-
Èé Ṣe Tó Fi Yẹ Kó o Ṣe Batisí?Ilé Ìṣọ́—2002 | April 1
-
-
14. Kí ni ìyàsímímọ́ àwọn ọmọlẹ́yìn Jésù túmọ̀ sí?
14 Ìyàsímímọ́ àtọkànwá fún Ọlọ́run tún gbọ́dọ̀ wáyé kí àwọn ọmọlẹ́yìn Jésù tó ṣe batisí. Ìyàsímímọ́ túmọ̀ sí yíyanisọ́tọ̀ fún ète mímọ́ kan. Ìgbésẹ̀ yìí ṣe pàtàkì gan-an débi pé a gbọ́dọ̀ sọ fún Jèhófà nínú àdúrà pé a ti pinnu láti fún un ní ìfọkànsìn tí a yà sọ́tọ̀ gedegbe títí ayérayé. (Diutarónómì 5:9) Àmọ́ ṣá o, a kò ya ara wa sí mímọ́ fún iṣẹ́ pàtó kan tàbí fún ènìyàn kan bí kò ṣe fún Ọlọ́run fúnra rẹ̀.
15. Èé ṣe táwọn tó múra tán fún ìbatisí fi ní láti ṣèrìbọmi?
15 Nígbà tá a bá ya ara wa sí mímọ́ fún Ọlọ́run nípasẹ̀ Kristi, a fi hàn pé a ti pinnu láti lo ìgbésí ayé wa nínú ṣíṣe ìfẹ́ Ọlọ́run bí a ti lànà rẹ̀ sílẹ̀ nínú Ìwé Mímọ́. Láti fi ẹ̀rí ìyàsímímọ́ yẹn hàn, àwọn tó múra tán fún ìbatisí gbọ́dọ̀ ṣe ìrìbọmi, àní bí Jésù ṣe ṣe batisí ní Odò Jọ́dánì láti fi hàn pé òun ti fi ara òun fún Ọlọ́run pátápátá. (Mátíù 3:13) Ó yẹ fún àfiyèsí pé Jésù ń gbàdúrà ní àkókò pàtàkì yẹn.—Lúùkù 3:21, 22.
16. Báwo la ṣe lè fi ayọ̀ wa hàn lọ́nà tó bójú mu nígbà tá a bá rí àwọn tó ń ṣe batisí?
16 Ìbatisí Jésù kì í ṣe ọ̀ràn eré, àmọ́ ó jẹ́ ohun tó kún fún ìdùnnú. Bẹ́ẹ̀ náà ni ìrìbọmi Kristẹni ṣe rí lóde òní. Nígbà tá a bá rí àwọn èèyàn tí wọ́n ń fi ẹ̀rí ìyàsímímọ́ wọn fún Ọlọ́run hàn, a lè fi ìdùnnú wa hàn nípa fífi tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀ pàtẹ́wọ́, ká sì gbóríyìn fún wọn. Àmọ́, a gbọ́dọ̀ yẹra fún sísà wọ́n, sísúfèé, àti irú àwọn nǹkan bẹ́ẹ̀, ká lè fi hàn pé a mọyì ìjẹ́mímọ́ ìgbésẹ̀ ìgbàgbọ́ tí wọ́n gbé yìí. A ó fi ìdùnnú wa hàn ní ọ̀nà tó gbayì.
17, 18. Kí ló ń jẹ́ ká mọ̀ bóyá àwọn kan tóótun láti ṣe ìbatisí?
17 Láìdàbí àwọn tó ń wọ́n omi sáwọn ọmọ ọwọ́ lára tàbí àwọn tó ń fi agbára mú kí àwọn tí kò mọ̀ nípa Ìwé Mímọ́ ṣe batisí, àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà kò fagbára mú ẹnikẹ́ni ṣe batisí rí. Àní, wọn kì í tiẹ̀ batisí àwọn tí kò bá tóótun nípa tẹ̀mí. Kódà, kí ẹnì kan tó di oníwàásù ìhìn rere tí kò tíì ṣe batisí pàápàá, àwọn Kristẹni alàgbà máa ń rí i dájú pé irú ẹni bẹ́ẹ̀ lóye àwọn lájorí ẹ̀kọ́ Bíbélì, pé ó ń gbé níbàámu pẹ̀lú wọn, pé ó sì dáhùn bẹ́ẹ̀ ni sí ìbéèrè bíi, “Ṣé lóòótọ́ lo fẹ́ di Ẹlẹ́rìí Jèhófà?”
