-
Jésù Jẹ́jọ́ Níwájú Sàhẹ́ndìrìn àti PílátùJésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
-
-
ORÍ 127
Jésù Jẹ́jọ́ Níwájú Sàhẹ́ndìrìn àti Pílátù
MÁTÍÙ 27:1-11 MÁÀKÙ 15:1 LÚÙKÙ 22:66–23:3 JÒHÁNÙ 18:28-35
ÌGBÌMỌ̀ SÀHẸ́NDÌRÌN GBỌ́ ẸJỌ́ JÉSÙ NÍGBÀ TÍ ILẸ̀ MỌ́
JÚDÁSÌ ÌSÌKÁRÍỌ́TÙ POKÙN SO
WỌ́N MÚ JÉSÙ LỌ SÍWÁJÚ PÍLÁTÙ KÓ LÈ DÁ ẸJỌ́ IKÚ FÚN UN
Ilẹ̀ ti fẹ́rẹ̀ẹ́ mọ́ nígbà tí Pétérù sẹ́ Jésù lẹ́ẹ̀kẹta. Ìgbìmọ̀ Sàhẹ́ndìrìn ti gbọ́ ẹjọ́ ẹ̀sùn èké tí wọ́n fi kan Jésù kí wọ́n lè fi í ṣe yẹ̀yẹ́, wọ́n sì ti pa dà sílé wọn. Nígbà tó fi máa di àárọ̀ ọjọ́ Friday, wọ́n tún kóra jọ, bóyá kí wọ́n lè jíròrò ohun tí wọ́n máa sọ kó lè dà bíi pé ó bófin mu báwọn ṣe gbọ́ ẹjọ́ Jésù lọ́nà àìtọ́ láàárín òru. Wọ́n wá mú Jésù wá síwájú wọn.
Wọ́n bi í pé: “Sọ fún wa, tó bá jẹ́ ìwọ ni Kristi náà.” Jésù dá wọn lóhùn pé: “Tí mo bá tiẹ̀ sọ fún yín, ẹ ò ní gba ọ̀rọ̀ mi gbọ́ rárá. Bákan náà, tí mo bá bi yín ní ìbéèrè, ẹ ò ní dáhùn.” Lẹ́yìn ìyẹn, Jésù jẹ́ kí wọ́n mọ̀ pé òun ni àsọtẹ́lẹ̀ tó wà nínú Dáníẹ́lì 7:13 sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀. Jésù sọ pé: “Láti ìsinsìnyí lọ, Ọmọ èèyàn máa jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún agbára Ọlọ́run.”—Lúùkù 22:67-69; Mátíù 26:63.
Wọ́n tún bi í lẹ́ẹ̀kan sí i pé: “Ṣé ìwọ wá ni Ọmọ Ọlọ́run?” Jésù dáhùn pé: “Ẹ̀yin fúnra yín ń sọ pé èmi ni.” Ó jọ pé ohun tí Jésù sọ yìí ló mú kí wọ́n fi ẹ̀sùn èké kàn án pé ó sọ ọ̀rọ̀ òdì, ìyẹn ló sì mú kí wọ́n gbà pé kò burú táwọn bá pa á. Wọ́n wá béèrè lọ́wọ́ ara wọn pé: “Kí la tún nílò ẹ̀rí fún?” (Lúùkù 22:70, 71; Máàkù 14:64) Wọ́n wá de Jésù, wọ́n sì mú un lọ sọ́dọ̀ Pọ́ńtíù Pílátù tó jẹ́ Gómìnà Róòmù.
Ó ṣeé ṣe kí Júdásì Ìsìkáríọ́tù rí Jésù nígbà tí wọ́n mú un lọ sọ́dọ̀ Pílátù. Nígbà tí Júdásì rí i pé wọ́n ti dájọ́ ikú fún Jésù, ohun tó ṣe dùn ún. Àmọ́, dípò tí ì bá fi bẹ Ọlọ́run pé kó dárí ji òun, ṣe ló pa dà sọ́dọ̀ àwọn olórí àlùfáà, tó sì lọ fún wọn ní ọgbọ̀n (30) ẹyọ fàdákà tó gbà lọ́wọ́ wọn. Ó wá sọ fún wọn pé: “Mo dẹ́ṣẹ̀ nígbà tí mo fi ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ lé yín lọ́wọ́.” Ohun tó sọ yẹn ò nítumọ̀ sáwọn olórí àlùfáà, torí náà wọ́n sọ fún un pé: “Kí ló kàn wá pẹ̀lú ìyẹn? Ìwọ ni kí o lọ wá nǹkan ṣe sí i!”—Mátíù 27:4.
Ni Júdásì bá da ọgbọ̀n (30) ẹyọ fàdákà náà sínú tẹ́ńpìlì, lẹ́yìn náà ó lọ ṣe ohun tó tún burú ju èyí tó ṣe tẹ́lẹ̀, ó lọ pa ara ẹ̀. Ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé ibi tó ti ń so ara ẹ̀ mọ́ igi ni ẹ̀ka igi náà ti ya. Ó wá jábọ́ sórí àpáta tó wà nísàlẹ̀ igi náà, ikùn rẹ̀ sì bẹ́.—Ìṣe 1:17, 18.
Àárọ̀ ọjọ́ yẹn kan náà ni wọ́n mú Jésù lọ sí ààfin Pọ́ńtíù Pílátù. Àmọ́ àwọn Júù tó mú un lọ síbẹ̀ ò bá a wọlé. Wọ́n gbà pé àwọn máa di aláìmọ́ tí wọ́n bá wọ ilé Kèfèrí nírú àkókò yẹn. Tí wọ́n bá sì jẹ́ aláìmọ́, wọn ò ní lè jẹ búrẹ́dì aláìwú ní Nísàn 15. Bẹ́ẹ̀ sì rèé, Nísàn 15 ni wọ́n máa ń bẹ̀rẹ̀ Àjọyọ̀ Búrẹ́dì Aláìwú tí wọ́n gbà pé ó jẹ́ apá kan Ìrékọjá.
Torí náà, Pílátù jáde síta, ó bi wọ́n pé: “Ẹ̀sùn wo lẹ fi kan ọkùnrin yìí?” Wọ́n dá a lóhùn pé: “Ká ní ọkùnrin yìí ò ṣe ohun tí kò dáa ni, a ò ní fà á lé ọ lọ́wọ́.” Ó ṣeé ṣe kí Pílátù mọ̀ pé ṣe làwọn èèyàn náà fẹ́ fọgbọ́n mú òun láti dá ẹjọ́ tí kò tọ́ fún Jésù, torí náà ó sọ fún wọn pé: “Ẹ̀yin fúnra yín ẹ mú un, kí ẹ sì fi òfin yín dá a lẹ́jọ́.” Àwọn Júù yẹn wá sọ ohun kan tó fi hàn pé ṣe ni wọ́n fẹ́ kí Pílátù pa Jésù. Wọ́n dá a lóhùn pé: “Kò bófin mu fún wa láti pa ẹnikẹ́ni.”—Jòhánù 18:29-31.
Lóòótọ́, wọ́n máa dá wàhálà sílẹ̀ tí wọ́n bá pa Jésù nígbà àjọyọ̀ yẹn. Àmọ́, tí wọ́n bá lè wá báwọn ará Róòmù ṣe lè rí ẹ̀sùn kà sí Jésù lẹ́sẹ̀, pé ó rú òfin ìjọba, àwọn ará Róòmù láṣẹ láti pa á, ìyẹn ò sì ní jẹ́ káwọn èèyàn gbà pé àwọn Júù ló pa Jésù.
Àwọn aṣáájú ẹ̀sìn yẹn ò sọ fún Pílátù pé àwọn ti gbọ́ ẹjọ́ Jésù, wọn ò sì sọ fún un pé wọ́n ti fẹ̀sùn kàn án pé ó ń sọ̀rọ̀ òdì. Ohun míì ni wọ́n sọ pé Jésù ṣe, wọ́n ní: “A rí i pé ọkùnrin yìí [1] fẹ́ dojú ìjọba ilẹ̀ wa dé, [2] ó ní ká má ṣe san owó orí fún Késárì, ó sì [3] ń pe ara rẹ̀ ní Kristi ọba.”—Lúùkù 23:2.
Torí pé ìjọba Róòmù ni Pílátù ń ṣojú fún, bí wọ́n ṣe sọ pé Jésù ń pe ara rẹ̀ ní ọba lè mú kí Pílátù gbà pé ẹ̀sùn tí wọ́n fi kan Jésù lẹ́sẹ̀ ńlẹ̀. Pílátù wá pa dà sínú ààfin rẹ̀, ó pe Jésù, ó sì bi í pé: “Ṣé ìwọ ni Ọba Àwọn Júù?” Lédè míì, ohun tó ń bi Jésù ni pé, ‘Ṣé o gbà pé o ti rú òfin ìjọba bó o ṣe pe ara rẹ ní ọba lòdì sí Késárì?’ Ó ṣeé ṣe kí Jésù fẹ́ mọ̀ bóyá Pílátù ti gbọ́ nǹkan kan nípa òun tẹ́lẹ̀, torí náà ó bi í pé: “Ṣé ìwọ lo ronú ìbéèrè yìí fúnra rẹ, àbí àwọn míì ló sọ ọ̀rọ̀ mi fún ọ?”—Jòhánù 18:33, 34.
Àmọ́ Pílátù ṣe bíi pé òun ò mọ nǹkan kan nípa Jésù, ó sì díbọ́n bíi pé òun fẹ́ mọ̀ sí i nípa rẹ̀, ó wá bi Jésù pé: “Èmi kì í ṣe Júù, àbí Júù ni mí?” Ó tún fi kún un pé: “Àwọn èèyàn orílẹ̀-èdè rẹ àti àwọn olórí àlùfáà ló fà ọ́ lé mi lọ́wọ́. Kí lo ṣe?”—Jòhánù 18:35.
Jésù sọ bọ́rọ̀ ṣe rí nígbà tí Gómìnà Pílátù bi í pé ṣé òun ni ọba àwọn Júù. Ẹsẹ̀kẹsẹ̀ ni Jésù dá a lóhùn, ó sì dájú pé ìdáhùn rẹ̀ ya Pílátù lẹ́nu.
-
-
Pílátù àti Hẹ́rọ́dù Rí I Pé Jésù Ò Jẹ̀biJésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
-
-
ORÍ 128
Pílátù àti Hẹ́rọ́dù Rí I Pé Jésù Ò Jẹ̀bi
MÁTÍÙ 27:12-14, 18, 19 MÁÀKÙ 15:2-5 LÚÙKÙ 23:4-16 JÒHÁNÙ 18:36-38
HẸ́RỌ́DÙ ÀTI PÍLÁTÙ GBỌ́ ẸJỌ́ JÉSÙ
Nígbà tí Pílátù béèrè lọ́wọ́ Jésù pé ṣé ọba ni lóòótọ́, ìdáhùn Jésù fi hàn pé kò fọ̀rọ̀ pa mọ́ fún un. Àmọ́ Ìjọba tí Jésù sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀ kò ní nǹkan kan ṣe pẹ̀lú ìṣàkóso Róòmù. Jésù sọ fún un pé: “Ìjọba mi kì í ṣe apá kan ayé yìí. Ká ní Ìjọba mi jẹ́ apá kan ayé yìí, àwọn ìránṣẹ́ mi ì bá ti jà kí wọ́n má bàa fà mí lé àwọn Júù lọ́wọ́. Àmọ́, bó ṣe rí yìí, Ìjọba mi ò wá láti orísun yìí.” (Jòhánù 18:36) Bọ́rọ̀ sì ṣe rí nìyẹn, Jésù ní Ìjọba kan lóòótọ́, àmọ́ kì í ṣe ti ayé yìí.
Pílátù ò fi ọ̀rọ̀ náà mọ síbẹ̀, ó tún bi Jésù pé: “Ó dáa, ṣé ọba ni ọ́?” Jésù jẹ́ kí Pílátù mọ̀ pé òun fúnra rẹ̀ ti dáhùn ìbéèrè yẹn, ó ní: “Ìwọ fúnra rẹ ń sọ pé ọba ni mí. Torí èyí la ṣe bí mi, torí èyí sì ni mo ṣe wá sí ayé, kí n lè jẹ́rìí sí òtítọ́. Gbogbo ẹni tó bá fara mọ́ òtítọ́ ń fetí sí ohùn mi.”—Jòhánù 18:37.
Jésù ti sọ fún Tọ́másì ṣáájú ìgbà yẹn pé: “Èmi ni ọ̀nà àti òtítọ́ àti ìyè.” Àmọ́ lọ́tẹ̀ yìí, Jésù jẹ́ kí Pílátù mọ̀ pé ìdí tóun fi wá sáyé ni kóun lè jẹ́rìí sí “òtítọ́,” ní pàtàkì òtítọ́ nípa Ìjọba òun. Jésù sì ti múra tán láti dúró lórí òtítọ́ yẹn kódà tó bá máa gba pé kí ẹ̀mí rẹ̀ lọ sí i. Pílátù wá bi Jésù pé: “Kí ni òtítọ́?” àmọ́ kò dúró gbọ́ ìdáhùn sí ìbéèrè yẹn. Ó gbà pé òun ti rí ẹ̀rí tóun lè fi ṣèdájọ́ Jésù.—Jòhánù 14:6; 18:38.
Pílátù wá pa dà sọ́dọ̀ àwọn èrò tó dúró síwájú ààfin rẹ̀. Ó ṣeé ṣe kí Jésù wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀ nígbà tó sọ́ fáwọn olórí àlùfáà àtàwọn èrò náà pé: “Mi ò rí ìwà ọ̀daràn kankan tí ọkùnrin yìí hù.” Ohun tó sọ yẹn bí wọn nínú, ni wọ́n bá pariwo pé: “Ó ń ru àwọn èèyàn sókè ní ti pé ó ń kọ́ wọn káàkiri gbogbo Jùdíà, bẹ̀rẹ̀ láti Gálílì títí dé ibí yìí pàápàá.”—Lúùkù 23:4, 5.
Ó dájú pé ó máa ya Pílátù lẹ́nu báwọn Júù yẹn ò ṣe láròjinlẹ̀, tí wọ́n sì nítara òdì. Nígbà táwọn olórí àlùfáà àtàwọn àgbààgbà yẹn túbọ̀ ń pariwo, Pílátù bi Jésù pé: “Ṣé o ò gbọ́ bí ẹ̀rí tí wọ́n ń jẹ́ lòdì sí ọ ṣe pọ̀ tó ni?” (Mátíù 27:13) Jésù ò tiẹ̀ dá a lóhùn. Àmọ́, ó ya Pílátù lẹ́nu pé ọkàn Jésù balẹ̀ gan-an bí wọ́n tiẹ̀ ń fi oríṣiríṣi ẹ̀sùn èké kàn án.
Àwọn Júù yẹn sọ pé Jésù ń ru àwọn èèyàn sókè “bẹ̀rẹ̀ láti Gálílì.” Pílátù wá ronú lórí ohun tí wọ́n sọ yẹn, ó rí i pé ará Gálílì ni Jésù. Torí náà, ó ń wá ọgbọ́n tó fi máa yẹ ìdájọ́ Jésù sílẹ̀. Hẹ́rọ́dù Áńtípà (tó jẹ́ ọmọ Hẹ́rọ́dù Ńlá) ló ń ṣàkóso Gálílì, ó sì wà ní Jerúsálẹ́mù nígbà yẹn torí Àjọyọ̀ Ìrékọjá. Torí náà, Pílátù ní kí wọ́n mú Jésù lọ sọ́dọ̀ rẹ̀. Ẹ rántí pé Hẹ́rọ́dù Áńtípà yìí ló ní kí wọ́n bẹ́ orí Jòhánù Arinibọmi. Nígbà tí Hẹ́rọ́dù wá gbọ́ pé Jésù ń ṣe ọ̀pọ̀ iṣẹ́ ìyanu lẹ́yìn ìgbà yẹn, ó ṣeé ṣe kó rò pé Jòhánù tóun pa ló pa dà di Jésù, torí náà ọkàn rẹ̀ ò balẹ̀.—Lúùkù 9:7-9.
Inú Hẹ́rọ́dù dùn gan-an nígbà tó rí Jésù. Kì í ṣe pé ó fẹ́ gba Jésù sílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe pé ó fẹ́ wádìí bóyá ẹ̀sùn èké ni wọ́n fi kàn án. Ṣe ni Hẹ́rọ́dù wulẹ̀ fẹ́ mọ Jésù, ó sì ń “retí pé kí òun rí i kó ṣiṣẹ́ àmì díẹ̀.” (Lúùkù 23:8) Àmọ́ o, ohun tí Jésù ṣe yàtọ̀ pátápátá sóhun tí Hẹ́rọ́dù ń retí. Kódà, Jésù ò sọ ohunkóhun nígbà tí Hẹ́rọ́dù ń béèrè ọ̀rọ̀ lọ́wọ́ rẹ̀. Ohun tí Jésù ṣe yẹn ya Hẹ́rọ́dù àtàwọn ọmọ ogun rẹ̀ lẹ́nu, torí náà wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í ‘kan Jésù lábùkù.’ (Lúùkù 23:11) Wọ́n wọ aṣọ tó rẹwà fún un, wọ́n sì ń fi ṣe yẹ̀yẹ́. Lẹ́yìn náà, Hẹ́rọ́dù ní kí wọ́n mú Jésù pa dà lọ sọ́dọ̀ Pílátù. Ṣáájú ìgbà yẹn, ọ̀tá ni Hẹ́rọ́dù àti Pílátù, àmọ́ ní báyìí, ohun tó ṣẹlẹ̀ yìí ti sọ àwọn méjèèjì di ọ̀rẹ́.
Nígbà tí wọ́n mú Jésù pa dà sọ́dọ̀ Pílátù, Pílátù pe àwọn olórí àlùfáà, àwọn aṣáájú Júù àtàwọn míì tó wà níbẹ̀, ó sọ fún wọn pé: “Mo yẹ̀ ẹ́ wò níwájú yín, àmọ́ mi ò rí ẹ̀rí pé ọkùnrin yìí jẹ̀bi ìkankan nínú ẹ̀sùn tí ẹ fi kàn án. Kódà, Hẹ́rọ́dù náà ò rí ẹ̀rí, torí ó dá a pa dà sọ́dọ̀ wa, ẹ wò ó! kò ṣe ohunkóhun tí ikú fi tọ́ sí i. Torí náà, ṣe ni màá fìyà jẹ ẹ́, màá sì tú u sílẹ̀.”—Lúùkù 23:14-16.
Ó wu Pílátù láti tú Jésù sílẹ̀, torí ó mọ̀ pé ìlara ló mú káwọn aṣáájú ẹ̀sìn yẹn mú un wá sọ́dọ̀ òun. Àmọ́ Pílátù tún wá rí ìdí míì tó fi gbà pé ó yẹ kóun tú Jésù sílẹ̀. Bó ṣe jókòó sórí ìjókòó ìdájọ́ rẹ̀, ìyàwó ẹ̀ rán ẹnì kan sí i, ó ní kí wọ́n sọ fún un pé: “Má ṣe ní ohunkóhun ṣe pẹ̀lú ọkùnrin olódodo yẹn, torí mo jìyà gan-an lójú àlá lónìí nítorí rẹ̀ [ó dájú pé Ọlọ́run ló fi ìran yẹn hàn án].”—Mátíù 27:19.
Báwo ni Pílátù ṣe máa wá ṣe ohun tó yẹ kó ṣe, kó lè tú ọkùnrin tí kò mọwọ́ mẹsẹ̀ yìí sílẹ̀?
-
-
Pílátù Sọ Pé: “Ẹ Wò Ó! Ọkùnrin Náà Nìyí!”Jésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
-
-
ORÍ 129
Pílátù Sọ Pé: “Ẹ Wò Ó! Ọkùnrin Náà Nìyí!”
MÁTÍÙ 27:15-17, 20-30 MÁÀKÙ 15:6-19 LÚÙKÙ 23:18-25 JÒHÁNÙ 18:39–19:5
PÍLÁTÙ GBÌYÀNJÚ LÁTI TÚ JÉSÙ SÍLẸ̀
ÀWỌN JÚÙ NÍ KÍ WỌ́N TÚ BÁRÁBÀ SÍLẸ̀
WỌ́N FI JÉSÙ ṢE YẸ̀YẸ́, WỌ́N SÌ FÌYÀ JẸ Ẹ́
Pílátù sọ fáwọn èèyàn tó fẹ̀sùn èké kan Jésù pé: “Mi ò rí ẹ̀rí pé ọkùnrin yìí jẹ̀bi ìkankan nínú ẹ̀sùn tí ẹ fi kàn án. Kódà, Hẹ́rọ́dù náà ò rí ẹ̀rí.” (Lúùkù 23:14, 15) Àmọ́ torí pé ó wu Pílátù láti dá Jésù sílẹ̀, ó dá ọgbọ́n kan, ó sọ fáwọn èèyàn náà pé: “Ẹ ní àṣà kan, pé kí n máa tú ẹnì kan sílẹ̀ fún yín nígbà Ìrékọjá. Torí náà, ṣé ẹ fẹ́ kí n tú Ọba Àwọn Júù sílẹ̀ fún yín?”—Jòhánù 18:39.
Pílátù rántí pé ọkùnrin kan wà lẹ́wọ̀n tó ń jẹ́ Bárábà, ògbójú olè ni, ó máa ń dìtẹ̀ síjọba, apààyàn sì ni. Torí náà Pílátù bi wọ́n pé: “Ta lẹ fẹ́ kí n tú sílẹ̀ fún yín, ṣé Bárábà ni àbí Jésù tí wọ́n ń pè ní Kristi?” Àwọn èèyàn náà ní kí Pílátù tú Bárábà sílẹ̀, àwọn olórí àlùfáà ló sì mú kí wọ́n sọ bẹ́ẹ̀. Pílátù béèrè lẹ́ẹ̀kan sí i pé: “Èwo nínú àwọn méjèèjì lẹ fẹ́ kí n tú sílẹ̀ fún yín?” Àwọn èèyàn náà tún pariwo pé: “Bárábà”!—Mátíù 27:17, 21.
Ohun tí wọ́n sọ yẹn ya Pílátù lẹ́nu, ló bá bi wọ́n pé: “Kí wá ni kí n ṣe sí Jésù tí wọ́n ń pè ní Kristi?” Àwọn èèyàn náà pariwo pé: “Kàn án mọ́gi!” (Mátíù 27:22) Kò tiẹ̀ jọ wọ́n lójú pé aláìṣẹ̀ ni wọ́n fẹ́ pa. Pílátù wá bi wọ́n pé: “Kí ló dé? Nǹkan burúkú wo ni ọkùnrin yìí ṣe? Mi ò rí ohunkóhun tó ṣe tí ikú fi tọ́ sí i; torí náà, ṣe ni màá fìyà jẹ ẹ́, màá sì tú u sílẹ̀.”—Lúùkù 23:22.
Pàbó ni gbogbo ìsapá Pílátù láti tú Jésù sílẹ̀ ń já sí, torí pé inú ń bí àwọn èèyàn yẹn, ṣe ni wọ́n pohùn pọ̀, tí wọ́n sì ń sọ fún Pílátù pé: “Kàn án mọ́gi!” (Mátíù 27:23) Àwọn aṣáájú ẹ̀sìn ti ṣi àwọn èèyàn yẹn lọ́nà débi pé wọ́n ṣáà fẹ́ ta ẹ̀jẹ̀ Jésù sílẹ̀! Ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ ni wọ́n fẹ́ ta sílẹ̀, ẹni tí kì í ṣe ọ̀daràn tàbí apààyàn. Bẹ́ẹ̀ sì rèé, ọjọ́ márùn-ún sẹ́yìn làwọn èèyàn kí i káàbọ̀ sí Jerúsálẹ́mù tiyì-tẹ̀yẹ, tí wọ́n sì pọ́n ọn lé bí Ọba. Ó dájú pé táwọn ọmọ ẹ̀yìn Jésù bá wà níbi tí wọ́n ti ní kí wọ́n kàn án mọ́gi yìí, ṣe ni wọ́n máa dákẹ́, tí wọ́n á sì fara pa mọ́.
Pílátù rí i pé ọ̀rọ̀ òun ò tà létí àwọn èèyàn tó ń fẹ̀sùn kan Jésù. Ṣe làwọn èèyàn náà kàn ń pariwo ṣáá, torí náà Pílátù bu omi, ó sì wẹ ọwọ́ rẹ̀ níwájú wọn. Ó wá sọ pé: “Ọwọ́ mi mọ́ kúrò nínú ẹ̀jẹ̀ ọkùnrin yìí. Ẹ̀yin fúnra yín ni kí ẹ lọ wá nǹkan ṣe sí i.” Ìyẹn ò tiẹ̀ tu irun kankan lára wọn, ṣe ni wọ́n tún ń sọ pé: “Kí ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ wá sórí àwa àti àwọn ọmọ wa.”—Mátíù 27:24, 25.
Gómìnà yìí mọ ohun tó yẹ kó ṣe, àmọ́ ó wù ú láti tẹ́ àwọn èèyàn yẹn lọ́rùn. Torí náà, ó tú Bárábà sílẹ̀, ó wá ní kí wọ́n bọ́ aṣọ Jésù kí wọ́n sì nà án.
