12 “Ní báyìí, ìwọ Ísírẹ́lì, kí ni Jèhófà Ọlọ́run rẹ fẹ́ kí o ṣe?+ Kò ju pé: kí o máa bẹ̀rù Jèhófà Ọlọ́run rẹ,+ kí o máa rìn ní gbogbo ọ̀nà rẹ̀,+ kí o máa nífẹ̀ẹ́ rẹ̀, kí o máa fi gbogbo ọkàn rẹ àti gbogbo ara* rẹ sin Jèhófà Ọlọ́run rẹ,+
16 Ní àkókò yẹn, àwọn tó bẹ̀rù Jèhófà bá ara wọn sọ̀rọ̀, kálukú pẹ̀lú ẹnì kejì rẹ̀, Jèhófà sì ń fiyè sí i, ó sì ń fetí sílẹ̀. Wọ́n sì kọ ìwé ìrántí kan níwájú rẹ̀+ torí àwọn tó ń bẹ̀rù Jèhófà àti àwọn tó ń ṣe àṣàrò lórí orúkọ rẹ̀.*+