34 Nígbà tí Áhábù ń jọba, Híélì ará Bẹ́tẹ́lì tún Jẹ́ríkò kọ́. Ẹ̀mí Ábírámù àkọ́bí rẹ̀ ló fi dí i nígbà tó fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lélẹ̀, ẹ̀mí Ségúbù àbíkẹ́yìn rẹ̀ ló sì fi dí i nígbà tó gbé àwọn ilẹ̀kùn rẹ̀ nàró, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ tí Jèhófà gbẹnu Jóṣúà ọmọ Núnì sọ.+