Lẹ́yìn táwọn ọmọ ogun yẹn na Jésù nínàkunà, wọ́n mú un pa dà sí ààfin gómìnà. Àwọn ọmọ ogun náà wá kóra jọ, wọ́n sì túbọ̀ ń fi Jésù ṣe yẹ̀yẹ́. Wọ́n fi ẹ̀gún hun adé kan, wọ́n dé e fún un, wọ́n sì tẹ̀ ẹ́ mọ́ ọn lórí. Lẹ́yìn náà, wọ́n fi ọ̀pá esùsú sí ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀, wọ́n sì fi aṣọ ìlékè rírẹ̀dòdò kan bò ó lára, irú èyí tí àwọn ọba máa ń wọ̀. Wọ́n wá ń fi ṣe yẹ̀yẹ́ pé: “A kí ọ o, ìwọ Ọba Àwọn Júù!” (Mátíù 27:28, 29) Wọ́n ń tutọ́ sí i lára, wọ́n sì ń gbá ojú rẹ̀. Wọ́n gba ọ̀pá esùsú lọ́wọ́ rẹ̀, wọ́n wá bẹ̀rẹ̀ sí í gbá orí rẹ̀ kí wọ́n lè túbọ̀ tẹ ẹ̀gún tó wà lára “adé” náà mọ́ ọn lórí.
Pẹ̀lú gbogbo ohun tí wọ́n fojú Jésù rí, bí Jésù ṣe dúró digbí láìmikàn wú Pílátù lórí gan-an, torí náà ó fẹ́ wá bó ṣe máa yọ ara ẹ̀ nínú ọ̀rọ̀ yìí, ó wá sọ pé: “Ẹ wò ó! Mo mú un jáde wá bá yín, kí ẹ lè mọ̀ pé èmi ò rí i pé ó jẹ̀bi kankan.” Ṣé ó ṣeé ṣe kí Pílátù ronú pé àwọn èèyàn yẹn máa jáwọ́ tí wọ́n bá rí bí ara Jésù ṣe bẹ́ yánnayànna, tí ẹ̀jẹ̀ sì ti bò ó? Bí wọ́n ṣe mú Jésù dúró síwájú àwọn ọ̀dájú yẹn, Pílátù sọ pé: “Ẹ wò ó! Ọkùnrin náà nìyí!”—Jòhánù 19:4, 5.
Bó tiẹ̀ jẹ́ pé wọ́n ti fi Jésù ṣe yẹ̀yẹ́, tí wọ́n sì ti dá ọgbẹ́ sí i lára, bí Jésù ṣe dákẹ́ jẹ́ẹ́ ní láti wú Pílátù lórí, torí ohun tó sọ fi hàn pé ó bọ̀wọ̀ fún Jésù, ó sì káàánú rẹ̀.
-
-
Ó Fa Jésù Lé Wọn Lọ́wọ́ Kí Wọ́n Lè Lọ Pa ÁJésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
-
-
ORÍ 130
Ó Fa Jésù Lé Wọn Lọ́wọ́ Kí Wọ́n Lè Lọ Pa Á
MÁTÍÙ 27:31, 32 MÁÀKÙ 15:20, 21 LÚÙKÙ 23:24-31 JÒHÁNÙ 19:6-17
PÍLÁTÙ GBÌYÀNJÚ LÁTI TÚ JÉSÙ SÍLẸ̀
WỌ́N DÁ JÉSÙ LẸ́BI, WỌ́N SÌ MÚ UN LỌ SÍBI TÍ WỌ́N TI FẸ́ PA Á
Onírúurú nǹkan ni wọ́n ti fojú Jésù rí, wọ́n ti hùwà ìkà sí i, wọ́n sì ti kàn án lábùkù. Pàbó ni gbogbo ìsapá Pílátù láti tú u sílẹ̀ ń já sí, kò tiẹ̀ tu irun kan lára àwọn olórí àlùfáà àtàwọn alátìlẹyìn wọn. Ohun tí wọ́n ṣáà fẹ́ ni pé kí Jésù kú, torí náà wọ́n ń kígbe pé: “Kàn án mọ́gi! Kàn án mọ́gi!” Àmọ́ Pílátù dá wọn lóhùn pé: “Ẹ mú un fúnra yín, kí ẹ sì pa á, torí èmi ò rí i pé ó jẹ̀bi kankan.”—Jòhánù 19:6.
Àwọn aṣáájú ẹ̀sìn yẹn ò rí ẹ̀sùn kankan tí wọ́n lè fi kan Jésù pé ó rú òfin ìjọba, torí náà Pílátù ò lè dájọ́ ikú fún un. Àmọ́ ṣé wọ́n lè rí ẹ̀sùn fi kàn án pé ó rú Òfin Ọlọ́run? Wọ́n wá ronú kan ẹ̀sùn tí wọ́n fi kàn án níwájú Sàhẹ́ndìrìn pé ó ń sọ̀rọ̀ òdì. Wọ́n ní: “A ní òfin kan, bí òfin yẹn sì ṣe sọ, ó yẹ kó kú, torí ó pe ara rẹ̀ ní ọmọ Ọlọ́run.” (Jòhánù 19:7) Ìgbà àkọ́kọ́ tí wọ́n máa sọ̀rọ̀ yìí létí Pílátù nìyẹn.
Ni Pílátù bá pa dà sínú ààfin rẹ̀ kó lè wá bó ṣe máa tú Jésù sílẹ̀. Ó ṣeé ṣe kí Pílátù máa ronú nípa bí wọ́n ṣe fìyà jẹ Jésù àtohun tí ìyàwó rẹ̀ sọ pé òun rí lójú àlá nípa Jésù. (Mátíù 27:19) Èwo wá ni ẹ̀sùn tí wọ́n tún fi kàn án yìí, tí wọ́n ní ó ń pe ara ẹ̀ ní “ọmọ Ọlọ́run”? Lóòótọ́ Pílátù mọ̀ pé Gálílì ni Jésù ti wá. (Lúùkù 23:5-7) Síbẹ̀ ó béèrè lọ́wọ́ Jésù pé: “Ibo lo ti wá?” (Jòhánù 19:9) Àbí ṣe ni Pílátù ń rò ó pé Jésù ti wà láyé nígbà kan rí, tí Ọlọ́run wá pa dà rán an wá sáyé?
Jésù ti sọ fún Pílátù tẹ́lẹ̀ pé ọba lòun àti pé Ìjọba òun kì í ṣe apá kan ayé yìí. Jésù mọ̀ pé kò pọn dandan kóun tún máa ṣàlàyé ọ̀rọ̀ yẹn, torí náà kò sọ nǹkan kan. Ṣe ló dà bíi pé Jésù kan Pílátù lábùkù bí ò ṣe sọ̀rọ̀ yẹn, ni Pílátù bá fi ìgbéraga sọ pé: “Ṣé o ò fẹ́ bá mi sọ̀rọ̀ ni? Àbí o ò mọ̀ pé mo ní àṣẹ láti tú ọ sílẹ̀, mo sì tún ní àṣẹ láti pa ọ́?”—Jòhánù 19:10.
Jésù wá sọ pé: “O ò lè ní àṣẹ kankan lórí mi àfi tí a bá fún ọ láṣẹ látòkè. Ìdí nìyẹn tí ẹ̀ṣẹ̀ ọkùnrin tó fi mí lé ọ lọ́wọ́ fi tóbi jù.” (Jòhánù 19:11) Kì í ṣe ẹnì kan péré ni Jésù ní lọ́kàn nígbà tó sọ ọ̀rọ̀ yẹn. Ohun tó sọ fi hàn pé Káyáfà, àwọn alátìlẹ́yìn rẹ̀ àti Júdásì Ìsìkáríọ́tù ló ní lọ́kàn, ẹ̀bi gbogbo wọn pọ̀ ju ti Pílátù lọ.
Ọ̀rọ̀ Jésù jọ Pílátù lójú, ó rí i pé ọkàn ẹ̀ balẹ̀, ó wá ń bẹ̀rù pé ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ló ti wá lóòótọ́. Torí náà, Pílátù ń wá bó ṣe máa tú Jésù sílẹ̀ lẹ́ẹ̀kan sí i. Làwọn Júù bá tún mẹ́nu ba ohun míì tó dẹ́rù ba Pílátù. Wọ́n halẹ̀ mọ́ ọn pé: “Tí o bá tú ọkùnrin yìí sílẹ̀, o kì í ṣe ọ̀rẹ́ Késárì. Ṣe ni gbogbo ẹni tó bá pe ara rẹ̀ ní ọba ń ta ko Késárì.”—Jòhánù 19:12.
Ni gómìnà yìí bá mú Jésù wá síta lẹ́ẹ̀kan sí i, ó jókòó sórí ìjókòó ìdájọ́, ó wá sọ fáwọn èèyàn náà pé: “Ẹ wò ó! Ọba yín nìyí!” Àmọ́ ọ̀rọ̀ yìí ò tíì sú àwọn Júù yẹn. Ṣe ni wọ́n ń kígbe pé: “Mú un lọ! Mú un lọ! Kàn án mọ́gi!” Pílátù wá bi wọ́n pé: “Ṣé kí n pa ọba yín ni?” Lóòótọ́, ọjọ́ pẹ́ tí ìjọba Róòmù ti ń ni àwọn Júù lára, ìyẹn ò sì tẹ́ wọn lọ́rùn, síbẹ̀ gbogbo ẹnu làwọn olórí àlùfáà yìí fi sọ pé: “A ò ní ọba kankan àfi Késárì.”—Jòhánù 19:14, 15.