18 Lọ́pọ̀ ìgbà, táwọn èèyàn bá ń kópa tó ṣe gúnmọ́ nínú iṣẹ́ ìwàásù Ìjọba náà, tí wọ́n sì sọ pé ó wu àwọn láti ṣe batisí ni àwọn Kristẹni alàgbà máa ń bá wọn jíròrò láti rí i dájú pé wọ́n jẹ́ onígbàgbọ́ tó ti ya ara wọ́n sí mímọ́ fún Jèhófà, tó sì ti dé ojú ìwọ̀n ohun tí Ọlọ́run ń béèrè fún ìbatisí. (Ìṣe 4:4; 18:8) Bí wọ́n bá ṣe fúnra wọn dáhùn àwọn ìbéèrè tó lé ní ọgọ́rùn-ún tó dá lórí àwọn ẹ̀kọ́ Bíbélì ló ń ran àwọn alàgbà lọ́wọ́ láti mọ̀ bóyá àwọn tó ń dáhùn ìbéèrè yìí dé ojú ìwọ̀n ohun tí Ìwé Mímọ́ là sílẹ̀ fún ìrìbọmi. Àwọn kan kò ní tóótun, nípa bẹ́ẹ̀ a ò ní gbà wọ́n láyè láti ṣe batisí gẹ́gẹ́ bíi Kristẹni.
Ṣé Nǹkan Kan Ń Dí Ẹ Lọ́wọ́ Ni?
19. Lójú ohun tó wà nínú Jòhánù 6:44, àwọn wo ló máa jẹ́ àjùmọ̀jogún pẹ̀lú Jésù?
19 Bóyá ohun tí wọ́n sọ fún ọ̀pọ̀ lára àwọn irú-wá-ògìrì-wá tí wọ́n batisí tipátipá ni pé wọ́n á lọ sí ọ̀run nígbà tí wọ́n bá kú. Àmọ́, ohun tí Jésù sọ nípa àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ ni pé: “Kò sí ènìyàn kankan tí ó lè wá sọ́dọ̀ mi láìjẹ́ pé Baba, tí ó rán mi, fà á.” (Jòhánù 6:44) Jèhófà ti fa àwọn ọ̀kẹ́ méje ó lé ẹgbàajì tí wọ́n máa jẹ́ àjùmọ̀jogún pẹ̀lú Jésù nínú Ìjọba ọ̀run sọ́dọ̀ Kristi. Ìbatisí tá a fagbára múni ṣe kò sì tíì mú kí ẹnikẹ́ni tóótun fún ipò ológo yẹn nínú ìṣètò Ọlọ́run.—Róòmù 8:14-17; 2 Tẹsalóníkà 2:13; Ìṣípayá 14:1.
20. Kí ló lè ran àwọn kan tí kò tíì ṣe ìrìbọmi lọ́wọ́?
20 Láti àárín àwọn ọdún 1930 ní pàtàkì ni ògìdìgbó tó ń retí àtila “ìpọ́njú ńlá” já, kí wọ́n sì máa gbé orí ilẹ̀ ayé títí láé, ti ń dara pọ̀ mọ́ ẹgbẹ́ “àwọn àgùntàn mìíràn” Jésù. (Ìṣípayá 7:9, 14; Jòhánù 10:16) Wọ́n tóótun fún ìbatisí nítorí pé wọ́n mú ìgbésí ayé wọn bá Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run mu, wọ́n sì nífẹ̀ẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú ‘gbogbo ọkàn-àyà wọn, ọkàn wọn, okun wọn, àti èrò inú wọn.’ (Lúùkù 10:25-28) Bó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn kan wà tí wọ́n gbà pé àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà ‘ń jọ́sìn Ọlọ́run ní ẹ̀mí àti òtítọ́,’ síbẹ̀ irú àwọn ẹni bẹ́ẹ̀ kò tíì tẹ̀ lé àpẹẹrẹ Jésù, kí wọ́n sì fi hàn pé àwọn ní ìfẹ́ jíjinlẹ̀ àti ìfọkànsìn tí a yà sọ́tọ̀ gedegbe fún Jèhófà nípa ṣíṣe batisí. (Jòhánù 4:23, 24; Diutarónómì 4:24; Máàkù 1:9-11) Àdúrà àtọkànwá tó sì ṣe pàtó lórí ìgbésẹ̀ pàtàkì yìí lè jẹ́ ohun tó máa mórí wọn yá, tó sì máa fún wọn níṣìírí láti mú ìgbésí ayé wọn wà níbàámu pẹ̀lú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, tí yóò mú kí wọ́n ya ara wọn sí mímọ́ pátápátá fún Jèhófà Ọlọ́run, kí wọ́n sì ṣe batisí.
