-
Ọlọ́run Ti Jí Jésù Dìde, Ibojì Rẹ̀ sì Ti Ṣófo!Jésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
-
-
ORÍ 134
Ọlọ́run Ti Jí Jésù Dìde, Ibojì Rẹ̀ sì Ti Ṣófo!
MÁTÍÙ 28:3-15 MÁÀKÙ 16:5-8 LÚÙKÙ 24:4-12 JÒHÁNÙ 20:2-18
ỌLỌ́RUN TI JÍ JÉSÙ DÌDE
OHUN TÓ ṢẸLẸ̀ NÍGBÀ TÀWỌN ÈÈYÀN DÉ IBI TÍ WỌ́N SIN JÉSÙ SÍ
JÉSÙ FARA HAN ONÍRÚURÚ ÈÈYÀN
Nígbà táwọn obìnrin tó lọ síbi tí wọ́n tẹ́ òkú Jésù sí débẹ̀, wọ́n rí i pé ibojì náà ṣófo. Ẹ wo bí ẹ̀rù ṣe máa bà wọ́n tó! Màríà Magidalénì wá sáré lọ bá “Símónì Pétérù àti ọmọ ẹ̀yìn kejì, ẹni tí Jésù nífẹ̀ẹ́ gan-an,” ìyẹn àpọ́sítélì Jòhánù. (Jòhánù 20:2) Àmọ́ àwọn obìnrin tó kù dúró síbi ibojì náà, wọ́n sì rí áńgẹ́lì kan, wọ́n tún rí áńgẹ́lì míì tó “wọ aṣọ funfun” nínú ibojì náà.—Máàkù 16:5.
Ọ̀kan lára àwọn áńgẹ́lì yẹn sọ fún wọn pé: “Ẹ má bẹ̀rù, torí mo mọ̀ pé Jésù tí wọ́n kàn mọ́gi lẹ̀ ń wá. Kò sí níbí, torí a ti jí i dìde, bó ṣe sọ gẹ́lẹ́. Ẹ wá wo ibi tí wọ́n tẹ́ ẹ sí. Kí ẹ tètè lọ sọ fún àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ pé a ti jí i dìde, torí ẹ wò ó! ó ń lọ sí Gálílì ṣáájú yín.” (Mátíù 28:5-7) ‛Jìnnìjìnnì bo àwọn obìnrin náà, wọn ò sì mọ ohun tí wọn ì bá ṣe,’ ni wọ́n bá sáré lọ ròyìn ohun tójú wọn rí fáwọn ọmọ ẹ̀yìn tó kù.—Máàkù 16:8.
Màríà ti sáré dé ọ̀dọ̀ Pétérù àti Jòhánù ní tiẹ̀. Ṣe ló ń mí hẹlẹhẹlẹ, ó wá sọ fún wọn pé: “Wọ́n ti gbé Olúwa kúrò nínú ibojì, a ò sì mọ ibi tí wọ́n tẹ́ ẹ sí.” (Jòhánù 20:2) Ojú ẹsẹ̀ ni Pétérù àti Jòhánù sáré lọ síbi ibojì náà. Ẹsẹ̀ Jòhánù yá ju ti Pétérù lọ, torí náà òun ló kọ́kọ́ dé ibojì yẹn. Kò wọnú ibojì náà, ó ń wò ó láti ìta, ó sì rí aṣọ tí wọ́n fi di òkú Jésù níbẹ̀.
Bí Pétérù ṣe débẹ̀, ṣe ló sáré wọnú ibojì náà lọ. Ó rí aṣọ ọ̀gbọ̀ àti aṣọ tí wọ́n fi di orí Jésù. Jòhánù wá wọlé sínú ibojì náà, ó sì gbà pé òótọ́ lohun tí Màríà sọ fún wọn. Bó tiẹ̀ jẹ́ pé onírúurú nǹkan ni Jésù ti sọ fún wọn kó tó kú, kò yé wọn pé ṣe ni Ọlọ́run jí Jésù dìde. (Mátíù 16:21) Gbogbo ohun tí wọ́n rí yà wọ́n lẹ́nu, ni wọ́n bá gbọ̀nà ilé wọn lọ. Àmọ́ Màríà tó ṣẹ̀ṣẹ̀ dé síbi ibojì náà ò kúrò níbẹ̀ ní tiẹ̀.
