17 “Kí ló dé tí ẹ ò jẹ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ náà ní ibi mímọ́,+ ṣebí ohun mímọ́ jù lọ ni, ó sì ti fún yín, kí ẹ lè ru ẹ̀bi àpéjọ náà, kí ẹ sì ṣe ètùtù fún wọn níwájú Jèhófà?
9 Èyí ló máa jẹ́ tìrẹ nínú ọrẹ mímọ́ jù lọ tí wọ́n fi iná sun: gbogbo ọrẹ tí wọ́n bá mú wá, títí kan àwọn ọrẹ ọkà+ wọn àtàwọn ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀+ wọn pẹ̀lú àwọn ẹbọ ẹ̀bi+ wọn tí wọ́n mú wá fún mi. Ohun mímọ́ jù lọ ló jẹ́ fún ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ.