-
Kí Lo Máa Gbádùn Láwọn Ìpàdé Wa?Àwọn Wo Ló Ń Ṣe Ìfẹ́ Jèhófà Lóde Òní?
-
-
Ẹ̀KỌ́ 5
Kí Lo Máa Gbádùn Láwọn Ìpàdé Wa?
Orílẹ̀-èdè Ajẹntínà
Orílẹ̀-èdè Sierra Leone
Orílẹ̀-èdè Belgium
Orílẹ̀-èdè Malaysia
Ọ̀pọ̀ èèyàn ni kì í lọ sí ilé ìjọsìn mọ́ torí wọn ò rí ìtọ́sọ́nà tàbí ìtùnú tí wọ́n fẹ́ níbẹ̀. Kí wá nìdí tó fi yẹ kó o lọ sí àwọn ìpàdé àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà? Kí lo máa rí níbẹ̀?
Wàá láyọ̀ pé o dara pọ̀ mọ́ àwọn èèyàn tó ní ìfẹ́ àti aájò. Ní ọgọ́rùn-ún ọdún kìíní, àwọn Kristẹni ṣètò ara wọn sí àwọn ìjọ, wọ́n sì ń ṣe àwọn ìpàdé láti jọ́sìn Ọlọ́run, láti kẹ́kọ̀ọ́ Ìwé Mímọ́ àti láti gbé ara wọn ró. (Hébérù 10:24, 25) Ìfẹ́ gbilẹ̀ gan-an láàárín wọn, wọ́n sì mọ̀ pé àwọn wà láàárín àwọn ọ̀rẹ́ tòótọ́, ìyẹn àwọn arákùnrin àti arábìnrin tí wọ́n jọ ń sin Ọlọ́run. (2 Tẹsalóníkà 1:3; 3 Jòhánù 14) Àpẹẹrẹ wọn là ń tẹ̀ lé, a sì ń láyọ̀ bíi tiwọn.
Wàá rí àǹfààní tó wà nínú kéèyàn mọ bá a ṣe lè fi àwọn ìlànà Bíbélì sílò. Àwọn ọkùnrin, obìnrin àtàwọn ọmọdé máa ń pàdé pọ̀ bíi ti ayé ìgbà tí wọ́n ń kọ Bíbélì. Àwọn olùkọ́ tó kúnjú ìwọ̀n máa ń ràn wá lọ́wọ́ láti mọ bí a ṣe lè máa fi ìlànà Bíbélì sílò ní ìgbésí ayé wa. (Diutarónómì 31:12; Nehemáyà 8:8) Gbogbo èèyàn ló lè dá sí ìjíròrò, a sì jọ máa ń kọrin, èyí ń jẹ́ ká lè sọ ìrètí tí àwa Kristẹni ní.—Hébérù 10:23.
Ìgbàgbọ́ rẹ nínú Ọlọ́run á lágbára sí i. Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù sọ fún ọ̀kan lára àwọn ìjọ tó wà nígbà ayé rẹ̀ pé: ‘Àárò yín ń sọ mí, ká lè jọ fún ara wa ní ìṣírí nípasẹ̀ ìgbàgbọ́ ẹnì kọ̀ọ̀kan wa, tiyín àti tèmi.’ (Róòmù 1:11, 12) Bá a ṣe ń pé jọ déédéé pẹ̀lú àwọn tá a jọ jẹ́ onígbàgbọ́ láwọn ìpàdé wa máa ń mú kí ìgbàgbọ́ wa lágbára, ó sì ń mú ká lè máa gbé ìgbé ayé Kristẹni.
O ò ṣe wá sí ìpàdé wa tó ń bọ̀ kí ìwọ fúnra rẹ lè rí àwọn nǹkan tá a sọ yìí? A máa fi ọ̀yàyà kí ẹ káàbọ̀. Ọ̀fẹ́ ni àwọn ìpàdé wa, a kì í gbé igbá owó.
Àpẹẹrẹ àwọn wo là ń tẹ̀ lé ní àwọn ìpàdé wa?
Àǹfààní wo la máa rí tá a bá ń lọ sí àwọn ìpàdé ìjọ?
-
-
Àǹfààní Wo La Máa Rí Tá A Bá Ń Bá Àwọn Tá A Jọ Jẹ́ Kristẹni Ṣọ̀rẹ́?Àwọn Wo Ló Ń Ṣe Ìfẹ́ Jèhófà Lóde Òní?
-
-
Ẹ̀KỌ́ 6
Àǹfààní Wo La Máa Rí Tá A Bá Ń Bá Àwọn Tá A Jọ Jẹ́ Kristẹni Ṣọ̀rẹ́?
Orílẹ̀-èdè Madagásíkà
Orílẹ̀-èdè Norway
Orílẹ̀-èdè Lẹ́bánónì
Orílẹ̀-èdè Ítálì
A máa ń lọ sí àwọn ìpàdé ìjọ déédéé, àní tó bá tiẹ̀ gba pé ká gba àárín igbó kìjikìji kọjá tàbí ká fara da ojú ọjọ́ tí kò bára dé. Láìka àwọn ìṣòro tá a ní sí àti àárẹ̀ lẹ́yìn iṣẹ́ ojoojúmọ́, kí nìdí táwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà fi máa ń rí i pé a wà pẹ̀lú àwọn tá a jọ jẹ́ onígbàgbọ́?
Ó ń gbé wa ró. Nígbà tí Pọ́ọ̀lù ń sọ nípa àwọn tá a jọ ń pàdé nínú ìjọ, ó sọ pé, ‘Ẹ jẹ́ ká gba ti ara wa rò.’ (Hébérù 10:24) Ọ̀rọ̀ yìí túmọ̀ sí “ká ronú dáadáa nípa,” ìyẹn ni pé ká mọ ara wa. Torí náà, ọ̀rọ̀ àpọ́sítélì yìí ń rọ̀ wá pé ká jẹ́ kí ọ̀rọ̀ àwọn ẹlòmíì jẹ wá lọ́kàn. Bá a ṣe túbọ̀ ń mọ àwọn ìdílé míì tá a jọ jẹ́ Kristẹni, a máa rí i pé àwọn kan lára wọn ti borí àwọn ìṣòro tó jọ tiwa, wọ́n sì lè ràn wá lọ́wọ́ láti borí tiwa.
Ó ń jẹ́ ká ní àwọn ọ̀rẹ́ àtàtà. Ní àwọn ìpàdé wa, a máa ń pé jọ pẹ̀lú àwọn arákùnrin àti arábìnrin wa, wọn kì í ṣe ẹni tá a mọ̀ lásán, ọ̀rẹ́ àtàtà ni wọ́n jẹ́. Láwọn ìgbà míì, a jọ máa ń ṣe eré ìnàjú tó dáa. Àǹfààní wo ni irú àjọṣe bẹ́ẹ̀ máa ń ṣe wá? Ó ń jẹ́ ká túbọ̀ mọyì ara wa, ó sì ń jẹ́ kí ìfẹ́ tó wà láàárín wa pọ̀ sí i. Tí àwọn ọ̀rẹ́ wa yìí bá wá níṣòro, a máa ń tètè ràn wọ́n lọ́wọ́ torí pé wọ́n ti di ọ̀rẹ́ wa àtàtà. (Òwe 17:17) Tá a bá ń fi gbogbo àwọn ará ìjọ ṣe ọ̀rẹ́, à ń fi hàn pé à ń “ṣìkẹ́ ara” wa lẹ́nì kọ̀ọ̀kan.—1 Kọ́ríńtì 12:25, 26.
A rọ̀ ẹ́ pé kó o mú àwọn tó ń ṣe ìfẹ́ Ọlọ́run lọ́rẹ̀ẹ́. Wàá rí irú ọ̀rẹ́ bẹ́ẹ̀ láàárín àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà. Jọ̀ọ́, má ṣe jẹ́ kí ohunkóhun dí ẹ lọ́wọ́ láti dara pọ̀ mọ́ wa.
Àǹfààní wo la máa rí tá a bá ń wà pẹ̀lú àwọn ará ní àwọn ìpàdé wa?
Ìgbà wo lo máa bẹ̀rẹ̀ sí í wá sí ìpàdé ìjọ wa?
-
-
Kí Là Ń Kọ́ Láwọn Ìpàdé Wa?Àwọn Wo Ló Ń Ṣe Ìfẹ́ Jèhófà Lóde Òní?
-
-
Ẹ̀KỌ́ 7
Kí Là Ń Kọ́ Láwọn Ìpàdé Wa?
Orílẹ̀-èdè New Zealand
Orílẹ̀-èdè Japan
Orílẹ̀-èdè Uganda
Orílẹ̀-èdè Lithuania
Nígbà tí ẹ̀sìn Kristẹni bẹ̀rẹ̀, ohun tí wọ́n máa ń ṣe ní àwọn ìpàdé ìjọ ni pé wọ́n máa ń kọrin, wọ́n máa ń gbàdúrà, wọ́n ń ka Ìwé Mímọ́, wọ́n sì ń jíròrò wọn, wọn ò ní àwọn àṣà ìkọ̀kọ̀ tí wọ́n ń tẹ̀ lé nínú ìsìn wọn. (1 Kọ́ríńtì 14:26) Ohun kan náà là ń ṣe láwọn ìpàdé wa.
Ẹ̀kọ́ tó wúlò látinú Bíbélì. Láwọn òpin ọ̀sẹ̀, ìjọ kọ̀ọ̀kan máa ń pé jọ láti gbọ́ Àsọyé Bíbélì fún ọgbọ̀n (30) ìṣẹ́jú, ó máa ń dá lórí bí Ìwé Mímọ́ ṣe lè mú kí ìgbésí ayé wa dára, ó sì máa ń jẹ́ ká mọ ìtumọ̀ àwọn nǹkan tó ń ṣẹlẹ̀ lásìkò yìí. Wọ́n máa ń rọ gbogbo wa pé ká gbé Bíbélì wa ká sì máa fojú bá ibi tí wọ́n ń kà lọ. Lẹ́yìn àsọyé náà, a máa ń ṣe Ìkẹ́kọ̀ọ́ “Ilé Ìṣọ́” fún wákàtí kan, a sì máa ń rọ gbogbo ará ìjọ pé kí wọ́n dá sí àpilẹ̀kọ tá à ń jíròrò lọ́sẹ̀ yẹn nínú Ilé Ìṣọ́ tó wà fún ìkẹ́kọ̀ọ́. Ìjíròrò yìí máa ń jẹ́ ká mọ bá a ṣe lè tẹ̀ lé àwọn ìlànà Bíbélì nínú ìgbé ayé wa. Àpilẹ̀kọ kan náà la máa ń kẹ́kọ̀ọ́ ní àwọn ìjọ wa tó ju ẹgbẹ̀rún lọ́nà àádọ́fà (110,000) lọ kárí ayé.
