ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w20 May ojú ìwé 8-11
  • Àwọn Ọba Tó Ń Bára Wọn Jà Lákòókò Òpin Yìí

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Àwọn Ọba Tó Ń Bára Wọn Jà Lákòókò Òpin Yìí
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2020
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • “Ọba Àríwá” Ní Àkókò Òpin Yìí
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2020
  • Jèhófà Ṣí Àwọn Ohun Tí Ó “Gbọ́dọ̀ Ṣẹlẹ̀ Láìpẹ́” Payá
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2012
  • Ta Ni “Ọba Àríwá” Lónìí?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2020
  • A Rí Ojútùú Ohun Ìjìnlẹ̀ Kan Tó Ṣeni Ní Kàyéfì
    Ìṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2020
w20 May ojú ìwé 8-11

Àwọn Ọba Tó Ń Bára Wọn Jà Lákòókò Òpin Yìí

Àwọn kan lára àsọtẹ́lẹ̀ tá a tọ́ka sí nínú àtẹ yìí ní ìmúṣẹ lásìkò kan náà. Gbogbo wọn ló jẹ́rìí sí i pé “àkókò òpin” là ń gbé yìí.​—Dán. 12:4.

Àtẹ yìí jẹ́ ká mọ àwọn àsọtẹ́lẹ̀ nípa àwọn ọba àríwá àti ọba gúúsù, ó sì jẹ́ ká mọ ọba méjèèjì náà látọdún 1870 títí di báyìí.
  • Àkọ́kọ́ nínú àtẹ mẹ́rin yìí jẹ́ ká mọ àwọn àsọtẹ́lẹ̀ tó ṣẹ lásìkò kan náà láwọn ọjọ́ ìkẹyìn, ìyẹn láti nǹkan bí ọdún 1870 sí 1918. Ó jẹ́ ká mọ̀ pé ọjọ́ ìkẹyìn bẹ̀rẹ̀ látọdún 1914. Àsọtẹ́lẹ̀ 1: Ẹranko olórí méje ti bẹ̀rẹ̀ sí i ṣàkóso tipẹ́tipẹ́ ṣááju ọdún 1870 tí àtẹ yìí bẹ̀rẹ̀. Nígbà Ogun Àgbáyé Kìíní, wọ́n dá ọgbẹ́ sí ìkeje lára orí ẹranko náà. Láti 1917 lọ ọgbẹ́ náà jinná, ara ẹranko náà sì yá. Àsọtẹ́lẹ̀ 2: A mọ ẹni tí ọba àríwá jẹ́ lọ́dún 1871, a sì mọ ẹni tí ọba gúúsù jẹ́ lọ́dún 1870. Jámánì di ọba àríwá lọ́dún 1871. Ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì ni ọba gúúsù níbẹ̀rẹ̀, àmọ́ nígbà tí Amẹ́ríkà dara pọ̀ mọ́ ọn lọ́dún 1917, ó di Agbára Ayé Gẹ̀ẹ́sì àti Amẹ́ríkà. Àsọtẹ́lẹ̀ 3: Bẹ̀rẹ̀ látọdún 1870 Russell àtàwọn alábàákẹ́gbẹ́ rẹ̀ la mọ̀ sí ‘ìránṣẹ́’ náà. Bẹ̀rẹ̀ látọdún 1881, ìwé ìròyìn Zion’s Watch Tower rọ àwọn tó ń ka ìwé ìròyìn náà pé kí wọ́n máa wàásù ìhìn rere. Àsọtẹ́lẹ̀ 4: Láti 1914 lọ ìkórè bẹ̀rẹ̀. Wọ́n ya èpò kúrò lára àlìkámà. Àsọtẹ́lẹ̀ 5: Láti 1917 lọ, àtẹ́lẹsẹ̀ tó jẹ́ irin àti amọ̀ fara hàn. Àwọn nǹkan mí ì tó fara hàn: Àwọn nǹkan tó ṣẹlẹ̀ láyé látọdún 1914 sí 1918, wọ́n ja Ogun Àgbáyé I. Àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ tó kan àwọn èèyàn Jèhófà: Látọdún 1914 sí 1918, wọ́n fi àwọn Akẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì tó wà ní Ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì àti Jámánì sẹ́wọ̀n. Lọ́dún 1918, wọ́n fi àwọn tó ń múpò iwájú ní oríléeṣẹ́ wa tó wà ní Amẹ́ríkà sẹ́wọ̀n.
    Àsọtẹ́lẹ̀ 1.