Àwọn obìnrin tó kù ti ń sáré lọ sọ́dọ̀ àwọn ọmọ ẹ̀yìn Jésù kí wọ́n lè sọ fún wọn pé Ọlọ́run ti jí Jésù dìde. Bí wọ́n ṣe ń lọ, Jésù pàdé wọn, ó sọ fún wọn pé: “Ẹ ǹlẹ́ o!” Làwọn obìnrin yẹn bá di ẹsẹ̀ Jésù mú, wọ́n sì “tẹrí ba fún un.” Jésù wá sọ fún wọn pé: “Ẹ má bẹ̀rù! Ẹ lọ ròyìn fún àwọn arákùnrin mi, kí wọ́n lè lọ sí Gálílì, ibẹ̀ ni wọ́n ti máa rí mi.”—Mátíù 28:9, 10.
Ṣáájú ìgbà yẹn, ìmìtìtì ilẹ̀ kan ṣẹlẹ̀ níbi ibojì yìí, àwọn áńgẹ́lì sì wá síbẹ̀. Àwọn ẹ̀ṣọ́ tó wà níbẹ̀ rí gbogbo ohun tó ṣẹlẹ̀ yìí, torí náà “jìnnìjìnnì bá wọn, wọ́n sì kú sára.” Nígbà tára wọn balẹ̀, wọ́n wọnú ìlú lọ, wọ́n sì “ròyìn gbogbo ohun tó ṣẹlẹ̀ fún àwọn olórí àlùfáà.” Àwọn olórí àlùfáà wá fi ọ̀rọ̀ náà lọ àwọn àgbààgbà Júù. Gbogbo wọn gbà láti fún àwọn ọmọ ogun yẹn lówó, kí wọ́n má bàa sọ bọ́rọ̀ náà ṣe rí gẹ́lẹ́ fáwọn èèyàn, àmọ́ wọ́n ní kí wọ́n máa sọ pé: “Àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ wá jí i gbé ní òru nígbà tí à ń sùn.”—Mátíù 28:4, 11, 13.
Ìjọba Róòmù lè pa ọmọ ogun kan tó bá ń sùn lẹ́nu iṣẹ́, torí náà àwọn àlùfáà yẹn ṣèlérí fáwọn ọmọ ogun yẹn pé: “Tí èyí [ìyẹn irọ́ tí wọ́n pa pé àwọn ń sùn lẹ́nu iṣẹ́] bá . . . dé etí gómìnà, a máa ṣàlàyé ọ̀rọ̀ náà fún un, kò ní sídìí láti da ara yín láàmú.” (Mátíù 28:14) Làwọn ọmọ ogun yẹn bá gba owó, wọ́n sì ṣe ohun táwọn àlùfáà ní kí wọ́n ṣe. Lẹ́yìn náà, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í sọ fáwọn èèyàn pé ṣe làwọn ọmọ ẹ̀yìn Jésù wá jí òkú ẹ̀ gbé, irọ́ yìí sì tàn káàkiri láàárín àwọn Júù.
Màríà Magidalénì ṣì wà níbi ibojì yẹn tó ń sunkún. Bó ṣe yọjú wo inú ibojì náà, ó rí áńgẹ́lì méjì tí wọ́n wọ aṣọ funfun! Àwọn méjèèjì jókòó síbi tí wọ́n tẹ́ Jésù sí tẹ́lẹ̀, ọ̀kan wà níbi orí, èkejì sì wà níbi ẹsẹ̀. Wọ́n wá bi Màríà pé: “Obìnrin yìí, kí ló dé tó ò ń sunkún?” Ó dá wọn lóhùn pé: “Wọ́n ti gbé Olúwa mi lọ, mi ò sì mọ ibi tí wọ́n tẹ́ ẹ sí.” Lẹ́yìn náà ó yíjú pa dà, ó tún rí ẹnì kan níwájú rẹ̀. Ẹni náà béèrè ìbéèrè táwọn áńgẹ́lì yẹn kọ́kọ́ bi í, ó wá fi kún un pé: “Ta lò ń wá?” Màríà rò pé ẹni tó ń tọ́jú ọgbà ni, torí náà ó dá a lóhùn pé: “Ọ̀gá, tó bá jẹ́ ìwọ lo gbé e kúrò, sọ ibi tí o tẹ́ ẹ sí fún mi, màá sì gbé e lọ.”—Jòhánù 20:13-15.
