-
Kí Ọ̀rọ̀ Yọ̀ Mọ́ni Lẹ́nuJàǹfààní Nínú Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run
-
-
Ẹ̀KỌ́ 4
Kí Ọ̀rọ̀ Yọ̀ Mọ́ni Lẹ́nu
BÍ O bá ń kàwé sókè, ǹjẹ́ àwọn gbólóhùn ọ̀rọ̀ kan máa ń kọ́ ọ lẹ́nu? Tàbí nígbà tó o bá dúró níwájú àwùjọ láti sọ ọ̀rọ̀ tí a yàn fún ọ, ǹjẹ́ o sábà máa ń wá ọ̀rọ̀ tó o fẹ́ sọ tì? Bó bá ń ṣe ọ́ bẹ́ẹ̀, ìṣòro rẹ lè jẹ́ pé ọ̀rọ̀ kò yọ̀ mọ́ ọ lẹ́nu. Ńṣe lẹni tí ọ̀rọ̀ bá yọ̀ mọ́ lẹ́nu máa ń kàwé geerege, ọ̀rọ̀ àti èrò rẹ̀ yóò sì máa jáde lọ́nà tó já gaara. Ìyẹn ò túmọ̀ sí pé onítọ̀hún ò ní máa dánu dúró, tàbí pé kí ó kàn máa da ọ̀rọ̀ sílẹ̀ wuuruwu. Kì í sì í ṣe pé kì í ronú kó tó máa sọ̀rọ̀. Ọ̀rọ̀ rẹ̀ máa ń lárinrin. Àfiyèsí àrà ọ̀tọ̀ ni yíyọ̀mọ́nilẹ́nu-ọ̀rọ̀ gbà nínú Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run.
Oríṣiríṣi nǹkan ló lè fa kí ọ̀rọ̀ má yọ̀ mọ́ni lẹ́nu. Èwo nínú àwọn ohun tó tẹ̀ lé e yìí ló yẹ kó o fún ní àfiyèsí àrà ọ̀tọ̀? (1) Nígbà tó o bá ń kàwé sétígbọ̀ọ́ àwọn èèyàn, tí o bá ń bá ọ̀rọ̀ tí o kò fi bẹ́ẹ̀ mọ̀ pàdé, ìyẹn lè mú kí o máa dánu dúró. (2) Dídánudúró níhìn-ín lọ́hùn-ún lè mú kó o máa sọ̀rọ̀ lọ́nà tó ń dákú-dájí. (3) Àìmúrasílẹ̀ lè dá kún ìṣòro yẹn. (4) Lára ohun tí kì í sábà jẹ́ kí ọ̀rọ̀ yọ̀ mọ́ni lẹ́nu níwájú àwùjọ ni àìto àwọn kókó ọ̀rọ̀ bó ṣe yẹ. (5) Àìní àkójọ ọ̀rọ̀ púpọ̀ lágbárí lè mú kí èèyàn máa sọ̀rọ̀ lọ́nà tó ń dákú-dájí nítorí pé ó máa ń wá ọ̀rọ̀ tó bá ohun tó fẹ́ sọ mu tì. (6) Bó bá di pé ọ̀rọ̀ téèyàn ń tẹnu mọ́ ti pọ̀ jù, ìyẹn lè ṣàìjẹ́ kí ọ̀rọ̀ yọ̀ mọ́ni lẹ́nu. (7) Àìmọ òfin ẹ̀hun èdè tó bẹ́ẹ̀ lè dá kún ìṣòro yẹn.
Bí ọ̀rọ̀ ò bá yọ̀ mọ́ ọ lẹ́nu, àwùjọ inú Gbọ̀ngàn Ìjọba lè má dìde lọ o, àmọ́ wọn ò ní fọkàn sí ọ̀rọ̀ rẹ, nǹkan ọ̀tọ̀ pátápátá gbáà ni wọn ó sì máa rò. Nípa bẹ́ẹ̀, èyí tó pọ̀ jù lọ nínú ọ̀rọ̀ rẹ ni kò ní wọ̀ wọ́n létí.
Ṣùgbọ́n o, a ní láti ṣọ́ra kí ọ̀rọ̀ tó yẹ kó tani jí kí ó sì yọ̀ mọ́ni lẹ́nu má lọ di èyí tí à ń pariwo sọ bóyá lọ́nà tó tiẹ̀ ń dá àwùjọ lágara pàápàá. Tó bá di pé àwọn èèyàn ń ka ọ̀nà tó o gbà ń sọ̀rọ̀ sí ti ẹni tí kò kani kún tàbí sí ti ẹni tí kò fi òótọ́ inú sọ̀rọ̀, ìyẹn yóò tako ète tí o fi ń sọ̀rọ̀, nítorí pé báyìí là ń ṣe nílẹ̀ wa, èèwọ̀ ni nílẹ̀ ibòmíràn. Ó yẹ ká rántí pé bó tilẹ̀ jẹ́ pé olùbánisọ̀rọ̀ tó ní ìrírí ni àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù, síbẹ̀ “nínú àìlera àti nínú ìbẹ̀rù àti pẹ̀lú ọ̀pọ̀ ìwárìrì” ló ti bá àwọn ará Kọ́ríńtì sọ̀rọ̀ kí ó má bàa di pé ó ń pàfiyèsí tí kò yẹ sí ara rẹ̀.—1 Kọ́r. 2:3.
Àwọn Àṣà Tó Yẹ Ká Yẹra Fún. Ọ̀pọ̀ èèyàn ló ní àṣà kí wọ́n máa ṣe “ẹn-in, ẹn-in” nígbà tí wọ́n bá ń sọ̀rọ̀. Ó ti mọ́ àwọn mìíràn lára pé bí wọ́n bá fẹ́ bẹ̀rẹ̀ ọ̀rọ̀, wọ́n á kọ́kọ́ sọ pé “nísinsìnyí,” tàbí kí wọ́n máa fi ọ̀rọ̀ bí “ṣẹ́ ẹ mọ̀” tàbí “ẹ ẹ̀ rí nǹkan,” há gbogbo ọ̀rọ̀ yòówù kí wọ́n máa sọ. Bóyá o lè má mọ bí o ṣe ń lo irú ọ̀rọ̀ bẹ́ẹ̀ lemọ́lemọ́ tó. O lè dán ara rẹ wò, kí o ní kí ẹnì kan tẹ́tí sí ọ, kí ó sì máa tún gbólóhùn wọ̀nyẹn sọ nígbàkigbà tó o bá ti lò ó nínú ọ̀rọ̀ rẹ. Àbájáde rẹ̀ lè yà ọ́ lẹ́nu.
Àwọn èèyàn kan máa ń kàwé, wọn sì máa ń sọ̀rọ̀ ní àsọpadàsẹ́yìn. Ìyẹn ni pé, bí wọ́n bá bẹ̀rẹ̀ ọ̀rọ̀, wọ́n á dánu dúró lágbedeméjì ọ̀rọ̀ wọn, wọ́n á tún wá padà sọ díẹ̀, ó kéré tán, lára ohun tí wọ́n ti sọ tẹ́lẹ̀.
Àwọn mìíràn sì wà tó jẹ́ pé ọ̀rọ̀ tiwọn máa ń já geere, ṣùgbọ́n bí wọ́n bá ń bá ọ̀rọ̀ kan bọ̀, wọ́n á tún ta mọ́ ọ̀rọ̀ mìíràn lágbedeméjì ọ̀rọ̀ tí wọ́n ń bá bọ̀. Òótọ́ ni pé ọ̀rọ̀ wọn máa ń já geere, àmọ́ bí wọ́n ṣe ń yí èrò padà lójijì máa ń ṣèdíwọ́ fún yíyọ̀ tó yẹ kí ọ̀rọ̀ máa yọ̀ mọ́ wọn lẹ́nu.