Wọ́n ń ràn wá lọ́wọ́ ká lè máa kọ́ni lọ́nà tó sunwọ̀n sí i. A tún máa ń pé jọ ní ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kan láàárín ọ̀sẹ̀ fún ìpàdé alápá mẹ́ta tí à ń pè ní Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni. Ohun tó wà nínú ìwé ìpàdé Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni la máa ń tẹ̀ lé. Apá àkọ́kọ́ lára ìpàdé náà ni Àwọn Ìṣúra Inú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, ó máa ń jẹ́ ká túbọ̀ lóye apá kan nínú Bíbélì táwọn ará ti kà ṣáájú. Lẹ́yìn ìyẹn ni Máa Lo Ara Rẹ Lẹ́nu Iṣẹ́ Ìwàásù níbi tí a ti máa ń rí àpẹẹrẹ bá a ṣe lè bá àwọn èèyàn jíròrò látinú Bíbélì. Agbani-nímọ̀ràn kan wà tó máa ń kíyè sí ọ̀rọ̀ wa kó lè ràn wá lọ́wọ́ láti sunwọ̀n sí i nínú bá a ṣe ń kàwé àti bá a ṣe ń sọ̀rọ̀. (1 Tímótì 4:13) Apá tó gbẹ̀yìn nínú ìpàdé náà ni Máa Hùwà Tó Yẹ Kristẹni níbi tí a ti máa ń jíròrò bá a ṣe lè fi àwọn ìlànà Bíbélì sílò nínú ìgbésí ayé wa ojoojúmọ́. Ó tún máa ń ní ìbéèrè àti ìdáhùn tó máa ń jẹ́ ká túbọ̀ lóye Bíbélì.
Tó o bá wá sí àwọn ìpàdé wa, ó dájú pé àwọn ẹ̀kọ́ àtàtà tó o máa kọ́ látinú Bíbélì máa wú ẹ lórí gan-an.—Àìsáyà 54:13.
Kí lo máa kọ́ láwọn ìpàdé àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà?
Èwo nínú àwọn ìpàdé wa ọ̀sọ̀ọ̀sẹ̀ ló wù ẹ́ láti lọ?
-
-
Kí Nìdí Tá A Fi Ń Múra Dáadáa Nígbà Tá A Bá Ń Lọ sí Àwọn Ìpàdé Wa?Àwọn Wo Ló Ń Ṣe Ìfẹ́ Jèhófà Lóde Òní?
-
-
Ẹ̀KỌ́ 8
Kí Nìdí Tá A Fi Ń Múra Dáadáa Nígbà Tá A Bá Ń Lọ sí Àwọn Ìpàdé Wa?
Orílẹ̀-èdè Iceland
Orílẹ̀-èdè Mẹ́síkò
Orílẹ̀-èdè Guinea-Bissau
Orílẹ̀-èdè Philippines
Ǹjẹ́ o kíyè sí àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà nínú àwòrán inú ìwé yìí bí wọ́n ṣe múra dáadáa nígbà tí wọ́n ń lọ sí àwọn ìpàdé ìjọ? Kí nìdí tí a fi máa ń rí i pé aṣọ àti ìmúra wa bójú mu?
Ká lè bọ̀wọ̀ fún Ọlọ́run wa. Òótọ́ ni pé ìrísí wa nìkan kọ́ ni Ọlọ́run ń wò, ó tún má ń wo inú ọkàn wa. (1 Sámúẹ́lì 16:7) Nígbà tí a bá pé jọ láti sin Ọlọ́run, ohun tá a fẹ́ látọkàn wá ni pé ká bọ̀wọ̀ fún un àti fún àwọn tá a jọ ń sìn ín. Tá a bá fẹ́ lọ síwájú ọba tàbí ààrẹ orílẹ̀-èdè, a máa múra dáadáa torí pé èèyàn pàtàkì ni wọ́n. Bákan náà, bí a ṣe múra wá sí ìpàdé ń fi hàn pé a bọ̀wọ̀ fún Jèhófà Ọlọ́run, “Ọba ayérayé” àti fún ibi tá a ti ń jọ́sìn rẹ̀.—1 Tímótì 1:17.
Ká lè fi ìlànà tí à ń tẹ̀ lé hàn. Bíbélì rọ àwa Kristẹni pé ká máa múra lọ́nà tó fi “ìmọ̀wọ̀n ara ẹni àti àròjinlẹ̀” hàn. (1 Tímótì 2:9, 10) Ìmúra tó fi “ìmọ̀wọ̀n ara ẹni” hàn túmọ̀ sí pé ká má ṣe wọ aṣọ tó máa mú káwọn èèyàn máa wò wá, ìyẹn kéèyàn máa wọṣọ torí kó lè ṣe fọ́rífọ́rí, aṣọ tó ń mọ́kàn ẹni fà sí ìṣekúṣe tàbí èyí tó ṣí ara sílẹ̀. Bákan náà, “àròjinlẹ̀” ń jẹ́ ká yan aṣọ tó dáa, ká sì yẹra fún wíwọ aṣọ jákujàku tàbí ṣíṣe àṣejù nínú ìmúra wa. Ìlànà yìí fún wa láyè kí kálukú wọ aṣọ tó wù ú tó bá ṣáà ti dáa. Bí a ò tiẹ̀ sọ̀rọ̀, tí ìmúra wa bá bójú mu tó sì buyì kún wa, ó máa ‘ṣe ẹ̀kọ́ Olùgbàlà wa lọ́ṣọ̀ọ́,’ á sì “yin Ọlọ́run lógo.” (Títù 2:10; 1 Pétérù 2:12) Tá a bá múra dáadáa lọ sí àwọn ìpàdé wa, ó máa mú káwọn èèyàn fojú tó dáa wo ìjọsìn Jèhófà.
Má ṣe kọ ìpàdé sílẹ̀ torí pé o kò ní irú aṣọ kan tó o máa wọ̀ wá sí Gbọ̀ngàn Ìjọba. Kò dìgbà tí aṣọ wa bá jẹ́ olówó ńlá tàbí tó rí rèǹtè-rente kó tó jẹ́ aṣọ tó dáa, tó mọ́ tónítóní, tó sì bójú mu.
Kí nìdí tí ìmúra wa fi ṣe pàtàkì nígbà tá a bá ń jọ́sìn Ọlọ́run?
