ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Tún Padà Ní Ìfẹ́ Tó O Ní Níṣàájú!
    Ìṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
    • Orí 7

      Tún Padà Ní Ìfẹ́ Tó O Ní Níṣàájú!

      ÉFÉSÙ

      1. Ìjọ wo ló ni àkọ́kọ́ lára iṣẹ́ tí Jésù fi rán Jòhánù, kí ni Jésù sì rán àwọn alábòójútó létí rẹ̀?

      ÌJỌ tó wà ní Éfésù ló gba iṣẹ́ àkọ́kọ́ tí Jésù fi rán Jòhánù. Ní àkókò yẹn, Éṣíà Kékeré ni ìlú Éfésù wà, ó ń gbèrú, ìlú etíkun ni, ìtòsí erékùṣù Pátímọ́sì ló sì wà. Jésù pàṣẹ fún Jòhánù pé: “Kọ̀wé sí áńgẹ́lì ìjọ ní Éfésù pé: Ìwọ̀nyí ni ohun tí ẹni tí ó di ìràwọ̀ méje mú ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ wí, ẹni tí ń rìn ní àárín ọ̀pá fìtílà méje oníwúrà.” (Ìṣípayá 2:1) Nínú ọ̀rọ̀ tí Jésù sọ yìí, ó pe àfiyèsí sí ọ̀kan lára àwọn ohun tó fi ipò àṣẹ tó wà hàn, ó sì ṣe bẹ́ẹ̀ nínú iṣẹ́ tó rán sí ìjọ mẹ́fà tó kù. Ó rán àwọn alábòójútó ní Éfésù létí pé abẹ́ àbójútó àti ààbò òun ni gbogbo alàgbà wà àti pé òun ń bẹ gbogbo ìjọ wò. Títí di àkókò tá a wà yìí, Jésù ń bá a lọ láti fìfẹ́ lo ipò orí rẹ̀, ó ń fìṣọ́ ṣọ́ àwọn alàgbà ó sì ń finúure ṣolùṣọ́ àgùntàn gbogbo àwọn tó wà nínú ìjọ. Látìgbàdégbà, ó ń ṣe àtúnṣe sí ètò ìjọ kí ìmọ́lẹ̀ tẹ̀mí lè máa túbọ̀ mọ́lẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni, Jésù ni Olórí Olùṣọ́ Àgùntàn agbo Ọlọ́run.—Mátíù 11:28-30; 1 Pétérù 5:2-4.

      2. (a) Àwọn ohun rere wo ni Jésù tìtorí rẹ̀ gbóríyìn fún ìjọ Éfésù? (b) Ìmọ̀ràn Pọ́ọ̀lù wo ló hàn gbangba pé àwọn alàgbà Éfésù tẹ̀ lé?

      2 Lẹ́yìn náà Jésù fi àpẹẹrẹ rere lélẹ̀ fún gbogbo wa nípa fífi ìgbóríyìn bẹ̀rẹ̀ márùn-ún lára iṣẹ́ tó rán sí ìjọ méje náà. Iṣẹ́ tó rán sí àwọn ará Éfésù ni pé: “Mo mọ àwọn iṣẹ́ rẹ, àti òpò àti ìfaradà rẹ, àti pé ìwọ kò lè gba àwọn ènìyàn búburú mọ́ra, àti pé ìwọ ti dán àwọn tí wọ́n sọ pé àpọ́sítélì ni àwọn wò, ṣùgbọ́n tí wọn kì í ṣe bẹ́ẹ̀, o sì rí wọn ní òpùrọ́. Ìwọ ń fi ìfaradà hàn pẹ̀lú, o sì ti rọ́jú nítorí orúkọ mi, àárẹ̀ kò sì mú ọ.” (Ìṣípayá 2:2, 3) Ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún ṣáájú ìgbà yẹn, àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù kìlọ̀ fáwọn alàgbà ìjọ Éfésù nípa “àwọn aninilára ìkookò,” ìyẹn àwọn apẹ̀yìndà tí ń yọ agbo lẹ́nu, ó sì sọ fáwọn alàgbà náà pé kí wọ́n “máa wà lójúfò” nípa títẹ̀lé àpẹẹrẹ àìṣàárẹ̀ tòun. (Ìṣe 20:29, 31) Bí Jésù ṣe wá gbóríyìn fún wọn nísinsìnyí fún iṣẹ́ takuntakun, ìfaradà àti àìṣàárẹ̀, ó ní láti jẹ́ pé wọ́n ti fi ìmọ̀ràn Pọ́ọ̀lù sílò.

      3. (a) Báwo làwọn “èké àpọ́sítélì” ṣe wá ọ̀nà láti tan àwọn olùṣòtítọ́ jẹ ní àkókò wa yìí? (b) Ìkìlọ̀ wo ni Pétérù fúnni nípa àwọn apẹ̀yìndà?

      3 Ní ọjọ́ Olúwa pẹ̀lú, àwọn “èké àpọ́sítélì” tí wọ́n ń “sọ àwọn ohun àyídáyidà láti fa àwọn ọmọ ẹ̀yìn lọ sẹ́yìn ara wọn” ti fara hàn. (2 Kọ́ríńtì 11:13; Ìṣe 20:30; Ìṣípayá 1:10) Lójú wọn, gbogbo àwọn ẹ̀ya ìsìn tí ìmọ̀ wọn ò ṣọ̀kan ló dára, wọ́n sọ pé Ọlọ́run ò ní ètò kankan, wọ́n sì sọ pé Jésù kò gba agbára Ìjọba ní 1914. Àsọtẹ́lẹ̀ tó wà nínú 2 Pétérù 3:3, 4 ṣẹ sí wọn lára. Ó kà pé: “Nítorí ẹ mọ èyí lákọ̀ọ́kọ́, pé ní àwọn ọjọ́ ìkẹyìn, àwọn olùyọṣùtì yóò wá pẹ̀lú ìyọṣùtì wọn, wọn yóò máa rìn ní ìbámu pẹ̀lú ìfẹ́-ọkàn ti ara wọn wọn yóò sì máa wí pé: ‘Wíwàníhìn-ín rẹ̀ yìí tí a ti ṣèlérí dà? Họ́wù, láti ọjọ́ tí àwọn baba ńlá wa ti sùn nínú ikú, ohun gbogbo ń bá a lọ gẹ́gẹ́ bí ó ti rí láti ìbẹ̀rẹ̀pẹ̀pẹ̀ ìṣẹ̀dá.’”

      4. (a) Báwo ni ìgbéraga àti ìṣọ̀tẹ̀ àwọn apẹ̀gàn ṣe fara hàn gbangba? (b) Láti fi hàn pé à ń ṣe bíi tàwọn ará Éfésù, kí làwa Kristẹni lónìí máa ń ṣe fáwọn alátakò tó ń parọ́?

      4 Àwọn ẹlẹ́gàn wọ̀nyí ṣọ̀tẹ̀, wọ́n sọ pé àwọn ò lè máa lọ polongo ìgbàgbọ́ àwọn fáwọn èèyàn. (Róòmù 10:10) Wọ́n wá ìtìlẹyìn àwọn àlùfáà ṣọ́ọ̀ṣì, wọ́n tún wá ìrànlọ́wọ́ àwọn ìwé ìròyìn àti ilé iṣẹ́ tẹlifíṣọ̀n láti tan ìròyìn èké kálẹ̀ nípa àwọn tí wọ́n ti fìgbà kan rí jẹ́ alábàákẹ́gbẹ́ wọn. Kò pẹ́ táwọn tó jẹ́ olóòótọ́ fi rí i pé irọ́ ni ọ̀rọ̀ ẹnu àwọn ẹlẹ́tàn wọ̀nyí àti pé ìwà wọn kò bá òtítọ́ mu. Bíi tàwọn ará Éfésù, àwa Kristẹni lónìí “kò lè gba àwọn ènìyàn búburú mọ́ra,” nítorí náà à ń yọ wọ́n lẹ́gbẹ́ kúrò nínú ìjọ.a

      5. (a) Àìlera wo ni Jésù sọ pé àwọn ará Éfésù ní? (b) Ọ̀rọ̀ wo ló yẹ kí àwọn ará Éfésù ti rántí?

