-
Jésù Fọ Tẹ́ńpìlì Mọ́ Lẹ́ẹ̀kan Sí IJésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
-
-
ORÍ 103
Jésù Fọ Tẹ́ńpìlì Mọ́ Lẹ́ẹ̀kan Sí I
MÁTÍÙ 21:12, 13, 18, 19 MÁÀKÙ 11:12-18 LÚÙKÙ 19:45-48 JÒHÁNÙ 12:20-27
JÉSÙ GÉGÙN-ÚN FÚN IGI Ọ̀PỌ̀TỌ́ KAN, Ó TÚN FỌ TẸ́ŃPÌLÌ MỌ́
JÉSÙ GBỌ́DỌ̀ KÚ KÓ TÓ LÈ FÚN Ọ̀PỌ̀ ÈÈYÀN NÍ ÌYÈ
Jésù àtàwọn ọmọ ẹ̀yìn ẹ̀ ti lo ọjọ́ mẹ́ta ní Bẹ́tánì lẹ́yìn tí wọ́n dé láti Jẹ́ríkò. Nígbà tó di àárọ̀ Monday Nísàn 10, wọ́n lọ sí Jerúsálẹ́mù. Bí wọ́n ṣe ń lọ, ebi ń pa Jésù. Torí náà, nígbà tó rí igi ọ̀pọ̀tọ́ kan, ó lọ sídìí ẹ̀. Kí ló wá bá lórí igi náà?
Oṣù March ń parí lọ lásìkò yẹn, ó ṣì di oṣù June kí igi ọ̀pọ̀tọ́ tó sèso. Àmọ́ igi ọ̀pọ̀tọ́ tí Jésù rí yìí tètè rúwé ní tiẹ̀, torí náà Jésù rò pé òun máa rí èso lórí ẹ̀. Nígbà tó débẹ̀ kò rí èso kankan bó ti wù kó kéré mọ. Ṣe làwọn ewé tó wà lórí igi yẹn kàn jẹ́ kó dà bíi pé èso ti wà lórí ẹ̀. Jésù wá sọ pé: “Kí ẹnì kankan má ṣe jẹ èso lórí rẹ mọ́ títí láé.” (Máàkù 11:14) Ẹsẹ̀kẹsẹ̀ ni igi náà bẹ̀rẹ̀ sí í wọ́wé, àmọ́ àárọ̀ ọjọ́ kejì làwọn ọmọ ẹ̀yìn ṣẹ̀ṣẹ̀ lóye ohun tí Jésù sọ.
Kò pẹ́ lẹ́yìn náà, Jésù àtàwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ dé Jerúsálẹ́mù, wọ́n sì lọ sínú tẹ́ńpìlì. Lọ́jọ́ tó ṣáájú ọjọ́ yẹn, Jésù lọ ṣàyẹ̀wò ohun tó ń lọ nínú tẹ́ńpìlì. Àmọ́ ní báyìí, kì í ṣe pé ó kàn ṣàyẹ̀wò tẹ́ńpìlì nìkan, ohun tó ṣe lọ́dún mẹ́ta sẹ́yìn nígbà Ìrékọjá ọdún 30 S.K. ló tún ṣe nígbà tó débẹ̀. (Jòhánù 2:14-16) Lọ́tẹ̀ yìí, ó lé “àwọn tó ń tajà àti àwọn tó ń rajà nínú tẹ́ńpìlì síta, ó sì dojú tábìlì àwọn tó ń pààrọ̀ owó dé àti bẹ́ǹṣì àwọn tó ń ta àdàbà.” (Máàkù 11:15) Kódà, kò gbà káwọn tó ń gbé nǹkan bọ̀ látinú ìlú yẹn gba àgbàlá tẹ́ńpìlì kọjá lọ síbòmíì.
Kí nìdí tó fi jẹ́ pé ọwọ́ tó le tóyẹn ni Jésù fi mú àwọn tó ń pààrọ̀ owó àtàwọn tó ń ta ẹran nínú tẹ́ńpìlì? Jésù sọ pé: “Ṣebí a ti kọ ọ́ pé, ‘A ó máa pe ilé mi ní ilé àdúrà fún gbogbo orílẹ̀-èdè’? Àmọ́ ẹ ti sọ ọ́ di ihò àwọn olè.” (Máàkù 11:17) Kí nìdí tí Jésù fi pè wọ́n lólè? Ìdí ni pé owó gọbọi ni wọ́n máa ń gbà lọ́wọ́ àwọn tó fẹ́ ra ẹran tí wọ́n máa fi ṣètùtù. Jésù gbà pé ìwà wọn ò yàtọ̀ sí ti olè.
Nígbà táwọn olórí àlùfáà, àwọn akọ̀wé òfin àtàwọn èèyàn ńláńlá tó wà nílùú gbọ́ ohun tí Jésù ṣe, wọ́n tún pa dà sórí ọ̀rọ̀ bí wọ́n ṣe máa pa á. Àmọ́, ohun kan wà tó ń dí wọn lọ́wọ́. Wọn ò mọ bí wọ́n ṣe máa pa Jésù torí pé ọ̀pọ̀ èèyàn ló ń tẹ̀ lé e kí wọ́n lè gbọ́rọ̀ ẹ̀.
Àwọn Júù nìkan kọ́ ló wá síbi Ìrékọjá yẹn, àwọn aláwọ̀ṣe náà wà níbẹ̀, ìyẹn àwọn tó gba ẹ̀sìn Júù. Lára wọn ni àwọn Gíríìkì tí wọ́n wá jọ́sìn Ọlọ́run níbi àjọyọ̀ náà. Wọ́n lọ bá Fílípì, bóyá torí pé orúkọ Gíríìkì ló ń jẹ́, wọ́n sọ fún un pé àwọn fẹ́ rí Jésù. Ó ṣeé ṣe kí Fílípì má mọ̀ bóyá wọ́n máa lè rí Jésù, torí náà ó fi ọ̀rọ̀ náà lọ Áńdérù. Làwọn méjèèjì bá lọ bá Jésù, torí ó ṣeé ṣe kó ṣì wà ní tẹ́ńpìlì nígbà yẹn.
Jésù mọ̀ pé ọjọ́ bíi mélòó kan ló kù fún òun láti kú, torí náà kì í ṣe àsìkò yìí ló yẹ kó máa wá bó ṣe máa ṣe ohun táwọn èèyàn fẹ́ tàbí kó máa wá bá á ṣe di gbajúmọ̀. Torí náà, ó sọ àpèjúwe kan fáwọn àpọ́sítélì méjèèjì yẹn, ó ní: “Wákàtí náà ti dé tí a máa ṣe Ọmọ èèyàn lógo. Lóòótọ́-lóòótọ́ ni mo sọ fún yín, láìjẹ́ pé hóró àlìkámà kan bọ́ sílẹ̀, kó sì kú, ó ṣì máa jẹ́ ẹyọ hóró kan ṣoṣo; àmọ́ tó bá kú, ìgbà yẹn ló máa so èso púpọ̀.”—Jòhánù 12:23, 24.
Hóró àlìkámà tàbí wíìtì kan lè dà bí ohun tí kò níye lórí. Síbẹ̀, tí wọ́n bá gbin hóró yìí, ó máa “kú,” á hù, á sì so. Torí pé Jésù jẹ́ èèyàn pípé, òun ló dà bíi hóró kan yẹn. Bó sì ṣe jẹ́ olóòótọ́ sí Ọlọ́run títí tó fi kú, ó máa ṣeé ṣe fún ọ̀pọ̀ èèyàn láti rí ìyè tí wọ́n bá fayé wọn sin Ọlọ́run bíi tiẹ̀. Jésù wá sọ pé: “Ẹnikẹ́ni tó bá fẹ́ràn ẹ̀mí rẹ̀ ń pa á run, àmọ́ ẹnikẹ́ni tó bá kórìíra ẹ̀mí rẹ̀ nínú ayé yìí máa pa á mọ́ fún ìyè àìnípẹ̀kun.”—Jòhánù 12:25.
