ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Ẹ́kísódù 17:14
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 14 Jèhófà wá sọ fún Mósè pé: “Kọ ọ̀rọ̀ yìí sínú ìwé fún ìrántí, kí o sì tún un sọ fún Jóṣúà pé, ‘Màá mú kí wọ́n gbàgbé Ámálékì pátápátá lábẹ́ ọ̀run.’”+

  • 1 Sámúẹ́lì 14:47, 48
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 47 Sọ́ọ̀lù fìdí ìjọba rẹ̀ múlẹ̀ lórí Ísírẹ́lì, ó sì bá gbogbo ọ̀tá rẹ̀ jà níbi gbogbo, ó bá àwọn ọmọ Móábù+ àti àwọn ọmọ Ámónì+ jà, ó tún bá àwọn ọmọ Édómù+ àti àwọn ọba Sóbà+ pẹ̀lú àwọn Filísínì+ jà; ó sì ń ṣẹ́gun níbikíbi tó bá lọ. 48 Ó fi ìgboyà jà, ó ṣẹ́gun àwọn ọmọ Ámálékì,+ ó sì gba Ísírẹ́lì lọ́wọ́ àwọn tó ń kó ohun ìní wọn lọ.

  • 1 Sámúẹ́lì 15:1-3
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 15 Nígbà náà, Sámúẹ́lì sọ fún Sọ́ọ̀lù pé: “Jèhófà rán mi láti fòróró yàn ọ́ ṣe ọba lórí àwọn èèyàn rẹ̀ Ísírẹ́lì;+ ní báyìí, gbọ́ ohun tí Jèhófà fẹ́ sọ.+ 2 Ohun tí Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun sọ nìyí: ‘Màá pe àwọn ọmọ Ámálékì wá jíhìn nítorí ohun tí wọ́n ṣe sí Ísírẹ́lì bí wọ́n ṣe gbéjà kò ó nígbà tó ń jáde bọ̀ láti Íjíbítì.+ 3 Ní báyìí, lọ ṣá àwọn ọmọ Ámálékì+ balẹ̀, kí o sì pa wọ́n run pátápátá+ pẹ̀lú gbogbo ohun tí wọ́n ní. O ò gbọ́dọ̀ dá wọn sí;* ṣe ni kí o pa gbogbo wọn,+ ọkùnrin àti obìnrin, ọmọdé àti ọmọ jòjòló, akọ màlúù àti àgùntàn, ràkúnmí àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.’”+

  • 1 Kíróníkà 4:42, 43
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 42 Àwọn kan lára àwọn ọmọ Síméónì, àwọn ọgọ́rùn-ún márùn-ún (500), lọ sí Òkè Séírì+ pẹ̀lú Pẹlatáyà, Nearáyà, Refáyà àti Úsíélì, àwọn ọmọ Íṣì tí wọ́n ṣáájú wọn. 43 Wọ́n pa àwọn tó ṣẹ́ kù lára àwọn Ámálékì+ tó yè bọ́, wọ́n sì ń gbé ibẹ̀ títí di òní yìí.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́