      5 Àmọ́, Jésù tọ́ka sí ìṣòro ńlá kan, bẹ́ẹ̀ náà ló sì ṣe nínú iṣẹ́ tó rán sí márùn-ún lára ìjọ méje náà. Ó sọ fáwọn ará Éfésù pé: “Bí ó tilẹ̀ rí bẹ́ẹ̀, mo ní èyí lòdì sí ọ, pé ìwọ ti fi ìfẹ́ tí ìwọ ní ní àkọ́kọ́ sílẹ̀.” (Ìṣípayá 2:4) Kò yẹ kó jẹ́ pé lórí ọ̀rọ̀ ìfẹ́ ni wọ́n á ti kùnà, nítorí ní ọdún márùndínlógójì [35] ṣáájú ìgbà yẹn, Pọ́ọ̀lù kọ̀wé sí wọn ó sì sọ nípa ‘ìfẹ́ ńlá tí’ Ọlọ́run “fi nífẹ̀ẹ́ wa,” ó wá rọ̀ wọ́n pé: “Ẹ di aláfarawé Ọlọ́run, gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ tí í ṣe olùfẹ́ ọ̀wọ́n, kí ẹ sì máa bá a lọ ní rírìn nínú ìfẹ́, gan-an gẹ́gẹ́ bí Kristi pẹ̀lú ti nífẹ̀ẹ́ yín.” (Éfésù 2:4; 5:1, 2) Yàtọ̀ síyẹn, ó yẹ kí wọ́n ti fi ọ̀rọ̀ tí Jésù sọ sọ́kàn, pé: “Jèhófà Ọlọ́run wa jẹ́ Jèhófà kan ṣoṣo, kí ìwọ sì nífẹ̀ẹ́ Jèhófà Ọlọ́run rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn-àyà rẹ àti pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ àti pẹ̀lú gbogbo èrò-inú rẹ àti pẹ̀lú gbogbo okun rẹ.” (Máàkù 12:29-31) Àwọn ará Éfésù kò ní ìfẹ́ tí wọ́n ní níṣàájú mọ́.

      6. (a) Yálà ó ti pẹ́ tá a ti wà nínú ìjọ tàbí a ṣẹ̀ṣẹ̀ dara pọ̀, ewu wo àtàwọn ohun wo ló yẹ ká ṣọ́ra fún? (b) Kí ló yẹ kí ìfẹ́ tá a ní sí Ọlọ́run sún wa ṣe?

      6 Yálà ó ti pẹ́ tá a ti wà nínú ìjọ tàbí a ṣẹ̀ṣẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí í dara pọ̀, a gbọ́dọ̀ ṣọ́ra ká má bàa pàdánù ìfẹ́ tá a kọ́kọ́ ní sí Jèhófà. Báwo la ṣe lè pàdánù rẹ̀? A lè pàdánù rẹ̀ tá a bá jẹ́ kí iṣẹ́ oúnjẹ òòjọ́ wa, ìfẹ́ láti kó owó tabua jọ tàbí ìlépa adùn di ohun pàtàkì nígbèésí ayé wa. Èyí lè mú kí ọkàn wa máa wà lórí àwọn ohun tara dípò kó máa wà lórí àwọn ohun tẹ̀mí. (Róòmù 8:5-8; 1 Tímótì 4:8; 6:9, 10) Tí irú nǹkan bẹ́ẹ̀ bá ti bẹ̀rẹ̀ sí í ṣẹlẹ̀ sí wa, ó yẹ kí ìfẹ́ tá a ní sí Jèhófà sún wa láti ṣàtúnṣe ká sì ‘máa bá a nìṣó ní wíwá ìjọba Ọlọ́run àti òdodo rẹ̀ lákọ̀ọ́kọ́,’ ká bàa lè ‘kó ìṣúra jọ pa mọ́ fún ara wa ní ọ̀run.’—Mátíù 6:19-21, 31-33.

      7. (a) Kí ló yẹ kó sún wa ṣe iṣẹ́ ìsìn wa sí Jèhófà? (b) Kí ni Jòhánù sọ nípa ìfẹ́?

      7 Ká jẹ́ kí ìfẹ́ jíjinlẹ̀ tá a ní sí Jèhófà máa sún wa ṣe gbogbo iṣẹ́ ìsìn tá à ń ṣe sí i. Ẹ jẹ́ ká ní ìmọrírì àtọkànwá fún gbogbo nǹkan tí Jèhófà àti Kristi ti ṣe fún wa. Ohun tí Jòhánù kọ̀wé rẹ̀ lẹ́yìn náà nìyẹn, ó ní: “Ìfẹ́ náà jẹ́ lọ́nà yìí, kì í ṣe pé àwa ti nífẹ̀ẹ́ Ọlọ́run, bí kò ṣe pé òun nífẹ̀ẹ́ wa, ó sì rán Ọmọ rẹ̀ jáde gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ìpẹ̀tù fún àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa.” Jòhánù ń bá a lọ láti sọ fún wa pé: “Ọlọ́run jẹ́ ìfẹ́, ẹni tí ó bá sì dúró nínú ìfẹ́ dúró ní ìrẹ́pọ̀ pẹ̀lú Ọlọ́run, Ọlọ́run sì dúró ní ìrẹ́pọ̀ pẹ̀lú rẹ̀.” Láé, ká má ṣe jẹ́ kí ìfẹ́ tá a ní sí Jèhófà, ìfẹ́ tá a ní sí Jésù Kristi Olúwa, àti ìfẹ́ tá a ní fún Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tó wà láàyè, dín kù! Yàtọ̀ sí fífi ìfẹ́ yìí hàn nípa fífi ìtara ṣe iṣẹ́ ìsìn wa sí Jèhófà, a tún lè fi hàn nípa ṣíṣègbọràn sí ‘àṣẹ yìí tí a gbà láti ọ̀dọ̀ rẹ̀, pé ẹni náà tí ó bá nífẹ̀ẹ́ Ọlọ́run ní láti máa nífẹ̀ẹ́ arákùnrin rẹ̀ pẹ̀lú.’—1 Jòhánù 4:10, 16, 21; Hébérù 4:12; tún wo 1 Pétérù 4:8; Kólósè 3:10-14; Éfésù 4:15.

      “Ṣe Àwọn Iṣẹ́ ti Ìṣáájú”

      8. Kí ni Jésù ní káwọn ara Éfésù ṣe?

      8 Àwọn ará Éfésù gbọ́dọ̀ padà ní ìfẹ́ tí wọ́n kọ́kọ́ ní bí wọn ò bá fẹ́ pàdánù. Jésù sọ fún wọn pé: “Nítorí náà, rántí inú ohun tí o ti ṣubú, kí o sì ronú pìwà dà, kí o sì ṣe àwọn iṣẹ́ ti ìṣáájú. Bí ìwọ kò bá ṣe bẹ́ẹ̀, èmi ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ rẹ, ṣe ni èmi yóò gbé ọ̀pá fìtílà rẹ kúrò ní àyè rẹ̀, àyàfi bí o bá ronú pìwà dà.” (Ìṣípayá 2:5) Kí làwọn Kristẹni nínú ìjọ Éfésù ṣe nígbà tí wọ́n gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí? A ò mọ̀. Ṣùgbọ́n a lérò pé wọ́n ronú pìwà dà wọ́n sì ta ìfẹ́ tí wọ́n ní sí Jèhófà jí. Bí wọn kò bá ṣe bẹ́ẹ̀, Jésù á fẹ́ fìtílà wọn pa, á sì gbé ọ̀pá fìtílà wọn kúrò. Ìyẹn túmọ̀ sí pé wọ́n á pàdánù àǹfààní tí wọ́n ní láti máa tan ìmọ́lẹ̀ òtítọ́.

