-
1 Kíróníkà 9:22-27Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
22 Gbogbo àwọn tí wọ́n yàn ṣe aṣọ́bodè ní àwọn ibi àbáwọlé jẹ́ igba ó lé méjìlá (212). Wọ́n wà ní ibi tí wọ́n tẹ̀ dó sí bí orúkọ wọn ṣe wà nínú àkọsílẹ̀ ìdílé wọn.+ Dáfídì àti Sámúẹ́lì aríran+ ló yàn wọ́n sí ipò ẹni tó ṣeé fọkàn tán tí wọ́n wà. 23 Àwọn àti àwọn ọmọ wọn ló ń ṣọ́ àwọn ẹnubodè ilé Jèhófà,+ ìyẹn ilé àgọ́. 24 Àwọn aṣọ́bodè wà ní ẹ̀gbẹ́ mẹ́rẹ̀ẹ̀rin, ìyẹn ní ìlà oòrùn, ìwọ̀ oòrùn, àríwá àti gúúsù.+ 25 Látìgbàdégbà, àwọn arákùnrin wọn máa ń wá láti àwọn ibi tí wọ́n tẹ̀ dó sí láti bá wọn ṣiṣẹ́ fún ọjọ́ méje. 26 Àwọn olórí* aṣọ́bodè mẹ́rin ló wà ní ipò ẹni tó ṣeé fọkàn tán. Ọmọ Léfì ni wọ́n, àwọn ló sì ń bójú tó àwọn yàrá* àti àwọn ibi ìṣúra tó wà nínú ilé Ọlọ́run tòótọ́.+ 27 Wọ́n máa ń wà níbi tí wọ́n ti ń ṣiṣẹ́ káàkiri ilé Ọlọ́run tòótọ́ láti òru mọ́jú, nítorí àwọn ló ń ṣe iṣẹ́ olùṣọ́, ọwọ́ wọn ni kọ́kọ́rọ́ máa ń wà, àwọn ló sì ń ṣí ilé náà láràárọ̀.
-