-
1 Kíróníkà 3:1-9Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
3 Àwọn ọmọkùnrin tí wọ́n bí fún Dáfídì ní Hébúrónì+ nìyí: Ámínónì+ àkọ́bí, ìyá rẹ̀ ni Áhínóámù+ ará Jésírẹ́lì; ìkejì ni Dáníẹ́lì, ìyá rẹ̀ ni Ábígẹ́lì+ ará Kámẹ́lì; 2 ìkẹta ni Ábúsálómù+ ọmọ Máákà ọmọbìnrin Tálímáì ọba Géṣúrì; ìkẹrin ni Ádóníjà+ ọmọ Hágítì; 3 ìkarùn-ún ni Ṣẹfatáyà, ìyá rẹ̀ ni Ábítálì; ìkẹfà sì ni Ítíréámù, ìyá rẹ̀ ní Ẹ́gílà ìyàwó Dáfídì. 4 Àwọn mẹ́fà yìí ni wọ́n bí fún un ní Hébúrónì; ọdún méje àti oṣù mẹ́fà ló fi jọba níbẹ̀, ó sì fi ọdún mẹ́tàlélọ́gbọ̀n (33) jọba ní Jerúsálẹ́mù.+
5 Àwọn tí wọ́n bí fún un ní Jerúsálẹ́mù+ nìyí: Ṣíméà, Ṣóbábù, Nátánì+ àti Sólómọ́nì;+ ìyá àwọn mẹ́rin yìí ni Bátí-ṣébà+ ọmọbìnrin Ámíélì. 6 Àwọn ọmọ mẹ́sàn-án míì ni Íbárì, Élíṣámà, Élífélétì, 7 Nógà, Néfégì, Jáfíà, 8 Élíṣámà, Élíádà àti Élífélétì. 9 Gbogbo àwọn yìí ni ọmọ Dáfídì, yàtọ̀ sí àwọn ọmọ àwọn wáhàrì,* Támárì+ sì ni arábìnrin wọn.
-