ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Ìfaradà Lérè
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba—2004 | August
    • Ìfaradà Lérè

      1 “Nípasẹ̀ ìfaradà níhà ọ̀dọ̀ yín ni ẹ ó fi jèrè ọkàn yín.” (Lúùkù 21:19) Gbólóhùn yìí, tá a mú látinú àsọtẹ́lẹ̀ Jésù nípa “ìparí ètò àwọn nǹkan,” jẹ́ kó yé wa kedere pé bá a ṣe ń sapá láti jẹ́ oníwà títọ́, a gbọ́dọ̀ múra tán láti fojú winá ọ̀pọ̀ àdánwò. Ṣùgbọ́n tí olúkúlùkù wa bá gbára lé okun Jèhófà, a ó lè “fara dà á dé òpin,” a ó sì rí ‘ìgbàlà.’—Mát. 24:3, 13; Fílí. 4:13.

      2 Inúnibíni, àìsàn, ìṣòro owó àti ìrora ọkàn lè mú kí nǹkan máa nira fún wa gan-an lójoojúmọ́. Àmọ́, a ò gbọ́dọ̀ gbàgbé pé Sátánì ò fìgbà kan juwọ́ sílẹ̀ nínú ìsapá rẹ̀ láti jin ìdúróṣinṣin wa sí Jèhófà lẹ́sẹ̀. Bá a bá jẹ́ olóòótọ́ sí Baba wa ọ̀run nínú gbogbo ohun tá à ń ṣe lójoojúmọ́, à ń jẹ́ kó túbọ̀ hàn gbangba pé onírọ́ ni Èṣù tí ń ṣáátá Ọlọ́run, tó ń sọ pé a ò ní jẹ́ oníwà títọ́. Ó mà ń fini lọ́kàn balẹ̀ o láti mọ̀ pé Ọlọ́run ń rí “omijé” wa nígbà tá a bá wà nínú ìṣòro! Omijé wa yìí ṣeyebíye lójú Jèhófà, ìwà títọ́ wa sì ń múnú rẹ̀ dùn!—Sm. 56:8; Òwe 27:11.

      3 Àdánwò Ń Yọ́ Wa Mọ́: Ìpọ́njú lè jẹ́ ká mọ̀ pé ìgbàgbọ́ wa ò lágbára mọ́ tàbí pé a ní àléébù kan, irú bí ìgbéraga tàbí àìnísùúrù. Dípò ká máa gbìyànjú láti yẹra fún àdánwò tàbí láti fòpin sí i nípa ṣíṣe àwọn ohun tí kò bá Ìwé Mímọ́ mu, a ní láti fiyè sí ìmọ̀ràn Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tó sọ pé ká “jẹ́ kí ìfaradà ṣe iṣẹ́ rẹ̀ pé pérépéré.” Kí nìdí? Nítorí pé tá a bá fi ìṣòtítọ́ fara da àdánwò, a ó lè “pé pérépéré, [a ó sì] yè kooro ní gbogbo ọ̀nà.” (Ják. 1:2-4) Ìfaradà lè jẹ́ ká ní àwọn ànímọ́ tó ṣeyebíye, irú bí ìfòyebánilò, ẹ̀mí ìfọ̀rọ̀rora-ẹni-wò àti àánú.—Róòmù 12:15.

      4 Ìjójúlówó Ìgbàgbọ́ Wa Ni A Óò Dán Wò: Nígbà tá a bá fara da àdánwò, ìgbàgbọ́ wa yóò di èyí tá a ti dán ìjójúlówó rẹ̀ wò, ìyẹn sì níye lórí gidigidi lójú Ọlọ́run. (1 Pét. 1:6, 7) Irú ìgbàgbọ́ bẹ́ẹ̀ yóò mú ká dúró gbọn-in nígbà ìṣòro lọ́jọ́ iwájú. Síwájú sí i, a ó mọ̀ pé Ọlọ́run tẹ́wọ́ gbà wá, èyí á sì jẹ́ kí ìrètí wa lágbára, kó sì túbọ̀ dá wa lójú sí i.—Róòmù 5:3-5.

      5 Jákọ́bù orí kìíní ẹsẹ̀ kejìlá sọ èrè gíga jù lọ tá a lè rí jẹ nítorí ìfaradà, ó ní: “Aláyọ̀ ni ẹni tí ń bá a nìṣó ní fífarada àdánwò, nítorí nígbà tí ó bá di ẹni tí a tẹ́wọ́ gbà, yóò gba adé ìyè.” Nítorí náà, ká má ṣe jáwọ́ láé nínú ìfọkànsìn wa sí Jèhófà, ká lọ fọkàn balẹ̀ pé yóò rọ̀jò ìbùkún sórí “àwọn tí ń bá a lọ láti máa nífẹ̀ẹ́ rẹ̀.”