Bí O Ṣe Lè Ṣàtúnṣe. Bí ìṣòro rẹ bá jẹ́ pé o máa ń wá ọ̀rọ̀ tó yẹ kó o lò tì, ńṣe ló yẹ kí o sapá gidigidi láti mọ àkójọ ọ̀rọ̀ púpọ̀ sí i. Túbọ̀ máa fojú ṣọ́ àwọn ọ̀rọ̀ tí o kò bá fi bẹ́ẹ̀ mọ̀ nínú Ilé Ìṣọ́, Jí!, tàbí àwọn ìtẹ̀jáde mìíràn tó o bá ń kà. Yẹ̀ wọ́n wò nínú ìwé atúmọ̀ èdè, wo bí wọ́n ṣe ń pè wọ́n, àti ìtumọ̀ wọn, wá mú lára wọn kún àkójọ ọ̀rọ̀ tó o ti mọ̀ sórí. Bí kò bá sí ìwé atúmọ̀ èdè lárọ̀ọ́wọ́tó rẹ, bẹ ẹnì kan tó bá mọ èdè náà sọ dáadáa pé kó ràn ọ́ lọ́wọ́.
Tí o bá sọ ọ́ dàṣà láti máa kàwé sókè déédéé, ìyẹn á jẹ́ kó o túbọ̀ ṣe dáadáa sí i. Máa ṣàkíyèsí ọ̀rọ̀ tó bá ṣòro fún ọ, kí o sì pè é sókè lọ́pọ̀ ìgbà.
Kí ìwé kíkà lè yọ̀ mọ́ ọ lẹ́nu, ó yẹ kó o mọ bí ọ̀rọ̀ inú gbólóhùn ṣe máa ń bá ara wọn rìn pọ̀. Ọ̀wọ́ ọ̀rọ̀ ni a sábà máa ń kà pa pọ̀ láti lè gbé èrò òǹkọ̀wé jáde bó ṣe yẹ. Fún ọ̀wọ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ní àfiyèsí pàtàkì. Bí ó bá jẹ́ pé sísàmì sí wọn ni yóò ràn ọ́ lọ́wọ́, sàmì sí wọn. Kì í ṣe nítorí kí o ṣáà ti pe ọ̀rọ̀ bó ṣe tọ́ nìkan lo fi ń kàwé bí kò ṣe pé kí o tún gbé èrò ibẹ̀ jáde kedere. Lẹ́yìn tí o bá ti ṣàyẹ̀wò gbólóhùn ọ̀rọ̀ kan tán, bọ́ sí òmíràn, kí o sì máa ṣe bẹ́ẹ̀ lọ títí tí wàá fi parí àyẹ̀wò ìpínrọ̀ kan délẹ̀. Mọ bí èrò ibẹ̀ ṣe so mọ́ra wọn. Lẹ́yìn náà, wá fi ìwé kíkà sókè dánra wò. Ka ìpínrọ̀ yẹn léraléra títí tí wàá fi lè kà á láìkọsẹ̀ àti láìdánudúró níbi tí kò tọ́. Lẹ́yìn náà kí o bọ́ sí àwọn ìpínrọ̀ yòókù.
Èyí tó kàn ni pé kó o wá fi kún bí o ṣe ń yára kàwé. Bí o bá ti ní òye bí ọ̀rọ̀ inú gbólóhùn ṣe máa ń bá ara wọn rìn pọ̀, wàá lè máa rí ju ọ̀rọ̀ kan ṣoṣo lọ lẹ́ẹ̀kan, wàá sì tún lè máa fọkàn ro ohun tó yẹ kó tẹ̀ lé e. Èyí á jẹ́ kó o túbọ̀ lè kàwé lọ́nà tó mọ́yán lórí.
Fífi kọ́ra láti máa kàwé geerege ní gbàrà tó o bá kọ́kọ́ fojú kàn án, jẹ́ ìdálẹ́kọ̀ọ́ tó ṣeyebíye. Bí àpẹẹrẹ, láìmúratẹ́lẹ̀ rárá, ka ẹsẹ ojoojúmọ́ tòní àti àlàyé rẹ̀ sókè; máa ka ẹsẹ ojoojúmọ́ sókè bẹ́ẹ̀ déédéé. Jẹ́ kó mọ́ ọ lára láti máa fi ojú kó ọ̀wọ́ ọ̀rọ̀ tó ń gbé èrò kọ̀ọ̀kan jáde pọ̀ dípò tí wàá fi máa wo ọ̀rọ̀ lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan.
Kí ọ̀rọ̀ lè yọ̀ mọ́ ọ lẹ́nu nígbà ìfọ̀rọ̀wérọ̀, máa ronú kó o tó sọ̀rọ̀. Máa ṣe bẹ́ẹ̀ déédéé nínú gbogbo ọ̀rọ̀ tó o bá ń sọ lójoojúmọ́. Kọ́kọ́ pinnu ohun tó o fẹ́ sọ ná àti bí o ṣe máa sọ wọ́n tẹ̀ léra wọn; lẹ́yìn náà kó o wá bẹ̀rẹ̀ sí sọ̀rọ̀. Má kàn ṣàdédé bẹ̀rẹ̀ sí sọ̀rọ̀ lọ gbuurugbu. Gbìyànjú láti máa sọ èrò kọ̀ọ̀kan délẹ̀ láìdánudúró, kí o má sì ta mọ́ èrò mìíràn lágbedeméjì ọ̀rọ̀. Bí o bá ń lo àwọn gbólóhùn kéékèèké, ìyẹn lè ràn ọ́ lọ́wọ́.
Ńṣe ló yẹ kí ọ̀rọ̀ máa wá sí ọ lẹ́nu wẹ́rẹ́ bí o bá mọ ohun tó o fẹ́ sọ gan-an. Ní pàtàkì, kò fi bẹ́ẹ̀ sídìí láti máa yan ọ̀rọ̀ pàtó tó o máa lò nínú ọ̀rọ̀ sísọ. Kódà, ká ní o fẹ́ ṣe ìdánrawò, ohun tó ti dára jù ni pé kí o kàn jẹ́ kí ohun tó o fẹ́ sọ ṣe kedere lọ́kàn rẹ, kí o wá máa ro ọ̀rọ̀ tó o máa fi gbé e jáde bí o ṣe ń sọ̀rọ̀ lọ. Bí o bá ń ṣe bẹ́ẹ̀, tí o sì ń fọkàn sí èrò tó wà lọ́kàn rẹ dípò ríronú lórí irú ọ̀rọ̀ pàtó tó ń jáde lẹ́nu rẹ, ńṣe lọ̀rọ̀ tó o máa sọ á kàn máa wá sí ọ lẹ́nu, wàá sì lè máa sọ èrò inú rẹ jáde bó ṣe rí lọ́kàn rẹ gan-an. Ṣùgbọ́n tó bá ti di pé ọ̀rọ̀ tó o máa lò ní pàtó lò ń rò dípò fífọkàn sí èrò tó o fẹ́ gbé yọ, wàá máa sọ̀rọ̀ lọ́nà tó ń dákú-dájí. Bí o bá fi kọ́ra, ó dájú pé wàá lè dẹni tí ọ̀rọ̀ yọ̀ mọ́ lẹ́nu, èyí tí í ṣe ànímọ́ pàtàkì fún sísọ̀rọ̀ àti kíkàwé lọ́nà tó múná dóko.
