16 Kí o run gbogbo èèyàn tí Jèhófà Ọlọ́run rẹ bá fi lé ọ lọ́wọ́.+ O* ò gbọ́dọ̀ káàánú wọn,+ o ò sì gbọ́dọ̀ sin àwọn ọlọ́run wọn,+ torí ìdẹkùn ló máa jẹ́ fún ọ.+
3 Ní báyìí, lọ ṣá àwọn ọmọ Ámálékì+ balẹ̀, kí o sì pa wọ́n run pátápátá+ pẹ̀lú gbogbo ohun tí wọ́n ní. O ò gbọ́dọ̀ dá wọn sí;* ṣe ni kí o pa gbogbo wọn,+ ọkùnrin àti obìnrin, ọmọdé àti ọmọ jòjòló, akọ màlúù àti àgùntàn, ràkúnmí àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.’”+
9 Ṣùgbọ́n Sọ́ọ̀lù àti àwọn ọmọ ogun rẹ̀ dá Ágágì sí* àti agbo ẹran tó dára jù, títí kan ọ̀wọ́ ẹran, àwọn ẹran àbọ́sanra, àwọn àgbò àti gbogbo ohun tó dára.+ Wọn ò fẹ́ pa wọ́n run. Àmọ́ wọ́n pa gbogbo nǹkan tí kò ní láárí, tí kò sì wúlò run.