    Ẹsẹ Ìwé Mímọ́ Ìfi. 11:7; 12:13, 17; 13:1-8, 12

    Àsọtẹ́lẹ̀ Ohun tó lé ní ẹgbẹ̀rún mẹ́ta (3,000) ọdún ni “ẹranko” náà fi ṣàkóso àwọn èèyàn. Ní àkókò òpin, wọ́n dá ọgbẹ́ sí ìkeje lára orí ẹranko náà. Nígbà tó yá, ọgbẹ́ náà jinná “gbogbo ayé” sì tẹ̀ lé ẹranko náà. Sátánì wá lo ẹranko náà láti “bá àwọn tó ṣẹ́ kù” lára ẹni àmì òróró jagun.

    Ìmúṣẹ Lẹ́yìn Ìkún Omi, àwọn ìjọba tó jẹ́ ọ̀tá Ọlọ́run bẹ̀rẹ̀ sí í ṣàkóso àwọn èèyàn. Ní ohun tó lé ní ẹgbẹ̀rún ọdún mẹ́ta (3,000) lẹ́yìn náà, Ilẹ̀ Ọba Gẹ̀ẹ́sì tó jẹ́ ọ̀kan lára àwọn ìjọba yẹn fara pa gan-an nígbà Ogun Àgbáyé Kìíní. Ó kọ́fẹ pa dà nígbà tí orílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà tì í lẹ́yìn. Pàápàá jù lọ ní àkókò òpin yìí, Sátánì ń lo àwọn ìjọba ayé láti ṣenúnibíni sáwọn èèyàn Ọlọ́run.

  • Àsọtẹ́lẹ̀ 2.

    Ẹsẹ Ìwé Mímọ́ Dán. 11:25-45

    Àsọtẹ́lẹ̀ Ọba àríwá àti ọba gúúsù máa bára wọn jà lákòókò òpin.

    Ìmúṣẹ Ilẹ̀ Jámánì bá ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì àti Amẹ́ríkà jagun. Lọ́dún 1945, Soviet Union àtàwọn alátìlẹyìn rẹ̀ di ọba àríwá. Lọ́dún 1991, ìjọba Soviet Union wá sópin ó sì pín yẹ́lẹyẹ̀lẹ. Nígbà tó yá Rọ́ṣíà àtàwọn alátìlẹyìn rẹ̀ di ọba àríwá.

  • Àsọtẹ́lẹ̀ 3.

    Ẹsẹ Ìwé Mímọ́ Àìsá. 61:1; Mál. 3:1; Lúùkù 4:18

    Àsọtẹ́lẹ̀ Jèhófà máa rán “ìránṣẹ́” rẹ̀ láti “tún ọ̀nà ṣe” kí Ìjọba Mèsáyà tó fìdí múlẹ̀. Ìránṣẹ́ yìí máa “kéde ìhìn rere fún àwọn oníwà pẹ̀lẹ́.”

    Ìmúṣẹ Bẹ̀rẹ̀ látọdún 1870, Arákùnrin C. T. Russell àtàwọn alábàákẹ́gbẹ́ rẹ̀ ṣèwádìí jinlẹ̀ nínú Bíbélì kí wọ́n lè ṣàlàyé ohun tí Bíbélì fi kọ́ni gan-an. Lọ́dún 1881, wọ́n rí i pé ó ṣe pàtàkì káwọn ìránṣẹ́ Ọlọ́run máa wàásù. Torí náà, wọ́n gbé àwọn àpilẹ̀kọ bí “À Ń Wá Ẹgbẹ̀rún Oníwàásù” àti “A Fòróró Yàn Wọ́n Láti Wàásù” jáde.

  • Àsọtẹ́lẹ̀ 4.