Nígbà tí Jèhófà yan Mósè pé kó lọ ṣojú òun lọ́dọ̀ orílẹ̀-èdè Ísírẹ́lì àti níwájú Fáráò ilẹ̀ Íjíbítì, ńṣe ni Mósè ka ara rẹ̀ sí ẹni tí kò kúnjú òṣùwọ̀n. Kí nìdí rẹ̀? Ìdí ni pé kì í ṣe ẹni tí ọ̀rọ̀ yọ̀ mọ́ lẹ́nu; bóyá ó ní ìṣòro ọ̀rọ̀ sísọ. (Ẹ́kís. 4:10; 6:12) Mósè ṣàwáwí lóríṣiríṣi, àmọ́ Ọlọ́run ò gba èyíkéyìí lára rẹ̀ wọlé. Jèhófà ní kí Áárónì lọ máa bá a gbọ̀rọ̀ sọ, àmọ́ Ó ran Mósè lọ́wọ́ láti dẹni tó ń fúnra rẹ̀ sọ̀rọ̀. Kódà, yàtọ̀ sí pé Mósè bá ẹnì kọ̀ọ̀kan àti àwùjọ kéékèèké sọ̀rọ̀, ó tún bá odindi orílẹ̀-èdè sọ̀rọ̀ léraléra lọ́nà tó múná dóko. (Diu. 1:1-3; 5:1; 29:2; 31:1, 2, 30; 33:1) Bí o bá ń sa ipá tìrẹ lójú méjèèjì láti lè dẹni tí ọ̀rọ̀ sísọ yọ̀ mọ́ lẹ́nu tí o sì gbẹ́kẹ̀ lé Jèhófà, ìwọ náà yóò lè fi ọ̀rọ̀ sísọ tìrẹ bọlá fún Ọlọ́run.
-
-
Dídánudúró Bó Ṣe YẹJàǹfààní Nínú Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run
-
-
Ẹ̀KỌ́ 5
Dídánudúró Bó Ṣe Yẹ
DÍDÁNUDÚRÓ níbi tó tọ́ ṣe kókó nígbà tí a bá ń sọ̀rọ̀. Yálà àsọyé là ń sọ o tàbí ẹnì kan là ń bá sọ̀rọ̀, ó ṣe pàtàkì pé ká dánu dúró níbi tó ti tọ́. Láìlo ìdánudúró wọ̀nyẹn, ńṣe lọ̀rọ̀ rẹ á dà bí ẹni tó ń sọ̀rọ̀ wótòwótò bí ẹyẹ ẹ̀gà dípò kó gbé èrò tó yéni kedere jáde. Lílo ìdánudúró bó ṣe yẹ á jẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ yéni yékéyéké. O sì tún lè lò ó lọ́nà tí yóò fi mú kí àwọn olùgbọ́ rẹ má ṣe gbàgbé àwọn kókó ọ̀rọ̀ rẹ.
Báwo lo ṣe lè mọ ìgbà tó yẹ kó o dánu dúró? Báwo ló ṣe yẹ kó o máa dánu dúró pẹ́ tó?
Dánu Dúró Níbi Àmì Ìpíngbólóhùn. Àmì ìpíngbólóhùn ti di apá tó ṣe pàtàkì nínú àwọn èdè tí a máa ń kọ sílẹ̀. Ó lè fi hàn pé gbólóhùn ọ̀rọ̀ kan tàbí ìbéèrè kan ti parí. Àwọn èdè kan máa ń lò ó láti fi ya ọ̀rọ̀ tó jẹ́ àyọlò sọ́tọ̀. Àwọn àmì ìpíngbólóhùn kan máa ń fi bí apá kan nínú gbólóhùn ṣe jẹ́ sí ìyókù gbólóhùn náà hàn. Bí ẹnì kan bá ń dá kàwé, yóò ti fojú ara rẹ̀ rí àwọn àmì ìpíngbólóhùn ibẹ̀. Àmọ́ bí ó bá ń kàwé sétígbọ̀ọ́ àwọn ẹlòmíràn, dandan ni kí ohùn rẹ̀ gbé ìtumọ̀ àwọn àmì ìpíngbólóhùn yòówù kó wà nínú ìwé yẹn yọ. (Fún ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ àlàyé, wo Ẹ̀kọ́ 1, “Kíkàwé Lọ́nà Tó Tọ́.”) Àìdánudúró nígbà tí àmì ìpíngbólóhùn bá fi hàn pé o yẹ bẹ́ẹ̀ lè mú kí àwọn olùgbọ́ má fi bẹ́ẹ̀ lóye ohun tó o kà tàbí kó tiẹ̀ da ìtumọ̀ ọ̀rọ̀ tó o kà rú.
Láfikún sí àmì ìpíngbólóhùn, ọ̀nà tí a gbà gbé èrò inú gbólóhùn yọ máa ń pinnu ibi tó ti yẹ kéèyàn dánu dúró. Gbajúgbajà akọrin kan sọ nígbà kan rí pé: “Mi ò mọ dùùrù tẹ̀ ju ọ̀pọ̀ atẹdùùrù lọ. Ṣùgbọ́n bí mo ṣe máa ń dáwọ́ dúró sí láàárín ọ̀rọ̀ orin ni wọ́n fi gbà mí lọ́gàá.” Bákan náà ni ti ọ̀rọ̀ sísọ ṣe jẹ́. Dídánudúró bó ṣe yẹ yóò buyì kún ọ̀rọ̀ tó o ti múra rẹ̀ dáadáa, yóò sì jẹ́ kó nítumọ̀.
Nígbà tó o bá ń múra láti kàwé sétígbọ̀ọ́ àwùjọ, o lè rí i pé á dára kí o sàmì sí ọ̀rọ̀ inú ìwé tí o máa kà. Fa ẹyọ ìlà kúkúrú kan lóòró síbi ọ̀rọ̀ tí o ti fẹ́ dánu dúró ṣíún, bóyá tó o ti máa dákẹ́ si-i lásán. Fa ìlà méjì pa pọ̀ lóòró síbi tó o ti máa dánu dúró pẹ́ díẹ̀ sí i. Bó bá di pé ọ̀nà tí wọ́n gbà kọ àwọn ibì kan fẹ́ ni ọ́ lára láti kà, tó ń mú kó o dánu dúró níbi tí kò yẹ, fi pẹ́ńsù fa ìlà kan láti fi kó àwọn ọ̀rọ̀ tó nira fún ọ yẹn pọ̀. Lẹ́yìn náà kí o wá ka àpólà ọ̀rọ̀ náà láti ìbẹ̀rẹ̀ dópin. Ọ̀pọ̀ àwọn olùbánisọ̀rọ̀ tó ti ń bá ọ̀rọ̀ sísọ bọ̀ tipẹ́ máa ń ṣe bẹ́ẹ̀.
Nínú ọ̀rọ̀ sísọ ojoojúmọ́, kì í sábà ṣòro fún ọ láti dánu dúró bó ṣe yẹ nítorí pé o kúkú ti mọ àwọn ohun tó o fẹ́ sọ. Àmọ́ tó bá ti dàṣà rẹ pé o máa ń dánu dúró lóòrèkóòrè, níbi tó yẹ àti níbi tí kò yẹ, ọ̀rọ̀ rẹ kò ní tani jí kò sì ní yéni dáadáa. A dámọ̀ràn bí o ṣe lè ṣàtúnṣe nínú Ẹ̀kọ́ 4, “Kí Ọ̀rọ̀ Yọ̀ Mọ́ni Lẹ́nu.”
Dánu Dúró fún Yíyí Èrò Padà. Tí o bá dánu dúró nígbà tó o fẹ́ ti orí kókó pàtàkì kan bọ́ sí òmíràn, á fún àwọn olùgbọ́ rẹ láǹfààní láti ronú, láti múra ọkàn wọn sílẹ̀, láti mọ̀ pé o fẹ́ mú ohun mìíràn sọ, èrò tó o tún máa sọ tẹ̀ lé e yóò sì túbọ̀ yé wọn kedere. Bí ó ti ṣe pàtàkì pé kí o rọra rìn bí o bá fẹ́ ṣẹ́ kọ́nà náà ló ṣe ṣe pàtàkì láti dánu dúró nígbà tó o bá ń ti orí èrò kan bọ́ sí òmíràn.
