ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • be ojú ìwé 4-ojú ìwé 8 ìpínrọ̀ 1
  • Káàbọ̀ sí Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Káàbọ̀ sí Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run
  • Jàǹfààní Nínú Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run
  • Ìsọ̀rí
  • Bí O Ṣe Lè Jàǹfààní ní Ẹ̀kúnrẹ́rẹ́
Jàǹfààní Nínú Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run
be ojú ìwé 4-ojú ìwé 8 ìpínrọ̀ 1
Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 5

Káàbọ̀ sí Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run

Ó JU igba orílẹ̀-èdè lọ káàkiri ayé tí àràádọ́ta ọ̀kẹ́ akẹ́kọ̀ọ́ ti ń jàǹfààní nínú Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run lọ́sọ̀ọ̀sẹ̀. Àwọn kan ṣẹ̀ṣẹ̀ bẹ̀rẹ̀ ni. Àwọn mìíràn sì ti ń lọ sí ilé ẹ̀kọ́ ọ̀hún láti ọ̀pọ̀ ọdún sẹ́yìn. A ń darí ilé ẹ̀kọ́ yìí ní ẹgbẹẹgbẹ̀rún ilé ìpàdé. Ibikíbi tó o bá ń gbé lórí ilẹ̀ ayé, ètò ẹ̀kọ́ kan náà yìí wà fún ọ. Tọmọdé tàgbà, gbogbo ẹ̀yà àti ìran, àtọ̀mọ̀wé àti púrúǹtù ló jùmọ̀ ń gba ìtọ́ni Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run yìí lọ́fẹ̀ẹ́.

Nígbà tí a fi ilé ẹ̀kọ́ yìí lọ́lẹ̀ nínú àwọn ìjọ Ẹlẹ́rìí Jèhófà lọ́dún 1943, a ṣàlàyé pé ète tó wà fún ni: “Láti múra gbogbo ‘àwọn olóòótọ́ èèyàn’ sílẹ̀, àwọn tí wọ́n ti gbọ́ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tí wọ́n sì ti fi hàn pé àwọn gbà á gbọ́, ‘kí wọ́n lè kọ́ àwọn ẹlòmíràn‘ . . . fún ète pàtàkì pé kí olúkúlùkù wọn . . . lè túbọ̀ já fáfá nínú sísọ ìrètí tí ń bẹ nínú wọn jáde fáyé gbọ́.” (Course in Theocratic Ministry, ojú ewé 4) Ète ilé ẹ̀kọ́ yìí kò yí padà títí dòní.

Kí ni ohun tó dára jù lọ tí kálukú wa lè fi ẹ̀bùn ọ̀rọ̀ sísọ tí Ọlọ́run fún wa ṣe ná? Bíbélì dáhùn rẹ̀ pé: “Gbogbo ohun eléèémí—kí ó yin Jáà.” (Sm. 150:6) Bí a bá ṣe ìyẹn, a óò mú inú Baba wa ọ̀run dùn. A óò jẹ́ kí ó hàn sí i láti ọkàn wa wá pé a mọrírì oore rẹ̀ àti ìfẹ́ tó fi hàn sí wa. Abájọ tá a fi gba àwọn Kristẹni níyànjú pé kí wọ́n máa “rú ẹbọ ìyìn sí Ọlọ́run nígbà gbogbo, èyíinì ni, èso ètè tí ń ṣe ìpolongo ní gbangba sí orúkọ rẹ̀”! (Héb. 13:15) A tẹ́wọ́ gbà ọ́ sí Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run gẹ́gẹ́ bí akẹ́kọ̀ọ́ kí á lè ràn ọ́ lọ́wọ́ láti lo àwọn ẹ̀bùn tó o ní láti fi yin Jèhófà.

Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé bí a ṣe ń kàwé fún àwùjọ àti bí a ṣe ń mọ ọ̀nà tí à ń gbà báni sọ̀rọ̀ àti bí a ṣe ń kọ́ni ló gbàfiyèsí púpọ̀ nínú ilé ẹ̀kọ́ yìí, àǹfààní Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run kò mọ síbẹ̀ nìkan. Bí o ṣe ń kópa nínú rẹ̀, a ó ràn ọ́ lọ́wọ́ láti di ẹni tó ń kàwé, ẹni tó mọ bá a ṣe ń fetí sílẹ̀ àti bá a ṣe ń rántí nǹkan, tó mọ bá a ṣe ń kẹ́kọ̀ọ́ àti bá a ṣe ń ṣe ìwádìí, bá a ṣe ń ṣe àyẹ̀wò fínnífínní àti bá a ṣe ń ṣàkójọ ọ̀rọ̀, bá a ṣe ń fọ̀rọ̀ wérọ̀ àti bá a ṣe ń dáhùn àwọn ìbéèrè, àti bí a ṣe ń kọ èrò ọkàn ẹni sílẹ̀. Inú Bíbélì fúnra rẹ̀ àti àwọn ìtẹ̀jáde tí a gbé karí Bíbélì ni ẹ̀kọ́ àti àwọn àlàyé àti àwọn ìjíròrò ní ilé ẹ̀kọ́ yìí yóò ti wá. Bí o ṣe ń gba òtítọ́ ṣíṣeyebíye tó wà nínú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run sínú ọkàn rẹ, wàá dẹni tó mọ bí a ṣe ń ronú lọ́nà ti Ọlọ́run. Èyí yóò sì ṣàǹfààní lọ́nà kíkọyọyọ nínú gbogbo apá ìgbésí ayé rẹ! Nípa bí Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ṣe níye lórí tó, ọ̀gbẹ́ni William Lyon Phelps, tó jẹ́ olùkọ́ni ní yunifásítì ní ọ̀rúndún ogún kọ̀wé pé: “Olúkúlùkù ẹni tó bá mọ Bíbélì ní àmọ̀dájú la lè pè ní ọ̀mọ̀wé. . . . Mo gbà gbọ́ pé bí èèyàn bá ní ìmọ̀ Bíbélì ṣùgbọ́n tí kò lọ sí ilé ẹ̀kọ́ gíga, ìyẹn ṣì wúlò ju pé kó lọ sí ilé ẹ̀kọ́ gíga láìní ìmọ̀ Bíbélì.”

Bí O Ṣe Lè Jàǹfààní ní Ẹ̀kúnrẹ́rẹ́

Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 4

Ó dájú pé, ìwọ, tó o jẹ́ akẹ́kọ̀ọ́, ní láti sapá kí o tó lè jàǹfààní lẹ́kùn-únrẹ́rẹ́ nínú Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run. Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù rọ Tímótì tó jẹ́ Kristẹni alábàákẹ́gbẹ́ rẹ̀ pé: “Máa fẹ̀sọ̀ ronú lórí nǹkan wọ̀nyí; fi ara rẹ fún wọn pátápátá, kí ìlọsíwájú rẹ lè fara hàn kedere fún gbogbo ènìyàn.” (1 Tím. 4:15) Àwọn ọ̀nà gbígbéṣẹ́ wo lo lè gbà ṣakitiyan?

Bó bá ṣeé ṣe, rí i dájú pé o kì í pa Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run jẹ lọ́sọ̀ọ̀sẹ̀. Lo ìwé yìí, Jàǹfààní Nínú Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run, bó ṣe tọ́ àti bó ṣe yẹ. Kọ orúkọ rẹ sí àyè tá a pèsè sí ojú ewé tá a kọ orúkọ ìwé yìí sí. Máa mú ìwé yìí dání wá sí ilé ẹ̀kọ́ yìí nígbà gbogbo. O tún lè kọ nǹkan sínú ìwé yìí. Bí o bá ka kókó pàtàkì kan nínú rẹ̀ tí o ronú pé á ràn ọ́ lọ́wọ́, fa ìlà sídìí rẹ̀. Lo àyè fẹ̀rẹ̀gẹ̀dẹ̀ tó wà létí ìwé yìí fún ṣíṣàkọsílẹ̀ àwọn kókó tó wúlò tí o bá kọ́ nígbà ìjíròrò ilé ẹ̀kọ́ yìí.

