-
Wíwàásù Ń Mú Ká Lè Lo ÌfaradàIṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba—2005 | June
-
-
Wíwàásù Ń Mú Ká Lè Lo Ìfaradà
1 Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run gbà wá níyànjú pé ká “fi ìfaradà sá eré ìje tí a gbé ka iwájú wa.” (Héb. 12:1) Bí sárésáré kan ṣe gbọ́dọ̀ lo ìfaradà kó bàa lè borí nínú ìdíje làwa náà ṣe gbọ́dọ̀ lo ìfaradà ká tó lè gba ẹ̀bùn ìyè àìnípẹ̀kun. (Héb. 10:36) Ọ̀nà wo ni iṣẹ́ òjíṣẹ́ wa gẹ́gẹ́ bíi Kristẹni fi lè ràn wá lọ́wọ́ láti fi ìṣòtítọ́ fara dà á títí dópin?—Mát. 24:13.
2 Ó Ń Fún Wa Lókun Nípa Tẹ̀mí: Bá a ṣe máa ń pòkìkí àwọn ìlérí àgbàyanu tó wà nínú Bíbélì nípa ayé tuntun òdodo máa ń jẹ́ kí ìrètí tá a ní túbọ̀ dá wa lójú dáadáa. (1 Tẹs. 5:8) Tá a bá ń lọ sóde ẹ̀rí déédéé, á ṣeé ṣe fún wa láti jẹ́ káwọn èèyàn mọ̀ nípa àwọn ẹ̀kọ́ tá a ti kọ́ látinú Bíbélì. A máa ń láǹfààní láti gbèjà ìgbàgbọ́ wa, a sì tún máa ń tipa bẹ́ẹ̀ lókun sí i nípa tẹ̀mí.
3 Ká tó lè kọ́ àwọn èèyàn débi tóhun tá a kọ́ wọn á fi yé wọn, òye òtítọ́ inú Bíbélì gbọ́dọ̀ yé àwa alára yékéyéké. A gbọ́dọ̀ ṣe ìwádìí jinlẹ̀ ká sì ṣàṣàrò lórí ohun tá a fẹ́ sọ. Bá a bá sapá tọkàntọkàn, a ó lè ní ìmọ̀ tó jinlẹ̀ dáadáa, a ó lè túbọ̀ máa lo ìgbàgbọ́, ara á sì tù wá nípa tẹ̀mí. (Òwe 2:3-5) Nítorí náà, bá a bá ṣe ń ran àwọn èèyàn lọ́wọ́ tó làwa náà á ṣe máa lókun nípa tẹ̀mí tó.—1 Tím. 4:15, 16.
4 Fífi ìtara lọ́wọ́ sí iṣẹ́ òjíṣẹ́ jẹ́ ọ̀kan pàtàkì lára “ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ìhámọ́ra ogun láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run,” èyí tá a nílò ká bàa lè dúró gbọn-in gbọn-in lòdì sí Èṣù àtàwọn ẹ̀mí Èṣù rẹ̀. (Éfé. 6:10-13, 15) Bí ọwọ́ wa ṣe máa ń dí lẹ́nu iṣẹ́ òjíṣẹ́ wa máa ń jẹ́ ká lè pọkàn pọ̀ sórí àwọn ohun tó lè gbé wa ró, ká sì yàgò fún dídi ẹni tí ayé Sátánì sọ dìdàkudà. (Kól. 3:2) Bá a ṣe ń kọ́ àwọn èèyàn nípa àwọn ọ̀nà Jèhófà là ń rán ara wa létí bó ṣe yẹ káwa náà máa hùwà mímọ́.—1 Pét. 2:12.
5 Ọlọ́run Ń Fún Wa Lókun: Lákòótán, iṣẹ́ ajíhìnrere tá à ń ṣe máa ń kọ́ wa láti gbọ́kàn lé Jèhófà. (2 Kọ́r. 4:1, 7) Ìbùkún yẹn mà ga o! Kíkọ́ tá à ń kọ́ láti ní irú ìgbọ́kànlé bẹ́ẹ̀ ń mú wa gbára dì, kì í ṣe láti lè ṣe iṣẹ́ òjíṣẹ́ wa láṣeyọrí nìkan ni, ṣùgbọ́n ká tún lè rára gba ohun yòówù tó lè dé bá wa nígbèésí ayé sí. (Fílí. 4:11-13) Ní tòótọ́, ká tó lè ní ìfaradà, ó ṣe pàtàkì pé ká kọ́ láti máa gbára lé Jèhófà pátápátá. (Sm. 55:22) Ọ̀pọ̀ ọ̀nà ni iṣẹ́ ìwàásù gbà ń ràn wá lọ́wọ́ láti lo ìfaradà.