21, 22. Kí nìdí táwọn kan fi ń lọ́ tìkọ̀ láti ya ara wọn sí mímọ́, kí wọ́n sì ṣe ìrìbọmi?
21 Àwọn kàn ò fẹ́ ya ara wọn sí mímọ́, kí wọ́n sì ṣe batisí nítorí pé àwọn nǹkan ti ayé tàbí ìlépa ọrọ̀ ti gba gbogbo àkókò wọn débi pé ìwọ̀nba àkókò díẹ̀ ni wọ́n ní fún àwọn nǹkan tẹ̀mí. (Mátíù 13:22; 1 Jòhánù 2:15-17) Ẹ wo bí ayọ̀ wọn ì bá ti pọ̀ tó, ká ní wọ́n lè yí ojú ìwòye wọn àti ohun tí wọ́n ń lépa padà! Sísún mọ́ Jèhófà yóò mú kí ipò tẹ̀mí wọn túbọ̀ dára sí i, yóò ràn wọ́n lọ́wọ́ láti bọ́ lọ́wọ́ ṣíṣàníyàn, yóò sì fún wọn ní àlàáfíà àti ìtẹ́lọ́rùn tó máa ń tinú ṣíṣe ìfẹ́ Ọlọ́run wá.—Sáàmù 16:11; 40:8; Òwe 10:22; Fílípì 4:6, 7.
22 Àwọn mìíràn sọ pé àwọn nífẹ̀ẹ́ Jèhófà, àmọ́ wọn ò fẹ́ ya ara wọn sí mímọ́ kí wọ́n sì ṣe ìrìbọmi nítorí pé wọ́n rò pé àwọn á tipa bẹ́ẹ̀ bọ́ lọ́wọ́ ìjíhìn. Àmọ́ olúkúlùkù wa ni yóò jíhìn fún Ọlọ́run. Ìgbà tá a ti gbọ́ ọ̀rọ̀ Jèhófà ni ẹrù iṣẹ́ náà ti já lé wa léjìká. (Ìsíkíẹ́lì 33:7-9; Róòmù 14:12) Gẹ́gẹ́ bí ‘àwọn àyànfẹ́,’ inú orílẹ̀-èdè kan tí a ti yà sí mímọ́ fún Jèhófà la bí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ìgbàanì sí. Ó sì tipa bẹ́ẹ̀ di dandan fún wọn láti fi ìṣòtítọ́ sìn ín ní ìbámu pẹ̀lú àwọn ìlànà rẹ̀. (Diutarónómì 7:6, 11) Kò sí ẹni tá a bí sínú irú orílẹ̀-èdè bẹ́ẹ̀ lóde òní, àmọ́ tá a bá ti rí ìtọ́ni pípéye gbà látinú Ìwé Mímọ́, ó yẹ ká fi ìgbàgbọ́ ṣiṣẹ́ lé e lórí.
23, 24. Àwọn ìbẹ̀rù wo ni kò yẹ kó máa mú kéèyàn lọ́ tìkọ̀ láti ṣe batisí?
23 Ìbẹ̀rù pé àwọn ò tíì ní ìmọ̀ tó lè mú káwọn kan máa sá fún ṣíṣe batisí. Àmọ́, gbogbo wa la ní ọ̀pọ̀ nǹkan láti kọ́, nítorí pé ‘aráyé kò lè rídìí iṣẹ́ tí Ọlọ́run tòótọ́ ti ṣe láé láti ìbẹ̀rẹ̀ dé òpin.’ (Oníwàásù 3:11) Gbé ọ̀ràn ìwẹ̀fà ará Etiópíà yẹ̀ wò. Gẹ́gẹ́ bí aláwọ̀ṣe, ó mọ Ìwé Mímọ́ títí dé àyè kan, ṣùgbọ́n kò lè dáhùn gbogbo ìbéèrè tó ní í ṣe pẹ̀lú àwọn ète Ọlọ́run. Àmọ́, nígbà tí ìwẹ̀fà náà gbọ́ nípa ètò tí Jèhófà ṣe fún ìgbàlà nípasẹ̀ ẹbọ ìràpadà Jésù, ojú ẹsẹ̀ ló ṣe ìrìbọmi.—Ìṣe 8:26-38.