A pèsè ẹ̀dà ìtòlẹ́sẹẹsẹ tí a tẹ̀, tí a ó tẹ̀ lé nínú Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run lọ́tọ̀. Ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ìsọfúnni nípa bí ètò ilé ẹ̀kọ́ ṣe máa rí yóò wà nínú ìtòlẹ́sẹẹsẹ ọ̀hún pẹ̀lú. O lè rí i pé yóò dára bó o bá fi ìtòlẹ́sẹẹsẹ náà sínú ìwé yìí, kó lè wà lárọ̀ọ́wọ́tó rẹ.

Bí o ṣe ń múra iṣẹ́ ilé ẹ̀kọ́ ti ọ̀sọ̀ọ̀sẹ̀ sílẹ̀, fi í sọ́kàn pé Bíbélì ni lájorí ìwé tí à ń lò. Kíka apá ibi tí a yàn nínú Bíbélì fún kíkà lọ́sẹ̀ ni kó gba iwájú o. Bí o bá sì lè ka àwọn ibi tí a ṣètò fún àwọn apá yòókù nínú ìtòlẹ́sẹẹsẹ náà ṣáájú, ìyẹn pẹ̀lú yóò ṣàǹfààní gan-an ni.

Lásìkò ilé ẹ̀kọ́ náà, àyè lè ṣí sílẹ̀ fún àwùjọ láti kópa níbẹ̀. Lo àǹfààní yẹn ní kíkún. Lílóhùn sí irú àwọn ìjíròrò bẹ́ẹ̀ jẹ́ ara nǹkan pàtàkì tí yóò mú ọ rántí ohun tó o gbọ́ tí yóò sì jẹ́ kí o lè fi í sílò nínú ìgbésí ayé rẹ.

Ó dájú pé gbogbo akẹ́kọ̀ọ́ ni yóò láǹfààní láti sọ ọ̀rọ̀ akẹ́kọ̀ọ́ tàbí kí wọ́n ṣe àṣefihàn níwájú ìjọ. Ṣe èyíkéyìí tí a bá yàn fún ọ nínú méjèèjì dáadáa. Sapá gidigidi láti rí i pé o túbọ̀ ṣe dáadáa sí i lórí ànímọ́ ọ̀rọ̀ sísọ tí wọ́n bá yàn fún ọ. Wọn yóò fún ọ nímọ̀ràn táá lè túbọ̀ mú ọ tẹ̀ síwájú. Má ṣe kọ ìrànlọ́wọ́ tí wọ́n bá fún ọ o. Kọ ìmọ̀ràn pàtó lórí ohun tí ìwọ fúnra rẹ lè ṣe láti tẹ̀ síwájú sínú ìwé rẹ. Nígbà tó sì jẹ́ pé ìpàkọ́ onípàkọ́ làá rí, ẹni ẹlẹ́ni ló ń báni rí tẹni, àbá onífẹ̀ẹ́, tí a gbé karí Bíbélì àti ìmọ̀ràn tí a óò fún ọ lè ràn ọ́ lọ́wọ́ gan-an láti tẹ̀ síwájú. Àní bó o bá tiẹ̀ ti wà nínú ilé ẹ̀kọ́ yìí láti ọ̀pọ̀ ọdún wá, kò yọ ẹ́ sílẹ̀.—Òwe 1:5.

Ṣé wàá fẹ́ láti tètè tẹ̀ síwájú? Bí o bá lo ìdánúṣe, ìyẹn lè ṣeé ṣe. Ka àwọn ibi tí a ti fa ọ̀rọ̀ akẹ́kọ̀ọ́ kọ̀ọ̀kan yọ ṣáájú. Bó bá wá di pé a nílò olùbánisọ̀rọ̀ mìíràn dípò ẹni tí a yàn tẹ́lẹ̀, ìwọ yóò lè yọ̀ǹda ara rẹ, ìyẹn á sì tún jẹ́ kó o túbọ̀ nírìírí sí i. Bí àwọn ẹlòmíràn bá ń sọ̀rọ̀, tẹ́tí bẹ̀lẹ̀jẹ́ sí bí wọ́n ṣe ń sọ ọ̀rọ̀ wọn. Èèyàn a máa kẹ́kọ̀ọ́ lára ọmọnìkejì rẹ̀.

