-
2 Sámúẹ́lì 5:6-10Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
6 Ọba àti àwọn ọkùnrin rẹ̀ jáde lọ sí Jerúsálẹ́mù láti lọ gbéjà ko àwọn ará Jébúsì+ tó ń gbé ilẹ̀ náà. Wọ́n pẹ̀gàn Dáfídì pé: “O ò ní wọ ibí yìí! Kódà àwọn afọ́jú àti àwọn arọ ló máa lé ọ dà nù.” Èrò wọn ni pé, ‘Dáfídì ò ní wọ ibí yìí.’+ 7 Síbẹ̀, Dáfídì gba ibi ààbò Síónì, èyí tó wá di Ìlú Dáfídì.+ 8 Nítorí náà, Dáfídì sọ lọ́jọ́ yẹn pé: “Kí àwọn tó máa lọ gbéjà ko àwọn ará Jébúsì gba ibi ihò omi wọlé láti pa ‘àwọn arọ àti àwọn afọ́jú,’ tí Dáfídì* kórìíra!” Ìdí nìyẹn tí wọ́n fi ń sọ pé: “Àwọn afọ́jú àti àwọn arọ kò ní wọlé.” 9 Nígbà náà, Dáfídì bẹ̀rẹ̀ sí í gbé ibi ààbò, wọ́n* sì pe ibẹ̀ ní Ìlú Dáfídì; Dáfídì bẹ̀rẹ̀ sí í kọ́lé yí ká orí Òkìtì*+ àti láwọn ibòmíì nínú ìlú.+ 10 Bí agbára Dáfídì ṣe ń pọ̀ sí i+ nìyẹn, Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun sì wà pẹ̀lú rẹ̀.+
-