24 Àwọn kan ń lọ́ tìkọ̀ láti ya ara wọn sí mímọ́ fún Ọlọ́run nítorí wọ́n ń bẹ̀rù pé àwọn lè kùnà. Monique, ọmọ ọdún mẹ́tàdínlógún sọ pé: “Mò ń sá fún ṣíṣe batisí nítorí mò ń bẹ̀rù pé mi ò ní lè gbé níbàámu pẹ̀lú ìyàsímímọ́ mi.” Àmọ́, bí a bá fi gbogbo ọkàn wa gbẹ́kẹ̀ lé Jèhófà, ‘yóò mú àwọn ipa ọ̀nà wa tọ́.’ Yóò ràn wá lọ́wọ́ láti máa “bá a lọ ní rírìn nínú òtítọ́” gẹ́gẹ́ bí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ olóòótọ́ tó ti ṣe ìyàsímímọ́.—Òwe 3:5, 6; 3 Jòhánù 4.
25. Ìbéèrè wo ló yẹ ká gbé yẹ̀ wò báyìí?
25 Nítorí ìgbẹ́kẹ̀lé kíkún nínú Jèhófà àti ìfẹ́ àtọkànwá tá a ní fún un, ọdọọdún ni ẹgbẹẹgbẹ̀rún ń ya ara wọn sí mímọ́, tí wọ́n sì ń ṣe ìrìbọmi. Dájúdájú, gbogbo ìránṣẹ́ Ọlọ́run tó ti ya ara wọn sí mímọ́ ló fẹ́ jẹ́ olóòótọ́ sí i. Àmọ́, àwọn àkókò líle koko là ń gbé, a sì ń dojú kọ onírúurú àdánwò ìgbàgbọ́. (2 Tímótì 3:1-5) Kí la lè ṣe láti máa gbé níbàámu pẹ̀lú ìyàsímímọ́ wa sí Jèhófà? Èyí ni a óò gbé yẹ̀ wò nínú àpilẹ̀kọ tó kàn.
-
-
Ẹ Máa Fi Ọkàn-àyà Tó Fẹsẹ̀ Múlẹ̀ Ṣinṣin Sin JèhófàIlé Ìṣọ́—2002 | April 1
-
-
Ẹ Máa Fi Ọkàn-àyà Tó Fẹsẹ̀ Múlẹ̀ Ṣinṣin Sin Jèhófà
“Ọkàn-àyà mi fẹsẹ̀ múlẹ̀ ṣinṣin, Ọlọ́run, Ọkàn-àyà mi fẹsẹ̀ múlẹ̀ ṣinṣin.”—SÁÀMÙ 57:7.
1. Èé ṣe tá a fi lè ní ìdánilójú bíi ti Dáfídì?
JÈHÓFÀ lè jẹ́ ká fẹsẹ̀ múlẹ̀ ṣinṣin nínú ìgbàgbọ́ Kristẹni, kí a lè rọ̀ mọ́ ẹ̀sìn Kristẹni tòótọ́ gẹ́gẹ́ bí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ tó ti ṣe ìyàsímímọ́. (Róòmù 14:4) Nítorí náà, a lè ní ìdánilójú bíi ti Dáfídì onísáàmù, ẹni tó kọrin pé: “Ọkàn-àyà mi fẹsẹ̀ múlẹ̀ ṣinṣin, Ọlọ́run.” (Sáàmù 108:1) Bí ọkàn-àyà wa bá fẹsẹ̀ múlẹ̀ ṣinṣin, ìyẹn yóò sún wa láti gbé níbàámu pẹ̀lú ìyàsímímọ́ wa sí Ọlọ́run. Tá a bá sì ń wojú rẹ̀ fún ìtọ́sọ́nà àti okun, a lè di ẹni tí kò ṣeé ṣí nípò, tó ń dúró ti ìpinnu àti ìgbàgbọ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olùpa ìwà títọ́ mọ́, tó sì ń “ní púpọ̀ rẹpẹtẹ láti ṣe nígbà gbogbo nínú iṣẹ́ Olúwa.”—1 Kọ́ríńtì 15:58.