Ìdí kan tí àwọn olùbánisọ̀rọ̀ kan fi máa ń kánjú fò láti orí èrò kan bọ́ sórí òmíràn láìdánudúró ni pé ohun tí wọ́n fẹ́ sọ̀rọ̀ lé lórí ti pọ̀ jù. Ní ti àwọn kan, ọ̀nà ìgbàsọ̀rọ̀ wọn ojoojúmọ́ ló bá wọn débẹ̀. Ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé bí gbogbo àwọn tó wà yí wọn ká pẹ̀lú ṣe ń sọ̀rọ̀ nìyẹn. Àmọ́ ìyẹn kì í jẹ́ kéèyàn lè kọ́ni lọ́nà tó múná dóko. Bí ohun tó o fẹ́ sọ bá ṣe pàtàkì, tí o kò sì fẹ́ kí àwọn tó gbọ́ ọ gbàgbé, ńṣe ni kó o kúkú fara balẹ̀ dáadáa láti mú kí ọ̀rọ̀ yẹn ṣe kedere. Mọ̀ dájú pé ìdánudúró ṣe pàtàkì fún ọ̀rọ̀ tó bá máa gbin èrò tó ṣe kedere síni lọ́kàn.
Bí o bá máa lo ìlapa èrò láti fi sọ ọ̀rọ̀ rẹ, ó yẹ kí o ṣètò ọ̀rọ̀ rẹ lọ́nà tó jẹ́ pé ibi tó o ti máa dánu dúró láàárín àwọn kókó pàtàkì yóò ti hàn gbangba. Bó bá jẹ́ iṣẹ́ oníwèé kíkà ni iṣẹ́ rẹ, sàmì sí àwọn ibi tí o ti máa ti orí kókó pàtàkì kan bọ́ sí èyí tó tẹ̀ lé e.
Bí a ṣe ń dánu dúró nígbà tí a bá fẹ́ yí èrò padà sábà máa ń gùn ju bí a ṣe ń dánu dúró nítorí àmì ìpíngbólóhùn lọ, àmọ́, kò ní gùn débi pé kí ọ̀rọ̀ máa falẹ̀. Bí wọ́n bá gùn jù, ńṣe ló máa mú kó dà bíi pé o kò múra iṣẹ́ rẹ sílẹ̀ tó bó ṣe yẹ ló jẹ́ kó o máa fọgbọ́n wá ohun tó o tún máa sọ.
Dánu Dúró Láti Fi Tẹnu Mọ́ Ọ̀rọ̀. Ìdánudúró tí a fi ń tẹnu mọ́ ọ̀rọ̀ sábà máa ń pàfiyèsí, ìyẹn, ìdánudúró tó máa ń wà ṣáájú tàbí èyí tó máa ń wà ní kété tá a sọ gbólóhùn ọ̀rọ̀ kan tán tàbí kété tá a béèrè ìbéèrè pàtàkì kan tán. Irú ìdánudúró bẹ́ẹ̀ máa ń fún àwùjọ láǹfààní láti ronú lórí ohun tí a ṣẹ̀ṣẹ̀ sọ, tàbí kó mú kí wọ́n ti máa retí ohun tí a fẹ́ sọ. Iṣẹ́ kan náà kọ́ là ń fi méjèèjì ṣe o. Yan ọ̀nà tó bá bá a mu jù lọ fún ọ láti lò nínú méjèèjì. Ṣùgbọ́n fi í sọ́kàn pé inú kìkì àwọn gbólóhùn tó bá ṣe pàtàkì nìkan ló yẹ ká ti máa lo ìdánudúró tí a fi ń tẹnu mọ́ ọ̀rọ̀. Àìjẹ́ bẹ́ẹ̀, àwọn gbólóhùn wọ̀nyẹn kò ní rinlẹ̀ lọ́kàn àwọn olùgbọ́ rẹ.
Nígbà tí Jésù ka Ìwé Mímọ́ sétígbọ̀ọ́ àwùjọ nínú sínágọ́gù ní Násárétì, ó lo ìdánudúró lọ́nà tó múná dóko. Ó kọ́kọ́ ka iṣẹ́ tí Ọlọ́run gbé lé e lọ́wọ́ látinú àkájọ ìwé wòlíì Aísáyà. Àmọ́ kí ó tó ṣàlàyé rẹ̀, ó ká àkájọ ìwé yẹn padà, ó dá a padà fún ẹni tó ń bójú tó o, ó sì jókòó. Lẹ́yìn náà, nígbà tí gbogbo àwọn tí ń bẹ nínú sínágọ́gù ti tẹjú mọ́ ọn, ó ní: “Lónìí, ìwé mímọ́ tí ẹ ṣẹ̀ṣẹ̀ gbọ́ tán yìí ní ìmúṣẹ.”—Lúùkù 4:16-21.
Dánu Dúró Nígbà Tí Ipò Nǹkan Bá Mú Kó Yẹ Bẹ́ẹ̀. Lẹ́ẹ̀kọ̀ọ̀kan, ìdíwọ́ lè mú kó di dandan fún ọ láti dánu dúró. Ariwo ọkọ̀ tí ń kọjá lọ tàbí ọmọ tó ń sunkún lè mú kó di dandan pé kí o dánu dúró nígbà ìfọ̀rọ̀wérọ̀ pẹ̀lú onílé kan lóde ẹ̀rí. Bí ìdíwọ́ tó wáyé níbi àpéjọ kan kò bá pọ̀ jù, bóyá o kàn lè gbóhùn sókè kí o sì máa bọ́rọ̀ rẹ lọ. Ṣùgbọ́n tí ariwo yẹn bá pọ̀ gan-an tí kò sì tún tètè dáwọ́ dúró, o gbọ́dọ̀ dánu dúró. Ìdí ni pé àwọn olùgbọ́ rẹ ò tiẹ̀ ní fetí sí ọ̀rọ̀ rẹ pàápàá. Nípa bẹ́ẹ̀, dánu dúró bó ṣe yẹ, kí o lè fi mú kí àwọn olùgbọ́ rẹ jẹ ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ àǹfààní àwọn nǹkan tó lárinrin tó o fẹ́ sọ fún wọn.
Dánu Dúró Kí Olùgbọ́ Lè Fèsì. Lóòótọ́ o, ó lè máà sí ibi tí wọ́n ti dìídì sọ ọ́ nínú ọ̀rọ̀ tó o fẹ́ sọ, pé kí àwùjọ dá sí i, síbẹ̀ ó ṣe pàtàkì pé kí o fún àwùjọ láyè láti dáhùn ọ̀rọ̀ sínú ara wọn láìjẹ́ pé wọ́n dáhùn síta. Bí o bá béèrè ìbéèrè tó yẹ kó mú kí àwùjọ ronú ṣùgbọ́n tí o kò dánu dúró pẹ́ tó bó ṣe yẹ, àwọn ìbéèrè yẹn kò ní fi bẹ́ẹ̀ ṣàǹfààní bó ṣe yẹ.