Màríà ò mọ̀ pé Jésù tí Ọlọ́run jí dìde lòun ń bá sọ̀rọ̀. Àmọ́ nígbà tí Jésù sọ pé: “Màríà!” ojú ẹsẹ̀ ni Màríà dá Jésù mọ̀, ó rántí bí Jésù ṣe máa ń pe òun. Inú Màríà dùn gan-an, òun náà wá pe Jésù, ó ní: “Rábónì!” (tó túmọ̀ sí “Olùkọ́!”). Àmọ́, Màríà ń bẹ̀rù pé Jésù ò ní pẹ́ fi òun sílẹ̀, torí náà ó rọ̀ mọ́ ọn. Ni Jésù bá sọ fún un pé: “Má rọ̀ mọ́ mi mọ́, torí mi ò tíì gòkè lọ sọ́dọ̀ Baba. Àmọ́ lọ bá àwọn arákùnrin mi, kí o sì sọ fún wọn pé, ‘Mò ń gòkè lọ sọ́dọ̀ Baba mi àti Baba yín àti sọ́dọ̀ Ọlọ́run mi àti Ọlọ́run yín.’ ”—Jòhánù 20:16, 17.
Màríà wá sáré lọ síbi táwọn àpọ́sítélì àtàwọn ọmọ ẹ̀yìn tó kù kóra jọ sí. Ó sọ fún wọn pé: “Mo ti rí Olúwa!” Ohun tó sọ yìí ò yàtọ̀ sóhun táwọn obìnrin tó kù ti sọ fún wọn tẹ́lẹ̀. (Jòhánù 20:18) Àmọ́, ṣe ni gbogbo ohun tí wọ́n sọ yẹn ‘dà bí ìsọkúsọ létí àwọn ọmọ ẹ̀yìn tó kù.’—Lúùkù 24:11.
-
-
Jésù Fara Han Ọ̀pọ̀ Èèyàn Lẹ́yìn Tó JíǹdeJésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
-
-
ORÍ 135
Jésù Fara Han Ọ̀pọ̀ Èèyàn Lẹ́yìn Tó Jíǹde
LÚÙKÙ 24:13-49 JÒHÁNÙ 20:19-29
JÉSÙ YỌ SÁWỌN ỌMỌ Ẹ̀YÌN LÓJÚ Ọ̀NÀ Ẹ́MÁỌ́SÌ
Ó ṢÀLÀYÉ ÌWÉ MÍMỌ́ FÁWỌN ỌMỌ Ẹ̀YÌN RẸ̀ LÉRALÉRA
TỌ́MÁSÌ Ò ṢIYÈMÉJÌ MỌ́
Ní Sunday, Nísàn 16, ara àwọn ọmọ ẹ̀yìn Jésù ò yá gágá, torí ohun tó ṣẹlẹ̀ níbi tí wọ́n sin Jésù sí ò yé wọn. (Mátíù 28:9, 10; Lúùkù 24:11) Nígbà tó yá, Kíléópà àti ọ̀kan lára àwọn ọmọ ẹ̀yìn kúrò ní Jerúsálẹ́mù, wọ́n ń lọ sí Ẹ́máọ́sì, wọ́n máa rin nǹkan bíi kìlómítà mọ́kànlá (11) kí wọ́n tó débẹ̀.
Bí wọ́n ṣe ń lọ, wọ́n jọ ń sọ àwọn nǹkan tó ti ṣẹlẹ̀. Lẹnì kan bá rìn bá wọn, ó sì bi wọ́n pé: “Àwọn ọ̀rọ̀ wo lẹ̀ ń bá ara yín fà bí ẹ ṣe ń rìn lọ?” Kíléópà dáhùn pé: “Ṣé àjèjì tó ń dá gbé ní Jerúsálẹ́mù ni ọ́ ni, tó ò fi mọ àwọn nǹkan tó ṣẹlẹ̀ lẹ́nu ọjọ́ mélòó kan yìí?” Ẹni yẹn wá béèrè pé: “Àwọn nǹkan wo?”—Lúùkù 24:17-19.
Wọ́n ní: “Àwọn nǹkan tó ṣẹlẹ̀ sí Jésù ará Násárẹ́tì, . . . àwa ń retí pé ọkùnrin yìí ni ẹni tó máa gba Ísírẹ́lì sílẹ̀.”—Lúùkù 24:19-21.