    Ẹsẹ Ìwé Mímọ́ Mát. 13:24-30, 36-43

    Àsọtẹ́lẹ̀ Ọ̀tá kan máa gbin èpò sí àárín àlìkámà, wọ́n máa jẹ́ kí àwọn méjèèjì jọ dàgbà débi pé èpò máa bo àlìkámà mọ́lẹ̀, wọ́n á sì wà bẹ́ẹ̀ títí dìgbà ìkórè. Lẹ́yìn ìyẹn, wọ́n á ya èpò sọ́tọ̀ kúrò lára àlìkámà.

    Ìmúṣẹ Àtọdún 1870 ni ìyàtọ̀ tó wà láàárín àwọn Kristẹni tòótọ́ àtàwọn èké Kristẹni ti túbọ̀ ṣe kedere. Lákòókò òpin yìí, Jèhófà ti kó àwọn Kristẹni tòótọ́ jọ sínú ìjọ rẹ̀, ó sì ti yà wọ́n sọ́tọ̀ kúrò lára àwọn èké Kristẹni.

  • Àsọtẹ́lẹ̀ 5.

    Ẹsẹ Ìwé Mímọ́ Dán. 2:31-33, 41-43

    Àsọtẹ́lẹ̀ Ère gìrìwò kan tó jẹ́ ti wúrà, fàdákà, bàbà àti irin ní àtẹ́lẹsẹ̀ irin àti amọ̀.

    Ìmúṣẹ Amọ̀ náà ṣàpẹẹrẹ àwọn gbáàtúù tó wà lábẹ́ àkóso Agbára Ayé Gẹ̀ẹ́sì àti Amẹ́ríkà. Àwọn èèyàn yìí ń ta ko ìjọba, ìyẹn sì mú kó ṣòro fún ìjọba láti lo agbára wọn tó dà bí irin.

  • Èkejì nínú àtẹ mẹ́rin yìí jẹ́ ká mọ àwọn àsọtẹ́lẹ̀ tó ṣẹ lásìkò kan náà láwọn ọjọ́ ìkẹyìn, ìyẹn láti nǹkan bí ọdún 1919 sí 1945. Jámánì ni ọba àríwá títí di ọdún 1945 nígbà tí Agbára Ayé Gẹ̀ẹ́sì àti Amẹ́ríkà sì jẹ́ ọba gúúsù. Àsọtẹ́lẹ̀ 6: Lọ́dún 1919, wọ́n kó àwọn Kristẹni ẹni àmì òróró jọ sínú ìjọ tá a mú pa dà bọ̀ sípò. Látọdún 1919 lọ, wọ́n túbọ̀ ń fìtara ṣe iṣẹ́ ìwàásù, wọn ò sì dáwọ́ dúró. Àsọtẹ́lẹ̀ 7: Lọ́dún 1920, wọ́n dá Ìmùlẹ̀ Àwọn Orílẹ̀-Èdè sílẹ̀, ó sì wà títí dìgbà Ogun Àgbáyé II. Àwọn nǹkan mí ì tó fara hàn: Àsọtẹ́lẹ̀ 1, ìṣàkóso ẹranko olórí méje náà ń bá a lọ. Àsọtẹ́lẹ̀ 5, àtẹ́lẹsẹ̀ tó jẹ́ irin àti amọ̀ ṣì wà nípò. Àwọn nǹkan tó ṣẹlẹ̀ láyé látọdún 1939 sí 1945, wọ́n ja Ogun Àgbáyé II. Àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ tó kan àwọn èèyàn Jèhófà: Látọdún 1933 sí 1945, wọ́n ju àwọn Ẹlẹ́rìí tó lé ní 11,000 sẹ́wọ̀n lórílẹ̀-èdè Jámánì. Látọdún 1939 sí 1945, wọ́n ju àwọn Ẹlẹ́rìí tó fẹ́rẹ̀ẹ́ tó 1,600 sẹ́wọ̀n nílẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì. Látọdún 1940 sí 1944, àwọn jàǹdùkú gbéjà ko àwọn Ẹlẹ́rìí níye ìgbà tó ju 2,500 lọ lórílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà.
    Àsọtẹ́lẹ̀ 6.