Ní àfikún sí i, bí àyè rẹ̀ bá yọ, o tún lè mú kí ìtẹ̀síwájú rẹ yá kánkán bó o bá ń ka ìwé yìí ṣáájú fúnra rẹ. Lẹ́yìn tó o bá ti mọ ohun tó wà nínú ẹ̀kọ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún àkọ́kọ́ dáadáa, bẹ̀rẹ̀ sí í fúnra rẹ kọ́ ohun tó wà nínú “Ètò Sísọni Di Sọ̀rọ̀sọ̀rọ̀ àti Olùkọ́ni” tó bẹ̀rẹ̀ látojú ewé 78. Lákọ̀ọ́kọ́, ka ẹ̀kọ́ kọ̀ọ̀kan kí o sì ṣe iṣẹ́ akẹ́kọ̀ọ́ tí a gbé karí rẹ̀. Kí o wá fi ohun tó ò ń kọ́ sílò nínú iṣẹ́ òjíṣẹ́ rẹ. Èyí lè túbọ̀ mú kó o tẹ̀ síwájú dáadáa gẹ́gẹ́ bí ẹni tó ń sọ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tó sì ń fi í kọ́ni.

Ẹ̀kọ́ tí ò ń kọ́ ní Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run yóò mú ọ gbára dì fún ohun tó ṣe pàtàkì jù lọ nínú ìgbésí ayé rẹ. Nígbà tó sì jẹ́ pé nítorí ìfẹ́ Ọlọ́run la fi wà láàyè, tí a bá ń yìn ín, á jẹ́ pé a lóye ète pàtàkì tí a fi ń bẹ láàyè nìyẹn. Ìyìn tó ga lọ́lá jù lọ ló sì yẹ Jèhófà Ọlọ́run. (Ìṣí. 4:11) Ẹ̀kọ́ tí à ń kọ́ ní ilé ẹ̀kọ́ yìí jẹ́ ọ̀nà kan tí a lè gbà yìn ín. Yóò jẹ́ ká lè ronú lọ́nà tó já gaara, ká hùwà ọlọgbọ́n, ká sì lè sọ àwọn àgbàyanu òtítọ́ tó wà nínú Ọ̀rọ̀ tí Ọlọ́run mí sí fáwọn èèyàn lọ́nà tí yóò fi wọ̀ wọ́n lọ́kàn.

ÈTÒ INÚ ILÉ Ẹ̀KỌ́ YÌÍ

  • Ìtòlẹ́sẹẹsẹ ọ̀sọ̀ọ̀sẹ̀ fún ìwé kíkà, ìkẹ́kọ̀ọ́, àti ìwádìí ṣíṣe, tí a gbé karí Bíbélì

  • Ìtọ́ni nípa bí a ṣe ń kàwé fún àwùjọ àti ọ̀nà tí à ń gbà báni sọ̀rọ̀ àti bí a ṣe ń kọ́ni