Torí pé ẹ̀rù ń ba Pílátù, ó gbà láti ṣe ohun táwọn Júù náà ń béèrè, ló bá ní kí wọ́n lọ pa Jésù. Àwọn ọmọ ogun wá bọ́ aṣọ ìlékè rírẹ̀dòdò tó wà lọ́rùn rẹ̀, wọ́n sì wọ aṣọ àwọ̀lékè rẹ̀ fún un. Ni wọ́n bá mú Jésù lọ síbi tí wọ́n ti fẹ́ pa á, wọ́n sì fi dandan mú un pé kó gbé òpó igi oró rẹ̀.
Jésù ò tíì fojú ba oorun látàárọ̀ Thursday, onírúurú nǹkan ni wọ́n sì ti fojú ẹ̀ rí. Ilẹ̀ tún ti mọ́ láàárọ̀ Friday Nísàn 14. Torí náà, bó ṣe ń gbé òpó igi oró náà lọ, agbára ẹ̀ tán. Àwọn ọmọ ogun wá rí ọkùnrin kan tó ń jẹ́ Símónì tó wá láti Kírénè nílẹ̀ Áfíríkà tó ń kọjá lọ, wọ́n sì fipá mú un pé kó bá Jésù gbé òpó igi oró náà. Ọ̀pọ̀ èèyàn ló ń tẹ̀ lé wọn nígbà tí wọ́n ń mú Jésù lọ, ohun tó ṣẹlẹ̀ sí Jésù yìí kó ẹ̀dùn ọkàn bá àwọn kan lára àwọn èèyàn náà, wọn wá bẹ̀rẹ̀ sí í sunkún.
Ni Jésù bá sọ fáwọn obìnrin tó ń sunkún pé: “Ẹ̀yin ọmọbìnrin Jerúsálẹ́mù, ẹ má sunkún torí mi mọ́. Kàkà bẹ́ẹ̀, ẹ sunkún torí ara yín àti àwọn ọmọ yín; torí ẹ wò ó! ọjọ́ ń bọ̀ tí àwọn èèyàn máa sọ pé, ‘Aláyọ̀ ni àwọn àgàn, àwọn ilé ọlẹ̀ tí kò bímọ àti àwọn ọmú tí ọmọ kò mu!’ Wọ́n á wá bẹ̀rẹ̀ sí í sọ fún àwọn òkè ńláńlá pé, ‘Ẹ wó lù wá!’ àti fún àwọn òkè kéékèèké pé, ‘Ẹ bò wá mọ́lẹ̀!’ Tí wọ́n bá ṣe àwọn nǹkan yìí nígbà tí igi ṣì tutù, kí ló máa ṣẹlẹ̀ nígbà tó bá rọ?”—Lúùkù 23:28-31.
Àwọn Júù ni Jésù ń darí ọ̀rọ̀ rẹ̀ sí. Orílẹ̀-èdè yẹn ló dà bí igi tó ti ń kú lọ, àmọ́ torí pé Jésù àtàwọn díẹ̀ kan tí wọ́n nígbàgbọ́ nínú rẹ̀ ṣì wà láàárín àwọn Júù yẹn ló ṣe dà bíi pé igi yẹn ṣì tutù díẹ̀. Nígbà tí Jésù àtàwọn ọmọ ẹ̀yìn ẹ̀ bá kúrò láàárín wọn, wọ́n máa dà bí igi tó ti rọ tí ò ní pẹ́ kú, torí pé Ọlọ́run ti pa wọ́n tì. Àwọn èèyàn yẹn máa sunkún gan-an tí Ọlọ́run bá lo àwọn ọmọ ogun Róòmù láti mú ìdájọ́ rẹ̀ wá sórí wọn.
-
-
Ọba Kan Ń Jìyà Láìṣẹ̀ Lórí Òpó IgiJésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
-
-
ORÍ 131
Ọba Kan Ń Jìyà Láìṣẹ̀ Lórí Òpó Igi
MÁTÍÙ 27:33-44 MÁÀKÙ 15:22-32 LÚÙKÙ 23:32-43 JÒHÁNÙ 19:17-24
WỌ́N KAN JÉSÙ MỌ́ ÒPÓ IGI ORÓ
ÀWỌN ÈÈYÀN FI JÉSÙ ṢE YẸ̀YẸ́ TORÍ ÀKỌLÉ TÍ WỌ́N GBÉ SÓRÍ RẸ̀
JÉSÙ ṢÈLÉRÍ FÚN ỌKÙNRIN KAN PÉ Ó MÁA WÀ NÍNÚ PÁRÁDÍSÈ
Àwọn ọmọ ogun mú Jésù àtàwọn olè méjì tí wọ́n fẹ́ pa lọ síbì kan tó wà nítòsí ìlú tí wọ́n ti gbọ́ ẹjọ́ Jésù. Gọ́gọ́tà tàbí Ibi Agbárí ni wọ́n ń pe ibẹ̀, àwọn èèyàn sì lè máa wo ohun tó ń ṣẹlẹ̀ níbẹ̀ “láti ọ̀ọ́kán.”—Máàkù 15:40.
Wọ́n bọ́ aṣọ Jésù àtàwọn olè náà. Wọ́n wá fún wọn ní wáìnì tí wọ́n pò pọ̀ mọ́ òjíá àti òróòro. Ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé àwọn obìnrin kan ní Jerúsálẹ́mù ló ṣe wáìnì náà kí àwọn tí wọ́n fẹ́ pa má bàa mọ ìrora náà lára, àwọn ọmọ ogun Róòmù ò sì ní kí wọ́n má fún wọn. Àmọ́ nígbà tí Jésù tọ́ ọ wò, kò mu ún. Kí nìdí tí ò fi mu ún? Jésù fẹ́ kí ọpọlọ òun máa ṣiṣẹ́ dáadáa kóun lè fọkàn sí gbogbo ohun tó ń ṣẹlẹ̀ lásìkò tó ń dojú kọ àdánwò tó le yìí. Ó fẹ́ jẹ́ olóòótọ́ sí Jèhófà dójú ikú.
Lẹ́yìn náà, àwọn ọmọ ogun tẹ́ Jésù sórí òpó yẹn kí wọ́n lè kàn án. (Máàkù 15:25) Wọ́n wá bẹ̀rẹ̀ sí í kan ìṣó mọ́ ọwọ́ àti ẹsẹ̀ rẹ̀, bí ìṣó ṣe ń ya ẹran àti iṣan ara rẹ̀ ni ìrora rẹ̀ ń pọ̀ sí i. Ìrora yẹn wá lágbára sí i nígbà tí wọ́n gbé òpó náà sókè torí ìṣó nìkan ló gbé ara Jésù dúró, ìyẹn sì túbọ̀ ń ya ojú ọgbẹ́ táwọn ìṣó náà ti dá sí i lára. Síbẹ̀, Jésù ò bẹ̀rẹ̀ sí í sọ̀rọ̀ burúkú sáwọn ọmọ ogun náà. Kàkà bẹ́ẹ̀, ó gbàdúrà pé: “Baba, dárí jì wọ́n, torí wọn ò mọ ohun tí wọ́n ń ṣe.”—Lúùkù 23:34.
Àwọn ará Róòmù sábà máa ń gbé àkọlé sórí ọ̀daràn tí wọ́n bá fẹ́ pa, káwọn èèyàn lè mọ ẹ̀ṣẹ̀ tẹ́ni náà dá. Torí náà, Pílátù ní kí wọ́n gbé àkọlé kan sórí Jésù, ohun tó kọ síbẹ̀ ni: “Jésù Ará Násárẹ́tì Ọba Àwọn Júù.” Ó rọrùn fún ọ̀pọ̀ èèyàn láti kà á torí pé ó kọ ọ́ ní èdè Hébérù, Látìn àti èdè Gíríìkì. Ohun tí Pílátù kọ yìí fi hàn pé kò fara mọ́ ohun táwọn Júù ní kó ṣe, pé àfi dandan kó pa Jésù. Àmọ́ ẹ̀rù ba àwọn olórí àlùfáà nígbà tí wọ́n rí ohun tí Pílátù kọ, wọ́n wá sọ fún un pé: “Má kọ ọ́ pé, ‘Ọba Àwọn Júù,’ àmọ́ pé ó sọ pé, ‘Èmi ni Ọba Àwọn Júù.’ ” Pílátù ò fẹ́ kí wọ́n darí òun mọ́, ló bá dá wọn lóhùn pé: “Ohun tí mo ti kọ, mo ti kọ ọ́.”—Jòhánù 19:19-22.
Inú tó sì ń bí àwọn àlùfáà yẹn ló mú kí wọ́n tún sọ̀rọ̀ nípa ẹ̀sùn tí wọ́n fi kan Jésù nígbà tí wọ́n gbọ́ ẹjọ́ ẹ̀ ní ìgbìmọ̀ Sàhẹ́ndìrìn. Àwọn tó ń kọjá lọ wá bẹ̀rẹ̀ sí í mi orí wọn nígbà tí wọ́n gbọ́ àwọn ọ̀rọ̀ yìí, wọ́n sì ń fi Jésù ṣe yẹ̀yẹ́, wọ́n ń sọ pé: “Ṣíọ̀! Ìwọ tí o fẹ́ wó tẹ́ńpìlì palẹ̀, kí o sì fi ọjọ́ mẹ́ta kọ́ ọ, gba ara rẹ là, kí o sọ̀ kalẹ̀ kúrò lórí òpó igi oró.” Bákan náà, àwọn olórí àlùfáà àtàwọn akọ̀wé òfin ń sọ ọ́ láàárín ara wọn pé: “Kí Kristi, Ọba Ísírẹ́lì sọ̀ kalẹ̀ látorí òpó igi oró, ká lè rí i, ká sì gbà gbọ́.” (Máàkù 15:29-32) Àwọn olè tí wọ́n kàn mọ́gi sí ọ̀tún àti òsì Jésù pàápàá ń fi ṣe yẹ̀yẹ́, bó tiẹ̀ jẹ́ pé kì í ṣe ọ̀daràn bíi tiwọn.
Àwọn ọmọ ogun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin tó wà níbẹ̀ náà fi Jésù ṣe yẹ̀yẹ́. Ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé wáìnì kíkan tí wọ́n ń mu ni wọ́n gbé fún Jésù, bó tiẹ̀ jẹ́ pé kò lè nawọ́ gbà á. Wọ́n tún fi àkọlé tó wà lórí rẹ̀ bú u, wọ́n ní: “Tó bá jẹ́ ìwọ ni Ọba Àwọn Júù, gba ara rẹ là.” (Lúùkù 23:36, 37) Ẹ ò rí i pé ó yani lẹ́nu! Ọkùnrin tó sọ fáwọn èèyàn pé òun ni ọ̀nà, òtítọ́ àti ìyè ni wọ́n fìyà jẹ báyìí láìṣẹ̀ láìrò, tí wọ́n sì tún kàn án lábùkù. Síbẹ̀, ó mú gbogbo ẹ̀ mọ́ra, kò bú àwọn Júù tó ń wò ó, bẹ́ẹ̀ ni kò sọ̀rọ̀ sáwọn ọmọ ogun Róòmù tí wọ́n ń fi ṣe yẹ̀yẹ́, kò sì dẹ́bi fáwọn ọ̀daràn méjèèjì tí wọ́n kàn mọ́gi sẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀.
Làwọn ọmọ ogun tó wà níbẹ̀ bá mú aṣọ àwọ̀lékè Jésù, wọ́n sì pín in sí ọ̀nà mẹ́rin. Wọ́n wá ṣẹ́ kèké kí wọ́n lè pinnu ẹni tó máa mú ọ̀kọ̀ọ̀kan. Àmọ́ aṣọ àwọ̀tẹ́lẹ̀ Jésù ṣàrà ọ̀tọ̀, kò “ní ojú rírán, ṣe ni wọ́n hun ún látòkè délẹ̀.” Torí náà, àwọn ọmọ ogun yẹn sọ pé: “Ẹ má ṣe jẹ́ ká ya á, àmọ́ ẹ jẹ́ ká fi kèké pinnu ti ẹni tó máa jẹ́.” Ìyẹn sì mú ohun tó wà nínú Ìwé Mímọ́ ṣẹ pé: “Wọ́n pín ẹ̀wù mi láàárín ara wọn, wọ́n sì ṣẹ́ kèké nítorí aṣọ mi.”—Jòhánù 19:23, 24; Sáàmù 22:18.
Nígbà tó yá, ọ̀kan lára àwọn ọ̀daràn tí wọ́n kàn mọ́gi lẹ́gbẹ̀ẹ́ Jésù gbà pé ọba ni Jésù máa jẹ́ lóòótọ́. Torí náà, ó bá ẹnì kejì rẹ̀ wí, ó sọ fún un pé: “Ṣé o ò bẹ̀rù Ọlọ́run rárá ni, ní báyìí tó jẹ́ pé ìdájọ́ kan náà nìwọ náà gbà? Ó tọ́ sí àwa, torí pé ohun tó yẹ wá là ń gbà yìí torí àwọn ohun tí a ṣe; àmọ́ ọkùnrin yìí ò ṣe nǹkan kan tó burú.” Ó wá bẹ Jésù pé: “Rántí mi tí o bá dé inú Ìjọba rẹ.”—Lúùkù 23:40-42.
Jésù dá a lóhùn pé: “Lóòótọ́ ni mo sọ fún ọ lónìí, o máa wà pẹ̀lú mi ní Párádísè,” kì í ṣe ní Ìjọba ọ̀run. (Lúùkù 23:43) Ìlérí tó ṣe fún ọkùnrin yìí yàtọ̀ sí èyí tó ṣe fáwọn àpọ́sítélì rẹ̀ pé wọ́n máa jókòó sórí ìtẹ́ pẹ̀lú òun nínú Ìjọba ọ̀run. (Mátíù 19:28; Lúùkù 22:29, 30) Júù ni ọ̀daràn yìí, torí náà ó ṣeé ṣe kó ti gbọ́ nípa Párádísè tí Jèhófà fi Ádámù àti Éfà sí pé kí wọ́n máa gbé pẹ̀lú àwọn ọmọ wọn. Ní báyìí tí olè yẹn ti fẹ́ kú, ọkàn rẹ̀ máa balẹ̀ pé òun á wà nínú Párádísè yẹn lọ́jọ́ iwájú.
-
-
“Ó Dájú Pé Ọmọ Ọlọ́run Ni Ọkùnrin Yìí”Jésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
-
-
ORÍ 132
“Ó Dájú Pé Ọmọ Ọlọ́run Ni Ọkùnrin Yìí”
MÁTÍÙ 27:45-56 MÁÀKÙ 15:33-41 LÚÙKÙ 23:44-49 JÒHÁNÙ 19:25-30
JÉSÙ KÚ LÓRÍ ÒPÓ IGI ORÓ
ÀWỌN OHUN TÓ ṢÀRÀ Ọ̀TỌ̀ ṢẸLẸ̀ NÍGBÀ TÍ JÉSU KÚ
Ó ti di “wákàtí kẹfà” báyìí, ọ̀sán sì ti pọ́n. Ṣàdédé ni òkùnkùn ṣú bo “gbogbo ilẹ̀ náà títí di wákàtí kẹsàn-án,” ìyẹn ní nǹkan bí aago mẹ́ta ọ̀sán. (Máàkù 15:33) Kì í ṣe ọ̀sán ló dòru bí òkùnkùn yẹn ṣe ṣú tàbí pé òṣùpá ló bo oòrùn lójú. Ìgbà òṣùpá tuntun ni ọ̀sán sábà máa ń dòru, àmọ́ àsìkò Ìrékọjá tí òṣùpá máa ń ràn mọ́jú nìyí. Yàtọ̀ síyẹn, odindi wákàtí mẹ́ta ni òkùnkùn yìí fi ṣú, bẹ́ẹ̀ sì rèé ọ̀sándòru kì í ju ìṣẹ́jú mélòó kan lọ. Torí náà, ó dájú pé Ọlọ́run ló mú kí òkùnkùn yẹn ṣú!
Ẹ wo bí ohun tó ṣẹlẹ̀ yẹn ṣe máa rí lára àwọn tó ń fi Jésù ṣe yẹ̀yẹ́. Lásìkò tí òkùnkùn ṣú bolẹ̀ yẹn, àwọn obìnrin mẹ́rin kan lọ síbi òpó igi oró tí wọ́n kan Jésù mọ́. Àwọn obìnrin náà ni Màríà ìyá rẹ̀, Sàlómẹ̀, Màríà Magidalénì àti Màríà ìyá àpọ́sítélì kan tó ń jẹ́ Jémíìsì Kékeré.
