹ́ bí àǹfààní tó o ní láti túbọ̀ sún mọ́ àwọn arákùnrin rẹ àti láti fún wọn ní ìṣírí.

      6 Ìròyìn Iṣẹ́ Ìsìn Pápá: Fífi ìròyìn iṣẹ́ ìsìn pápá rẹ sílẹ̀ ní gbàrà tí oṣù bá ti parí tún jẹ́ ọ̀nà mìíràn láti ṣètìlẹ́yìn fún alábòójútó Ìkẹ́kọ̀ọ́ Ìwé Ìjọ. O lè fi ìròyìn rẹ lé òun fúnra rẹ̀ lọ́wọ́ tàbí kó o fi sínú àpótí tó wà fún ìròyìn iṣẹ́ ìsìn pápá ní Gbọ̀ngàn Ìjọba. Akọ̀wé lè lo àpótí yìí láti fi ṣàkójọ ìròyìn iṣẹ́ ìsìn pápá tí àwọn alábòójútó Ìkẹ́kọ̀ọ́ Ìwé Ìjọ ti gbà jọ.

      7 Ìfọwọ́sowọ́pọ̀ rẹ pẹ̀lú alábòójútó Ìkẹ́kọ̀ọ́ Ìwé Ìjọ rẹ kò ṣàì lérè nínú o. Ju gbogbo rẹ̀ lọ, jẹ́ kó dá ọ lójú pé Jèhófà yóò ‘wà pẹ̀lú ẹ̀mí tí o fi hàn.’—Fílí. 4:23.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́