Àwọn ìlànà wo la máa ń tẹ̀ lé lórí ọ̀rọ̀ aṣọ àti ìmúra?
-
-
Ọ̀nà Wo Ló Dáa Jù Láti Gbà Múra Ìpàdé Ìjọ Sílẹ̀?Àwọn Wo Ló Ń Ṣe Ìfẹ́ Jèhófà Lóde Òní?
-
-
Ẹ̀KỌ́ 9
Ọ̀nà Wo Ló Dáa Jù Láti Gbà Múra Ìpàdé Ìjọ Sílẹ̀?
Orílẹ̀-èdè Kàǹbódíà
Orílẹ̀-èdè Ukraine
Tó o bá ń kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì lọ́dọ̀ ọ̀kan lára àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà, ó ṣeé ṣe kó o máa múra ibi tẹ́ ẹ máa kẹ́kọ̀ọ́ sílẹ̀ kẹ́ ẹ tó ṣe ìkẹ́kọ̀ọ́ náà. Bákan náà, ó dára kó o máa múra ìpàdé ìjọ sílẹ̀ kó o tó lọ, kó o lè jàǹfààní tó pọ̀ gan-an. Téèyàn bá ń ṣe bẹ́ẹ̀ déédéé, ẹ̀kọ́ púpọ̀ lá máa rí kọ́.
Pinnu ìgbà tó o máa múra ìpàdé àti ibi tó o ti máa múra. Ìgbà wo ló rọrùn fún ẹ jù láti pọkàn pọ̀? Ṣé àárọ̀ kùtù ni, kó o tó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́, àbí lálẹ́ nígbà tí àwọn ọmọ rẹ ti lọ sùn? Ká tiẹ̀ sọ pé o ò lè fi àkókò gígùn kẹ́kọ̀ọ́, yan iye àkókò tó o lè lò, kó o sì rí i dájú pé ohunkóhun ò dí ẹ lọ́wọ́. Wá ibi tí kò sí ariwo, kó o sì yẹra fún gbogbo ohun tó lè gbà ẹ́ lọ́kàn, pa rédíò, tẹlifíṣọ̀n àti fóònù rẹ. Máa gbàdúrà kó o tó bẹ̀rẹ̀ sí í kẹ́kọ̀ọ́, á jẹ́ kó o lè kó àníyàn ọjọ́ yẹn kúrò lọ́kàn kó o sì pọkàn pọ̀ sórí Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run.—Fílípì 4:6, 7.
Sàmì sí àwọn kókó inú ibi tí a fẹ́ kọ́, kó o sì múra láti dá sí i. Kọ́kọ́ wo àwọn kókó tó wà nínú ibi tá a fẹ́ kọ́. Ronú nípa àkòrí àpilẹ̀kọ tàbí orí ìwé náà, kó o sì wo bí ìsọ̀rí kọ̀ọ̀kan ṣe tan mọ́ kókó pàtàkì inú àpilẹ̀kọ náà, wo àwọn àwòrán tó wà níbẹ̀, kó o sì ka àwọn ìbéèrè tó gbé àwọn kókó inú ẹ̀kọ́ náà yọ. Lẹ́yìn náà, ka ìpínrọ̀ kọ̀ọ̀kan, kó o sì wá ìdáhùn sí àwọn ìbéèrè tó wà níbẹ̀. Ṣí àwọn ẹsẹ Ìwé Mímọ́ tó wà níbẹ̀, kà wọ́n, kó o sì ronú nípa bí wọ́n ṣe ti ọ̀rọ̀ náà lẹ́yìn. (Ìṣe 17:11) Tó o bá ti rí ìdáhùn, fa ìlà sí i tàbí kó o sàmì sí àwọn ọ̀rọ̀ pàtàkì tàbí àpólà ọ̀rọ̀ nínú ìpínrọ̀ náà, tó máa jẹ́ kó o rántí ìdáhùn náà. Ní ìpàdé, o lè nawọ́ nígbà tó o bá fẹ́, kó o sì dáhùn ṣókí ní ọ̀rọ̀ ara rẹ.
Bó o ṣe ń ka oríṣiríṣi ẹ̀kọ́ tá à ń jíròrò lọ́sọ̀ọ̀sẹ̀ nípàdé, wàá máa fi àwọn ohun tuntun kún ‘ibi tí ò ń kó ìṣúra sí,’ ìyẹn ìmọ̀ tó o ní nípa Bíbélì.—Mátíù 13:51, 52.
Àwọn nǹkan wo lo lè máa ṣe láti múra àwọn ìpàdé sílẹ̀ déédéé?
Báwo lo ṣe lè múra sílẹ̀ láti dáhùn ní ìpàdé?
-
-
Kí Ni Ìjọsìn Ìdílé?Àwọn Wo Ló Ń Ṣe Ìfẹ́ Jèhófà Lóde Òní?
-
-
Ẹ̀KỌ́ 10
Kí Ni Ìjọsìn Ìdílé?
Orílẹ̀-èdè South Korea
Orílẹ̀-èdè Brazil
Orílẹ̀-èdè Ọsirélíà
Orílẹ̀-èdè Guinea
Ọjọ́ pẹ́ tí Jèhófà ti fẹ́ kí ìdílé kọ̀ọ̀kan ní àkókò tí wọ́n á jọ wà pa pọ̀, kí wọ́n lè túbọ̀ sún mọ́ òun kí wọ́n sì wà níṣọ̀kan. (Diutarónómì 6:6, 7) Ìdí nìyẹn tí àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà fi máa ń ní àkókò kan lọ́sọ̀ọ̀sẹ̀ tí ìdílé á fi jọ́sìn pa pọ̀, tí wọ́n á jókòó pẹ̀sẹ̀, tí wọ́n á sì jọ sọ̀rọ̀ nípa àwọn nǹkan tó máa mú kí wọ́n túbọ̀ sún mọ́ Ọlọ́run. Kódà tó bá jẹ́ pé ṣe lò ń dá gbé, ó máa dáa gan-an kó o lo irú àkókò bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú Ọlọ́run, kó o fi kẹ́kọ̀ọ́ kókó kan tó wù ẹ́ nínú Bíbélì.