Ó dájú pé kì í ṣe ìgbà téèyàn bá ń sọ̀rọ̀ lórí pèpéle nìkan ló ṣe pàtàkì pé kí èèyàn máa dánu dúró nínú ọ̀rọ̀, ó ṣe pàtàkì nígbà tí a bá ń wàásù fúnni pẹ̀lú. Ó dà bíi pé sísọ̀rọ̀ lọ gbuurugbu láìdánudúró ti mọ́ àwọn kan lára. Bí ìyẹn bá jẹ́ ìṣòro rẹ, sapá gidigidi láti fi dídánudúró nínú ọ̀rọ̀ sísọ kọ́ra. Ìjùmọ̀sọ̀rọ̀ rẹ pẹ̀lú àwọn èèyàn á túbọ̀ sunwọ̀n sí i, bẹ́ẹ̀ ni wàá lè túbọ̀ kọ́ni lọ́nà tó já fáfá lóde ẹ̀rí. Ìdánudúró ni pé kéèyàn dákẹ́ ọ̀rọ̀ fúngbà kúkúrú, bẹ́ẹ̀ òótọ́ ọ̀rọ̀ táwọn kan sọ ni pé, dídákẹ́ fúngbà díẹ̀ máa ń jẹ́ kí èèyàn ráyè sinmẹ̀dọ̀, ó ń jẹ́ kí ọ̀rọ̀ ẹni rinlẹ̀, ó ń pàfiyèsí ẹni, ó sì ń jẹ́ kí etí sinmi.
Nínú ìfọ̀rọ̀wérọ̀ ojoojúmọ́, ńṣe làwọn èèyàn jọ máa ń sọ èrò ọkàn wọn fún ara wọn. Bí o bá ń fetí sí ọ̀rọ̀ àwọn èèyàn, tí o sì nífẹ̀ẹ́ sí ohun tí wọ́n sọ, àwọn náà á fẹ́ gbọ́ tìrẹ pẹ̀lú. Èyí ń béèrè pé kí o dánu dúró pẹ́ tó, kí wọ́n lè rí àyè ṣàlàyé ara wọn.
Lóde ẹ̀rí, iṣẹ́ ìwàásù wa sábà máa ń wọni lọ́kàn dáadáa tí a bá sọ ọ́ di ìfọ̀rọ̀wérọ̀. Ọ̀pọ̀ Ẹlẹ́rìí rí i pé, tí àwọn àti onílé bá ti kíra tán, ó máa ń dára láti sọ kókó tí àwọn fẹ́ sọ̀rọ̀ lé lórí kí wọ́n sì béèrè ìbéèrè kan. Wọ́n á dánu dúró kí onílé lè fèsì, wọ́n á sì wá fi hàn pé àwọn gbọ́ ohun tí onílé wí. Nínú ìfọ̀rọ̀wérọ̀ náà, wọn lè fọ̀rọ̀ lọ onílé lọ́pọ̀ ìgbà kí ó lè sọ sí ọ̀rọ̀ náà. Wọ́n mọ̀ pé ó túbọ̀ máa ń rọrùn láti ranni lọ́wọ́ nígbà tí àwọn bá mọ ohun tí onítọ̀hún ń rò nípa kókó tí àwọn ń sọ̀rọ̀ lé lórí.—Òwe 20:5.
Lóòótọ́ o, kì í ṣe gbogbo èèyàn ló máa dáhùn sí ọ̀rọ̀ wa lọ́nà tó tẹni lọ́rùn. Ṣùgbọ́n ìyẹn kò sọ pé kí Jésù máà dánu dúró pẹ́ kí àwọn èèyàn lè ráyè sọ̀rọ̀ tiwọn, títí kan àwọn alátakò rẹ̀ pàápàá. (Máàkù 3:1-5) Bí a bá fún ẹni tá à ń bá sọ̀rọ̀ láyè láti sọ̀rọ̀, ó máa ń mú kí onítọ̀hún ronú, ó sì lè tipa bẹ́ẹ̀ sọ ohun tí ń bẹ nínú ọkàn rẹ̀. Ní tòótọ́, ọ̀kan nínú ète iṣẹ́ ìwàásù wa ni láti sọ àwọn kókó pàtàkì inú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, tí àwọn èèyàn ní láti ṣèpinnu lé lórí, ní ọ̀nà tí yóò ta ọkàn wọn jí, kí wọ́n lè ṣiṣẹ́ lórí ohun tí wọ́n gbọ́.—Héb. 4:12.
Dídánudúró bó ṣe yẹ lóde ẹ̀rí dà bí iṣẹ́ ọnà kan. Bí a bá lo ìdánudúró bó ṣe yẹ, ó máa ń mú kí ohun tí à ń sọ túbọ̀ yéni kedere, kó má sì ṣeé gbàgbé.
-
-
Títẹnumọ́ Ọ̀rọ̀ Bó Ṣe YẹJàǹfààní Nínú Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run
-
-
Ẹ̀KỌ́ 6
Títẹnumọ́ Ọ̀rọ̀ Bó Ṣe Yẹ
NÍGBÀ tí o bá ń sọ̀rọ̀ tàbí tí o bá ń kàwé sétígbọ̀ọ́ àwọn èèyàn, yàtọ̀ sí pé ó ṣe pàtàkì pé kí o pe ọ̀rọ̀ kọ̀ọ̀kan bó ṣe tọ́, ó tún jẹ́ ohun yíyẹ pé kí o tẹnu mọ́ àwọn ọ̀rọ̀ àti gbólóhùn pàtàkì tó jẹ́ kókó ọ̀rọ̀ lọ́nà tí yóò gbé èrò ibẹ̀ yọ kedere.
Títẹnumọ́ ọ̀rọ̀ bó ṣe tọ́ kò mọ sórí pé kó o kàn tẹnu mọ́ ìwọ̀nba ọ̀rọ̀ díẹ̀ tàbí kó o tẹnu mọ́ ọ̀rọ̀ púpọ̀ pàápàá. Ọ̀rọ̀ tó yẹ gan-an lo ní láti tẹnu mọ́. Bó bá jẹ́ ọ̀rọ̀ tí kò yẹ lò ń tẹnu mọ́, òye ohun tí ò ń sọ lè má ṣe kedere sí àwọn olùgbọ́ rẹ, ìyẹn sì lè mú kí wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí fọkàn ro àwọn nǹkan mìíràn. Bí ó ti wù kí ohun tí ò ń sọ wúlò tó, bí o kò bá tẹnu mọ́ ọ̀rọ̀ bó ṣe yẹ, kò ní lè ta àwùjọ jí kí wọ́n lè ṣiṣẹ́ lórí ohun tí wọ́n gbọ́.
Onírúurú ọ̀nà la tún lè gbà tẹnu mọ́ ọ̀rọ̀ síwájú sí i, a sì sábà máa ń lo àwọn ọ̀nà yẹn pa pọ̀, àwọn nìwọ̀nyí: títúbọ̀ gbóhùn sókè, fífi bí ọ̀rọ̀ ṣe rí lára hàn lọ́nà tó ṣe kedere, mímọ̀ọ́mọ̀ pe ọ̀rọ̀ ketekete lọ́kọ̀ọ̀kan, dídánudúró kó o tó sọ gbólóhùn kan tàbí lẹ́yìn tó o sọ ọ́ tán tàbí kí o tilẹ̀ ṣe méjèèjì pa pọ̀ àti nípa lílo ìfaraṣàpèjúwe àti ìrísí ojú. Nínú àwọn èdè kan, a tún lè tẹnu mọ́ ọ̀rọ̀ nípa rírẹ ohùn sílẹ̀ tàbí ká mú kí ohùn túbọ̀ rinlẹ̀. Ronú nípa irú ọ̀rọ̀ tí o fẹ́ sọ àti ibi tó o ti máa sọ ọ́, kí o wá yan ọ̀nà tó máa bá a mu jù lọ láti lò.
