-
Nọ́ńbà 27:21Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
21 Á sì máa dúró níwájú àlùfáà Élíásárì, ẹni tí yóò máa bá a ṣe ìwádìí níwájú Jèhófà nípasẹ̀ ohun tí Úrímù+ bá sọ. Àṣẹ rẹ̀ ni wọ́n á máa tẹ̀ lé tí wọ́n bá ń jáde, àṣẹ rẹ̀ ni wọ́n á sì máa tẹ̀ lé tí wọ́n bá ń wọlé, òun àti gbogbo àwọn ọmọ Ísírẹ́lì pẹ̀lú gbogbo àpéjọ náà.”
-
-
1 Sámúẹ́lì 30:7, 8Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
7 Ìgbà náà ni Dáfídì sọ fún àlùfáà Ábíátárì+ ọmọ Áhímélékì pé: “Jọ̀wọ́, mú éfódì wá.”+ Torí náà, Ábíátárì mú éfódì wá fún Dáfídì. 8 Dáfídì wádìí lọ́dọ̀ Jèhófà+ pé: “Ṣé kí n lépa àwọn jàǹdùkú* yìí? Ṣé màá lé wọn bá?” Ó sọ fún un pé: “Lépa wọn, torí ó dájú pé wàá lé wọn bá, wàá sì gba àwọn èèyàn rẹ pa dà.”+
-