Ohun tí Jésù sọ lẹ́yìn èyí fi hàn pé kò ro tara ẹ̀ nìkan, torí ó sọ pé: “Tí ẹnikẹ́ni bá fẹ́ ṣe ìránṣẹ́ fún mi, kó máa tẹ̀ lé mi, ibi tí mo bá sì wà ni ìránṣẹ́ mi náà máa wà. Tí ẹnikẹ́ni bá fẹ́ ṣe ìránṣẹ́ fún mi, Baba máa bọlá fún un.” (Jòhánù 12:26) Ẹ ò rí i pé èrè ńlá nìyẹn! Àwọn tí Baba bá bọlá fún máa làǹfààní láti bá Kristi jọba.
Nígbà tí Jésù ronú nípa ìyà tó máa jẹ òun àti bí wọ́n ṣe máa pa òun nípa ìkà, ó sọ pé: “Ní báyìí, ìdààmú bá mi, kí sì ni kí n sọ? Baba, gbà mí kúrò nínú wákàtí yìí.” Àmọ́, Jésù fẹ́ kí ìfẹ́ Baba rẹ̀ ṣẹ, ó wá sọ pé: “Síbẹ̀, torí èyí ni mo fi wá sí wákàtí yìí.” (Jòhánù 12:27) Gbogbo ohun tí Ọlọ́run fẹ́ kó ṣẹlẹ̀ ló bá Jésù lára mu, títí kan bí wọ́n ṣe máa pa á kó lè fi ẹ̀mí rẹ̀ rúbọ.
-
-
Lẹ́yìn Táwọn Júù Gbọ́ Ohùn Ọlọ́run, Ṣé Wọ́n Gba Jésù Gbọ́?Jésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
-
-
ORÍ 104
Lẹ́yìn Táwọn Júù Gbọ́ Ohùn Ọlọ́run, Ṣé Wọ́n Gba Jésù Gbọ́?
Ọ̀PỌ̀ ÈÈYÀN GBỌ́ OHÙN ỌLỌ́RUN
OHUN TÓ MÁA PINNU BÍ ỌLỌ́RUN ṢE MÁA DÁ ÈÈYÀN LẸ́JỌ́
Lọ́jọ́ Monday, Nísàn 10, Jésù wà ní tẹ́ńpìlì, ó sọ pé òun ò ní pẹ́ kú. Ó ń ká Jésù lára pé ikú òun lè kó ẹ̀gàn bá orúkọ Ọlọ́run, ó wá sọ pé: “Baba, ṣe orúkọ rẹ lógo.” Ni ohùn kan tó rinlẹ̀ bá dún láti ọ̀run pé: “Mo ti ṣe é lógo, màá sì tún ṣe é lógo.”—Jòhánù 12:27, 28.
Ohun tó ṣẹlẹ̀ ò yé àwọn tó wà níbẹ̀. Àwọn kan rò pé ààrá ló sán. Àwọn míì sọ pé: “Áńgẹ́lì kan ti bá a sọ̀rọ̀.” (Jòhánù 12:29) Àmọ́ ohùn Jèhófà ni wọ́n gbọ́ yẹn! Kì í sì í ṣe ìgbà àkọ́kọ́ nìyí táwọn èèyàn máa gbọ́ tí Ọlọ́run bá Jésù sọ̀rọ̀.