2, 3. Kí ni ìtumọ̀ ọ̀rọ̀ Pọ́ọ̀lù tó wà nínú 1 Kọ́ríńtì 16:13?
2 Nínú ọ̀rọ̀ ìyànjú tí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù sọ fún àwọn ọmọlẹ́yìn Jésù ní Kọ́ríńtì ìgbàanì, tó sì dájú pé ó tún kan àwa Kristẹni òde òní, ó sọ pé: “Ẹ wà lójúfò, ẹ dúró gbọn-in gbọn-in nínú ìgbàgbọ́, ẹ máa bá a nìṣó bí ọkùnrin, ẹ di alágbára ńlá.” (1 Kọ́ríńtì 16:13) Ní èdè Gíríìkì, ọ̀kọ̀ọ̀kan àwọn àṣẹ wọ̀nyí la sọ bí ohun tó ń ṣẹlẹ̀ lọ́wọ́, tó sì tipa bẹ́ẹ̀ jẹ́ ìgbésẹ̀ tí kò yẹ kó dáwọ́ dúró. Kí ni ìjẹ́pàtàkì ọ̀rọ̀ ìṣílétí yìí?
3 A lè “wà lójúfò” nípa tẹ̀mí tá a bá ń kọ ojú ìjà sí Èṣù, tá a sì sún mọ́ Ọlọ́run. (Jákọ́bù 4:7, 8) Gbígbára lé Jèhófà ń mú kó ṣeé ṣe fún wa láti wà níṣọ̀kan, ká sì ‘dúró gbọn-in nínú ìgbàgbọ́ Kristẹni.’ Gbogbo wa—títí kan ọ̀pọ̀ obìnrin tó wà láàárín wa—ní láti “máa bá a nìṣó bí ọkùnrin” nípa fífi ìgboyà sin Ọlọ́run gẹ́gẹ́ bí olùpòkìkí Ìjọba náà. (Sáàmù 68:11) A ó “di alágbára ńlá” bí a bá ń wo ojú Baba wa ọ̀run fún okun láti ṣe ìfẹ́ rẹ̀.—Fílípì 4:13.
4. Kí ló mú wa ṣe batisí gẹ́gẹ́ bíi Kristẹni?
4 A fi hàn pé a tẹ́wọ́ gba òtítọ́ nígbà tá a ya ara wa sí mímọ́ pátápátá fún Jèhófà, tá a sì fi ẹ̀rí èyí hàn nípa ṣíṣe ìrìbọmi. Àmọ́, kí ló ṣamọ̀nà sí ṣíṣe batisí? Lákọ̀ọ́kọ́, a gba ìmọ̀ pípéye nípa Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run sínú. (Jòhánù 17:3) Èyí ló jẹ́ ká nígbàgbọ́, tó tún sún wa láti ronú pìwà dà, tó sì mú ká fi tọkàntọkàn kẹ́dùn ìwà àìtọ́ tá a ti hù sẹ́yìn. (Ìṣe 3:19; Hébérù 11:6) Ẹ̀yìn ìyẹn la yí padà, nítorí pé ká lè máa gbé ìgbésí ayé tó wà níbàámu pẹ̀lú ìfẹ́ Ọlọ́run la ṣe sá fún àwọn ìwà búburú. (Róòmù 12:2; Éfésù 4:23, 24) Ohun tó wá tẹ̀ lé èyí ni pé a fi tọkàntọkàn ya ara wa sí mímọ́ fún Jèhófà nínú àdúrà. (Mátíù 16:24; 1 Pétérù 2:21) A bẹ Ọlọ́run pé kó fún wa ní ẹ̀rí ọkàn rere, a sì ṣe batisí gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rí ìyàsímímọ́ wa fún un. (1 Pétérù 3:21) Ríronú lórí àwọn ìgbésẹ̀ wọ̀nyí yóò ràn wá lọ́wọ́ láti wà lójúfò, ká máa sapá nìṣó láti gbé níbàámu pẹ̀lú ìyàsímímọ́ wa, ká sì máa bá a lọ láti fi ọkàn-àyà tó fẹsẹ̀ múlẹ̀ ṣinṣin sin Jèhófà.
-