    Ẹsẹ Ìwé Mímọ́ Mát. 13:30; 24:14, 45; 28:19, 20

    Àsọtẹ́lẹ̀ Wọ́n máa kó “àlìkámà” jọ sínú “ilé ìkẹ́rùsí,” Jésù máa yan “ẹrú olóòótọ́ àti olóye” pé kó máa bójú tó àwọn “ará ilé” rẹ̀. Wọ́n sì máa wàásù “ìhìn rere Ìjọba yìí ní gbogbo ilẹ̀ ayé tí à ń gbé.”

    Ìmúṣẹ Lọ́dún 1919, Jésù yan ẹrú olóòótọ́ pé kó máa bójú tó àwọn èèyàn Ọlọ́run. Àtìgbà yẹn làwọn Akẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì ti túbọ̀ tẹra mọ́ iṣẹ́ ìwàásù. Lónìí, àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ń wàásù ní ilẹ̀ tó ju ọgọ́rùn-ún méjì (200) lọ, a sì ń tẹ àwọn ìwé tó ń ṣàlàyé Bíbélì jáde ní èdè tó ju ẹgbẹ̀rún kan (1,000) lọ.

  • Àsọtẹ́lẹ̀ 7.

    Ẹsẹ Ìwé Mímọ́ Dán. 12:11; Ìfi. 13:11, 14, 15

    Àsọtẹ́lẹ̀ Ẹranko kan tó “ní ìwo méjì” máa sọ fún àwọn tó ń gbé ayé pé kí wọ́n ṣe “ère ẹranko” kan, á sì fún ère “ẹranko náà ní èémí.”

    Ìmúṣẹ Agbára Ayé Gẹ̀ẹ́sì àti Amẹ́ríkà ló dá Ìmùlẹ̀ Àwọn Orílẹ̀-Èdè sílẹ̀, àwọn orílẹ̀-èdè míì sì dara pọ̀ mọ́ Ìmùlẹ̀ yìí. Nígbà tó yá, ọba àríwá náà dara pọ̀ mọ́ ọn, ìyẹn láti ọdún 1926 sí 1933. Ṣe làwọn èèyàn ń gbógo tó yẹ Ìjọba Ọlọ́run fún Ìmùlẹ̀ Àwọn Orílẹ̀-Èdè, ohun kan náà ni wọ́n sì ṣe fún Ìparapọ̀ Àwọn Orílẹ̀-Èdè tí wọ́n dá sílẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀.

  • Ẹ̀kẹta nínú àtẹ mẹ́rin yìí jẹ́ ká mọ àwọn àsọtẹ́lẹ̀ tó ṣẹ lásìkò kan náà láwọn ọjọ́ ìkẹyìn, ìyẹn láti ọdún 1945 sí 1991. Soviet Union àtàwọn alátìlẹyìn rẹ̀ ni ọba àríwá títí di ọdún 1991, nígbà tó yá Rọ́ṣíà àtàwọn alátìlẹyìn rẹ̀ di ọba àríwá. Agbára Ayé Gẹ̀ẹ́sì àti Amẹ́ríkà ṣì ni ọba gúúsù. Àsọtẹ́lẹ̀ 8: Eruku bọ́ǹbù jẹ́ ká rí ọṣẹ́ tí Agbára Ayé Gẹ̀ẹ́sì àti Amẹ́ríkà ṣe. Àsọtẹ́lẹ̀ 9: Wọ́n dá Ìparapọ̀ Àwọn Orílẹ̀-Èdè sílẹ̀ lọ́dún 1945, ó sì rọ́pò Ìmùlẹ̀ Àwọn Orílẹ̀-Èdè. Àwọn nǹkan mí ì tó fara hàn: Àsọtẹ́lẹ̀ 1, ìṣàkóso ẹranko olórí méje náà ń bá a lọ. Àsọtẹ́lẹ̀ 5, àtẹ́lẹsẹ̀ tó jẹ́ irin àti amọ̀ ṣì wà nípò. Àsọtẹ́lẹ̀ 6, lọ́dún 1945 àwọn akéde Ìjọba Ọlọ́run ju 156,000 lọ. Lọ́dún 1991, àwọn akéde Ìjọba Ọlọ́run ju 4,278,000 lọ. Àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ tó kan àwọn èèyàn Jèhófà: Látọdún 1945 sí 1951, ìjọba Soviet Union kó ẹgbẹẹgbẹ̀rún àwọn Ẹlẹ́rìí lọ sígbèkùn ní Siberia.
    Àsọtẹ́lẹ̀ 8.

