ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Jẹ́nẹ́sísì 20:6
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 6 Ọlọ́run tòótọ́ sọ fún un lójú àlá pé: “Mo mọ̀ pé òótọ́ inú lo fi ṣe ohun tí o ṣe, torí ẹ̀ ni mi ò fi jẹ́ kí o dẹ́ṣẹ̀ sí mi. Ìdí nìyẹn tí mi ò fi jẹ́ kí o fọwọ́ kàn án.

  • Diutarónómì 17:12
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 12 Ṣe ni kí ẹ pa ẹni tó bá ṣorí kunkun,* tó kọ̀ láti fetí sí àlùfáà tó ń bá Jèhófà Ọlọ́run rẹ ṣiṣẹ́ tàbí sí adájọ́ náà.+ Kí o mú ohun tó burú kúrò ní Ísírẹ́lì.+

  • 1 Sámúẹ́lì 15:23
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 23 nítorí ẹ̀ṣẹ̀ kan náà ni ìṣọ̀tẹ̀+ àti iṣẹ́ wíwò+ jẹ́, ọ̀kan náà sì ni kíkọjá àyè jẹ́ pẹ̀lú lílo agbára abàmì àti ìbọ̀rìṣà.* Nítorí o ti kọ ọ̀rọ̀ Jèhófà,+ òun náà ti kọ̀ ọ́ ní ọba.”+

  • 2 Sámúẹ́lì 6:7
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 7 Ni ìbínú Jèhófà bá ru sí Úsà, Ọlọ́run tòótọ́ pa á  + níbẹ̀ nítorí ìwà àìlọ́wọ̀+ tí ó hù, ó sì kú síbẹ̀ ní ẹ̀gbẹ́ Àpótí Ọlọ́run tòótọ́.

  • 2 Kíróníkà 26:16-18
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 16 Àmọ́, bó ṣe di alágbára tán, ìgbéraga wọ̀ ọ́ lẹ́wù débi tó fi fa àjálù bá ara rẹ̀, ó hùwà àìṣòótọ́ sí Jèhófà Ọlọ́run rẹ̀ bó ṣe wá sínú tẹ́ńpìlì Jèhófà láti sun tùràrí lórí pẹpẹ tùràrí.+ 17 Lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀, àlùfáà Asaráyà àti ọgọ́rin (80) àlùfáà Jèhófà tó nígboyà wọlé tẹ̀ lé e. 18 Wọ́n kojú Ọba Ùsáyà, wọ́n sì sọ fún un pé: “Ùsáyà, kò tọ́ sí ọ láti sun tùràrí sí Jèhófà!+ Àwọn àlùfáà nìkan ló yẹ kó máa sun tùràrí, torí àwọn ni àtọmọdọ́mọ Áárónì,+ àwọn tí a ti yà sí mímọ́. Jáde kúrò ní ibi mímọ́, nítorí o ti hùwà àìṣòótọ́, o ò sì ní rí ògo kankan gbà lọ́dọ̀ Jèhófà Ọlọ́run nítorí èyí.”

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́