-
Jèhófà ‘Ń Fi Àwọn Ọ̀rọ̀ Ìgbàgbọ́ Bọ́ Wa’Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba—2005 | January
-
-
Jèhófà ‘Ń Fi Àwọn Ọ̀rọ̀ Ìgbàgbọ́ Bọ́ Wa’
1 Ó gba ìsapá gidi kéèyàn tó lè jẹ́ olùbẹ̀rù Ọlọ́run kó sì máa bá a lọ bẹ́ẹ̀ nígbèésí ayé. (1 Tím. 4:7-10) Bí a bá gbójú lé agbára wa, kò ní pẹ́ tó fi máa rẹ̀ wá tá a ó sì ṣubú. (Aísá. 40:29-31) Ọ̀nà kan tá a fi lè gba okun látọ̀dọ̀ Jèhófà ni pé ká jẹ́ ẹni “tí a fi àwọn ọ̀rọ̀ ìgbàgbọ́ bọ́.”—1 Tím. 4:6.
2 Oúnjẹ Tẹ̀mí Tó Ń Fúnni Lókun: Jèhófà ń tipasẹ̀ Ọ̀rọ̀ rẹ̀ àti “ẹrú olóòótọ́ àti olóye” pèsè oúnjẹ tẹ̀mí tó ń fúnni lókun. (Mát. 24:45) Ǹjẹ́ à ń ṣe ohun tó yẹ ká ṣe káwọn oúnjẹ yẹn lè ṣe wá lóore? Ṣé a kì í jẹ́ kí ọjọ́ kan lọ láìjẹ́ pé a ka Bíbélì? Ǹjẹ́ a ní àkókò kan tá a yà sọ́tọ̀ láti máa fi dá kẹ́kọ̀ọ́ àti láti máa fi ṣàṣàrò? (Sm. 1:2, 3) Irú àwọn oúnjẹ tẹ̀mí tó ń fúnni lókun yìí máa ń fún wa lókun, kì í sì í jẹ́ kí ayé Sátánì rí wa gbéṣe. (1 Jòh. 5:19) Tí a bá ń fọkàn wa ro àwọn ohun tó tọ́ tá a sì ń hù ú níwà nígbà gbogbo, Jèhófà á dúró tì wá.—Fílí. 4:8, 9.
3 Ìpàdé ìjọ tún jẹ́ ọ̀nà mìíràn tí Jèhófà gbà ń fún wa lókun. (Héb. 10:24, 25) Ìtọ́ni tẹ̀mí tá a ń rí gbà láwọn ìpàdé wọ̀nyí àti ìbákẹ́gbẹ́pọ̀ tó gbámúṣé tá a ń ní níbẹ̀ ń jẹ́ ká lè dúró ṣinṣin lásìkò ìṣòro. (1 Pét. 5:9, 10) Ọ̀dọ́ kan tó jẹ́ Kristẹni sọ pé: “Kò sọ́jọ́ tí mo lọ síléèwé tí kì í ṣe pé ìrẹ̀wẹ̀sì ni màá bá bọ̀. Ṣùgbọ́n àwọn ìpàdé ìjọ wa yàtọ̀, ńṣe ló dà bí ibòji nínú oòrùn ọ̀sán ganrínganrín, nítorí ó ń jẹ́ kí n ní ìbàlẹ̀ ọkàn láti lè kojú wàhálà iléèwé lọ́jọ́ kejì.” Ẹ ò rí i pé ìbùkún ńlá gbáà là ń rí gbà bá a ti ń sapá láti wà ní gbogbo ìpàdé!
4 Máa Polongo Òtítọ́: Iṣẹ́ ìwàásù dà bí oúnjẹ lójú Jésù, nítorí pé ó máa ń fún un lókun. (Jòh. 4:32-34) Lọ́nà kan náà, ara wa máa ń yá gágá nígbà tá a bá ń sọ àwọn àgbàyanu ìlérí Ọlọ́run fáwọn ẹlòmíràn. Dídí tọ́wọ́ wa ń dí nínú iṣẹ́ òjíṣẹ́ tún ń jẹ́ ká lè túbọ̀ pọkàn pọ̀ sórí Ìjọba Ọlọ́run àti àwọn ìbùkún tó máa mú wá fún wa láìpẹ́. Ká sòótọ́, ó máa ń sọ agbára wa dọ̀tun.—Mát. 11:28-30.
5 Àǹfààní ńlá la ní o pé à ń jẹ oúnjẹ tẹ̀mí tó ń fúnni lókun tí Jèhófà ń pèsè fáwọn èèyàn rẹ̀ lónìí! Nítorí náà, títí láé ni kẹ́ ẹ jẹ́ ká máa fi ìdùnnú polongo òtítọ́ láti fi yìn ín.—Aísá. 65:13, 14.