    Ẹsẹ Ìwé Mímọ́ Dán. 8:23, 24

    Àsọtẹ́lẹ̀ Ọba kan tí ojú rẹ̀ le máa “mú ìparun wá lọ́nà tó ṣàrà ọ̀tọ̀.”

    Ìmúṣẹ Agbára Ayé Gẹ̀ẹ́sì àti Amẹ́ríkà ti pa àìlóǹkà èèyàn, ó sì ti pa ọ̀pọ̀ ilẹ̀ run. Bí àpẹẹrẹ nígbà Ogun Àgbáyé Kejì, orílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà fa ìparun tí kò láfiwé nígbà tó ju bọ́ǹbù méjì sí ilẹ̀ àwọn tó jẹ́ ọ̀tá òun àti ti ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì.

  • Àsọtẹ́lẹ̀ 9.

    Ẹsẹ Ìwé Mímọ́ Dán. 11:31; Ìfi. 17:3, 7-11

    Àsọtẹ́lẹ̀ Ẹranko “aláwọ̀ rírẹ̀dòdò” kan tó ní ìwo mẹ́wàá máa jáde látinú ọ̀gbun àìnísàlẹ̀, òun sì ni ọba kẹjọ. Ìwé Dáníẹ́lì pe ọba yìí ní “ohun ìríra tó ń fa ìsọdahoro.”

    Ìmúṣẹ Nígbà Ogun Àgbáyé Kejì, Ìmùlẹ̀ Àwọn Orílẹ̀-Èdè kò lágbára mọ́. Lẹ́yìn tí ogun náà parí, ‘wọ́n gbé’ Ìparapọ̀ Àwọn Orílẹ̀-Èdè kalẹ̀. Ṣe làwọn èèyàn ń gbógo tó yẹ Ìjọba Ọlọ́run fún Ìparapọ̀ Àwọn Orílẹ̀-Èdè bíi ti Ìmùlẹ̀ Àwọn Orílẹ̀-Èdè tó wà ṣáájú rẹ̀. Ìparapọ̀ Àwọn Orílẹ̀-Èdè máa gbéjà ko ẹ̀sìn.

  • Ẹ̀kẹrin nínú àtẹ mẹ́rin yìí jẹ́ ká mọ àwọn àsọtẹ́lẹ̀ tó ṣẹ lásìkò kan náà láwọn ọjọ́ ìkẹyìn yìí títí dìgbà ogun Amágẹ́dọ́nì. Rọ́ṣíà àtàwọn alátìlẹyìn rẹ̀ ni ọba àríwá. Agbára Ayé Gẹ̀ẹ́sì àti Amẹ́ríkà ṣì ni ọba gúúsù. Àsọtẹ́lẹ̀ 10: Àwọn alákòóso kéde ‘àlàáfíà àti ààbò.’ Lẹ́yìn náà, ìpọ́njú ńlá bẹ̀rẹ̀ . Àsọtẹ́lẹ̀ 11: Àwọn orílẹ̀-èdè pa gbogbo ẹ̀sìn èké run. Àsọtẹ́lẹ̀ 12: Àwọn ìjọba gbéjà ko àwọn èèyàn Ọlọ́run. Jèhófà kó àwọn tó ṣẹ́ kù lára àwọn ẹni àmì òróró lọ sọ́run. Àsọtẹ́lẹ̀ 13: Amágẹ́dọ́nì. Ẹni tó jókòó sórí ẹṣin funfun parí ìṣẹ́gun rẹ̀. Jèhófà pa ẹranko olórí méje náà run; òkúta kan kọ lu àtẹ́lẹsẹ̀ irin àti àmọ́ ère gìrìwò náà, ó sì rún eré náà wómúwómú. Àwọn nǹkan mí ì tó fara hàn: Àsọtẹ́lẹ̀ 1, ìṣàkóso ẹranko olórí méje náà ń bá a lọ títí dìgbà ogun Amágẹ́dọ́nì. Àsọtẹ́lẹ̀ 5, àtẹ́lẹsẹ̀ tó jẹ́ irin àti amọ̀ ṣì wà nípò títí dìgbà ogun Amágẹ́dọ́nì. Àsọtẹ́lẹ̀ 6, lónìí àwọn akéde ju 8,580,000 lọ. Àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ tó kan àwọn èèyàn Jèhófà: Lọ́dún 2017, àwọn aláṣẹ ilẹ̀ Rọ́ṣíà ju àwọn Ẹlẹ́rìí sẹ́wọ̀n, wọ́n sì gbẹ́sẹ̀ lé àwọn ilé ètò Ọlọ́run.
    Àsọtẹ́lẹ̀ 10 àti 11.