Ó jẹ́ àkókò láti túbọ̀ sún mọ́ Jèhófà. “Ẹ sún mọ́ Ọlọ́run, á sì sún mọ́ yín.” (Jémíìsì 4:8) A máa túbọ̀ mọ Jèhófà nígbà tí a bá mọ púpọ̀ sí i nípa irú ẹni tó jẹ́ àti ìwà rẹ̀ bó ṣe wà lákọsílẹ̀ nínú Bíbélì Ọ̀rọ̀ rẹ̀. Ọ̀nà kan tó rọrùn láti bẹ̀rẹ̀ ìjọsìn ìdílé rẹ ni pé kí ẹ ka Bíbélì sókè. Ẹ lè máa tẹ̀ lé ètò Ìpàdé Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni lọ́sọ̀ọ̀sẹ̀. Ẹ lè yan apá kan nínú Bíbélì náà fún ẹnì kọ̀ọ̀kan nínú ìdílé láti kà, kí gbogbo yín sì jíròrò ohun tí ẹ kọ́ níbẹ̀.
Ó jẹ́ àkókò tí ìdílé túbọ̀ máa ń wà níṣọ̀kan. Àwọn tọkọtaya, àwọn òbí àtàwọn ọmọ túbọ̀ máa ń wà níṣọ̀kan tí wọ́n bá jọ ń kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì pa pọ̀ nínú ìdílé. Ó yẹ kó jẹ́ àkókò ayọ̀ àti àlàáfíà, kó sì tún jẹ́ ohun tí wọ́n á máa wọ̀nà fún lọ́sọ̀ọ̀sẹ̀. Àwọn òbí lè yan ohun tí wọ́n á jọ sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀ bí ọjọ́ orí àwọn ọmọ wọn bá ṣe mọ, wọ́n lè yan àkòrí kan nínú Ilé Ìṣọ́ tàbí Jí! tàbí látorí ìkànnì jw.org/yo. Ẹ lè sọ̀rọ̀ nípa ìṣòro kan tí àwọn ọmọ yín ní nílé ìwé àti bí wọ́n ṣe lè borí rẹ̀. Ẹ lè wò lára àwọn ètò wa lórí Tẹlifíṣọ̀n JW (tv.jw.org) kẹ́ ẹ sì jọ sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀. Ẹ tún lè fi àwọn orin tí a máa kọ ní ìpàdé dánra wò, kẹ́ ẹ sì gbádùn rẹ̀. Ẹ sì lè jẹ ìpápánu lẹ́yìn ìjọsìn ìdílé yín.
Àkókò pàtàkì tí ẹ̀ ń lò lọ́sọ̀ọ̀sẹ̀ láti jọ́sìn Jèhófà pa pọ̀ yìí máa ran gbogbo yín lọ́wọ́ kí ẹ lè jadùn Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, Ọlọ́run á sì mú kí ìsapá yín yọrí sí rere.—Sáàmù 1:1-3.
Kí nìdí tá a fi ní àkókò tá a máa ń ṣe ìjọsìn ìdílé?
Báwo ni àwọn òbí ṣe lè jẹ́ kí gbogbo ìdílé gbádùn ìjọsìn ìdílé?
-
-
Kí Nìdí Tí A Fi Ń Lọ sí Àwọn Àpéjọ Ńlá?Àwọn Wo Ló Ń Ṣe Ìfẹ́ Jèhófà Lóde Òní?
-
-
Ẹ̀KỌ́ 11
Kí Nìdí Tí A Fi Ń Lọ sí Àwọn Àpéjọ Ńlá?
Orílẹ̀-èdè Mẹ́síkò
Orílẹ̀-èdè Jámánì
Orílẹ̀-èdè Botswana
Orílẹ̀-èdè Nicaragua
Orílẹ̀-èdè Ítálì
Kí nìdí tínú àwọn èèyàn yìí fi ń dùn? Torí pé wọ́n wà ní ọ̀kan lára àwọn àpéjọ wa ni. Bíi ti àwọn èèyàn Ọlọ́run láyé àtijọ́, tí Ọlọ́run sọ fún pé kí wọ́n máa pé jọ lẹ́ẹ̀mẹta lọ́dún, àwa náà máa ń fojú sọ́nà fún àwọn ìgbà tá a máa ń lọ sí àpéjọ ńlá. (Diutarónómì 16:16) Àpéjọ mẹ́ta la máa ń ṣe lọ́dọọdún, àwọn ni: àpéjọ àyíká ọlọ́jọ́ kan, tó máa ń wáyé lẹ́ẹ̀méjì àti àpéjọ agbègbè ọlọ́jọ́ mẹ́ta. Báwo ni àwọn àpéjọ yìí ṣe ń ṣe wá láǹfààní?
Wọ́n ń mú kí ẹgbẹ́ ará wa túbọ̀ wà níṣọ̀kan. Bí inú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ṣe máa ń dùn nígbà tí wọ́n bá ń yin Jèhófà ní “àwọn àpéjọ,” bẹ́ẹ̀ náà ni inú wa máa ń dùn nígbà tá a bá ń jọ́sìn rẹ̀ láwọn àpéjọ pàtàkì. (Sáàmù 26:12, àlàyé ìsàlẹ̀ ìwé; 111:1) Àwọn àpéjọ yìí máa ń jẹ́ ká lè pàdé pẹ̀lú àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà láti àwọn ìjọ míì tàbí àwọn orílẹ̀-èdè míì pàápàá, ká sì jọ fara rora. Ní ọ̀sán, a máa ń jẹun pa pọ̀ ní gbọ̀ngàn àpéjọ wa, èyí sì ń jẹ́ ká túbọ̀ gbádùn àjọṣe alárinrin láwọn àpéjọ náà. (Ìṣe 2:42) Láwọn àpéjọ yìí, a máa ń fojú ara wa rí ìfẹ́ tó so “gbogbo àwọn ará” wa pọ̀ kárí ayé.—1 Pétérù 2:17.