      9. (a) Ọ̀rọ̀ ìṣírí wo ni Jésù ní láti sọ fáwọn ará Éfésù? (b) Báwo làwọn ìjọ lẹ́yìn ìgbà ayé Jòhánù kò ṣe ka ìmọ̀ràn tí Jésù fún àwọn ará Éfésù sí?

      9 Bó tilẹ̀ rí bẹ́ẹ̀, Jésù ní ọ̀rọ̀ ìṣírí kan láti sọ fáwọn ará Éfésù. Ó ní: “Síbẹ̀, ìwọ ní èyí, pé o kórìíra àwọn iṣẹ́ ẹ̀ya ìsìn Níkóláọ́sì, èyí tí èmi pẹ̀lú kórìíra.” (Ìṣípayá 2:6) Ó kéré tán wọ́n kórìíra ẹ̀ya ìsìn bí Jésù Kristi Olúwa ṣe kórìíra rẹ̀. Àmọ́ bí ọdún ti ń gorí ọdún, ọ̀pọ̀ ìjọ ò ka ọ̀rọ̀ tí Jésù sọ yìí sí. Níní tí wọn ò ní ìfẹ́ fún Jèhófà, fún òtítọ́, àti fún ara wọn mú kí wọ́n sú lọ sínú òkùnkùn tẹ̀mí. Ni wọ́n bá pín yẹ́lẹyẹ̀lẹ sí àìlóǹkà ẹ̀ya ìsìn tó ń ta ko ara wọn. Àwọn Kristẹni aláfẹnujẹ́ tí wọ́n jẹ́ adàwékọ tí wọn kò ní ìfẹ́ kankan fún Jèhófà yọ orúkọ Ọlọ́run kúrò nínú àwọn ìwé Bíbélì tí wọ́n fọwọ́ kọ lédè Gíríìkì. Níní tí wọn ò ní ìfẹ́ tún mú kí wọ́n máa fi àwọn ẹ̀kọ́ Bábílónì àti ti Gíríìkì kọ́ni, irú bíi hẹ́ẹ̀lì oníná, pọ́gátórì, àti Mẹ́talọ́kan, wọ́n sọ pé ẹ̀kọ ìsìn Kristẹni ni. Púpọ̀ jù lọ lára àwọn tí wọ́n sọ pé Kristẹni làwọn kò nífẹ̀ẹ́ Ọlọ́run àti òtítọ́, nítorí náà, wọ́n ṣíwọ́ wíwàásù ìhìn rere Ìjọba Ọlọ́run. Àwọn tó wá ń ṣàkóso lé wọn lórí ni ẹgbẹ́ àwọn àlùfáà onímọtara-ẹni-nìkan tí wọ́n ṣe ìjọba fún ara wọn lórí ilẹ̀ ayé.—Fi wé 1 Kọ́ríńtì 4:8.

      10. Báwo ni nǹkan ti rí fún ìsìn ṣọ́ọ̀ṣì ní 1918?

      10 Nígbà tí ìdájọ́ bẹ̀rẹ̀ ní ilé Ọlọ́run lọ́dún 1918, gbangba gbàǹgbà ni ẹgbẹ́ àlùfáà àwọn ẹ̀ya ìsìn ṣọ́ọ̀ṣì ń ṣe ìtìlẹyìn fáwọn tó ń jà nígbà Ogun Àgbáyé Kìíní, wọ́n ń rọ àwọn Kátólíìkì àti Pùròtẹ́sítáǹtì níhà méjèèjì tó ń bára wọn jà pé kí wọ́n máa pa ara wọn. (1 Pétérù 4:17) Àwọn ìsìn ṣọ́ọ̀ṣì kò dà bí ìjọ Éfésù tó kórìíra ohun tí ẹ̀ya ìsìn Níkóláọ́sì ń ṣe. Ìdí ni pé ọjọ́ pẹ́ tí àwọn ẹ̀kọ́ èké tó ta ko Ọlọ́run ti ba àwọn ìsìn ṣọ́ọ̀ṣì jẹ́, ẹgbẹ́ àlùfáà wọn sì ti di alátìlẹyìn ayé tí Jésù sọ pé àwọn ọmọlẹ́yìn òun ò gbọ́dọ̀ jẹ́ apá kan rẹ̀. (Jòhánù 15:17-19) Níwọ̀n bí àwọn ìjọ wọn kò ti mọ̀ pé Ìjọba Ọlọ́run ni ẹṣin ọ̀rọ̀ Bíbélì, wọn kì í ṣe ọ̀pá fìtílà tó ń tan ìmọ́lẹ̀ òtítọ́ tó wà nínú Ìwé Mímọ́, bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn to wà nínú ìjọ wọn kì í ṣe ara tẹ́ńpìlì tẹ̀mí ti Jèhófà. Àwọn aṣáájú wọn lọ́kùnrin (àti lóbìnrin) kì í ṣe ìràwọ̀, kàkà bẹ́ẹ̀, ńṣe ni àṣírí wọn tú pé wọ́n wà lára àwọn tó para pọ̀ di “ọkùnrin oníwà àìlófin” náà.—2 Tẹsalóníkà 2:3; Málákì 3:1-3.

      11. (a) Ní 1918, àwùjọ àwọn Kristẹni wo ló ṣiṣẹ́ lórí ọ̀rọ̀ tí Jésù sọ fáwọn ará Éfésù? (b) Kí ni ẹgbẹ́ Jòhánù ń ṣe láti 1919 wá?

      11 Àmọ́ ẹgbẹ́ Jòhánù jáde wá látinú wàhálà àkókò Ogun Àgbáyé Kìíní tàwọn ti ìfẹ́ fún Jèhófà, wọ́n sì tún nífẹ̀ẹ́ òtítọ́, èyí tó ń sún wọn láti máa fi ìtara sin Jèhófà. Lọ́dún 1916, lẹ́yìn ikú Charles T. Russell tó jẹ́ ààrẹ àkọ́kọ́ fún Watch Tower Society, àwọn kan fẹ́rẹ̀ẹ́ sọ ọ́ di òrìṣà àkúnlẹ̀bọ, ìdí tí wọ́n sì fi fẹ́ ṣe bẹ́ẹ̀ ni kí wọ́n lè mú ẹ̀ya ìsìn wọlé, àmọ́ ẹgbẹ́ Jòhánù kò gbà fún wọn. Ó hàn gbangba pé lẹ́yìn tí inúnibíni àti ìpọ́njú ti kọ́ àwùjọ àwọn Kristẹni yìí lẹ́kọ̀ọ́, ìdájọ́ “o káre láé” ni Ọ̀gá wọn ṣe fún wọn, ó sì tún pè wọ́n pé kí wọ́n wọnú ayọ̀ òun. (Mátíù 25:21, 23) Látinú àwọn ohun tó ń ṣẹlẹ̀ láyé àti látinú ìrírí tí àwọn fúnra wọn ní, wọ́n rí ìmúṣẹ àmì tí Jésù sọ pé ó máa fi hàn pé òun ti wà níhìn-ín láìṣeé-fojú-rí nínú agbára Ìjọba. Láti 1919, wọ́n tẹ̀ síwájú láti túbọ̀ nípìn-ín nínú ìmúṣẹ àsọtẹ́lẹ̀ ńlá tí Jésù sọ, pé: “A ó sì wàásù ìhìn rere ìjọba yìí ní gbogbo ilẹ̀ ayé tí a ń gbé, láti ṣe ẹ̀rí fún gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè; nígbà náà ni òpin yóò sì dé.” (Mátíù 6:9, 10; 24:3-14) Tó bá jẹ́ pé ìfẹ́ tí wọ́n ní sí Jèhófà tẹ́lẹ̀ kù díẹ̀ káàtó láwọn ọ̀nà kan, kò rí bẹ́ẹ̀ mọ́ nítorí pé láti 1919 yẹn ni iná ìfẹ́ wọn ti ń jó lala.