Lọ́dún mẹ́ta ààbọ̀ sẹ́yìn, nígbà tí Jésù ń ṣèrìbọmi, Jòhánù Arinibọmi gbọ́ tí Ọlọ́run sọ pé: “Èyí ni Ọmọ mi, àyànfẹ́, ẹni tí mo ti tẹ́wọ́ gbà.” Nígbà tó yá, lẹ́yìn Ìrékọjá ọdún 32 S.K., Ọlọ́run yí Jésù pa dà di ológo níṣojú Jémíìsì, Jòhánù àti Pétérù. Àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta gbọ́ nígbà tí Ọlọ́run sọ pé: “Èyí ni Ọmọ mi, àyànfẹ́, ẹni tí mo ti tẹ́wọ́ gbà. Ẹ fetí sí i.” (Mátíù 3:17; 17:5) Èyí tó ṣẹlẹ̀ nínú tẹ́ńpìlì yìí ni ìgbà kẹta tí Jèhófà sọ̀rọ̀, kí ọ̀pọ̀ èèyàn lè gbọ́!
Jésù sọ pé: “Kì í ṣe torí tèmi ni ohùn yìí ṣe dún, torí tiyín ni.” (Jòhánù 12:30) Ohùn yẹn jẹ́ ẹ̀rí pé Ọmọ Ọlọ́run ni lóòótọ́ àti pé òun ni Mèsáyà tí a ṣèlérí.
Bí Jésù ṣe jẹ́ olóòótọ́ nígbà tó wà láyé jẹ́ àpẹẹrẹ tó yẹ káwa èèyàn tẹ̀ lé, ó sì tún jẹ́ kó dá wa lójú pé dandan ni kí Sátánì Èṣù, tó jẹ́ alákòóso ayé pa run. Jésù sọ pé: “Ní báyìí, à ń ṣèdájọ́ ayé yìí; ní báyìí, a máa lé alákòóso ayé yìí jáde.” Tí Jésù bá kú, ó lè fẹ́ dà bíi pé wọ́n ti rẹ́yìn rẹ̀, àmọ́ ìṣẹ́gun ló máa jẹ́. Lọ́nà wo? Ó sọ pé: “Síbẹ̀, tí a bá gbé mi sókè kúrò ní ayé, màá fa onírúurú èèyàn sọ́dọ̀ ara mi.” (Jòhánù 12:31, 32) Jésù máa kú lórí òpó igi, ìyẹn á jẹ́ kó lè fa àwọn èèyàn sọ́dọ̀ ara rẹ̀ kí wọ́n lè rí ìyè.
Nígbà tí Jésù sọ pé a máa ‘gbé òun sókè,’ àwọn èèyàn sọ pé: “A gbọ́ látinú Òfin pé Kristi máa wà títí láé. Kí ló dé tí o wá sọ pé wọ́n gbọ́dọ̀ gbé Ọmọ èèyàn sókè? Ta ni Ọmọ èèyàn yìí?” (Jòhánù 12:34) Pẹ̀lú gbogbo ẹ̀rí tí wọ́n rí, tí wọ́n sì tún gbọ́ ohùn Ọlọ́run, síbẹ̀ èyí tó pọ̀ jù nínú wọn ni ò gbà pé Jésù gan-an ni Ọmọ èèyàn, Mèsáyà tí Ọlọ́run ṣèlérí.
Ṣáájú àkókò yìí, Jésù ti fi ara rẹ̀ wé “ìmọ́lẹ̀,” ó tún ṣe bẹ́ẹ̀ lẹ́ẹ̀kan sí i. (Jòhánù 8:12; 9:5) Ó sọ pé: “Ìmọ́lẹ̀ máa wà láàárín yín fúngbà díẹ̀ sí i. Ẹ rìn nígbà tí ẹ ṣì ní ìmọ́lẹ̀ náà, kí òkùnkùn má bàa borí yín . . . Nígbà tí ẹ ṣì ní ìmọ́lẹ̀, ẹ ní ìgbàgbọ́ nínú ìmọ́lẹ̀ náà, kí ẹ lè di ọmọ ìmọ́lẹ̀.” (Jòhánù 12:35, 36) Jésù wá kúrò níbẹ̀ torí pé kì í ṣe Nísàn 10 ló máa kú. Nísàn 14 tó jẹ́ ọjọ́ Ìrékọjá ni wọ́n tó máa ‘gbé e sókè,’ tí wọ́n sì máa kàn án mọ́ òpó igi.—Gálátíà 3:13.
