-
Jẹ́nẹ́sísì 49:22-26Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
22 “Jósẹ́fù+ jẹ́ èéhù igi eléso, igi tó ń so lẹ́bàá ìsun omi, tí àwọn ẹ̀ka rẹ̀ nà sórí ògiri. 23 Àmọ́ àwọn tafàtafà ń fòòró rẹ̀, wọ́n ta á lọ́fà, wọ́n sì ń dì í sínú.+ 24 Síbẹ̀, ọfà* rẹ̀ dúró sí àyè rẹ̀,+ ọwọ́ rẹ̀ lágbára, ó sì já fáfá.+ Èyí wá láti ọwọ́ alágbára Jékọ́bù, láti ọwọ́ olùṣọ́ àgùntàn, òkúta Ísírẹ́lì. 25 Ó* wá láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run bàbá rẹ, yóò sì ràn ọ́ lọ́wọ́, ó wà pẹ̀lú Olódùmarè, yóò sì fi àwọn ìbùkún ọ̀run lókè bù kún ọ, pẹ̀lú àwọn ìbùkún ibú nísàlẹ̀,+ pẹ̀lú àwọn ìbùkún ọmú àti ilé ọmọ. 26 Àwọn ìbùkún bàbá rẹ yóò ga ju àwọn ìbùkún òkè ayérayé lọ, yóò ga ju àwọn ohun tó wuni lórí àwọn òkè tó ti wà tipẹ́.+ Wọn yóò máa wà ní orí Jósẹ́fù, ní àtàrí ẹni tí Ọlọ́run yà sọ́tọ̀ láàárín àwọn arákùnrin rẹ̀.+
-