ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Ẹ́kísódù 30:34-36
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 34 Jèhófà wá sọ fún Mósè pé: “Mú àwọn lọ́fínńdà yìí ní ìwọ̀n kan náà:+ àwọn ẹ̀kán sítákítè, ọ́níkà, gábánọ́mù onílọ́fínńdà àti ògidì oje igi tùràrí. 35 Kí o fi ṣe tùràrí;+ kí o ro àwọn èròjà náà pọ̀ dáadáa,* fi iyọ̀ sí i,+ kó jẹ́ ògidì, kó sì jẹ́ mímọ́. 36 Kí o gún lára rẹ̀, kó sì kúnná, kí o wá bù lára rẹ̀ síwájú Ẹ̀rí nínú àgọ́ ìpàdé, níbi tí màá ti pàdé rẹ. Kó jẹ́ mímọ́ jù lọ fún yín.

  • Ìfihàn 5:8
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 8 Nígbà tó gbà á, àwọn ẹ̀dá alààyè mẹ́rin àti àwọn àgbààgbà mẹ́rìnlélógún  + (24) náà wólẹ̀ níwájú Ọ̀dọ́ Àgùntàn náà, ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn ní háàpù kan lọ́wọ́ àti abọ́ wúrà tí tùràrí kún inú rẹ̀. (Tùràrí náà túmọ̀ sí àdúrà àwọn ẹni mímọ́.)+

  • Ìfihàn 8:3-5
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 3 Áńgẹ́lì míì dé, ó dúró níbi pẹpẹ,+ ó gbé àwo tùràrí tí wọ́n fi wúrà ṣe* dání, a sì fún un ní tùràrí tó pọ̀ gan-an+ pé kó sun ún lórí pẹpẹ tí wọ́n fi wúrà ṣe+ tó wà níwájú ìtẹ́ náà bí gbogbo àwọn ẹni mímọ́ ṣe ń gbàdúrà. 4 Èéfín tùràrí látọwọ́ áńgẹ́lì náà àti àdúrà+ àwọn ẹni mímọ́ gòkè lọ síwájú Ọlọ́run. 5 Àmọ́ lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀, áńgẹ́lì náà mú àwo tùràrí náà, ó kó díẹ̀ lára iná pẹpẹ sínú rẹ̀, ó sì jù ú sí ayé. Ààrá sán, a gbọ́ ohùn, mànàmáná kọ yẹ̀rì,+ ìmìtìtì ilẹ̀ sì wáyé.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́