Kíléópà àti ẹnì kejì rẹ̀ wá bẹ̀rẹ̀ sí í sọ àwọn nǹkan tó ṣẹlẹ̀ lọ́jọ́ yẹn. Wọ́n sọ fún un pé àwọn obìnrin kan lọ síbi tí wọ́n sin Jésù sí, àmọ́ wọn ò bá òkú rẹ̀ níbẹ̀. Wọ́n tún sọ pé àwọn obìnrin yẹn rí ohun àrà kan tó ṣẹlẹ̀, wọ́n rí àwọn áńgẹ́lì tó sọ fún wọn pé Jésù ti jíǹde. Nígbà táwọn míì sì lọ yẹ ibojì náà wò, wọ́n “bá ibẹ̀ bí àwọn obìnrin náà ṣe sọ gẹ́lẹ́.”—Lúùkù 24:24.
Ohun tó ṣẹlẹ̀ yẹn ò yé àwọn ọmọ ẹ̀yìn méjì yìí rárá. Ni ọkùnrin yẹn bá tọ́ wọn sọ́nà, ó sì tún èrò wọn ṣe, ó fi ìdánilójú sọ fún wọn pé: “Ẹ̀yin aláìlóye, tí ọkàn yín ò tètè gba gbogbo ohun tí àwọn wòlíì sọ gbọ́! Ṣé kò pọn dandan kí Kristi jìyà àwọn nǹkan yìí, kó sì wọnú ògo rẹ̀ ni?” (Lúùkù 24:25, 26) Ó wá bẹ̀rẹ̀ sí í ṣàlàyé oríṣiríṣi nǹkan tí Ìwé Mímọ́ sọ nípa Kristi.
Nígbà tó yá, àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta dé ìtòsí Ẹ́máọ́sì. Ọ̀rọ̀ tí ọkùnrin yẹn ń sọ ń dùn mọ́ àwọn méjèèjì, ni wọ́n bá sọ fún un pé: “Dúró sọ́dọ̀ wa, torí ó ti ń di ọwọ́ alẹ́, ọjọ́ sì ti lọ.” Ó gbà láti dúró, wọ́n sì jọ jẹun. Bí wọ́n ṣe fẹ́ jẹun, ọkùnrin náà gbàdúrà, ó bu búrẹ́dì, ó sì fún wọn. Bí wọ́n ṣe dá a mọ̀ nìyẹn pé Jésù ni, ló bá pòórá. (Lúùkù 24:29-31) Ó ṣẹ̀ṣẹ̀ wá dá wọn lójú pé Jésù ti jíǹde!
Inú àwọn ọmọ ẹ̀yìn náà dùn, wọ́n ń sọ bó ṣe rí lára wọn, wọ́n ní: “Àbí ẹ ò rí i bí ọkàn wa ṣe ń jó fòfò nínú wa bó ṣe ń bá wa sọ̀rọ̀ lójú ọ̀nà, tó ń ṣàlàyé Ìwé Mímọ́ fún wa ní ẹ̀kúnrẹ́rẹ́?” (Lúùkù 24:32) Kíá ni wọ́n pa dà sí Jerúsálẹ́mù kí wọ́n lè ròyìn ohun tó ṣẹlẹ̀ fáwọn àpọ́sítélì, àmọ́ wọ́n tún rí àwọn míì lọ́dọ̀ wọn. Kí Kíléópà àti èkejì rẹ̀ tó bẹ̀rẹ̀ sí í ròyìn ohun tí wọ́n rí, wọ́n gbọ́ táwọn yòókù sọ pé: “Ní tòótọ́, a ti gbé Olúwa dìde, ó sì fara han Símónì!” (Lúùkù 24:34) Àwọn náà wá sọ bí Jésù ṣe fara hàn wọ́n. Wọ́n jẹ́rìí sí i pé Jésù ti jíǹde lóòótọ́.
Bí Jésù tún ṣe yọ sí wọn lójijì nìyẹn! Lẹ̀rù bá ba gbogbo wọn! Ó yà wọ́n lẹ́nu gan-an torí pé wọ́n ti tilẹ̀kùn pa. Ohun tó sì jẹ́ kí wọ́n tilẹ̀kùn ni pé ẹ̀rù àwọn Júù ń bà wọ́n. Àmọ́ Jésù rèé láàárín wọn yìí. Ó wá fi ohùn tútù sọ fún wọn pé: “Àlàáfíà fún yín o.” Àmọ́ ẹ̀rù ń bà wọ́n, ‘wọ́n rò pé ẹ̀mí làwọn ń rí,’ ohun tí wọ́n ń rò tẹ́lẹ̀ náà sì nìyẹn.—Lúùkù 24:36, 37; Mátíù 14:25-27.