Nígbà tó o bá fẹ́ yan ọ̀rọ̀ tó o máa tẹnu mọ́, fi àwọn ohun tó tẹ̀ lé e yìí sọ́kàn. (1) Nínú gbogbo gbólóhùn tó o bá ń kà, ohun tó máa ń fi ọ̀rọ̀ tó o máa tẹnu mọ́ hàn kì í ṣe gbólóhùn tí ọ̀rọ̀ yẹn wà nìkan, àlàyé ọ̀rọ̀ tí ìwé yẹn ń bá bọ̀ tún wà lára ohun tí yóò fi í hàn. (2) A lè lo ìtẹnumọ́ ọ̀rọ̀ láti fi gbé ìbẹ̀rẹ̀ èrò tuntun kan yọ, yálà òun ni kókó ọ̀rọ̀ tàbí pé ó kàn tún jẹ́ ọ̀nà mìíràn tí a gbà ṣàlàyé ọ̀rọ̀. Ó sì tún lè pàfiyèsí sí ìparí àlàyé ọ̀rọ̀. (3) Olùbánisọ̀rọ̀ lè lo ìtẹnumọ́ ọ̀rọ̀ láti fi sọ bí ọ̀rọ̀ kan ṣe rí lára òun. (4) A tún lè lo ìtẹnumọ́ ọ̀rọ̀ bó ṣe yẹ láti fi gbé àwọn kókó pàtàkì inú ọ̀rọ̀ kan yọ.
Kí olùbánisọ̀rọ̀ tàbí ẹnì kan tí ń kàwé sétígbọ̀ọ́ àwùjọ tó lè lo ìtẹnumọ́ ọ̀rọ̀ ní àwọn ọ̀nà tí a sọ yìí, ọ̀rọ̀ tó ń sọ ní láti yé e yékéyéké, kí ó sì fẹ́ pé kí ọ̀rọ̀ ọ̀hún wọ àwọn olùgbọ́ òun lọ́kàn ṣinṣin. Nehemáyà 8:8 sọ̀rọ̀ nípa ìtọ́ni táwọn èèyàn gbà nígbà ayé Ẹ́sírà pé: “Wọ́n sì ń bá a lọ láti ka ìwé náà sókè, láti inú òfin Ọlọ́run tòótọ́, wọ́n ń làdí rẹ̀, wọ́n sì ń fi ìtumọ̀ sí i; wọ́n sì ń mú kí ìwé kíkà náà yéni.” Ó hàn gbangba pé àwọn tó ka Òfin Ọlọ́run tí wọ́n sì ṣàlàyé rẹ̀ nígbà yẹn lọ́hùn ún, mọ bí ó ti ṣe pàtàkì tó láti mú kí ìtumọ̀ ohun tí àwọn kà yé àwọn olùgbọ́ àwọn, kí wọ́n rántí, kí wọ́n sì fi í sílò.
Ohun Tó Lè Fa Ìṣòro. Ọ̀pọ̀ jù lọ èèyàn ló jẹ́ pé nínú ìfọ̀rọ̀wérọ̀ wọn ojoojúmọ́, wọ́n máa ń mú kí ohun tí àwọn ní lọ́kàn yéni kedere. Àmọ́ tí wọ́n bá ń ka ọ̀rọ̀ tí ẹlòmíràn kọ, á di ìṣòro fún wọn láti mọ ọ̀rọ̀ tàbí gbólóhùn tó yẹ kí wọ́n tẹnu mọ́. Ojútùú rẹ̀ ni pé kí èèyàn ti lóye ọ̀rọ̀ inú ìwé náà kedere. Ìyẹn gba fífarabalẹ̀ ṣàyẹ̀wò ọ̀rọ̀ inú ìwé yẹn dáadáa. Nípa bẹ́ẹ̀, bí a bá yàn ọ́ láti ka ìwé ní ìpàdé ìjọ, ńṣe ni kí o múra rẹ̀ sílẹ̀ dáadáa.
Àwọn kan máa ń ṣe ohun tí a lè pè ní “títẹnumọ́ ọ̀rọ̀ lóòrèkóòrè” dípò títẹnumọ́ ọ̀rọ̀ tó yẹ. Bí wọ́n bá ti kàwé lọ sàà, wọ́n á kàn tún wá ọ̀rọ̀ kan tẹnu mọ́, yálà ìtẹnumọ́ yẹn nítumọ̀ o tàbí kò ní. Àwọn mìíràn a kàn máa tẹnu mọ́ àwọn ìsọ̀ǹgbè ọ̀rọ̀ lọ ni ní tiwọn, bóyá kí wọ́n máa tẹnu mọ́ ọ̀rọ̀ atọ́kùn tàbí ọ̀rọ̀ aso-ọ̀rọ̀-pọ̀ lọ́nà tó pọ̀ jù. Bí títẹnumọ́ ọ̀rọ̀ kò bá túbọ̀ mú kí ọ̀rọ̀ wa ṣe kedere sí i, kì í pẹ́ tí yóò fi dà bí àṣà lásán tí yóò sì máa gbàfiyèsí àwùjọ.
Gbígbìyànjú láti lo ìtẹnumọ́ ọ̀rọ̀ máa ń mú kí àwọn olùbánisọ̀rọ̀ kan máa túbọ̀ gbóhùn sókè débi tá fi mú kí àwùjọ rò pé ńṣe ni olùbánisọ̀rọ̀ ń jágbe mọ́ àwọn. Ká sòótọ́, ìyẹn náà kò fi bẹ́ẹ̀ dára. Bí ọ̀nà tí olùbánisọ̀rọ̀ gbà ń tẹnu mọ́ ọ̀rọ̀ kò bá bá ọ̀nà tó ń gbà sọ̀rọ̀ mu, yóò jẹ́ kó dà bíi pé kò ka àwọn olùgbọ́ rẹ̀ kún. Ohun tó ti dùn ni pé kéèyàn kàn fi ìfẹ́ rọ àwọn olùgbọ́ rẹ̀ kí ó sì mú kí wọ́n rí i pé, yàtọ̀ sí pé ohun tí òun ń wí bá Ìwé Mímọ́ mu, ó tún bọ́gbọ́n mu pẹ̀lú!
Bí O Ṣe Lè Ṣàtúnṣe. Lọ́pọ̀ ìgbà, ẹni tó níṣòro nínú títẹnumọ́ ọ̀rọ̀ kì í mọ̀ pé òun ní in. Ẹlòmíràn ló ṣẹ̀ṣẹ̀ máa wá sọ fún un. Bó bá di pé ó yẹ kó o ṣàtúnṣe lórí èyí, alábòójútó ilé ẹ̀kọ́ yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ láti ṣe é. Ẹ̀wẹ̀, má tijú láti sọ pé kí olùbánisọ̀rọ̀ mìíràn tó gbó ṣáṣá ràn ọ́ lọ́wọ́ pẹ̀lú. Ní kí ó fara balẹ̀ fetí sí bí o ṣe ń kàwé àti bí o ṣe ń sọ̀rọ̀ kí ó sì wá dábàá àwọn ohun tí o lè ṣe láti tẹ̀ síwájú sí i.
Ní ìbẹ̀rẹ̀ pàá, ẹni tó ń fún ọ nímọ̀ràn lè dábàá pé àpilẹ̀kọ kan nínú Ilé Ìṣọ́ ni kí o lò fún ìdánrawò. Ó dájú pé yóò sọ pé kí o ṣàyẹ̀wò gbólóhùn kọ̀ọ̀kan tó wà níbẹ̀ láti fi mọ ọ̀rọ̀ àti àpólà ọ̀rọ̀ tó yẹ kí o tẹnu mọ́ kí ìtumọ̀ ọ̀rọ̀ ibẹ̀ lè tètè yéni. Ó lè rán ọ létí pé kí o fún àwọn ọ̀rọ̀ kan tí a fi lẹ́tà wínníwínní kọ ní àfiyèsí àrà ọ̀tọ̀. Rántí pé ńṣe lọ̀rọ̀ inú gbólóhùn máa ń so pọ̀ mọ́ra. Dípò kí á máa dá ẹyọ ọ̀rọ̀ kọ̀ọ̀kan tẹnu mọ́ nínú gbólóhùn, ọ̀wọ́ ọ̀rọ̀ ló sábà máa ń gba ìtẹnumọ́. Nínú èdè Yorùbá àti nínú àwọn èdè kan, a lè gba akẹ́kọ̀ọ́ níyànjú pé kó kíyè sí àmì orí ọ̀rọ̀ àti ọmọ ìdí ọ̀rọ̀ dáadáa láti fi mọ ọ̀nà tó yẹ kó gbà tẹnu mọ́ ọ̀rọ̀.