-
-
Apá Karùn-ún: Bí A Ṣe Lè Darí Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Tí Yóò Máa Tẹ̀ SíwájúIṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba—2005 | January
-
-
Apá Karùn-ún: Bí A Ṣe Lè Darí Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Tí Yóò Máa Tẹ̀ Síwájú
Bí A Ó Ṣe Mọ Ìwọ̀n Tí Òye Akẹ́kọ̀ọ́ Máa Gbé
1 Jésù máa ń kíyè sí bí agbára òye àwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ ṣe mọ nígbà tó bá ń kọ́ wọn, nípa bẹ́ẹ̀, kì í sọ̀rọ̀ ju “bí òye wọn ti mọ.” (Máàkù 4:33, Ìròyìn Ayọ̀; Jòh. 16:12) Bẹ́ẹ̀ náà ló ṣe yẹ kí àwọn olùkọ́ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run lóde òní mọ ìwọ̀nba kókó tí wọ́n máa kọ́ àwọn akẹ́kọ̀ọ́ wọn nígbà ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì. Bí òye olùkọ́ àti ti akẹ́kọ̀ọ́ bá ṣe pọ̀ tó àti ipò àwọn méjèèjì ni wọn ó fi mọ ohun tí wọ́n máa kọ́ ní ìjókòó ẹ̀ẹ̀kan.
2 Kọ́ Ọ Lọ́nà Tí Yóò Fi Ní Ìgbàgbọ́ Tó Lágbára: Àwọn akẹ́kọ̀ọ́ kan wà tó jẹ́ pé kíá lòye ohun tí wọ́n ń kọ́ máa ń yé wọn, bẹ́ẹ̀ sì rèé, ńṣe la máa tẹ̀ ẹ́ jẹ́jẹ́ fáwọn akẹ́kọ̀ọ́ míì. Nítorí náà, kò yẹ kó jẹ́ pé torí àtilè ka ojú ìwé tó pọ̀ la ò ṣe ní bìkítà nípa bí akẹ́kọ̀ọ́ ṣe máa ní òye tó kún rẹ́rẹ́. Ó ṣe tán orí ìpìlẹ̀ tó lágbára, ìyẹn Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, ló yẹ kí gbogbo akẹ́kọ̀ọ́ gbé ìgbàgbọ́ wọn kà.—Òwe 4:7; Róòmù 12:2.
3 Bó o ṣe ń bá akẹ́kọ̀ọ́ rẹ ṣèkẹ́kọ̀ọ́ lọ́sọ̀ọ̀sẹ̀, máa lo àkókò tó pọ̀ tó kí akẹ́kọ̀ọ́ náà lè ní òye Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run kó sì tẹ́wọ́ gbà á. Tó o bá ń kánjú jù, akẹ́kọ̀ọ́ náà ò ní lóye bí òtítọ́ tó ń kọ́ ti ṣe pàtàkì tó. Fara balẹ̀ ṣàlàyé àwọn kókó pàtàkì tó wà nínú ẹ̀kọ́ náà àtàwọn ẹsẹ Ìwé Mímọ́ tó tì wọ́n lẹ́yìn.—2 Tím. 3:16, 17.
4 Má Ṣe Yà Bàrá: Bí kò ṣe yẹ ká kánjú tá a bá ń bá akẹ́kọ̀ọ́ wa ṣèkẹ́kọ̀ọ́, bẹ́ẹ̀ náà ni kò ṣe yẹ ká máa yà sígbó yà síjù. Bó bá jẹ́ pé ọ̀rọ̀ tí kò sí lára ohun tẹ́ ẹ̀ ń kọ́ ló ń gbé akẹ́kọ̀ọ́ náà níkùn, ẹ lè jẹ́ kó dìgbà tẹ́ ẹ bá parí ìkẹ́kọ̀ọ́ kẹ́ ẹ tó gbé e yẹ̀ wò.—Oníw. 3:1.
5 Àmọ́ ṣá o, tí àwa náà ò bá ṣọ́ra àlàyé wa lè pọ̀ jù nígbà ìkẹ́kọ̀ọ́ náà nítorí bí ìmọ̀ òtítọ́ tá a ní ṣe rí lára wa. (Sm. 145:6, 7) Lóòótọ́ o, àwọn àyàbá tàbí ìrírí kọ̀ọ̀kan lè jẹ́ kí ẹ̀kọ́ tètè yéni àmọ́ kò yẹ ká jẹ́ kí ìwọ̀nyí pọ̀ jù tàbí kó gùn jù débi pé akẹ́kọ̀ọ́ ò ní lè ní ìmọ̀ pípéye nípa àwọn ẹ̀kọ́ pàtàkì inú Bíbélì.
6 Tí a bá ń kọ́ àwọn akẹ́kọ̀ọ́ wa ní ìwọ̀nba ohun tí òye wọn lè gbé nígbà ìkẹ́kọ̀ọ́ kọ̀ọ̀kan, a ó lè ràn wọ́n lọ́wọ́ kí wọ́n lè máa “rìn nínú ìmọ́lẹ̀ Jèhófà.”—Aísá. 2:5.
-