ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Jẹ́nẹ́sísì 17:8
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 8 Màá fún ìwọ àti ọmọ* rẹ ní ilẹ̀ tí o gbé nígbà tí o jẹ́ àjèjì,+ ìyẹn gbogbo ilẹ̀ Kénáánì, yóò jẹ́ ohun ìní wọn títí láé, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run+ wọn.”

  • Jẹ́nẹ́sísì 23:4
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 4 “Àjèjì ni mo jẹ́ nílẹ̀ yìí,+ àárín yín ni mo sì ń gbé. Ẹ fún mi níbì kan tí mo lè sìnkú sí nílẹ̀ yín, kí n lè sin òkú ìyàwó mi síbẹ̀.”

  • 1 Kíróníkà 16:19-22
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 19 Èyí jẹ́ nígbà tí ẹ kéré níye,

      Bẹ́ẹ̀ ni, tí ẹ kéré níye gan-an, tí ẹ sì jẹ́ àjèjì ní ilẹ̀ náà.+

      20 Wọ́n ń rìn kiri láti orílẹ̀-èdè dé orílẹ̀-èdè,

      Láti ọ̀dọ̀ ìjọba kan dé ọ̀dọ̀ àwọn èèyàn míì.+

      21 Kò gbà kí ẹnikẹ́ni ni wọ́n lára,+

      Ṣùgbọ́n nítorí wọn, ó bá àwọn ọba wí,+

      22 Ó ní, ‘Ẹ má fọwọ́ kan àwọn ẹni àmì òróró mi,

      Ẹ má sì ṣe ohun búburú sí àwọn wòlíì mi.’+

  • Ìṣe 7:4, 5
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 4 Lẹ́yìn náà, ó jáde kúrò ní ilẹ̀ àwọn ará Kálídíà, ó sì ń gbé ní Háránì. Lẹ́yìn tí bàbá rẹ̀ kú,+ Ọlọ́run darí rẹ̀ láti ibẹ̀ pé kí ó lọ máa gbé ní ilẹ̀ tí ẹ̀ ń gbé báyìí.+ 5 Síbẹ̀, kò fún un ní ogún kankan nínú rẹ̀, rárá, kò tiẹ̀ fún un ní ibi tó lè gbẹ́sẹ̀ lé; àmọ́ ó ṣèlérí pé òun máa fún un láti fi ṣe ohun ìní, lẹ́yìn rẹ̀ òun á fún ọmọ* rẹ̀,+ bó tiẹ̀ jẹ́ pé kò tíì ní ọmọ kankan.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́