2 Jèhófà sọ fún Mósè pé: “Sọ fún Áárónì ẹ̀gbọ́n rẹ pé kó má kàn wá sínú ibi mímọ́+ tó wà lẹ́yìn aṣọ ìdábùú+ nígbàkigbà, níwájú ìbòrí Àpótí, kó má bàa kú,+ torí màá fara hàn nínú ìkùukùu*+ lórí ìbòrí+ náà.
14 “Kó mú lára ẹ̀jẹ̀+ akọ màlúù náà, kó fi ìka rẹ̀ wọ́n ọn síwájú ìbòrí náà ní apá ìlà oòrùn, kó sì fi ìka rẹ̀ wọ́n lára ẹ̀jẹ̀ náà lẹ́ẹ̀méje síwájú ìbòrí+ náà.
11 Lẹ́yìn náà, Dáfídì fún Sólómọ́nì ọmọ rẹ̀ ní àwòrán ìkọ́lé+ ti ibi àbáwọlé*+ àti ti àwọn ilé rẹ̀, àwọn yàrá tí wọ́n ń kó nǹkan pa mọ́ sí, àwọn yàrá orí òrùlé, àwọn yàrá inú àti ti ilé ìbòrí ìpẹ̀tù.*+