Àpọ́sítélì Jòhánù wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ ìyá Jésù bó ṣe dúró sí “tòsí òpó igi oró” náà, ó dájú pé ọ̀fọ̀ ńlá ló ṣẹ obìnrin yìí. Ẹ wo bó ṣe máa rí lára Màríà bó ṣe ń wo ọmọ ẹ̀ tó ń jẹ̀rora lórí òpó igi oró. Ṣe ló dà bí ìgbà tí wọ́n fi “idà gígùn kan” gún ọkàn rẹ̀. (Jòhánù 19:25; Lúùkù 2:35) Bó tiẹ̀ jẹ́ pé Jésù ń jẹ̀rora, ó ronú nípa bó ṣe máa bójú tó ìyá rẹ̀. Ó rọra yíjú sí Jòhánù, ó sì sọ fún ìyá rẹ̀ pé: “Obìnrin, wò ó! Ọmọ rẹ!” Lẹ́yìn náà, ó yíjú sí Màríà, ó sì sọ fún Jòhánù pe: “Wò ó! Ìyá rẹ!”—Jòhánù 19:26, 27.
Ó dájú pé opó ni Màríà nígbà yẹn, torí náà Jésù ní kí ọmọ ẹ̀yìn tó fẹ́ràn gan-an máa bójú tó ìyá òun. Jésù mọ̀ pé àwọn àbúrò òun, ìyẹn àwọn ọmọ ìyá rẹ̀ ò tíì gba òun gbọ́. Ìdí nìyẹn tó fi ṣètò ẹni táá máa bójú tó ìyá ẹ̀, táá lè máa pèsè ohun tó nílò nípa tara àti nípa tẹ̀mí. Ẹ ò rí i pé àpẹẹrẹ tó dáa nìyẹn!
Nígbà tí ojú ọjọ́ mọ́lẹ̀ lẹ́yìn òkùnkùn yẹn, Jésù sọ pé: “Òùngbẹ ń gbẹ mí.” Ohun tó sọ yìí mú àsọtẹ́lẹ̀ kan ṣẹ. (Jòhánù 19:28; Sáàmù 22:15) Lójú Jésù, ṣe ló dà bí ìgbà tí Baba rẹ̀ ò dá sí i mọ́, kí wọ́n lè dán ìwà títọ́ rẹ̀ wò lẹ́kùn-ún rẹ́rẹ́. Jésù wá sọ ọ̀rọ̀ kan, ó jọ pé èdè Árámáíkì táwọn ará Gálílì ń sọ ló fi sọ ọ́, ó ké jáde pé: “Élì, Élì, làmá sàbákìtanì?” ìyẹn túmọ̀ sí, “Ọlọ́run mi, Ọlọ́run mi, kí ló dé tí o fi kọ̀ mí sílẹ̀?” Àwọn kan lára àwọn tó wà nítòsí ibẹ̀ ò lóye ohun tó sọ, ni wọ́n bá sọ pé: “Ẹ wò ó! Ó ń pe Èlíjà.” Ọ̀kan lára wọn wá sáré lọ rẹ kànrìnkàn sínú wáìnì kíkan, ó fi sórí ọ̀pá esùsú, ó sì fún un pé kó mu ún. Àmọ́ àwọn míì sọ pé: “Ẹ fi sílẹ̀! Ká wò ó bóyá Èlíjà máa wá gbé e sọ̀ kalẹ̀.”—Máàkù 15:34-36.
Jésù wá ké jáde pé: “A ti ṣe é parí!” (Jòhánù 19:30) Lóòótọ́, Jésù ti parí gbogbo ohun tí Baba rẹ̀ ní kó wá ṣe láyé. Lẹ́yìn náà, Jésù sọ pé: “Baba, ọwọ́ rẹ ni mo fi ẹ̀mí mi lé.” (Lúùkù 23:46) Jésù tipa bẹ́ẹ̀ fún Ọlọ́run ní ìwàláàyè rẹ̀, ó sì gbà pé ó máa mú kóun pa dà wà láàyè lẹ́ẹ̀kan sí i. Jésù ò ṣiyèméjì rárá, ó gbẹ́kẹ̀ lé Ọlọ́run, lẹ́yìn náà ó tẹ orí rẹ̀ ba, ó sì kú.
Bí Jésù ṣe kú báyìí, ìmìtìtì ilẹ̀ tó lágbára kan ṣẹlẹ̀, ó sì la àwọn àpáta sọ́tọ̀ọ̀tọ̀. Ìmìtìtì ilẹ̀ yìí le débi pé ó ṣí àwọn ibojì tó wà lẹ́yìn odi Jerúsálẹ́mù, ó sì da àwọn òkú tó wà nínú wọn jáde. Nígbà táwọn tó ń gba ibẹ̀ kọjá rí àwọn òkú yìí níta, wọ́n sáré wọnú “ìlú mímọ́ náà,” wọ́n sì sọ ohun tójú wọn rí fáwọn míì.—Mátíù 12:11; 27:51-53.
Ní gbàrà tí Jésù kú, aṣọ ńlá gígùn tí wọ́n fi pààlà sáàárín Ibi Mímọ́ àti Ibi Mímọ́ Jù Lọ nínú tẹ́ńpìlì Ọlọ́run ya sí méjì, látòkè dé ìsàlẹ̀. Ohun ìyanu tó ṣẹlẹ̀ yẹn fi hàn pé ìbínú Ọlọ́run wà lórí àwọn tó pa Ọmọ rẹ̀, ìyẹn ló sì jẹ́ kó ṣeé ṣe fún ọ̀pọ̀ èèyàn láti wọ ọ̀run tó jẹ́ Ibi Mímọ́ Jù Lọ.—Hébérù 9:2, 3; 10:19, 20.
Kò ṣòro láti rí ìdí tẹ́rù fi ba àwọn èèyàn yẹn. Kódà, gbogbo ohun tó ṣẹlẹ̀ yìí dẹ́rù ba ọ̀gágun tó bójú tó bí wọ́n ṣe pa Jésù, ó sọ pé: “Ó dájú pé Ọmọ Ọlọ́run ni ọkùnrin yìí.” (Máàkù 15:39) Ó ṣeé ṣe kí ọkùnrin yìí wà níbi tí Pílátù ti ń gbọ́ ẹjọ́ Jésù, nígbà táwọn aṣáájú ẹ̀sìn fẹ̀sùn kàn án pé ó ń pe ara rẹ̀ ní ọmọ Ọlọ́run. Gbogbo ohun tí ọkùnrin yìí rí ti wá mú kó gbà pé olódodo ni Jésù, ó sì dá a lójú pé Ọmọ Ọlọ́run ni lóòótọ́.
Ohun tó ṣẹlẹ̀ yìí kó ẹ̀dùn ọkàn bá ọ̀pọ̀ èèyàn, ó sì kó ìtìjú bá wọn, débi pé ṣe ni “wọ́n ń lu àyà wọn” bí wọ́n ṣe ń lọ sílé wọn. (Lúùkù 23:48) Àwọn kan ń wo ohun tó ń ṣẹlẹ̀ yìí láti ọ̀ọ́kán, àwọn obìnrin tó jẹ́ ọmọ ẹ̀yìn Jésù sì wà lára wọn, ọ̀pọ̀ lára wọn ló ti fìgbà kan rí bá a rìnrìn àjò. Ó dájú pé ohun tó ṣẹlẹ̀ yìí máa kó ẹ̀dùn ọkàn bá àwọn náà.
-
-
Wọ́n Ṣètò Òkú Jésù, Wọ́n sì Lọ Sin ÍnJésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
-
-
ORÍ 133
Wọ́n Ṣètò Òkú Jésù, Wọ́n sì Lọ Sin Ín
MÁTÍÙ 27:57–28:2 MÁÀKÙ 15:42–16:4 LÚÙKÙ 23:50–24:3 JÒHÁNÙ 19:31–20:1
WỌ́N GBÉ ARA JÉSÙ SỌ̀ KALẸ̀ LÁTORÍ ÒPÓ IGI ORÓ
WỌ́N ṢÈTÒ ÒKÚ NÁÀ KÍ WỌ́N LÈ SIN ÍN
ÀWỌN OBÌNRIN BÁ IBOJÌ NÁÀ TÓ ṢÓFO
Ọjọ́ Friday Nísàn 14 ti fẹ́rẹ̀ẹ́ parí. Sábáàtì lọjọ́ tó tẹ̀ lé e, ìyẹn Nísàn 15, ó sì máa tó bẹ̀rẹ̀ nígbà tí oòrùn bá wọ̀. Jésù ti kú báyìí, àmọ́ àwọn olè méjì tó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀ ò tíì kú ní tiwọn. Ohun tí Òfin sọ nípa ẹni tí wọ́n bá kàn mọ́gi ni pé wọn ò gbọ́dọ̀ fi òkú rẹ̀ “sílẹ̀ lórí òpó igi náà di ọjọ́ kejì,” àmọ́ wọ́n gbọ́dọ̀ sin ín “lọ́jọ́ yẹn.”—Diutarónómì 21:22, 23.