    Ẹsẹ Ìwé Mímọ́ 1 Tẹs. 5:3; Ìfi. 17:16

    Àsọtẹ́lẹ̀ Àwọn orílẹ̀-èdè máa kéde “àlàáfíà àti ààbò,” bẹ́ẹ̀ sì ni “ìwo mẹ́wàá” àti “ẹranko náà” máa gbéjà ko “aṣẹ́wó náà,” wọ́n sì máa pa á run. Lẹ́yìn ìyẹn, Jèhófà máa pa gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè run yán-án-yán.

    Ìmúṣẹ Àwọn orílẹ̀-èdè máa sọ pé àwọn ti jẹ́ kí àlàáfíà àti ààbò wà láyé. Lẹ́yìn náà, àwọn orílẹ̀-èdè tó ń ti Ìparapọ̀ Àwọn Orílẹ̀-Èdè lẹ́yìn máa pa gbogbo ẹ̀sìn èké run. Ìṣẹ̀lẹ̀ yìí ló máa bẹ̀rẹ̀ ìpọ́njú ńlá. Ìpọ́njú ńlá yìí máa dópin nígbà tí Jésù bá pa èyí tó ṣẹ́ kù lára ayé Sátánì run nígbà ogun Amágẹ́dọ́nì.

  • Àsọtẹ́lẹ̀ 12.

    Ẹsẹ Ìwé Mímọ́ Ìsík. 38:​11, 14-17; Mát. 24:31

    Àsọtẹ́lẹ̀ Gọ́ọ̀gù máa wọ ilẹ̀ àwọn èèyàn Ọlọ́run. Lẹ́yìn náà, àwọn áńgẹ́lì máa kó “àwọn àyànfẹ́” jọ.

    Ìmúṣẹ Ọba àríwá àtàwọn ìjọba ayé yòókù máa gbéjà ko àwọn èèyàn Ọlọ́run. Ní àkókò díẹ̀ lẹ́yìn tí ìgbéjàkò yẹn bá bẹ̀rẹ̀, Jèhófà máa kó àwọn tó ṣẹ́ kù lára àwọn ẹni àmì òróró lọ sọ́run.

  • Àsọtẹ́lẹ̀ 13.

    Ẹsẹ Ìwé Mímọ́ Ìsík. 38:18-23; Dán. 2:34, 35, 44, 45; Ìfi. 6:2; 16:14, 16; 17:14; 19:20

    Àsọtẹ́lẹ̀ ‘Ẹni tó jókòó sórí ẹṣin funfun’ máa “parí ìṣẹ́gun rẹ̀” nígbà tó bá pa Gọ́ọ̀gù àtàwọn ọmọ ogun rẹ̀ run. Wọ́n máa ju “ẹranko náà” sínú “adágún iná tó ń jó,” òkúta kan sì máa rún ère gìrìwò náà wómúwómú.

    Ìmúṣẹ Jésù tó jẹ́ Ọba Ìjọba Ọlọ́run máa wá gba àwọn èèyàn Ọlọ́run sílẹ̀. Òun àtàwọn ọ̀kẹ́ méje ó lé ẹgbàajì (144,000) tí wọ́n á jọ ṣàkóso pa pọ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ ogun ọ̀run máa pa gbogbo orílẹ̀-èdè tó gbéjà ko àwọn èèyàn Ọlọ́run run, ìyẹn ló sì máa fòpin sí ìṣàkóso Sátánì.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́