ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • g 1/14 ojú ìwé 3
  • OHUN TÓ Ń LỌ LÁYÉ

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • OHUN TÓ Ń LỌ LÁYÉ
  • Jí!—2014
  • Ìsọ̀rí
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Amẹ́ríkà
  • Nàìjíríà
  • Sípéènì
  • Kárí ayé
  • Kí Nìdí Tí Àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà Kì í Fi Lo Àgbélébùú Nínú Ìjọsìn?
    Àwọn Ìbéèrè Táwọn Èèyàn Sábà Máa Ń Béèrè Nípa Ẹlẹ́rìí Jèhófà
  • Ṣé Òótọ́ Ni Jésù Kú Lórí Àgbélébùú?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2011
  • Ìdí Táwọn Kristẹni Tòótọ́ Kì Í Fi Í Lo Àgbélébùú Nínú Ìjọsìn
    Kí Ni Bíbélì Fi Kọ́ni Gan-an?
  • Kí Nìdí Táwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà Kì í Fi í Lo Àgbélébùú?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2008
Àwọn Míì
Jí!—2014
g 1/14 ojú ìwé 3

OHUN TÓ Ń LỌ LÁYÉ

Amẹ́ríkà

[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 3]

Ìwádìí kan fi hàn pé ó fẹ́rẹ̀ẹ́ jẹ́ pé ẹnì kan nínú èèyàn mẹ́ta ni kì í pọkàn pọ̀ tí wọ́n bá fẹ́ sọdá títì. Ohun tó sì máa ń fà á ni pé wọ́n máa ń gbọ́ orin bí wọ́n ṣe ń sọdá, wọ́n máa ń sọ̀rọ̀ lórí fóònù, àtàwọn nǹkan míì bẹ́ẹ̀. Ohun tó burú jù lọ tó lè fa àìpọkàn pọ̀ ni títẹ àtẹ̀jíṣẹ́ lójú títì. Ńṣe ni àwọn tó bá ń tẹ àtẹ̀jíṣẹ́ máa ń wọ́sẹ̀ rìn lójú títì nígbà tó jẹ́ pé àwọn tó bá pọkàn pọ̀ máa ń sọdá kánmọ́kánmọ́. Bákan náà, àwọn tó ń tẹ àtẹ̀jíṣẹ́ lójú títì kì í sábà kíyè sí àwọn iná tó ń darí ọkọ̀, wọ́n sábà máa ń sọdá níbi tí kò ti yẹ kí wọ́n sọdá, tàbí kí wọ́n sọdá títì láìwọ̀tún-wòsì.

Nàìjíríà

[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 3]

Àwọn tó máa ń kó àwọn obìnrin láti orílẹ̀-èdè Nàìjíríà lọ ṣiṣẹ́ nílẹ̀ Yúróòpù máa ń fipá mú káwọn obìnrin náà mulẹ̀ pé àwọn ò ní tú àṣìrí fún ẹnikẹ́ni, ojúbọ òrìṣà ni wọ́n sì ti máa ń ṣe ìmùlẹ̀ náà. Wọ́n sì máa ń dẹ́rù bà wọ́n pé tí wọ́n bá fi tú àṣírí pé iṣẹ́ aṣẹ́wó ni wọ́n ń fi wọ́n ṣe pẹ́rẹ́n, àwọn òòṣà máa fìyà jẹ wọ́n gidigidi.

Sípéènì

[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 3]

Àwọn kan tó pẹ́ tí wọ́n ti ń wáṣẹ́ kì í fi ìwé ẹ̀rí yunifásítì wọn àtàwọn ìwé ẹ̀rí míì tó fi hàn pé wọ́n kàwé dáadáa wáṣẹ́ mọ́. Ìdí tí wọ́n sì fi máa ń ṣe bẹ́ẹ̀ ni pé àwọn tó fẹ́ gbà wọ́n síṣẹ́ lè máa wò ó pé ìwé tí wọ́n kà ti pọ̀ ju iṣẹ́ tí wọ́n fẹ́ gbà wọ́n fún lọ.

Kárí ayé

[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 3]

Èéfín tó máa ń jáde látinú àwọn ohùn èlò ìdáná bí àdògán ló ń gbẹ̀mí àwọn èèyàn jù lọ láwọn orílẹ̀-èdè tó ṣẹ̀ṣẹ̀ ń gòkè àgbà. Ó tó mílíọ̀nù mẹ́rin èèyàn tó ń kú lọ́dọọdún látàrí àìsàn tí kì í jẹ́ kéeyàn lè mí dáadáa tí èéfín máa ń fà. Àwọn olùṣèwádìí sọ pé àwọn èéfín olóró tó ń jáde látara àwọn igi ìdáná tàbí àwọn àdògán eléèédú léwu gan-an ni, kò sì yàtọ̀ sí èéfín olóró tó ń jáde látara sìgá.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́