Wọ́n ń mú ká tẹ̀ síwájú nínú ìjọsìn Ọlọ́run. Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì jàǹfààní torí pé ọ̀rọ̀ inú Ìwé Mímọ́ tí wọ́n ṣàlàyé fún wọn “yé wọn.” (Nehemáyà 8:8, 12) Àwa náà mọyì ẹ̀kọ́ Bíbélì tá a máa ń kọ́ láwọn àpéjọ wa. Inú Bíbélì la ti mú àwọn ẹ̀kọ́ náà. À ń kọ́ bá a ṣe lè máa ṣe ìfẹ́ Ọlọ́run láyé wa látinú àwọn àsọyé alárinrin, àpínsọ àsọyé àtàwọn àṣefihàn ohun tó ṣẹlẹ̀. Tá a bá gbọ́ bí àwọn ará wa ṣe ń fara da ìṣòro tó ń dé bá àwọn Kristẹni tòótọ́ lásìkò tí nǹkan nira yìí, ó máa ń fún wa ní ìṣírí. Ní àwọn àpéjọ agbègbè wa, àwọn àwòkẹ́kọ̀ọ́ máa ń mú kí àwọn ìtàn inú Bíbélì túbọ̀ ṣe kedere, wọ́n sì ń kọ́ wa láwọn ẹ̀kọ́ tó wúlò. Ní gbogbo àpéjọ, a máa ń ṣe ìrìbọmi fún àwọn tó fẹ́ fi hàn pé àwọn ti ya ara wọn sí mímọ́ fún Ọlọ́run.
Kí nìdí tí àwọn àpéjọ wa fi máa ń fún wa láyọ̀?
Àǹfààní wo lo máa rí tó o bá wá sí àpéjọ wa?
-
-
Báwo La Ṣe Ṣètò Iṣẹ́ Ìwàásù Ìjọba Ọlọ́run?Àwọn Wo Ló Ń Ṣe Ìfẹ́ Jèhófà Lóde Òní?
-
-
Ẹ̀KỌ́ 12
Báwo La Ṣe Ṣètò Iṣẹ́ Ìwàásù Ìjọba Ọlọ́run?
Orílẹ̀-èdè Sípéènì
Orílẹ̀-èdè Belarus
Orílẹ̀-èdè Hong Kong
Orílẹ̀-èdè Peru
Ṣáájú kí Jésù tó kú, ó sọ pé: “A ó sì wàásù ìhìn rere Ìjọba yìí ní gbogbo ilẹ̀ ayé tí à ń gbé, kó lè jẹ́ ẹ̀rí fún gbogbo orílẹ̀-èdè, nígbà náà ni òpin yóò dé.” (Mátíù 24:14) Àmọ́, báwo la ṣe máa ṣe iṣẹ́ ìwàásù tó máa kárí ayé yìí? Bí a ṣe máa ṣe é ni pé, a máa tẹ̀ lé àpẹẹrẹ tí Jésù fi lélẹ̀ nígbà tó wà láyé.—Lúùkù 8:1.
À ń wá àwọn èèyàn lọ sílé wọn ká lè bá wọn sọ̀rọ̀. Jésù kọ́ àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ pé kí wọ́n máa wàásù ìhìn rere láti ilé dé ilé. (Mátíù 10:11-13; Ìṣe 5:42; 20:20) Àwọn ajíhìnrere ọgọ́rùn-ún ọdún kìíní yẹn ní àwọn agbègbè tí wọ́n ti ń wàásù. (Mátíù 10:5, 6; 2 Kọ́ríńtì 10:13) Bákan náà lónìí, a ṣètò iṣẹ́ ìwàásù wa dáadáa, a sì fún ìjọ kọ̀ọ̀kan ní ibi tí wọ́n á ti máa wàásù. Èyí jẹ́ ká lè máa tẹ̀ lé àṣẹ tí Jésù pa fún wa pé ká “wàásù fún àwọn èèyàn ká sì jẹ́rìí kúnnákúnná.”—Ìṣe 10:42.
À ń sapá láti wàásù fún àwọn èèyàn láwọn ibi tá a ti lè rí wọn. Jésù tún fi àpẹẹrẹ lélẹ̀ bó ṣe wàásù níbi táwọn èèyàn máa ń wà, irú bí etíkun tàbí nídìí kànga àdúgbò. (Máàkù 4:1; Jòhánù 4:5-15) Àwa náà máa ń bá àwọn èèyàn sọ̀rọ̀ nípa Bíbélì láwọn ibi tá a ti lè ṣe bẹ́ẹ̀, ìyẹn lẹ́gbẹ̀ẹ́ ọ̀nà, níbi iṣẹ́, nínú ọgbà ìgbafẹ́ tàbí lórí fóònù. A tún máa ń wàásù fún àwọn aládùúgbò wa, àwọn tá a jọ ń ṣiṣẹ́, àwọn ọmọ ilé ìwé wa àtàwọn mọ̀lẹ́bí wa nígbà tí àyè rẹ̀ bá yọ. Gbogbo àwọn ohun tí à ń ṣe yìí ti jẹ́ kí ọ̀pọ̀ mílíọ̀nù èèyàn kárí ayé gbọ́ “ìhìn rere ìgbàlà.”—Sáàmù 96:2.