      12. (a) Ní àpéjọ àgbègbè mánigbàgbé tó wáyé lọ́dún 1922, ìpè wo ló jáde lọ? (b) Orúkọ wo làwọn Kristẹni tòótọ́ tẹ́wọ́ gbà ní 1931, kí ni wọ́n sì ronú pìwà dà rẹ̀?

      12 Ẹgbẹ̀rún méjìdínlógún àwọn Kristẹni wọ̀nyí ló pé jọ sí àpéjọ àgbègbè mánigbàgbé kan tó wáyé ní Cedar point, Ohio, lórílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà ní September 5 sí 13, 1922. Ní ìpàdé náà, ìpè kan jáde lọ pé: “Ẹ padà sí pápá, ẹ̀yin ọmọ Ọlọ́run gíga jù lọ! . . . Ayé gbọ́dọ̀ mọ̀ pé Jèhófà ni Ọlọ́run àti pé Jésù Kristi ni Ọba àwọn ọba àti Olúwa àwọn olúwa. . . . Nítorí náà, ẹ fọn rere, ẹ fọn rere, ẹ fọn rere Ọba náà àti ìjọba rẹ̀.” Àwọn Kristẹni wọ̀nyí túbọ̀ ń gbé orúkọ ńlá Jèhófà lárugẹ. Bí àpẹẹrẹ, ní àpéjọ àgbègbè kan ní Columbus, Ohio, lórílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà ní 1931, inú wọn dùn láti tẹ́wọ́ gba orúkọ tí Ọlọ́run fi hàn nínú àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà, ìyẹn, Ẹlẹ́rìí Jèhófà. (Aísáyà 43:10, 12) Látorí Ilé Ìṣọ́ March 1, 1939, wọ́n yí orúkọ ìwé ìròyìn pàtàkì tí ètò yìí ń lò padà sí Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jèhófà, nípa bẹ́ẹ̀, Ẹlẹ́dàá wa àti àkóso rẹ̀ ni ìwé ìròyìn náà ń bu ọlá tó ga jù lọ fún. Pẹ̀lú bí ìfẹ́ táwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ní sí Jèhófà ṣe dọ̀tun, tó bá jẹ́ pé láwọn ìgbà tó ti kọjá, a ti kùnà lọ́nà kan ṣá láti bọlá fún orúkọ ológo Jèhófà àti Ìjọba rẹ̀ tí a kò sì gbé e ga, a ti ronú pìwà dà èyí.—Sáàmù 106:6, 47, 48.

      “Ẹni Tí Ó Bá Ṣẹ́gun”

      13. (a) Ìbùkún wo ló dúró de àwọn ará Éfésù bí wọ́n bá “ṣẹ́gun”? (b) Báwo làwọn Kristẹni ní Éfésù yóò ṣe “ṣẹ́gun”?

      13 Níkẹyìn, Jésù pe àfiyèsí sí ẹ̀mí mímọ́ pé òun ló ń tipasẹ̀ òun sọ èrè táwọn olóòótọ́ á rí gbà fún ìṣòtítọ́ wọn, bẹ́ẹ̀ náà ló sì ṣe pe àfiyèsí sí i nínú iṣẹ́ tó rán sí ìjọ mẹ́fà tó kù. Ó sọ fáwọn ará Éfésù pé: “Kí ẹni tí ó bá ní etí gbọ́ ohun tí ẹ̀mí ń sọ fún àwọn ìjọ: Ẹni tí ó bá ṣẹ́gun ni èmi yóò yọ̀ǹda fún láti jẹ nínú igi ìyè, èyí tí ń bẹ nínú párádísè Ọlọ́run.” (Ìṣípayá 2:7) Àwọn tí wọ́n ní etí-ìgbọ́ yóò hára gàgà láti fiyè sí ohun tó wà nínú iṣẹ́ pàtàkì tí Jésù rán sí wọn yẹn, wọ́n á mọ̀ pé ọ̀dọ̀ Jésù kọ́ ló ti pilẹ̀ṣẹ̀, kàkà bẹ́ẹ̀, ó pilẹ̀ṣẹ̀ láti ọ̀dọ̀ Jèhófà Olúwa Ọba Aláṣẹ náà, nípasẹ̀ ẹ̀mí mímọ́, tàbí agbára ìṣiṣẹ́ Rẹ̀. Báwo wá ni wọ́n á ṣe “ṣẹ́gun”? Wọ́n á ṣẹ́gun tí wọ́n bá tẹ̀ lé àpẹẹrẹ Jésù, ẹni tó pa ìwà títọ́ mọ́ títí dé ojú ikú tó sì lè tipa bẹ́ẹ̀ sọ pé: “Ẹ mọ́kànle! Mo ti ṣẹ́gun ayé.”—Jòhánù 8:28; 16:33; tún wo 1 Jòhánù 5:4.

      14. Kí ni “párádísè Ọlọ́run” tí Jésù mẹ́nu kàn ní láti tọ́ka sí?

      14 Níwọ̀n bí àwọn ẹni àmì òróró, irú bí àwọn ará Éfésù, kò ti nírètí láti gbé nínú Párádísè lórí ilẹ̀ ayé, ọ̀nà wo la gbà san èrè fún wọn nípa jíjẹ “nínú igi ìyè, èyí tí ń bẹ nínú párádísè Ọlọ́run”? Èyí kò lè jẹ́ Párádísè tá a mú bọ̀ sípò lórí ilẹ̀ ayé, níwọ̀n bó ti jẹ́ pé ọ̀kẹ́ méje ó lé ẹgbàajì [144,000] àwọn Kristẹni ẹni àmì òróró, tí àwọn tí wọ́n wà nínú ìjọ Éfésù jẹ́ ara rẹ̀, ni a ti rà láti inú aráyé láti ṣàkóso pẹ̀lú Ọ̀dọ́ Àgùntàn náà, Kristi Jésù, lórí Òkè Síónì ti ọ̀run gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ tẹ̀mí. (Éfésù 1:5-12; Ìṣípayá 14:1, 4) Nítorí náà, ó ní láti jẹ́ pé ohun tí gbólóhùn yìí ń tọ́ka sí ni ọ̀run tó dà bí ọgbà, èyí tí àwọn aṣẹ́gun wọ̀nyí jogún rẹ̀. Níbẹ̀, “nínú párádísè Ọlọ́run,” àní níwájú Jèhófà gan-an, àwọn tó ṣẹ́gun wọ̀nyí tí a ti fún ní àìleèkú yóò máa bá a lọ láti wà láàyè títí láé, èyí tí jíjẹ nínú igi ìyè náà ṣàpẹẹrẹ.

      15. Kí nìdí tí ìṣírí tí Jésù fúnni láti ṣẹ́gun fi jẹ́ ohun tí ogunlọ́gọ̀ ńlá nífẹ̀ẹ́ sí gidigidi lónìí?

      15 Àwọn tó ń fi àìyẹsẹ̀ ṣètìlẹyìn fún ọ̀kẹ́ méje ó lé ẹgbàajì [144,000] àwọn ẹni àmì òróró lórí ilẹ̀ ayé ńkọ́? Àwọn wọ̀nyí tí wọ́n jẹ́ ogunlọ́gọ̀ ńlá Ẹlẹ́rìí Jèhófà tí wọ́n ń bá àwọn ẹni àmì òróró kẹ́gbẹ́ náà ń ṣẹ́gun. Ṣùgbọ́n ìrètí wọn dá lórí wíwọ Párádísè orí ilẹ̀ ayé, níbi tí wọ́n á ti mu nínú “odò omi ìyè” tí wọ́n á sì rí ìmúláradá láti inú “ewé àwọn igi” tí a gbìn sí ẹ̀gbẹ̀ẹ̀gbẹ́ odò yẹn. (Ìṣípayá 7:4, 9, 17; 22:1, 2) Tó bá jẹ́ pé ara àwùjọ yìí lo wà, kí ìwọ náà máa fi ìfẹ́ rẹ hàn sí Jèhófà kó o sì ṣẹ́gun nínú ogun jíjà ti ìgbàgbọ́. Nípa bẹ́ẹ̀ ọwọ́ rẹ lè tẹ ayọ̀ ìyè àìnípẹ̀kun nínú Párádísè lórí ilẹ̀ ayé.—Fi wé 1 Jòhánù 2:13, 14.