Ohun táwọn Júù ṣe nígbà tí Jésù ń wàásù jẹ́ ká rí i pé àsọtẹ́lẹ̀ Àìsáyà ṣẹ sí wọn lára bí wọn ò ṣe gbà pé Jésù ni Mèsáyà. Àìsáyà sọ tẹ́lẹ̀ pé ojú àwọn èèyàn yẹn máa lẹ̀ pọ̀, ọkàn wọn sì máa le kí wọ́n má bàa yí pa dà kí wọ́n sì rí ìgbàlà. (Àìsáyà 6:10; Jòhánù 12:40) Ohun tó sì ṣẹlẹ̀ nìyẹn, ọ̀pọ̀ àwọn Júù ni ò gbà pé Jésù ni olùgbàlà tí Ọlọ́run ṣèlérí, wọn ò gbà pé òun ni ọ̀nà kan ṣoṣo tí wọ́n lè gbà rí ìyè.
Òótọ́ ni pé Nikodémù, Jósẹ́fù ará Arimatíà àtàwọn alákòóso míì “ní ìgbàgbọ́ nínú” Jésù. Àmọ́ ṣé wọ́n máa fi hàn pé àwọn nígbàgbọ́ nínú rẹ̀ lóòótọ́? Ṣé ìbẹ̀rù máa mú kí wọ́n yẹra fún Jésù, kí wọ́n má bàa lé wọn kúrò nínú sínágọ́gù? Àbí wọ́n á fi Jésù sílẹ̀ torí pé “wọ́n nífẹ̀ẹ́ ògo èèyàn”?—Jòhánù 12:42, 43.
Jésù ṣàlàyé ohun tó túmọ̀ sí láti nígbàgbọ́ nínú òun, ó sọ pé: “Ẹnikẹ́ni tó bá ní ìgbàgbọ́ nínú mi, kò ní ìgbàgbọ́ nínú èmi nìkan, àmọ́ ó tún ní ìgbàgbọ́ nínú ẹni tó rán mi; ẹnikẹ́ni tó bá sì rí mi, ó rí Ẹni tó rán mi pẹ̀lú.” Àwọn ẹ̀kọ́ òtítọ́ tí Ọlọ́run rán Jésù pé kó fi kọ́ àwọn èèyàn ṣe pàtàkì gan-an, torí náà Jésù sọ pé: “Ẹnikẹ́ni tí kò bá kà mí sí, tí kò sì gba àwọn ọ̀rọ̀ mi ní ẹni tó máa dá a lẹ́jọ́. Ọ̀rọ̀ tí mo ti sọ ló máa dá a lẹ́jọ́ ní ọjọ́ ìkẹyìn.”—Jòhánù 12:44, 45, 48.
Jésù wá sọ pé: “Èrò ara mi kọ́ ni mò ń sọ, àmọ́ Baba tó rán mi fúnra rẹ̀ ti fún mi ní àṣẹ kan nípa ohun tí màá wí àti ohun tí màá sọ. Mo sì mọ̀ pé àṣẹ rẹ̀ túmọ̀ sí ìyè àìnípẹ̀kun.” (Jòhánù 12:49, 50) Jésù mọ̀ pé láìpẹ́ wọ́n máa ta ẹ̀jẹ̀ òun sílẹ̀, ìyẹn ni pé ó máa fi ẹ̀mí rẹ̀ rúbọ káwọn tó bá nígbàgbọ́ nínú rẹ̀ lè rí ìgbàlà.—Róòmù 5:8, 9.
-