Kí Jésù lè jẹ́ kí wọ́n mọ̀ pé wọn ò rí ìran abàmì , pé òun gangan ni wọ́n rí, ó fi ọwọ́ àti ẹsẹ̀ rẹ̀ hàn wọ́n, ó ní: “Kí ló dé tí ọkàn yín ò balẹ̀, kí sì nìdí tí ẹ fi bẹ̀rẹ̀ sí í ṣiyèméjì lọ́kàn yín? Ẹ wo ọwọ́ mi àti ẹsẹ̀ mi, kí ẹ lè mọ̀ pé èmi náà ni; ẹ fọwọ́ kàn mí kí ẹ lè rí i, torí pé ẹ̀mí ò ní ẹran ara àti egungun bí ẹ ṣe rí i pé èmi ní.” (Lúùkù 24:36-39) Lóòótọ́, inú wọn dùn gan-an, ẹnu sì yà wọ́n, àmọ́ wọ́n ṣì ń lọ́ra láti gbà gbọ́.
Jésù tún ṣe nǹkan míì kó lè jẹ́ kí wọ́n mọ̀ pé òun gangan ni. Ó bi wọ́n pé: “Ṣé ẹ ní nǹkan jíjẹ níbẹ̀?” Wọ́n fún un ní ẹja yíyan kan, ó sì jẹ ẹ́. Ó wá sọ pé: “Àwọn ọ̀rọ̀ tí mo bá yín sọ nìyí, nígbà tí mo ṣì wà lọ́dọ̀ yín [kí n tó kú], pé gbogbo ohun tí a kọ nípa mi nínú Òfin Mósè àti nínú ìwé àwọn Wòlíì àti Sáàmù gbọ́dọ̀ ṣẹ.”—Lúùkù 24:41-44.
Jésù ti ṣàlàyé ohun tí Ìwé Mímọ́ sọ fún Kíléópà àti èkejì rẹ̀, ó tún wá ṣàlàyé fún gbogbo àwọn tó kóra jọ síbẹ̀ pé: “Ohun tí a kọ nìyí: pé Kristi máa jìyà, ó sì máa dìde láàárín àwọn òkú ní ọjọ́ kẹta, àti pé ní gbogbo orílẹ̀-èdè, bẹ̀rẹ̀ láti Jerúsálẹ́mù, a máa wàásù ní orúkọ rẹ̀ pé kí àwọn èèyàn ronú pìwà dà kí wọ́n lè rí ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀. Ẹ máa jẹ́ ẹlẹ́rìí àwọn nǹkan yìí.”—Lúùkù 24:46-48.
Fún ìdí kan, Tọ́másì ò sí níbẹ̀ lọ́jọ́ yẹn. Láwọn ọjọ́ tó tẹ̀ lé e, ṣe làwọn yòókù fayọ̀ sọ fún un pé: “A ti rí Olúwa!” Àmọ́ Tọ́másì sọ pé: “Láìjẹ́ pé mo rí àpá ìṣó ní ọwọ́ rẹ̀, tí mo ki ìka mi bọ àpá ìṣó náà, tí mo sì ki ọwọ́ mi bọ ẹ̀gbẹ́ rẹ̀, mi ò ní gbà gbọ́ láé.”—Jòhánù 20:25.
Lẹ́yìn ọjọ́ kẹjọ, àwọn ọmọ ẹ̀yìn tún pàdé nínú ilé kan, wọ́n tilẹ̀kùn pa, àmọ́ Tọ́másì wà níbẹ̀ lọ́tẹ̀ yìí. Ni Jésù bá tún yọ sí wọn, ó sì kí wọn pé: “Àlàáfíà fún yín o.” Jésù wá yíjú sí Tọ́másì, ó ní: “Fi ìka rẹ síbí, kí o sì wo ọwọ́ mi, ki ọwọ́ rẹ bọ ẹ̀gbẹ́ mi, kí o má sì ṣiyèméjì mọ́, àmọ́ kí o gbà gbọ́.” Ni Tọ́másì bá kígbe pé: “Olúwa mi àti Ọlọ́run mi!” (Jòhánù 20:26-28) Ní báyìí, ó ti wá dá Tọ́másì lójú pé Jésù ti jíǹde, ó sì ti di ẹ̀dá ẹ̀mí tó jẹ́ aṣojú Jèhófà Ọlọ́run.
Jésù sọ pé: “Ṣé o ti wá gbà gbọ́ torí pé o rí mi? Aláyọ̀ ni àwọn tí kò rí, síbẹ̀ tí wọ́n gbà gbọ́.”—Jòhánù 20:29.
-