      [Àlàyé ìsàlẹ̀ ìwé]

      a Fún ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ìtàn nípa bí àwọn èké àpọ́sítélì ṣe fara hàn, wo ojú ewé 37 sí 44 nínú ìwé náà, Reasoning From the Scriptures, tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe.

      [Àpótí tó wà ní ojú ìwé 36]

      Yíyin Jèhófà àti Ọmọ Rẹ̀ Tìfẹ́tìfẹ́

      Nínú ìwé orin táwa èèyàn Jèhófà ṣe ní 1905, ìlọ́po méjì àwọn orin tá a fi ń yin Jèhófà la fi ń yin Jésù. Nínú ìwé orin wa ti 1928, ó fẹ́rẹ̀ẹ́ lè jẹ́ pé iye kan náà ni orin tá a fi ń yin Jèhófà àti orin tá a fi ń yin Jésù. Ṣùgbọ́n nínú ìwé orin tó dé gbẹ̀yìn ní 1984, iye àwọn orin tá a fi ń bọlá fún Jèhófà jẹ́ ìlọ́po mẹ́rin èyí tá a fi ń bọlá fún Jésù. Èyí wà ní ìbámu pẹ̀lú ọ̀rọ̀ tí Jésù fúnra rẹ̀ sọ, pé: “Baba tóbi jù mí lọ.” (Jòhánù 14:28) Ìfẹ́ fún Jèhófà ló gbọ́dọ̀ gba iwájú, lọ́wọ́ kan náà, ká ní ìfẹ́ jíjinlẹ̀ fún Jésù ká sì fi ìmọrírì hàn fún ẹbọ iyebíye tó rú nítorí wa àti ipò tó wà gẹ́gẹ́ bí Àlùfáà Àgbà Ọlọ́run.

      [Àtẹ Ìsọfúnnni tó wà ní ojú ìwé 34]

      Bí Ìmọ̀ràn Jésù Ṣe Lọ

      (orí àti ẹsẹ tí ìmọ̀ràn rẹ̀ wà nínú ìwé Ìṣípayá)

      O ránṣẹ́ Àṣẹ tó ní Ìgbóríyìn Ó fi ìṣòro Ìbáwí Ìbùkún tí

      sí ìjọ láti fúnni ló fi bẹ̀rẹ̀ wọn hàn àti/tàbí yóò yọrí sí

      nímọ̀ràn ọ̀rọ̀ rẹ̀ kedere ìṣírí

      Éfésù 2:1 2:2, 3 2:4 2:5, 6 2:7

      Símínà 2:8 2:9 — 2:10 2:11

      Págámù 2:12 2:13 2:14, 15 2:16 2:17

      Tíátírà 2:18 2:19 2:20, 21 2:24, 25 2:26-28

      Sádísì 3:1 — 3:1, 2 3:3, 4 3:5

      Filadéfíà 3:7 3:8 — 3:8-11 3:12

      Laodíkíà 3:14 — 3:15-17 3:18-20 3:21

  • Lílàkàkà Láti Jẹ́ Aṣẹ́gun
    Ìṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
    • Orí 8

      Lílàkàkà Láti Jẹ́ Aṣẹ́gun

      SÍMÍNÀ

      1. (a) Ìjọ wo ni Jésù tá a ti ṣe lógo fi iṣẹ́ rẹ̀ kejì ránṣẹ́ sí? (b) Bí Jésù ṣe pe ara rẹ̀ ní “Ẹni Àkọ́kọ́ àti Ẹni Ìkẹyìn,” kí ló rán àwọn Kristẹni nínú ìjọ náà létí?

      LÓNÌÍ, ahoro ni ìlú Éfésù ayé ọjọ́un, àwókù rẹ̀ nìkan lèèyàn lè rí. Àmọ́ ìlú ńlá kan ṣì wà níbi tí Jésù fiṣẹ́ rẹ̀ kejì ránṣẹ́ sí. Orílẹ̀-èdè Turkey ni ìlú ọ̀hún wà, Izmir sì lorúkọ rẹ̀. Ó jẹ́ kìlómítà mẹ́rìndínlọ́gọ́ta [56] sí àríwá ibi tí àwókù ìlú Éfésù wà. Dòní olónìí, àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ní ìjọ mẹ́rin níbẹ̀ tó ń fìtara ṣiṣẹ́. Ní ọ̀rúndún kìíní, ìlú Símínà ló wà níbi tí ìlú Izmir wà báyìí. Wàyí o, fetí sí ọ̀rọ̀ tí Jésù tún sọ. Ó ní: “Sì kọ̀wé sí áńgẹ́lì ìjọ ní Símínà pé: Ìwọ̀nyí ni ohun tí òun wí, ‘Ẹni Àkọ́kọ́ àti Ẹni Ìkẹyìn,’ ẹni tí ó di òkú tẹ́lẹ̀, tí ó sì tún wá sí ìyè.” (Ìṣípayá 2:8) Bí Jésù ṣe sọ fáwọn Kristẹni tó wà ní Símínà pé òun jẹ́ ẹni àkọ́kọ́ àti ẹni ìkẹyìn, ńṣe ló ń rán wọn létí pé òun ni olùpàwà-títọ́mọ́ àkọ́kọ́ tí Jèhófà fọwọ́ ara rẹ̀ jí dìde sí ìyè tẹ̀mí gẹ́gẹ́ bí ẹ̀dá aláìleèkú, àti pé òun lẹni ìkẹyìn tí Jèhófà fọwọ́ ara rẹ̀ jí dìde bẹ́ẹ̀. Jésù ló máa jí gbogbo àwọn Kristẹni ẹni àmì òróró yòókù dìde. Nítorí náà, ó kúnjú ìwọ̀n dáadáa láti fún àwọn arákùnrin rẹ̀ nímọ̀ràn, àwọn tí wọ́n nírètí láti ní ìyè àìleèkú ní ọ̀run bíi tiẹ̀.

      2. Kí nìdí tí ọ̀rọ̀ Ẹni “tí ó ti di òkú tẹ́lẹ̀ tí ó sì tún wá sí ìyè” fi fún gbogbo Kristẹni níṣìírí?

      2 Nínú kéèyàn fara da inúnibíni nítorí òdodo, Jésù ló gbapò iwájú, ó sì rí èrè rẹ̀ gba. Jíjẹ́ tó jẹ́ olóòótọ́ títí dé ojú ikú àti jíjí tó jí dìde ló mú kí gbogbo Kristẹni nírètí. (Ìṣe 17:31) Bí Jésù ṣe “di òkú tẹ́lẹ̀ tí ó sì tún wá sí ìyè” fi hàn pé ohunkóhun téèyàn bá fara dà nítorí òtítọ́ kì í ṣe lórí asán. Àjíǹde Jésù máa ń fún gbogbo Kristẹni níṣìírí gan-an, pàápàá tó bá di pé kí wọ́n jìyà nítorí ìgbàgbọ́ wọn. Ṣé ò ń jìyà nítorí ìgbàgbọ́ rẹ? Tó bá rí bẹ́ẹ̀, ọ̀rọ̀ tí Jésù sọ tẹ̀ lé e fún ìjọ Símínà lè fún ọ níṣìírí.

      3. (a) Ọ̀rọ̀ ìfinilọ́kànbalẹ̀ wo ni Jésù sọ fún àwọn Kristẹni ní Símínà? (b) Bó tilẹ̀ jẹ́ pé tálákà làwọn Kristẹni ní Símínà, kí nìdí tí Jésù fi sọ pé “ọlọ́rọ̀” ni wọ́n?