-
-
Apá Kẹwàá: Bí A Ṣe Lè Darí Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Tí Yóò Máa Tẹ̀ SíwájúIṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba—2005 | June
-
-
Apá Kẹwàá: Bí A Ṣe Lè Darí Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Tí Yóò Máa Tẹ̀ Síwájú
Bá A Ṣe Lè Kọ́ Àwọn Akẹ́kọ̀ọ́ Ní Iṣẹ́ Ìwàásù Ilé-dé-Ilé
1 Bí àwọn alàgbà bá pinnu pé akẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì kan ti yẹ lẹ́ni tó lè di akéde tí kò tíì ṣèrìbọmi, akẹ́kọ̀ọ́ náà lè bẹ̀rẹ̀ sí bá àwọn ará lọ sóde ẹ̀rí. (Wo ìwé A Ṣètò Wa Láti Ṣe Ìfẹ́ Jèhófà, ojú ìwé 79 sí 81.) Báwo la ṣe lè ran akẹ́kọ̀ọ́ náà lọ́wọ́ kó lè dẹni tó ń wàásù láti ilé dé ilé?
2 Ẹ Jọ Máa Múra Sílẹ̀: Kò sóhun tá a lè fi rọ́pò ìmúrasílẹ̀ tó jíire. Kọ́ akẹ́kọ̀ọ́ náà bó ṣe lè rí àwọn ọ̀nà ìgbọ́rọ̀kalẹ̀ tá a dábàá nínú Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa àti nínú ìwé Bí A Ṣe Lè Bẹ̀rẹ̀ Awọn Ìjíròrò Bibeli Kí A Sì Máa Báa Nìṣó, kó o sì ràn án lọ́wọ́ láti yan ọ̀nà ìgbọ́rọ̀kalẹ̀ tó rọrùn tó sì bá ìpínlẹ̀ ìwàásù yín mu. Látìgbà tó o bá ti kọ́kọ́ mú un lọ sóde ẹ̀rí ni kó o ti gbà á nímọ̀ràn pé kó máa lo Bíbélì tó bá ń wàásù.—2 Tím. 4:2.
3 Àǹfààní tó pọ̀ ló wà nínú kí akéde tuntun máa ṣe ìdánrawò ṣáájú. Nígbà tí akéde náà bá ń ṣe ìdánrawò, kọ́ ọ bá a ṣe máa fọgbọ́n fèsì ọ̀rọ̀ táwọn tó wà ní ìpínlẹ̀ ìwàásù yín sábà máa ń sọ. (Kól. 4:6) Fi í lọ́kàn balẹ̀ pé kì í ṣe dandan ni kí àwa tá à ń wàásù mọ ìdáhùn sí gbogbo ìbéèrè táwọn èèyàn bá bi wá. Ó sì tún máa ń dáa tá a bá sọ fún wọn pé a ó kọ́kọ́ lọ ṣèwádìí nílé tá a ó sì padà wá láti jíròrò ọ̀rọ̀ náà síwájú sí i.—Òwe 15:28.
4 Ẹ Jọ Máa Wàásù: Nígbà àkọ́kọ́ tí akẹ́kọ̀ọ́ náà bá tẹ̀lé ọ lọ sẹ́nu iṣẹ́ ìwàásù ilé-dé-ilé, ṣe ni kó o jẹ́ kó máa wo bó o ṣe ń lo àwọn ọ̀nà ìgbọ́rọ̀kalẹ̀ tẹ ẹ́ ti jọ múra sílẹ̀. Lẹ́yìn náà, o lè wá ní kó dá sí i. Nígbà míì, ó lè jẹ́ pé ohun tó máa dáa jù ni pé kó o jẹ́ kí akéde tuntun náà ka àwọn ẹsẹ Ìwé Mímọ́ tó wà níbẹ̀, kó sì ṣàlàyé rẹ̀. Fi ànímọ́ àti ìṣesí akẹ́kọ̀ọ́ náà sọ́kàn o. (Fílí. 4:5) Má gbàgbé láti máa gbóríyìn fún un bó o ṣe ń kọ́ ọ ní ṣísẹ̀-n-tẹ̀lé kóun náà lè di ẹni tó mọ iṣẹ́ ìwàásù ṣe dáadáa.
5 Ó ṣe pàtàkì pé kó o ran akéde tuntun lọ́wọ́ kóun náà lè mọ bó ṣe máa ṣètò táá fi lè máa jáde fún iṣẹ́ ìwàásù déédéé láìpa ọ̀sẹ̀ kankan jẹ, bó bá ṣeé ṣe. (Fílí. 3:16) Ẹ ṣètò pàtó kẹ́ ẹ lè jọ máa ṣiṣẹ́ lóde ẹ̀rí, kó o sì fún un níṣìírí pé kó máa bá àwọn mìíràn tó nítara ṣiṣẹ́. Àpẹẹrẹ àwọn tó ń bá jáde òde ẹ̀rí àti bí wọ́n ṣe jọ ń kẹ́gbẹ́ á jẹ́ kóun náà lè kúnjú ìwọ̀n, inú rẹ̀ á sì lè máa dùn bó ṣe ń wàásù láti ilé dé ilé.
-