  • Kíkópa nínú ìjíròrò ní ilé ẹ̀kọ́

  • Àǹfààní láti sọ ọ̀rọ̀ níwájú ìjọ

  • Ìrànlọ́wọ́ tí a óò pèsè fún ọ gẹ́gẹ́ bí ẹnì kan kí o lè tẹ̀ síwájú

ÀWỌN OHUN PÀTÀKÌ TÍ A FÚN LÁFIYÈSÍ

  • Fífetísílẹ̀ àti rírántí nǹkan

  • Kíkàwé

  • Kíkẹ́kọ̀ọ́

  • Ṣíṣe ìwádìí

  • Ṣíṣe àyẹ̀wò fínnífínní àti ṣíṣàkójọ ọ̀rọ̀

  • Fífọ̀rọ̀wérọ̀

  • Dídáhùn àwọn ìbéèrè

  • Ṣíṣàkọsílẹ̀ èrò ọkàn ẹni

ÌPÌLẸ̀ TÍ A ÓÒ GBÉ E KÀ

Mímọ bí a ṣe ń sọ̀rọ̀ kí ó sì wọni lọ́kàn dà bí iṣẹ́ ọnà kan. Gbogbo èèyàn kọ́ ló mọ̀ nípa iṣẹ́ ọnà. Ọ̀pọ̀ ìwé làwọn èèyàn ti kọ láti fi ran àwọn èèyàn lọ́wọ́ kí wọ́n lè túbọ̀ sọ̀rọ̀ lọ́nà tó dáa. Àmọ́, Ẹlẹ́dàá, Ẹni tó fún ọmọ aráyé lágbára ọ̀rọ̀ sísọ, mọ̀ nípa ọ̀rọ̀ sísọ àti ìkọ́ni ju ọmọ aráyé èyíkéyìí tó jẹ́ olùkọ́ni-ní-ọ̀rọ̀-sísọ. Ọmọ bíbí kan ṣoṣo rẹ̀ fọwọ́ sowọ́ pọ̀ pẹ̀lú rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí Àgbà Òṣìṣẹ́ nígbà tó ń dá ọpọlọ èèyàn àti àwọn ẹ̀yà ara tí à ń lò fún ọ̀rọ̀ sísọ àti gbogbo ohun ìyanu inú ìṣẹ̀dá yòókù.

Nígbà tí ó dá àwọn áńgẹ́lì àti àwọn èèyàn, Ọmọ yẹn wá di ẹni tí a mọ̀ sí Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, Ẹni pàtàkì tí Ọlọ́run ń lò láti fún àwọn áńgẹ́lì àti àwọn èèyàn ní ìtọ́ni. (Òwe 8:30; Jòh. 1:1-3) Ọmọ yìí ló rán wá sí ayé gẹ́gẹ́ bíi Jésù Kristi Olúwa. Òun ni àkọsílẹ̀ onímìísí ń sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀ pé: “Háà ń ṣe ogunlọ́gọ̀ sí ọ̀nà ìkọ́nilẹ́kọ̀ọ́ rẹ̀.” Àwọn tó gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì jẹ́rìí sí i pé: “Ènìyàn mìíràn kò tíì sọ̀rọ̀ báyìí rí.” (Mát. 7:28; Jòh. 7:46) Ó ju ogójì ìgbà lọ tí àwọn ìwé Ìhìn Rere pe Jésù ní Olùkọ́, ó sì tọ́ bẹ́ẹ̀. Ẹ̀kọ́ púpọ̀ ni a lè rí kọ́ lọ́dọ̀ rẹ̀ nípa ọ̀rọ̀ sísọ àti kíkọ́ni.

Àkọsílẹ̀ nípa bí Jèhófà Ọlọ́run ṣe lo àwọn ọkùnrin àti obìnrin tí ipò ìgbésí ayé wọn yàtọ̀ síra láti mú ìfẹ́ rẹ̀ ṣẹ wà nínú Bíbélì pẹ̀lú. Àwọn kan nínú wọn jíṣẹ́ tó ṣe ṣókí ṣùgbọ́n tó lágbára. Ọ̀pọ̀ nínú wọn kò sọ̀rọ̀ níwájú àwùjọ tó pọ̀ rẹpẹtẹ, ṣùgbọ́n wọ́n fi ìṣòtítọ́ kópa nínú jíjẹ́rìí nípa Ọlọ́run tòótọ́ àti ète rẹ̀. Ó dájú pé èyí tó pọ̀ jù nínú wọn ni kì í ṣe sọ̀rọ̀sọ̀rọ̀ tó dá-ń-tọ́, ṣùgbọ́n Ọlọ́run bù kún ìsapá wọn. A lè rí ẹ̀kọ́ kọ́ látinú ohun tí Bíbélì sọ nípa ọ̀nà tí wọ́n gbà ṣe iṣẹ́ òjíṣẹ́ wọn.—Sm. 68:11.

Lóòótọ́ o, Bíbélì kì í ṣe ìwé tí a ṣe fún kíkọ́ni nípa bí a ṣe ń sọ̀rọ̀ láwùjọ. Ṣùgbọ́n, àwọn tó bá fi òye kàwé yóò rí i pé ìjìnlẹ̀ òye tó ṣeyebíye wà nínú rẹ̀ nípa bí a ṣe ń sọ̀rọ̀ àti bí a ṣe ń kọ́ni lọ́nà tó ń wọni lọ́kàn. A sapá gidigidi láti rí i pé Bíbélì ni ìpìlẹ̀ tí a gbé ìwé Jàǹfààní Nínú Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run kà.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́