-
Wọn Ò Mú Ìlérí Wọn ṢẹÀwọn Ẹ̀kọ́ Tó O Lè Kọ́ Látinú Bíbélì
-
-
Ẹ̀KỌ́ 24
Wọn Ò Mú Ìlérí Wọn Ṣẹ
Jèhófà sọ fún Mósè pé: ‘Wá bá mi lórí òkè. Kí n lè kọ àwọn òfin mi sórí òkúta pẹlẹbẹ fún ẹ.’ Mósè gun orí òkè náà lọ, ó sì wà níbẹ̀ fún ogójì (40) ọ̀sán àti ogójì (40) òru. Ní gbogbo àsìkò yẹn, Jèhófà kọ Òfin Mẹ́wàá náà sórí òkúta pẹlẹbẹ méjì, ó sì gbé e fún Mósè.
Nígbà táwọn ọmọ Ísírẹ́lì ò tètè rí Mósè, wọ́n gbà pé ó ti pa àwọn tì. Wọ́n wá sọ fún Áárónì pé: ‘A fẹ́ kí ẹnì kan máa darí wa. Ṣe ọlọ́run kan fún wa!’ Áárónì wá sọ pé: ‘Ẹ kó àwọn wúrà yín wá.’ Ó fi iná yọ́ wúrà náà, ó sì fi ṣe ère màlúù. Àwọn èèyàn náà sọ pé: ‘Ère yìí ni Ọlọ́run wa tó kó wa jáde nílẹ̀ Íjíbítì!’ Wọ́n wá bẹ̀rẹ̀ sí í jọ́sìn ère màlúù oníwúrà náà, wọ́n sì ń ṣe àríyá. Ṣé ohun tí wọ́n ṣe yìí burú àbí kò burú? Ó burú torí pé àwọn èèyàn náà ti ṣèlérí pé Jèhófà nìkan làwọn á máa jọ́sìn. Àmọ́, wọn ò mú ìlérí wọn ṣẹ.
Jèhófà rí gbogbo ohun tó ń ṣẹlẹ̀, ó sì sọ fún Mósè pé: ‘Sọ̀ kalẹ̀ lọ bá àwọn èèyàn náà. Wọ́n ti ṣàìgbọràn sí mi, wọ́n sì ti ń bọ òrìṣà.’ Mósè wá sọ̀ kalẹ̀ látorí òkè náà pẹ̀lú àwọn òkúta pẹlẹbẹ méjì tó wà lọ́wọ́ ẹ̀.
Bó ṣe ń sún mọ́ ibi táwọn èèyàn náà wà, ó gbọ́ tí wọ́n ń kọrin. Ó tún rí i tí wọ́n ń jó tí wọ́n sì ń forí balẹ̀ fún ère màlúù náà. Inú bí Mósè gan-an. Ló bá la òkúta pẹlẹbẹ méjèèjì tó wà lọ́wọ́ ẹ̀ mọ́lẹ̀, wọ́n sì fọ́ yángá. Ẹsẹ̀kẹsẹ̀ ló ba ère màlúù náà jẹ́. Ó wá bi Áárónì pé: ‘Kí ló dé tó o jẹ́ káwọn èèyàn yìí mú kó o hùwà burúkú yìí?’ Áárónì sọ pé: ‘Má bínú. Ìwọ náà mọ ìwà àwọn èèyàn yìí. Wọ́n ní àwọn ń wá ọlọ́run, ni mo bá gba àwọn wúrà wọn, mo dà á sínú iná, òun sì ni mo fi ṣe ọmọ màlúù yìí.’ Kò yẹ kí Áárónì ṣe irú nǹkan bẹ́ẹ̀. Mósè wá pa dà sórí òkè náà, ó sì bẹ Jèhófà pé kó dárí jì wọ́n.
Jèhófà dárí ji àwọn tó ṣègbọràn nínú wọn. Ṣé ìwọ náà rí i pé ó ṣe pàtàkì pé káwọn ọmọ Ísírẹ́lì máa tẹ̀ lé Mósè tó jẹ́ aṣáájú wọn?
“Nígbàkigbà tí o bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Ọlọ́run, má fi falẹ̀, san án, nítorí inú rẹ̀ kì í dùn sí àwọn òmùgọ̀. Ohun tí o jẹ́jẹ̀ẹ́, san án.”—Oníwàásù 5:4
-
-
Wọ́n Kọ́ Àgọ́ ÌjọsìnÀwọn Ẹ̀kọ́ Tó O Lè Kọ́ Látinú Bíbélì
-
-
Ẹ̀KỌ́ 25
Wọ́n Kọ́ Àgọ́ Ìjọsìn
Nígbà tí Mósè wà lórí Òkè Sínáì, Jèhófà ní kó kọ́ àgọ́ kan táwọn ọmọ Ísírẹ́lì á ti máa jọ́sìn òun. Wọ́n á máa gbé àgọ́ náà lọ sí gbogbo ibi tí wọ́n bá fẹ́ lọ.