Ta lo rò pé o lè sọ ìhìn rere Ìjọba Ọlọ́run fún àti ohun tí ìyẹn máa ṣe fún wọn lọ́jọ́ iwájú? Má ṣe fi ọ̀rọ̀ ìtùnú yìí mọ sọ́dọ̀ ara rẹ nìkan. Sọ ọ́ fún wọn láìjáfara!
“Ìhìn rere” wo la gbọ́dọ̀ kéde?
Báwo ni àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe ń tẹ̀ lé àpẹẹrẹ Jésù lẹ́nu iṣẹ́ ìwàásù?
-
-
Àwọn Wo Ni Aṣáájú-Ọ̀nà?Àwọn Wo Ló Ń Ṣe Ìfẹ́ Jèhófà Lóde Òní?
-
-
Ẹ̀KỌ́ 13
Àwọn Wo Ni Aṣáájú-Ọ̀nà?
Orílẹ̀-èdè Kánádà
Ìwàásù ilé-dé-ilé
Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì
Ìdákẹ́kọ̀ọ́
Ọ̀rọ̀ náà “aṣáájú-ọ̀nà” sábà máa ń tọ́ka sí àwọn tó lọ wá agbègbè tuntun, tí wọ́n sì la ọ̀nà fún àwọn tó ń bọ̀ lẹ́yìn. A lè pe Jésù ní aṣáájú-ọ̀nà torí Ọlọ́run rán an wá sí ayé kó wá ṣe iṣẹ́ òjíṣẹ́ tó ń fúnni ní ìyè, kó sì ṣí ọ̀nà ìgbàlà sílẹ̀ fún àwa èèyàn. (Mátíù 20:28) Lónìí, àwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ ń tẹ̀ lé àpẹẹrẹ rẹ̀ bí wọ́n ṣe ń lo àkókò tó pọ̀ lẹ́nu iṣẹ́ sísọ àwọn èèyàn “di ọmọ ẹ̀yìn.” (Mátíù 28:19, 20) Àwọn kan lára wọn ń ṣe iṣẹ́ tí à ń pè ní iṣẹ́ aṣáájú-ọ̀nà.
Òjíṣẹ́ tó ń fi ọ̀pọ̀ àkókò wàásù là ń pè ní aṣáájú-ọ̀nà. Gbogbo àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà ló ń kéde ìhìn rere. Àmọ́, àwọn kan ti ṣètò ìgbé ayé wọn kí wọ́n lè ṣe aṣáájú-ọ̀nà déédéé, wọ́n máa ń fi àádọ́rin (70) wákàtí wàásù lóṣooṣù. Ọ̀pọ̀ wọn ti dín àkókò tí wọ́n fi ń ṣiṣẹ́ kù kí wọ́n lè ṣe aṣáájú-ọ̀nà. A ti yan àwọn kan láti ṣe aṣáájú-ọ̀nà àkànṣe níbi tá a ti nílò àwọn oníwàásù tó pọ̀ sí i, wọ́n sì ń fi àádóje (130) wákàtí tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ wàásù lóṣooṣù. Àwọn aṣáájú-ọ̀nà máa ń jẹ́ kí ìwọ̀nba ohun tí wọ́n ní tẹ́ wọn lọ́rùn, wọ́n gbẹ́kẹ̀ lé Jèhófà pé ó máa pèsè àwọn nǹkan tó pọn dandan fún wọn. (Mátíù 6:31-33; 1 Tímótì 6:6-8) Àwọn tí kò lè ṣe aṣáájú-ọ̀nà déédéé àti àkànṣe lè ṣe aṣáájú-ọ̀nà olùrànlọ́wọ́ láwọn ìgbà tó bá ṣeé ṣe, wọ́n á lo àkókò tó pọ̀ sí i lẹ́nu iṣẹ́ ìwàásù, ó lè jẹ́ ọgbọ̀n (30) tàbí àádọ́ta (50) wákàtí lóṣù.
Ìfẹ́ tí àwọn aṣáájú-ọ̀nà ní fún Ọlọ́run àtàwọn èèyàn ló ń mú kí wọ́n ṣe iṣẹ́ náà. Bíi ti Jésù, a kíyè sí pé ọ̀pọ̀ èèyàn lónìí ló yẹ kí wọ́n mọ̀ nípa Ọlọ́run àtàwọn ohun tó fẹ́ ṣe. (Máàkù 6:34) A mọ ohun tó lè ràn wọ́n lọ́wọ́ báyìí, tó máa mú kí wọ́n ní ìrètí pé ọ̀la ń bọ̀ wá dáa. Ìfẹ́ tí àwọn aṣáájú-ọ̀nà ní sí àwọn èèyàn ló ń mú kí wọ́n máa lo ọ̀pọ̀ àkókò àti okun wọn láti kọ́ àwọn èèyàn nípa Ọlọ́run. (Mátíù 22:39; 1 Tẹsalóníkà 2:8) Ìyẹn ń mú kí ìgbàgbọ́ àwọn aṣáájú-ọ̀nà lágbára, kí wọ́n sún mọ́ Ọlọ́run, kí wọ́n sì máa láyọ̀ gan-an.—Ìṣe 20:35.
Àwọn wo là ń pè ní aṣáájú-ọ̀nà?
Kí ló mú kí àwọn kan máa ṣe aṣáájú-ọ̀nà déédéé tàbí àkànṣe?
-
-
Àwọn Ilé Ẹ̀kọ́ Tó Wà fún Àwọn Aṣáájú-Ọ̀nàÀwọn Wo Ló Ń Ṣe Ìfẹ́ Jèhófà Lóde Òní?
