ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • “Ẹ̀mí Mímọ́ Rán Wọn Jáde”
    “Jẹ́rìí Kúnnákúnná Nípa Ìjọba Ọlọ́run”
    • Àwọn alátakò tínú ń bí wọ́ Bánábà lọ sí ẹ̀yìn odi ìlú Áńtíókù ti Písídíà.

      APÁ 4 • ÌṢE 13:1–14:28

      ‘Ẹ̀mí Mímọ́ Rán Wọn Jáde’

      ÌṢE 13:4

      Nínú apá yìí, a máa sọ̀rọ̀ nípa ìrìn àjò míṣọ́nnárì àkọ́kọ́ tí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù lọ. Ó fẹ́rẹ̀ẹ́ jẹ́ pé gbogbo ìlú tí Pọ́ọ̀lù dé ni wọ́n ti ṣenúnibíni sí i. Síbẹ̀, ẹ̀mí mímọ́ ń ran Pọ́ọ̀lù lọ́wọ́ kó lè máa bá a lọ láti máa wàásù, ó sì ń dá àwọn ìjọ tuntun sílẹ̀. Bá a ṣe ń kẹ́kọ̀ọ́ nípa ìtàn tó gbádùn mọ́ni yìí, ó dájú pé ó máa wu àwa náà pé ká fìtara ṣe iṣẹ́ òjíṣẹ́ wa.

      Àwọn èèyàn tínú ń bí halẹ̀ mọ́ àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà ní Kánádà lọ́dún 1945.
  • Wọ́n ní “Ìdùnnú àti Ẹ̀mí Mímọ́ ní Ẹ̀kúnrẹ́rẹ́”
    “Jẹ́rìí Kúnnákúnná Nípa Ìjọba Ọlọ́run”
    • ÌRÌN ÀJÒ NÍGBÀ AYÉ ÀWỌN ÀPỌ́SÍTÉLÌ

      Láyé àtijọ́, ìrìn àjò orí ilẹ̀ kì í yá, ó máa ń tánni lókun, ó sì máa ń náni lówó ju kéèyàn wọ́ ọkọ̀ ojú omi lọ. Àmọ́ o, ọ̀pọ̀ ibi lèèyàn ò lè dé nígbà yẹn láìjẹ́ pé ó fẹsẹ̀ rìn.

      Èèyàn lè fẹsẹ̀ rin nǹkan bí ọgbọ̀n (30) kìlómítà lóòjọ́. Ẹni náà máa ní láti fara da àwọn nǹkan bí oòrùn, òjò, ooru àti òtútù. Ó sì ṣeé ṣe kó pàdé àwọn dánàdánà lójú ọ̀nà. Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù sọ pé òun wà “nínú ìrìn àjò lọ́pọ̀ ìgbà, nínú ewu odò, nínú ewu dánàdánà.”​—2 Kọ́r. 11:26.

      Àwọn ọ̀nà tó dáa wà lọ́pọ̀ ibi káàkiri Ilẹ̀ Ọba Róòmù. Láwọn òpópónà térò sábà máa ń gbà, wọ́n máa ń ṣe ilé ìgbàlejò táwọn arìnrìn-àjò ti lè sùn mọ́jú lẹ́yìn ìrìn àjò ọjọ́ kan. Àwọn ilé ìgbàlejò náà tún máa ń ní ilé ìtajà táwọn arìnrìn àjò ti lè ra àwọn nǹkan pẹ́ẹ́pẹ̀ẹ̀pẹ́ tí wọ́n nílò. Àwọn òǹkọ̀wé kan sọ pé àwọn ilé ìgbàlejò àti ilé ìtajà yẹn máa ń kún fọ́fọ́, ó máa ń dọ̀tí, ó máa ń móoru, ẹ̀fọn sì máa ń pọ̀ níbẹ̀. Àwọn èèyànkéèyàn ló sì máa ń kúnbẹ̀. Àwọn tó ń bójú tó àwọn ilé ìgbàlejò náà sábà máa ń ja àwọn arìnrìn-àjò lólè, wọ́n sì tún láwọn aṣẹ́wó tó ń ṣiṣẹ́ fún wọn.

      Ó dájú pé àwọn Kristẹni máa ṣe gbogbo ohun tí wọ́n lè ṣe kí wọ́n má bàa máa dé sáwọn ilé ìgbàlejò yẹn. Àmọ́, tí wọ́n bá ń rìnrìn àjò láwọn ìlú tí wọn ò ti ní mọ̀lẹ́bí tàbí ọ̀rẹ́, wọ́n máa ní láti sùn síbẹ̀.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́