Jèhófà sọ pé: ‘Sọ fáwọn èèyàn náà pé kí wọ́n mú ohunkóhun tí agbára wọn bá gbé wá kí wọ́n lè fi kọ́ àgọ́ náà.’ Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì mú wúrà, fàdákà, bàbà, àwọn òkúta iyebíye àtàwọn ohun ọ̀ṣọ́ wá. Wọ́n tún mú òwú, aṣọ ọ̀gbọ̀, awọ ẹran àtàwọn nǹkan míì wá. Ohun tí wọ́n mú wá pọ̀ débi tí Mósè fi sọ fún wọn pé: ‘Ohun tẹ́ ẹ mú wá ti tó! Ẹ má ṣe mú ohunkóhun wá mọ́.’
Àwọn ọkùnrin àtàwọn obìnrin tí wọ́n mọṣẹ́ dáadáa ló kọ́ àgọ́ yìí. Jèhófà tún fún wọn lọ́gbọ́n láti ṣe iṣẹ́ náà. Àwọn kan ń ṣètò òwú tí wọ́n máa lò, àwọn míì sì ń fi òwú náà hun aṣọ. Àwọn kan ń to òkúta, wọ́n ń fi wúrà ṣe oríṣiríṣi nǹkan, wọ́n sì ń gbẹ́ igi.
Àwọn èèyàn náà kọ́ àgọ́ náà gẹ́lẹ́ bí Jèhófà ṣe ní kí wọ́n kọ́ ọ. Wọ́n ṣe aṣọ ìdábùú tó rẹwà gan-an láti fi pín àgọ́ náà sí méjì, kó lè pààlà sí Ibi Mímọ́ àti Ibi Mímọ́ Jù Lọ. Inú Ibi Mímọ́ Jù Lọ ni wọ́n gbé àpótí májẹ̀mú sí. Igi àti wúrà ni wọ́n fi ṣe é. Ọ̀pá fìtílà tí wọ́n fi wúrà ṣe, tábìlì kan àti pẹpẹ tí wọ́n ti ń sun tùràrí wà nínú Ibi Mímọ́. Báàfù bàbà kan àti pẹpẹ ńlá kan sì wà nínú àgbàlá tẹ́ńpìlì náà. Táwọn ọmọ Ísírẹ́lì bá tí ń rí àpótí májẹ̀mú yìí, wọ́n máa ń rántí ìlérí tí wọ́n ṣe fún Jèhófà láti máa ṣègbọràn sí i. Ṣé o mọ ohun tí májẹ̀mú túmọ̀ sí? Májẹ̀mú jẹ́ ìlérí àrà ọ̀tọ̀ kan téèyàn gbọ́dọ̀ fọwọ́ pàtàkì mú.
Jèhófà yan Áárónì àtàwọn ọmọkùnrin ẹ̀ láti máa ṣe isẹ́ àlùfáà nínú àgọ́ yìí. Wọ́n ní láti máa bójú tó ibẹ̀, kí wọ́n sì máa rúbọ sí Jèhófà níbẹ̀. Áárónì tó jẹ́ àlùfáà àgbà nìkan ló lẹ́tọ̀ọ́ láti wọ Ibi Mímọ́ Jù Lọ. Ẹ̀ẹ̀kan lọ́dún ló máa ń wọ ibẹ̀, ohun tó sì máa ń gbé lọ síbẹ̀ ni ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ tiẹ̀, tàwọn ẹbí ẹ̀ àti ti gbogbo Ísírẹ́lì lápapọ̀.
Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì kọ́ àgọ́ náà parí lẹ́yìn ọdún kan tí wọ́n kúrò nílẹ̀ Íjíbítì. Ní báyìí, wọ́n ti wá ní ibi tí wọ́n á ti máa jọ́sìn Jèhófà.
Jèhófà jẹ́ kí ògo ẹ̀ bo àgọ́ náà, ó sì tún mú kí ìkùukùu yọ lórí àgọ́ ìjọsìn yìí. Tí wọ́n bá ń rí ìkùukùu yẹn lórí àgọ́ náà, wọn ò ní kúrò níbi tí wọ́n wà, àmọ́ tí ìkùukùu náà bá sún sókè, wọ́n mọ̀ pé àkókò ti tó láti gbéra kúrò níbi tí wọ́n wà nìyẹn. Wọ́n á tú àgọ́ ìjọ́sìn náà palẹ̀, wọ́n á sì máa tẹ̀ lé ìkùukùu náà.
“Ni mo bá gbọ́ ohùn kan tó dún ketekete látorí ìtẹ́ náà, ó sọ pé: ‘Wò ó! Àgọ́ Ọlọ́run wà pẹ̀lú aráyé, á máa bá wọn gbé, wọ́n á sì jẹ́ èèyàn rẹ̀. Ọlọ́run fúnra rẹ̀ máa wà pẹ̀lú wọn.’”—Ìfihàn 21:3
-