      3 Jésù sọ pé: “Mo mọ ìpọ́njú àti ipò òṣì rẹ—ṣùgbọ́n ọlọ́rọ̀ ni ọ́—àti ọ̀rọ̀ òdì láti ẹnu àwọn tí ń sọ pé àwọn jẹ́ Júù, síbẹ̀ tí wọn kì í ṣe bẹ́ẹ̀ ṣùgbọ́n tí wọ́n jẹ́ sínágọ́gù Sátánì.” (Ìṣípayá 2:9) Oríyìn nìkan ni Jésù gbé fún àwọn arákùnrin rẹ̀ tó wà ní Símínà, kò sọ pé ohun kan kù díẹ̀ káàtó nípa wọn. Wọ́n ti jìyà gan-an nítorí ìgbàgbọ́ wọn. Tálákà ni wọ́n, wọn ò ní ohun ìní tara, ó sì ṣeé ṣe kíyẹn jẹ́ nítorí ìṣòtítọ́ wọn. (Hébérù 10:34) Àwọn ohun tẹ̀mí ló jẹ wọn lógún jù, wọ́n sì ti kó ìṣúra jọ pa mọ́ ní ọ̀run bí ìmọ̀ràn Jésù. (Mátíù 6:19, 20) Nítorí náà, ojú “ọlọ́rọ̀” ni Olórí Olùṣọ́ Àgùntàn fi wò wọ́n—Fi wé Jákọ́bù 2:5.

      4. Àwọn wo ló ṣe àtakò púpọ̀ sí àwọn Kristẹni ní Símínà, kí sì ni àwọn alátakò náà jẹ́ lójú Jésù?

      4 Ohun kan tí Jésù kíyè sí ni pé àwọn Kristẹni tí wọ́n wà ní Símínà ti fara da ọ̀pọ̀ àtakò táwọn Júù ṣe sí wọn. Ṣáájú ìgbà yẹn, ọ̀pọ̀ lára àwọn ẹlẹ́sìn Júù wọ̀nyẹn dìídì gbógun ti ìtànkálẹ̀ ìsìn Kristẹni. (Ìṣe 13:44, 45; 14:19) Láìpẹ́ lẹ́yìn tí Jerúsálẹ́mù pa run, àwọn Júù tí wọ́n wà ní Símínà ṣì ń fi ẹ̀mí bíi ti Sátánì yìí hàn. Abájọ tó fi jẹ́ pé “sínágọ́gù Sátánì” ni wọ́n lójú Jésù!a

      5. Ìdánwò wo ní ń bẹ níwájú fún àwọn Kristẹni ní Símínà?

      5 Pẹ̀lú irú ìkórìíra tí wọ́n ní sáwọn Kristẹni ní Símínà yìí, Jésù tù wọ́n nínú pé: “Má fòyà àwọn ohun tí ìwọ máa tó jìyà rẹ̀. Wò ó! Èṣù yóò máa bá a nìṣó ní sísọ àwọn kan nínú yín sí ẹ̀wọ̀n kí a lè dán yín wò ní kíkún, kí ẹ sì lè ní ìpọ́njú fún ọjọ́ mẹ́wàá. Jẹ́ olùṣòtítọ́ àní títí dé ikú, dájúdájú, èmi yóò sì fún ọ ní adé ìyè.” (Ìṣípayá 2:10) Nínú ẹsẹ yìí lédè Gíríìkì, ìgbà mẹ́ta ni Jésù lo ọ̀rọ̀ arọ́pò orúkọ ẹlẹ́ni púpọ̀ náà, “yín,” èyí tó fi hàn pé ìjọ náà lódindi ni ọ̀rọ̀ rẹ̀ kan. Jésù kò ṣèlérí pé àdánwò àwọn Kristẹni ní Símínà yóò dópin láìpẹ́. Àwọn kan lára wọn ò ní yéé jìyà inúnibíni wọ́n á sì sọ wọ́n sẹ́wọ̀n. Wọ́n á ní ìpọ́njú fún “ọjọ́ mẹ́wàá.” Nọ́ńbà náà, ẹẹ́wàá, dúró fún pátápátá porogodo tàbí ìpé pérépéré nínú àwọn nǹkan ti orí ilẹ̀ ayé. Kódà àwọn olùpàwà-títọ́mọ́ wọ̀nyẹn tí wọ́n jẹ́ ọlọ́rọ̀ nípa tẹ̀mí yóò rí ìdánwò tó le gan-an nígbà tí wọ́n ṣì wà nínú ẹran ara.

      6. (a) Kí nìdí tí kò fi yẹ káwọn Kristẹni ní Símínà fòyà? (b) Kí ni Jésù fi parí iṣẹ́ tó rán sí ìjọ tó wà ní Símínà?

      6 Bó tilẹ̀ rí bẹ́ẹ̀, kò yẹ káwọn Kristẹni ní Símínà fòyà tàbí juwọ́ sílẹ̀. Bí wọ́n bá jẹ́ olóòótọ́ títí dé òpin, “adé ìyè” ni èrè tí wọ́n á rí gbà, fún àwọn, èyí jẹ́ ìwàláàyè àìleèkú ní ọ̀run. (1 Kọ́ríńtì 9:25; 2 Tímótì 4:6-8) Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù wo ẹ̀bùn iyebíye yìí gẹ́gẹ́ bí ohun tó yẹ láti tìtorí rẹ̀ fi gbogbo nǹkan mìíràn rúbọ, àní ìwàláàyè rẹ̀ ti orí ilẹ̀ ayé pàápàá. (Fílípì 3:8) Ó hàn gbangba pé bó ṣe rí lójú àwọn olùṣòtítọ́ tó wà ní Símínà nìyẹn. Ọ̀rọ̀ tí Jésù fi parí iṣẹ́ tó rán sí wọn ni pé: “Kí ẹni tí ó bá ní etí gbọ́ ohun tí ẹ̀mí ń sọ fún àwọn ìjọ: Ẹni tí ó bá ṣẹ́gun ni ikú kejì kì yóò pa lára lọ́nàkọnà.” (Ìṣípayá 2:11) Ó mú un dá àwọn tó bá ṣẹ́gun lójú pé wọ́n á ní ìyè àìleèkú ní ọ̀run, èyí tí ọwọ́ ikú kò lè tẹ̀.—1 Kọ́ríńtì 15:53, 54.

      “Ìpọ́njú fún Ọjọ́ Mẹ́wàá”

      7, 8. Bíi ti ìjọ tó wà ní Símínà, báwo ni ìjọ Kristẹni ṣe di èyí tí a “dán . . . wò ní kíkún” lọ́dún 1918?

      7 Bíi tàwọn Kristẹni ní Símínà, ẹgbẹ́ Jòhánù àtàwọn alábàákẹ́gbẹ́ wọn lónìí ni a ti “dán . . . wò ní kíkún,” ìdánwò náà sì ṣì ń bá a lọ. Jíjẹ́ tí wọ́n jẹ́ olóòótọ́ lábẹ́ àdánwò fi wọ́n hàn gẹ́gẹ́ bí èèyàn Ọlọ́run. (Máàkù 13:9, 10) Ọ̀rọ̀ tí Jésù sọ fáwọn Kristẹni ní Símínà jẹ́ ojúlówó ìtùnú fáwọn èèyàn Jèhófà kéréje jákèjádò ayé ní kété lẹ́yìn tí ọjọ́ Olúwa bẹ̀rẹ̀. (Ìṣípayá 1:10) Látọdún 1879 làwọn wọ̀nyí ti ń hú ọrọ̀ tẹ̀mí jáde látinú Bíbélì Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, wọ́n sì ń fún àwọn ẹlòmíràn lára ọrọ̀ tẹ̀mí náà ní fàlàlà. Ṣùgbọ́n nígbà Ogun Àgbáyé Kìíní, wọ́n dojú kọ ìkórìíra àti àtakò gbígbónájanjan nítorí pé wọn kò lọ́wọ́ sí wàhálà ogun náà, àti nítorí pé wọ́n ń fi àìṣojo túdìí àṣírí àṣìṣe àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì. Wọ́n rí inúnibíni, àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì ló sì ṣokùnfà rẹ̀. Inúnibíni yìí le gan-an nígbà tó di ọdún 1918, a sì lè fi wé ohun táwọn Júù ní Símínà fojú àwọn Kristẹni tó wà ní Símínà rí.