Nínú ìgbésẹ̀ tó kàn, olùgbani-nímọ̀ràn lè sọ pé kí o gbé àlàyé ọ̀rọ̀ tó gùn ju gbólóhùn ọ̀rọ̀ kan ṣoṣo yẹ̀ wò láti lè mọ ọ̀rọ̀ tó yẹ ká tẹnu mọ́. Kókó pàtàkì wo ni ìpínrọ̀ yẹn lódindi dá lé lórí? Báwo ló ṣe yẹ kí ìyẹn nípa lórí ohun tó o máa tẹnu mọ́ nínú gbólóhùn ọ̀rọ̀ kọ̀ọ̀kan tó wà níbẹ̀? Wo ẹṣin ọ̀rọ̀ àpilẹ̀kọ yẹn àti àkòrí ọ̀rọ̀ kékeré tó wà lókè ibi tí ò ń gbé yẹ̀ wò. Báwo ni ìwọ̀nyẹn ṣe kan àwọn gbólóhùn tí o yàn láti tẹnu mọ́? Gbogbo ìwọ̀nyí jẹ́ kókó tó yẹ kó o gbé yẹ̀ wò. Ṣùgbọ́n gbìyànjú láti má ṣe fi agbára tẹnu mọ́ iye ọ̀rọ̀ tó pọ̀ jù.
Yálà o máa sọ̀rọ̀ fàlàlà láìgbáralé àkọsílẹ̀ ni o tàbí ìwé lo fẹ́ kà, ó ṣeé ṣe kí ẹni tó ń fún ọ nímọ̀ràn sọ fún ọ pé kó o jẹ́ kí àlàyé ọ̀rọ̀ tó o máa ṣe lórí ibi tó o fẹ́ kà nípa lórí ọ̀nà tó o máa gbà tẹnu mọ́ ọ̀rọ̀. Ó yẹ kí o mọ ibi tí àlàyé ọ̀rọ̀ kan ti parí tàbí ibi tí ọ̀rọ̀ ti kúrò lórí kókó pàtàkì kan bọ́ sórí òmíràn. Yóò dùn mọ́ àwùjọ tí o bá pe àfiyèsí wọn sí irú àwọn ibi bẹ́ẹ̀. A lè ṣe èyí nípa títẹnumọ́ àwọn ọ̀rọ̀ bíi lákọ̀ọ́kọ́, lẹ́yìn náà, paríparì ọ̀rọ̀ yìí ni pé, nípa báyìí àti ní tòótọ́.
Ẹni tó ń fún ọ nímọ̀ràn yóò tún pe àfiyèsí rẹ sí àwọn ibi tó yẹ kó o ti fi bí ọ̀rọ̀ ṣe káni lára sí hàn. Láti lè ṣe èyí o lè tẹnu mọ́ ọ̀rọ̀ bíi, gidigidi, gan-an, pátápátá, rárá, gbọ́dọ̀, ní pàtàkì àti léraléra. Bí o bá tẹnu mọ́ wọn bẹ́ẹ̀, yóò nípa lórí ìhà tí àwọn olùgbọ́ rẹ yóò kọ sí ohun tí ò ń bá wọn sọ. A óò túbọ̀ sọ̀rọ̀ nípa èyí nínú Ẹ̀kọ́ 11, “Ohùn Tó Tura àti Ohùn Bí Nǹkan Ṣe Rí Lára.”
Láti mú kí ọ̀nà tó ò ń gbà tẹnu mọ́ ọ̀rọ̀ túbọ̀ dán mọ́rán, a óò tún gbà ọ́ níyànjú pé kí o jẹ́ kí àwọn kókó pàtàkì tó ò ń fẹ́ kí àwùjọ rántí ṣe kedere lọ́kàn rẹ. A óò máa fún èyí ní àfiyèsí síwájú sí i nígbà tí a bá dórí bí ànímọ́ yìí ṣe kan ìwé kíkà sétígbọ̀ọ́ àwùjọ nínú Ẹ̀kọ́ 7, “Títẹnumọ́ Àwọn Kókó Pàtàkì,” àti bí ó ṣe kan ọ̀rọ̀ sísọ nínú Ẹ̀kọ́ 37, “Mú Kí Kókó Ọ̀rọ̀ Fara Hàn Kedere.”
Tó bá jẹ́ pé ńṣe lò ń gbìyànjú láti rí i pé o túbọ̀ ń ṣe dáadáa sí i lóde ẹ̀rí, ńṣe ni kí o fún ọ̀nà tó o gbà ń ka Ìwé Mímọ́ ní àfiyèsí àrà ọ̀tọ̀. Jẹ́ kó mọ́ ọ lára láti máa bi ara rẹ léèrè pé, ‘Kí nìdí tí mo fi ń ka ẹsẹ yìí ná?’ Bí ẹni tó ń kọ́ni bá kàn ń pe ọ̀rọ̀ ibẹ̀ jáde lẹ́nu bó ṣe tọ́, ìyẹn nìkan kò tó. Kódà, bí ó bá ń fi bí ọ̀rọ̀ ṣe rí lára hàn nínú ìwé kíkà rẹ̀ pàápàá, ìyẹn lè máa tíì tó. Bí o bá ń dáhùn ìbéèrè ẹnì kan tàbí tí ò ń kọ́ni ní òtítọ́ pàtàkì kan, ó dára kí o tẹnu mọ́ ọ̀rọ̀ tàbí gbólóhùn ọ̀rọ̀ inú Ìwé Mímọ́ tó ti ohun tí ẹ̀ ń sọ̀rọ̀ lé lórí lẹ́yìn. Àìjẹ́ bẹ́ẹ̀, kókó ọ̀rọ̀ yẹn lè má hàn sí ẹni tí ò ń kàwé sí létí.
Níwọ̀n bí ìtẹnumọ́ ọ̀rọ̀ ti wé mọ́ kí èèyàn tẹnu mọ́ àwọn ọ̀rọ̀ àti àpólà ọ̀rọ̀ kan, ẹni tí kò ì pẹ́ tó bẹ̀rẹ̀ ọ̀rọ̀ sísọ lè wá bẹ̀rẹ̀ sí tẹnu mọ́ àwọn ọ̀rọ̀ àti àpólà ọ̀rọ̀ wọ̀nyẹn jù. Yóò wá rí bí ẹni tó ṣẹ̀ṣẹ̀ ń kọ́ bí a ṣe ń lo ohun èlò orin tó jẹ́ pé á kọ́kọ́ máa fi agbára tẹ̀ ẹ́. Àmọ́, bí ó ti ń fi dánra wò léraléra, “okùn orin” kọ̀ọ̀kan tó bá wá ń tẹ̀ á di apá kan “orin adùnyùngbà” tó ń gbé ìtumọ̀ tó wúni lórí yọ.
Bí o bá ti wá mọ àwọn kókó pàtàkì bíi mélòó kan, wàá lè jàǹfààní látinú ṣíṣàkíyèsí àwọn olùbánisọ̀rọ̀ tó ti pẹ́ lẹ́nu ọ̀rọ̀ sísọ. Kò ní pẹ́ tí wàá fi rí bí títẹnumọ́ ọ̀rọ̀ ní onírúurú ìwọ̀n tó yàtọ̀ síra ṣe wúlò gan-an. Wàá sì tún wá rí bí ó ṣe wúlò tó láti lo ìtẹnumọ́ ọ̀rọ̀ lóríṣiríṣi ọ̀nà láti fi mú kí ìtumọ̀ ọ̀rọ̀ ṣe kedere. Dídi ẹni tó mọ bí a ṣe ń tẹnu mọ́ ọ̀rọ̀ bó ṣe yẹ yóò tún mú kí bí o ṣe ń kàwé àti bí o ṣe ń sọ̀rọ̀ túbọ̀ múná dóko.