  • Apá Kejì: Bí A Ṣe Lè Darí Àwọn Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Tí Yóò Máa Tẹ̀ Síwájú
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba—2004 | August
    • Apá Kejì: Bí A Ṣe Lè Darí Àwọn Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Tí Yóò Máa Tẹ̀ Síwájú

      Mímúrasílẹ̀ Láti Darí Ìkẹ́kọ̀ọ́

      1 Bá a bá fẹ́ kọ́ni lẹ́kọ̀ọ́ lọ́nà tó múná dóko nígbà tá a bá ń darí ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì, a ò kàn ní sọ̀rọ̀ lórí ohun tó wà nínú ìwé ìkẹ́kọ̀ọ́ tàbí ká kàn ka àwọn ẹsẹ Ìwé Mímọ́ tá a tọ́ka sí níbẹ̀ nìkan. Ó yẹ ká ṣàlàyé ọ̀rọ̀ ibẹ̀ lọ́nà táá fi wọ akẹ́kọ̀ọ́ lọ́kàn. Èyí gba pé ká múra sílẹ̀ dáadáa, ká sì máa ronú nípa akẹ́kọ̀ọ́ náà bá a ṣe ń múra sílẹ̀.—Òwe 15:28.

      2 Bí A Ṣe Lè Múra Sílẹ̀: Lákọ̀ọ́kọ́ ná, gbàdúrà sí Jèhófà nípa akẹ́kọ̀ọ́ náà àtàwọn ohun tó lè mú kó tẹ̀ síwájú nípa tẹ̀mí. Bẹ Jèhófà pé kó jẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ lè wọ̀ ọ́ lọ́kàn. (Kól. 1:9, 10) Láti lè lóye kókó pàtàkì ibi tẹ́ ẹ fẹ́ kẹ́kọ̀ọ́ yékéyéké, kọ́kọ́ ronú lórí àkọlé ẹ̀kọ́ náà, àwọn ìsọ̀rí inú rẹ̀ àti àwòrán èyíkéyìí tó bá wà níbẹ̀. Bi ara rẹ pé, ‘Ẹ̀kọ́ wo ni ibi tí mo kà yìí ń kọ́ni?’ Èyí á jẹ́ kó o lè tẹnu mọ́ àwọn kókó ọ̀rọ̀ ibẹ̀ nígbà tó o bá ń darí ìkẹ́kọ̀ọ́ náà.

      3 Fara balẹ̀ ṣàyẹ̀wò àpilẹ̀kọ náà láti ìpínrọ̀ dé ìpínrọ̀. Rí i pé o mọ ìdáhùn sí àwọn ìbéèrè tó wà fún ìpínrọ̀ kọ̀ọ̀kan, kó o sì sàmì sí àwọn ọ̀rọ̀ tàbí àpólà ọ̀rọ̀ tó jẹ́ kókó pàtàkì nìkan. Ronú nípa bí àwọn ẹsẹ Ìwé Mímọ́ tá a tọ́ka sí ṣe bá kókó pàtàkì inú ìpínrọ̀ kọ̀ọ̀kan mu, kó o sì wo èyí tó o máa kà lára àwọn ẹsẹ Ìwé Mímọ́ wọ̀nyí nígbà tẹ́ ẹ bá ń ṣe ìkẹ́kọ̀ọ́. Ó dára tó o bá lè kọ àwọn kókó pàtàkì inú ẹsẹ Ìwé Mímọ́ sétí ìwé ìkẹ́kọ̀ọ́ rẹ. Ó yẹ kí akẹ́kọ̀ọ́ rí i ní kedere pé inú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ni ohun tí òun ń kọ́ ti wá.—1 Tẹs. 2:13.

      4 Mú Kí Ìkẹ́kọ̀ọ́ Náà Bá Ipò Akẹ́kọ̀ọ́ Mu: Lẹ́yìn náà, bó o ṣe ń ka àpilẹ̀kọ náà, máa kíyè sí àwọn ohun tó lè mú kí akẹ́kọ̀ọ́ náà tẹ̀ síwájú nípa tẹ̀mí. Gbìyànjú láti ronú àwọn ìbéèrè tó lè béèrè àtàwọn kókó tó lè ṣòro fún un láti lóye tàbí láti gbà. Bi ara rẹ pé: ‘Kí ló yẹ kó mọ̀ tàbí tó yẹ kó ṣiṣẹ́ lé lórí kó bàa lè tẹ̀ síwájú nípa tẹ̀mí? Báwo ni mo ṣe lè mú kí ọ̀rọ̀ mi wọ̀ ọ́ lọ́kàn?’ Rí i pé o fi àwọn nǹkan wọ̀nyí sọ́kàn tẹ́ ẹ bá ń ṣèkẹ́kọ̀ọ́. Nígbà míì, o lè rí i pé ó yẹ kó o wá àkàwé kan tàbí àlàyé kan sílẹ̀, tàbí àwọn ìbéèrè kan tó o máa lò nígbà ìkẹ́kọ̀ọ́ náà, láti mú kí akẹ́kọ̀ọ́ rẹ lè lóye ìtumọ̀ kókó kan tàbí ẹsẹ Ìwé Mímọ́ kan. (Neh. 8:8) Àmọ́ o, má ṣe máa mú àfikún àlàyé tí kò fi bẹ́ẹ̀ pọn dandan wọnú ẹ̀kọ́ náà. Ṣíṣe àtúnyẹ̀wò ṣókí lẹ́yìn ìkẹ́kọ̀ọ́ yóò jẹ́ kó lè rántí àwọn kókó inú ẹ̀kọ́ náà.

      5 Inú wa máa ń dùn gan-an táwọn ẹni tuntun bá ń so èso òdodo, èyí tó máa fi ìyìn fún Jèhófà! (Fílí. 1:11) Kó o lè ràn wọ́n lọ́wọ́ láti ṣe bẹ́ẹ̀, máa múra sílẹ̀ dáadáa ní gbogbo ìgbà tó o bá fẹ́ darí ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́