      8 Inúnibíni tó ń wáyé lákòókò náà lórílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà bá a débi tó le gan-an nígbà tí wọ́n rán Joseph F. Rutherford tó jẹ́ ààrẹ tuntun fún Watch Tower Society àtàwọn alábàákẹ́gbẹ́ rẹ̀ méje lọ sẹ́wọ̀n ní June 22, 1918, ogún [20] ọdún sì ni wọ́n ní ọ̀pọ̀ jù lọ wọn máa lò lẹ́wọ̀n. Ní oṣù mẹ́sàn-án lẹ́yìn náà, wọ́n gba ìdúró wọn wọ́n sì tú wọn sílẹ̀. Ní May 14, 1919, ilé ẹjọ́ kòtẹ́milọ́rùn fagi lé ẹjọ́ tí kò tọ́ tí wọ́n dá fún wọn; wọ́n fi hàn pé àádóje [130] àṣìṣe ló wà nínú ìgbẹ́jọ́ náà. Ní 1918, adájọ́ Manton tó jẹ́ ẹlẹ́sìn Roman Kátólíìkì tó sì jẹ́ abẹnugan nínú ẹgbẹ́ St. Gregory Ńlá kọ̀ láti gba onídùúró àwọn Kristẹni wọ̀nyẹn. Lẹ́yìn náà, ní 1939, ilé ẹjọ́ dá òun náà lẹ́jọ́, wọ́n jù ú sẹ́wọ̀n ọdún méjì wọ́n sì ní kó sanwó ìtanràn tí iye rẹ̀ jẹ́ ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá [10,000] dọ́là lórí ẹ̀sùn mẹ́fà tí wọ́n fi kàn án pé ó tọrọ owó ó sì gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀.

      9. Kí ni Hitler fojú àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà rí ní Jámánì nígbà ìṣàkóso Násì, báwo lèyí sì ṣe rí lára ẹgbẹ́ àlùfáà?

      9 Nígbà ìṣàkóso Násì ní Jámánì, Hitler fòfin de iṣẹ́ ìwàásù àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà pátápátá. Fún ọ̀pọ̀ ọdún, wọ́n fi ìwà ìkà sé ẹgbẹẹgbẹ̀rún Ẹlẹ́rìí Jèhófà mọ́ àgọ́ ìṣẹ́niníṣẹ̀ẹ́ àti ẹ̀wọ̀n, níbi tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ti kú, wọ́n sì pa nǹkan bí ọgọ́rùn-ún méjì àwọn ọ̀dọ́kùnrin tí wọ́n kọ̀ láti jà nínú ẹgbẹ́ ọmọ ogun Hitler. Ọ̀rọ̀ àlùfáà Kátólíìkì kan tí wọ́n tẹ̀ jáde nínú ìwé ìròyìn The German Way ti May 29, 1938 fi hàn pé àwọn àlùfáà ṣọ́ọ̀ṣì ṣètìlẹyìn fún Ìjọba Hitler láti ṣe gbogbo èyí. Díẹ̀ nínú ohun tí àlùfáà náà sọ ni pé: “Ní báyìí, wọ́n ti fòfin de àwọn tí wọ́n ń pè ní . . . Akẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì [ìyẹn àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà] lórílẹ̀-èdè Jámánì . . . Nígbà tí Adolf Hitler gorí àlééfà, Ẹgbẹ́ Àwọn Bíṣọ́ọ̀bù Kátólíìkì ilẹ̀ Jámánì ò yéé béèrè ohun tí wọ́n fẹ́, ni Hitler bá sọ pé: ‘Oníjàngbọ̀n làwọn tí wọ́n ń pè ní Akẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Onítara [ìyẹn àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà] wọ̀nyí; . . . afàwọ̀rajà ni wọ́n lójú mi; mi ò lè fàyè gba Judge Rutherford tó jẹ́ ará Amẹ́ríkà yìí láti ba àwọn Kátólíìkì ilẹ̀ Jámánì lórúkọ jẹ́; mo fòpin sí ìsìn [àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà] ní Jámánì.’” Àlùfáà náà gbóríyìn fún Hitler fún ohun tó sọ yìí, ó ní: “Sàdáńkátà!”

      10. (a) Báwo làwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe fojú winá inúnibíni bí ọjọ́ Olúwa ṣe ń tẹ̀ síwájú? (b) Kí ló sábà máa ń jẹ́ àbájáde rẹ̀ táwa Kristẹni bá jà fún òmìnira ìsìn nílé ẹjọ́?

      10 Bí ọjọ́ Olúwa ṣe ń tẹ̀ síwájú, Ejò náà àti irú-ọmọ rẹ̀ ò yéé bá àwọn Kristẹni ẹni àmì òróró àtàwọn alábàákẹ́gbẹ́ wọn jà. Púpọ̀ nínú àwọn wọ̀nyí ni wọ́n fi sẹ́wọ̀n tí wọ́n sì ṣe inúnibíni sí lọ́nà rírorò. (Ìṣípayá 12:17) Àwọn ọ̀tá wọ̀nyẹn ò yéé ‘fi òfin dìmọ̀ ìwà ìkà,’ ṣùgbọ́n àwa èèyàn Jèhófà ò yẹhùn lórí ọ̀rọ̀ tá a sọ, pé: “Àwa gbọ́dọ̀ ṣègbọràn sí Ọlọ́run gẹ́gẹ́ bí olùṣàkóso dípò àwọn ènìyàn.” (Sáàmù 94:20; Ìṣe 5:29) Lọ́dún 1954, ìwé ìròyìn Ilé Ìṣọ́ sọ pé: ‘Láàárín ogójì ọdún tó kọjá, ó ju àádọ́rin [70] orílẹ̀-èdè lọ tí wọ́n ti ṣe òfin tó ká àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà lọ́wọ́ kò tí wọ́n sì ṣe inúnibíni sí wọn.’ Àwa Kristẹni Ẹlẹ́rìí Jèhófà ti jà fún òmìnira ìsìn nílé ẹjọ́ níbi tó bá ti ṣeé ṣe, a sì ti ṣẹ́gun láwọn orílẹ̀-èdè kan. Ní Ilé Ẹjọ́ Gíga Jù Lọ Ilẹ̀ Amẹ́ríkà nìkan, àádọ́ta [50] ìgbà ni ilé ẹjọ́ ti dá wa láre.

      11. Àsọtẹ́lẹ̀ Jésù wo nípa àmì wíwàníhìn-ín rẹ̀ ló ti ṣẹ sára àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ní ọjọ́ Olúwa?

      11 Yàtọ̀ sáwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà, kò tún sí àwọn mìíràn tí wọ́n ń fi tọkàntọkàn tẹ̀ lé àṣẹ tí Jésù pa pé ká san àwọn ohun ti Késárì padà fún Késárì. (Lúùkù 20:25; Róòmù 13:1, 7) Síbẹ̀, ọ̀pọ̀ lara wa ni wọ́n ti fi sẹ́wọ̀n ní ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè lábẹ́ onírúurú ìjọba, ó sì ń bá a lọ bẹ́ẹ̀ títí di ìsinsìnyí ní ilẹ̀ Amẹ́ríkà, ní Yúróòpù, ní Áfíríkà, àti ní Éṣíà. Kò tún sí àwọn mìíràn tí wọn fi iye tó pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ nínú wọn sẹ́wọ̀n. Ara ohun tí Jésù sọ nígbà tó ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ ńlá nípa àmì wíwàníhìn-ín rẹ̀ ni pé: “Nígbà náà ni àwọn ènìyàn yóò fà yín lé ìpọ́njú lọ́wọ́, wọn yóò sì pa yín, ẹ ó sì jẹ́ ẹni ìkórìíra lọ́dọ̀ gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè ní tìtorí orúkọ mi.” (Mátíù 24:3, 9) Dájúdájú, èyí ti ṣẹ sára àwa Kristẹni Ẹlẹ́rìí Jèhófà ní ọjọ́ Olúwa.