-
-
Ẹ̀KỌ́ 14
Àwọn Ilé Ẹ̀kọ́ Tó Wà fún Àwọn Aṣáájú-Ọ̀nà
Orílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà
Ilé Ẹ̀kọ́ Gílíádì, ní Patterson, New York
Orílẹ̀-èdè Panama
Ọjọ́ pẹ́ tí ètò ìdálẹ́kọ̀ọ́ ti jẹ́ apá pàtàkì nínú ìjọsìn àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà. Ètò Ọlọ́run ṣètò ilé ẹ̀kọ́ lákànṣe fún àwọn tó ń fi ọ̀pọ̀ àkókò wàásù Ìjọba Ọlọ́run kí wọ́n lè ‘ṣe iṣẹ́ òjíṣẹ́ wọn láìkù síbì kan.’—2 Tímótì 4:5.
Ilé Ẹ̀kọ́ Àwọn Aṣáájú-Ọ̀nà. Tó bá ti pé ọdún kan tí ẹnì kan bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ aṣáájú-ọ̀nà, ó máa lọ sí ilé ẹ̀kọ́ ọlọ́jọ́ mẹ́fà tó ṣeé ṣe kó wáyé ní Gbọ̀ngàn Ìjọba kan tí kò jìnnà sí agbègbè rẹ̀. Ilé ẹ̀kọ́ náà máa jẹ́ kó túbọ̀ sún mọ́ Jèhófà, á jẹ́ kó túbọ̀ mọ bí a ṣe ń wàásù, kó sì máa fi òtítọ́ bá iṣẹ́ ìsìn rẹ̀ lọ.
Ilé Ẹ̀kọ́ Àwọn Ajíhìnrere. A dá ilé ẹ̀kọ́ olóṣù méjì yìí sílẹ̀ láti dá àwọn aṣáájú-ọ̀nà tó nírìírí lẹ́kọ̀ọ́, àwọn tó ṣe tán láti fi agbègbè wọn sílẹ̀, kí wọ́n lè lọ sìn ní ibikíbi tí ètò Ọlọ́run bá ti nílò wọn. Ńṣe ló dà bí ìgbà tí wọ́n ń sọ pé, “Èmi nìyí! Rán mi!” Wọ́n fìwà jọ Ajíhìnrere tó ga jù lọ tó gbé ayé rí, ìyẹn Jésù Kristi. (Àìsáyà 6:8; Jòhánù 7:29) Wọ́n lè ní láti fi àwọn nǹkan kan du ara wọn torí pé ibi tí wọ́n wà jìnnà sí ìlú wọn. Àṣà ìbílẹ̀ ibi tí wọ́n kó lọ lè yàtọ̀ pátápátá, títí kan ojú ọjọ́ àti oúnjẹ. Ó sì lè pọn dandan pé kí wọ́n kọ́ èdè tuntun. Ilé ẹ̀kọ́ yìí máa jẹ́ kí àwọn àpọ́n, àwọn obìnrin tí kò lọ́kọ àti àwọn tọkọtaya tí wọ́n jẹ́ ẹni ọdún mẹ́tàlélógún (23) sí márùndínláàádọ́rin (65) ní àwọn ìwà tó yẹ Kristẹni tó máa wúlò lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn wọn. Wọ́n á tún kọ́ àwọn ohun táá jẹ́ kí wọ́n túbọ̀ wúlò fún Jèhófà àti ètò rẹ̀.
Ilé Ẹ̀kọ́ Gílíádì. Ní èdè Hébérù, “Gílíádì” túmọ̀ sí “Òkìtì Ẹ̀rí.” Láti ọdún 1943 tí a ti dá ilé ẹ̀kọ́ yìí sílẹ̀, a ti rán àwọn míṣọ́nnárì tó ju ẹgbẹ̀rún mẹ́jọ (8,000) tí wọ́n gba ìdálẹ́kọ̀ọ́ láti lọ máa wàásù káàkiri “gbogbo ayé,” wọ́n sì ń ṣe àṣeyọrí lọ́pọ̀lọpọ̀. (Ìṣe 13:47) Bí àpẹẹrẹ, nígbà tí àwọn míṣọ́nnárì kọ́kọ́ dé orílẹ̀-èdè Peru, kò sí ìjọ kankan níbẹ̀. Àmọ́ ní báyìí, ìjọ tó wà níbẹ̀ ti lé ní ẹgbẹ̀rún (1,000). Nígbà táwọn míṣọ́nnárì bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ ìwàásù ní ilẹ̀ Japan, àwọn Ẹlẹ́rìí tó wà níbẹ̀ kò tó mẹ́wàá. Àmọ́ ní báyìí wọ́n ti lé ní ọ̀kẹ́ mẹ́wàá (200,000). Oṣù márùn-ún ni wọ́n fi ń lọ sí Ilé ẹ̀kọ́ Gílíádì, wọ́n sì máa ń kẹ́kọ̀ọ́ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run jinlẹ̀ níbẹ̀. Àwọn aṣáájú-ọ̀nà àkànṣe, àwọn míṣọ́nnárì tó wà ní pápá, àwọn tó ń sìn ní ẹ̀ka ọ́fíìsì tàbí àwọn alábòójútó àyíká ló máa ń lọ sí ilé ẹ̀kọ́ yìí kí wọ́n lè gba ìdálẹ́kọ̀ọ́ tó jinlẹ̀ táá jẹ́ kí wọ́n lè ṣèrànwọ́ láti mú kí iṣẹ́ ìwàásù fẹsẹ̀ múlẹ̀, kó sì gbòòrò sí i kárí ayé.
Kí nìdí tá a fi ṣètò Ilé Ẹ̀kọ́ Àwọn Aṣáájú-Ọ̀nà?
Àwọn wo ló lè lọ sí Ilé Ẹ̀kọ́ Àwọn Ajíhìnrere?
-