Má ṣe fi kíkọ́ ìlò ìtẹnumọ́ ọ̀rọ̀ mọ sí kìkì ìwọ̀nba ohun mélòó kan tó ṣáà ti ṣe pàtàkì. Láti lè sọ̀rọ̀ lọ́nà to mọ́yán lórí, máa bá a nìṣó láti ṣiṣẹ́ lé e lórí títí wàá fi mọ bí a ṣe ń lo ìtẹnumọ́ ọ̀rọ̀ dáadáa, débi pé bí o ṣe ń lò ó á máa dùn mọ́ àwọn èèyàn létí.
-
-
Títẹnumọ́ Àwọn Kókó PàtàkìJàǹfààní Nínú Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run
-
-
Ẹ̀KỌ́ 7
Títẹnumọ́ Àwọn Kókó Pàtàkì
KÌ Í ṣe gbólóhùn kọ̀ọ̀kan nìkan ni òǹkàwé tó dáńgájíá máa ń fún láfiyèsí, kódà kì í ṣe ìpínrọ̀ tí irú gbólóhùn bẹ́ẹ̀ ti fara hàn nìkan ló máa fún láfiyèsí. Nígbà tó bá ń kàwé, yóò ní àwọn kókó pàtàkì tó wà nínú àkójọ ọ̀rọ̀ tó fẹ́ kà jáde látòkèdélẹ̀ lọ́kàn. Èyí lá jẹ́ kó mọ ibi tó máa tẹnu mọ́.
Bí kò bá ṣe bẹ́ẹ̀, kò ní sí àwọn kókó tó máa hàn gedegbe nínú ohun tó bá kà. Kò ní sóhun tó máa fara hàn kedere. Nígbà tó bá kà á tán, ó lè ṣòro fún àwùjọ láti rántí kókó kan pàtó tó ṣe pàtàkì.
Títẹnumọ́ àwọn kókó pàtàkì bó ṣe yẹ sábà máa ń gbé àkọsílẹ̀ tí a bá ń kà látinú Bíbélì yọ. Irú ìtẹnumọ́ bẹ́ẹ̀ lè mú kí kíka àwọn ìpínrọ̀ túbọ̀ nítumọ̀ nígbà ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì inú ilé tàbí ní ìpàdé ìjọ. Ó sì ṣe pàtàkì pàápàá nígbà táa bá ń ka àsọyé tó jẹ́ ìwé kíkà, bó ṣe máa ń rí nínú àwọn àsọyé kan ní àpéjọ àgbègbè wa.
Bí O Ṣe Lè Ṣe É. Ní ilé ẹ̀kọ́, wọ́n lè yan ibì kan fún ọ láti kà nínú Bíbélì. Kí ló yẹ kí o tẹnu mọ́? Bí àkójọ ọ̀rọ̀ tó o fẹ́ kà bá dá lórí kókó pàtàkì kan tàbí ìṣẹ̀lẹ̀ pàtàkì kan, á dára pé kí o jẹ́ kí nǹkan yẹn hàn kedere.
Yálà apá tó o fẹ́ kà jẹ́ ewì tàbí àlàyé, òwe tàbí ìtàn, àwọn olùgbọ́ rẹ yóò jàǹfààní tó o bá kà á dáadáa. (2 Tím. 3:16, 17) Láti lè ṣe èyí, o gbọ́dọ̀ ronú nípa ibi tó o fẹ́ kà àtàwọn tó o fẹ́ kà á fún.
Bó o bá fẹ́ ka ìwé sókè níbi ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì kan tàbí ní ìpàdé ìjọ, kí làwọn kókó pàtàkì tó yẹ kó o tẹnu mọ́? Àwọn ìdáhùn sí ìbéèrè tó wà níbẹ̀ ni kó o kà sí àwọn kókó pàtàkì wọ̀nyẹn. Pẹ̀lúpẹ̀lù, tẹnu mọ́ àwọn kókó tó jẹ mọ́ àkọlé kékeré tí àkójọ ọ̀rọ̀ náà wà lábẹ́ rẹ̀.
Tó o bá níṣẹ́ nínú ìjọ, kò yẹ kí o kọ gbogbo ọ̀rọ̀ tó o fẹ́ sọ sórí ìwé kó o wá máa kà á. Àmọ́ ṣá o, a máa ń pèsè ìwé kíkà fún àwọn àsọyé kan nígbà àpéjọ kó lè jẹ́ pé ọ̀rọ̀ kan náà la máa gbọ́ ní àwọn àpéjọ wa, ká sì sọ wọ́n lọ́nà kan náà. Kí olùbánisọ̀rọ̀ lè tẹnu mọ́ àwọn kókó pàtàkì nínú irú ìwé kíkà bẹ́ẹ̀, ó yẹ kó kọ́kọ́ fara balẹ̀ ṣàyẹ̀wò àkójọ ọ̀rọ̀ ọ̀hún. Kí làwọn kókó pàtàkì ibẹ̀? Ó yẹ kó lè dá wọn mọ̀. Kì í ṣe àwọn èrò tó bá kàn ṣáà ti ronú pé ó dùn mọ́ni ló ti di kókó pàtàkì. Ṣùgbọ́n àwọn kókó pàtàkì yìí jẹ́ lájorí èrò tí à ń fi àkójọ ọ̀rọ̀ ọ̀hún fúnra rẹ̀ ṣàlàyé. Nígbà mìíràn, kókó pàtàkì tí a sọ ní gbólóhùn ṣókí la fi ń nasẹ̀ ìtàn tàbí àlàyé kan nínú àsọyé tó jẹ́ ìwé kíkà. Lọ́pọ̀ ìgbà, ẹ̀yìn tá a bá ti ṣàlàyé àwọn ẹ̀rí tó ti kókó pàtàkì kan lẹ́yìn ni gbólóhùn tó rinlẹ̀ yóò tó wáyé. Nígbà tí olùbánisọ̀rọ̀ bá ti dá àwọn kókó wọ̀nyí mọ̀, ó yẹ kí ó fàlà sídìí wọn nínú ìwé tó fẹ́ kà. Wọn kì í sábà pọ̀, wọ́n lè má ju mẹ́rin tàbí márùn-ún lọ. Lẹ́yìn ìyẹn, ó ní láti fi kíkà rẹ̀ dánra wò gan-an débi pé àwọn tí yóò kà á fún yóò lè tètè dá wọn mọ̀. Ìwọ̀nyí gan-an ni kókó tó yẹ kó hàn gedegbe nínú àsọyé náà. Bí ó bá tẹnu mọ́ ibi tó yẹ nígbà tó bá ń ka àkójọ ọ̀rọ̀ ọ̀hún, á ṣeé ṣe láti lè tètè rántí àwọn kókó pàtàkì wọ̀nyẹn. Ohun tó yẹ kó jẹ olùbánisọ̀rọ̀ lógún nìyẹn.
Onírúurú ọ̀nà ni olùbánisọ̀rọ̀ lè gbà tẹnu mọ́ ọ̀rọ̀ bó ṣe yẹ láti lè mú kí àwọn olùgbọ́ dá àwọn kókó pàtàkì mọ̀. Ó lè lo ìtara tó túbọ̀ pọ̀ sí i, ó lè yára tàbí kó rọra sọ ọ́, ó lè yí ìwọ̀n ohùn tó ń lò láti fi bí nǹkan ṣe rí lára hàn padà, tàbí kí ó fara ṣàpèjúwe lọ́nà tó yẹ, àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ.
-