Bákan náà, àwọn Júù máa ń pe ọ̀sán Friday yìí ní àsìkò Ìpalẹ̀mọ́. Àsìkò yẹn ni wọ́n máa dáná, tí wọ́n sì máa ṣe gbogbo ohun tí wọ́n bá fẹ́ ṣe, torí tí Sábáàtì bá ti bẹ̀rẹ̀, wọn ò ní lè ṣe iṣẹ́ kankan mọ́ títí tó fi máa parí. Tí oòrùn bá ti wọ̀, Sábáàtì onípele méjì tàbí Sábáàtì “ńlá” bẹ̀rẹ̀ nìyẹn. (Jòhánù 19:31) Ìdí tí wọ́n fi pè é bẹ́ẹ̀ ni pé Nísàn 15 yìí ni ọjọ́ àkọ́kọ́ nínú ọjọ́ méje tí wọ́n fi ń ṣe Àjọyọ̀ Búrẹ́dì Aláìwú, Sábáàtì ni wọ́n sì máa ń ka ọjọ́ yẹn sí. (Léfítíkù 23:5, 6) Àmọ́ lọ́tẹ̀ yìí, ọjọ́ kìíní àjọyọ̀ yìí bọ́ sí ọjọ́ kan náà pẹ̀lú ọjọ́ Sábáàtì táwọn ọmọ Ísírẹ́lì ń pa mọ́ lọ́sọ̀ọ̀sẹ̀.
Torí náà, àwọn Júù ní kí Pílátù tètè wá bí wọ́n ṣe máa pa Jésù àtàwọn olè méjì tí wọ́n kàn mọ́gi sẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀. Ọgbọ́n wo ni wọ́n máa dá sí i? Wọ́n máa ní láti ṣẹ́ ẹsẹ̀ wọn. Ìyẹn á jẹ́ kó tètè rẹ̀ wọ́n, wọn ò sì ní lè mí mọ́. Làwọn ọmọ ogun bá lọ ṣẹ́ ẹsẹ̀ àwọn olè méjì tó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ Jésù. Àmọ́ torí pé Jésù ti kú ní tiẹ̀, wọn ò ṣẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀. Ìyẹn mú àsọtẹ́lẹ̀ tó wà nínú Sáàmù 34:20 ṣẹ, pé: “Ó ń dáàbò bo gbogbo egungun rẹ̀; kò sí ìkankan nínú wọn tí a ṣẹ́.”
Káwọn ọmọ ogun yìí lè gbà pé Jésù ti kú lóòótọ́, ọ̀kan lára wọn fi ọ̀kọ̀ gún un lẹ́gbẹ̀ẹ́, lápá ibi tí ọkàn rẹ̀ wà, “ẹ̀jẹ̀ àti omi sì tú jáde lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀.” (Jòhánù 19:34) Ohun tó ṣẹlẹ̀ yìí mú àsọtẹ́lẹ̀ míì ṣẹ nínú Ìwé Mímọ́, pé: “Wọ́n máa wo ẹni tí wọ́n gún.”—Sekaráyà 12:10.
“Ọkùnrin ọlọ́rọ̀ kan” tó ń jẹ́ Jósẹ́fù wà níbẹ̀ nígbà tí wọ́n pa Jésù, ará Arimatíà lọkùnrin yìí, ọ̀kan lára ìgbìmọ̀ Sàhẹ́ndìrìn táwọn èèyàn máa ń bọ̀wọ̀ fún sì ni. (Mátíù 27:57) ‘Èèyàn dáadáa àti olódodo’ làwọn èèyàn mọ̀ ọ́n sí, ó sì ń “retí Ìjọba Ọlọ́run.” Kódà, kò fara mọ́ bí wọ́n ṣe dá ẹjọ́ Jésù, torí ó “jẹ́ ọmọ ẹ̀yìn Jésù, àmọ́ tí kò jẹ́ káwọn èèyàn mọ̀ torí pé ó ń bẹ̀rù àwọn Júù.” (Lúùkù 23:50; Máàkù 15:43; Jòhánù 19:38) Jósẹ́fù fìgboyà béèrè lọ́wọ́ Pílátù pé kó jẹ́ kóun gbé òkú Jésù. Pílátù wá pe ọ̀gágun tó bójú tó bí wọ́n ṣe pa Jésù, ọ̀gágun náà sì jẹ́rìí sí i pé Jésù ti kú. Torí náà, Pílátù gbà kí Jósẹ́fù lọ gbé òkú náà.
Jósẹ́fù ra aṣọ ọ̀gbọ̀ tó dáa tó sì mọ́, lẹ́yìn náà ó gbé òkú Jésù sọ̀ kalẹ̀ látorí òpó igi. Ó fi aṣọ yẹn di òkú Jésù, kí wọ́n lè lọ sin ín. Nikodémù náà wà níbẹ̀, òun lẹni tó “wá sọ́dọ̀ [Jésù] ní òru.” (Jòhánù 19:39) Ó mú àdàpọ̀ òjíá àti álóé wá síbẹ̀, nǹkan bí ọgọ́rùn-ún (100) ìwọ̀n pọ́n-ùn àwọn ará Róòmù (ìyẹn nǹkan bíi dọ́là méjìdínláàádọ́rùn-ún [88]). Lẹ́yìn tí wọ́n fi àwọn èròjà yìí pa ara Jésù, wọ́n fi aṣọ wé e lọ́nà táwọn Júù ń gbà wé òkú kí wọ́n tó sin ín.
Jósẹ́fù ní ibojì kan sítòsí ibi ti wọ́n ti pa Jésù. Inú òkúta ni wọ́n gbẹ́ ibojì náà sí, wọn ò sì tẹ́ ẹnikẹ́ni síbẹ̀ rí, ibẹ̀ ni wọ́n lọ tẹ́ Jésù sí. Lẹ́yìn tí wọ́n tẹ́ ẹ síbẹ̀, wọ́n yí òkúta ńlá kan dí ẹnu ọ̀nà ibojì náà. Kíákíá ni wọ́n ṣe gbogbo ohun tí wọ́n ṣe yìí kí Sábáàtì tó bẹ̀rẹ̀. Ó ṣeé ṣe kí Màríà Magidalénì àti Màríà ìyá Jémíìsì Kékeré náà wà níbẹ̀, káwọn náà lè lọ́wọ́ sí bí wọ́n ṣe sin òkú Jésù. Lẹ́yìn tí wọ́n ṣe tán, wọ́n sáré lọ sílé láti lọ “pèsè èròjà tó ń ta sánsán àti àwọn òróró onílọ́fínńdà,” kí wọ́n lè túbọ̀ fi tọ́jú òkú Jésù lẹ́yìn tí Sábáàtì bá parí.—Lúùkù 23:56.
Nígbà tó di ọjọ́ kejì, ìyẹn ọjọ́ Sábáàtì, àwọn olórí àlùfáà àtàwọn Farisí lọ bá Pílátù, wọ́n sọ fún un pé: “A rántí ohun tí afàwọ̀rajà yẹn sọ nígbà tó ṣì wà láàyè, pé, ‘Lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́ta, a máa jí mi dìde.’ Torí náà, pàṣẹ kí wọ́n sé sàréè náà mọ́ títí di ọjọ́ kẹta, kí àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ má bàa wá jí i gbé, kí wọ́n sì sọ fún àwọn èèyàn pé, ‘A ti jí i dìde!’ Ẹ̀tàn tó gbẹ̀yìn yìí máa wá burú ju ti àkọ́kọ́ lọ.” Pílátù wá dá wọn lóhùn pé: “Ẹ mú ẹ̀ṣọ́. Ẹ lọ sé ibẹ̀ mọ́ bí ẹ bá ṣe lè ṣe é.”—Mátíù 27:63-65.
Láàárọ̀ kùtù ọjọ́ Sunday, Màríà Magidalénì, Màríà ìyá Jémíìsì àtàwọn obìnrin míì mú èròjà tó ń ta sánsán lọ síbi ibojì náà kí wọ́n lè fi tọ́jú òkú Jésù. Wọ́n ń sọ láàárín ara wọn pé: “Ta ló máa bá wa yí òkúta kúrò ní ẹnu ọ̀nà ibojì náà?” (Máàkù 16:3) Àmọ́ ìmìtìtì ilẹ̀ kan ti wáyé kí wọ́n tó dé ibẹ̀. Ọlọ́run ti rán áńgẹ́lì rẹ̀ láti yí òkúta yẹn kúrò lẹ́nu ọ̀nà ibojì náà, àwọn ẹ̀ṣọ́ ti sá lọ, ibojì náà sì ti ṣófo!
-