      12. Báwo ni ẹgbẹ́ Jòhánù ṣe fún àwa èèyàn Ọlọ́run lókun láti kojú inúnibíni?

      12 Ẹgbẹ́ Jòhánù ń bá a lọ láti rán àwa èèyàn Ọlọ́run létí kókó pàtàkì tó wà nínú ọ̀rọ̀ tí Jésù sọ fáwọn Kristẹni tó wà ní Símínà, ìdí tí wọ́n sì fi ń ṣe èyí ni láti fún wa lókun láti kojú inúnibíni. Bí àpẹẹrẹ, bí inúnibíni Násì ṣe bẹ̀rẹ̀, Ilé Ìṣọ́ gbé àwọn àpilẹ̀kọ kan jáde lédè Gẹ̀ẹ́sì ní 1933 àti 1934. Irú àwọn àpilẹ̀kọ bẹ́ẹ̀ ni, “Ẹ Má Bẹ̀rù Wọn,” èyí tó jíròrò Mátíù 10:26-33; “Ìdánwò Lílekoko,” tó dá lórí Dáníẹ́lì 3:17, 18; àti “Ẹnu Àwọn Kìnnìún,” tí wọ́n gbé ka Dáníẹ́lì 6:22. Láàárín ọdún 1980 sí 1989 tó jẹ́ àkókò tá a kọ́kọ́ tẹ ìwé yìí jáde lédè Gẹ̀ẹ́sì àti àkókò tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà fojú winá inúnibíni rírorò ní èyí tó ju ogójì [40] ilẹ̀ lọ, ẹgbẹ́ Jòhánù ti fi ìwé ìròyìn Ilé Ìṣọ́ fún àwa èèyàn Ọlọ́run lókun nípasẹ̀ àwọn àpilẹ̀kọ bíi, “Wọn Jẹ Alayọ Bi A Tilẹ̀ Nṣe Inunibini Si Wọn!” àti “Awọn Kristian Nkoju Inunibini Pẹlu Ifarada.”b

      13. Bíi tàwọn Kristẹni ní Símínà, kí nìdí táwa Kristẹni Ẹlẹ́rìí Jèhófà kò fi bẹ̀rù inúnibíni?

      13 Ní tòdodo, àwa Kristẹni Ẹlẹ́rìí Jèhófà ń jìyà inúnibíni àtàwọn ìdánwò mìíràn fún ọjọ́ mẹ́wàá ìṣàpẹẹrẹ. Bíi tàwọn Kristẹni ní Símínà láyé ọjọ́un, a ò bẹ̀rù; bẹ́ẹ̀ ni kò yẹ kí ẹnikẹ́ni nínú wa fòyà bí wàhálà tó ń ṣẹlẹ̀ lórí ilẹ̀ ayé ṣe ń burú sí i. A ti múra tán láti fayọ̀ fara da ìjìyà, kódà láti fara dà á tí wọ́n bá ‘kó àwọn ohun ìní wa lọ.’ (Hébérù 10:32-34) Tá a bá ń kẹ́kọ̀ọ́ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tá a sì ń sọ ọ́ di tara wa, a óò jẹ́ alágbára nínú ìgbàgbọ́. Jẹ́ kó dá ọ lójú pé Jèhófà lágbára láti dáàbò bò ọ́ bó o ṣe ń pa ìṣòtítọ́ rẹ mọ́, á sì ṣe bẹ́ẹ̀. Bíbélì sọ pé: “[Ẹ] kó gbogbo àníyàn yín lé e, nítorí ó bìkítà fún yín.”—1 Pétérù 5:6-11.

      [Àwọ̀n Àlàyé ìsàlẹ̀ ìwé]

      a Ní nǹkan bí ọgọ́ta [60] ọdún lẹ́yìn tí Jòhánù kú, wọ́n fi iná sun Polycarp ẹni ọdún mẹ́rìndínláàádọ́rùn-ún [86] ní Símínà nítorí pé ó kọ̀ láti sọ pé òun ò nígbàgbọ́ nínú Jésù mọ́. Ìwé kan tá a gbọ́ pé wọ́n kọ ní àkókò tí nǹkan yìí ṣẹlẹ̀, tí àkọlé rẹ̀ jẹ́ The Martyrdom of Polycarp, sọ pé nígbà tí wọ́n ń kó igi tí wọ́n máa fi dá iná náà jọ, “àwọn Júù ràn wọ́n lọ́wọ́, ìtara tó sì pọ̀ lápọ̀jù ni wọ́n fi ṣe bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àṣà wọn,” bẹ́ẹ̀, “ọjọ́ Sábáàtì ńlá” lọ́jọ́ ìpànìyàn náà bọ́ sí.

      b Wo Ilé Ìṣọ́ November 1, 1933 lédè Gẹ̀ẹ́sì; Ilé Ìṣọ́ October 1 àti 15, December 1 àti 15, 1934 lédè Gẹ̀ẹ́sì; Ile-Iṣọ Naa ti November 1, 1983.

      [Àpótí/Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 39]

      Fún ọ̀pọ̀ ọdún làwọn òpìtàn ti ń jẹ́rìí sí ìdúróṣinṣin àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ní Jámánì nígbà ìṣàkóso Násì. Ìwé náà Mothers in the Fatherland, láti ọwọ́ òpìtàn Claudia Koonz, tí wọ́n tẹ̀ ní 1986, sọ pé: “Ọ̀kẹ́ àìmọye gbogbo àwọn ará ilẹ̀ Jámánì tí wọn ò sí nínú ẹgbẹ́ òṣèlú Násì wá ọ̀nà bí wọ́n á ṣe máa gbé lábẹ́ àkóso Násì bó tilẹ̀ jẹ́ pé wọn ò gba ti àkóso náà. . . . Àmọ́ ní ìhà kejì, ọ̀kẹ́ kan [20,000] àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà kọ̀ jálẹ̀ láti gbà pẹ̀lú ohun tí Ìjọba Násì ní kí wọ́n ṣe. . . . Àwọn ló ta yọ nínú àwọn tí wọn para pọ̀ yarí fún Ìjọba Násì, ìsìn wọn sì tì wọ́n lẹ́yìn. Àtìbẹ̀rẹ̀ làwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà ò ti gbà fún Ìjọba Násì lọ́nà èyíkéyìí. Kódà nígbà táwọn ọlọ́pàáanú tá a mọ̀ sí Gestapo pa iléeṣẹ́ wọn tó wà ní Jámánì run ní 1933 tí wọ́n sì fòfin de ẹ̀ya ìsìn wọn, síbẹ̀ wọ́n kọ̀ láti sọ pé ‘Heil Hitler’ [tó túmọ̀ sí Ti Hitler Ni Ìgbàlà]. Nǹkan bí ìdajì àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà (tí ọ̀pọ̀ jù lọ wọn jẹ́ ọkùnrin) ni wọ́n rán lọ sí àgọ́ ìṣẹ́niníṣẹ̀ẹ́, wọ́n pa ẹgbẹ̀rún kan lára wọn, ẹgbẹ̀rún mìíràn sì kú láàárín ọdún 1933 sí 1945. . . . Àwọn àlùfáà Kátólíìkì àti Pùròtẹ́sítáǹtì ń rọ àwọn ọmọ ìjọ wọn pé kí wọ́n ṣe ohun tí Hitler sọ. Tí wọ́n bá kọ̀, àṣẹ ṣọ́ọ̀ṣì àti ti Ìjọba ni wọ́n tàpá sí yẹn.”

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́