ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Àìsáyà 56:6, 7
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    •  6 Ní ti àwọn àjèjì tó fara mọ́ Jèhófà láti máa ṣe ìránṣẹ́ fún un,

      Láti nífẹ̀ẹ́ orúkọ Jèhófà,+

      Kí wọ́n sì di ìránṣẹ́ rẹ̀,

      Gbogbo àwọn tó ń pa Sábáàtì mọ́, tí wọn ò sì kẹ́gàn rẹ̀,

      Tí wọ́n ń rọ̀ mọ́ májẹ̀mú mi,

       7 Màá tún mú wọn wá sí òkè mímọ́ mi,+

      Màá sì mú kí wọ́n máa yọ̀ nínú ilé àdúrà mi.

      Màá tẹ́wọ́ gba odindi ẹbọ sísun wọn àtàwọn ẹbọ wọn lórí pẹpẹ mi.

      Torí a ó máa pe ilé mi ní ilé àdúrà fún gbogbo èèyàn.”+

  • Àìsáyà 66:20
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 20 Wọ́n máa kó gbogbo àwọn arákùnrin yín jáde látinú gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè,+ wọ́n á fi wọ́n ṣe ẹ̀bùn fún Jèhófà, lórí ẹṣin, nínú kẹ̀kẹ́ ẹṣin, nínú kẹ̀kẹ́ tí wọ́n bo orí rẹ̀, lórí àwọn ìbaaka àti lórí àwọn ràkúnmí tó ń yára kánkán, wọ́n á kó wọn wá sórí òkè mímọ́ mi, ìyẹn Jerúsálẹ́mù,” ni Jèhófà wí, “bí ìgbà tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì fi ohun èlò tó mọ́ gbé ẹ̀bùn wọn wá sínú ilé Jèhófà.”

  • Ìsíkíẹ́lì 20:40
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 40 “‘Torí ní òkè mímọ́ mi, ní òkè gíga Ísírẹ́lì,+ ni gbogbo ilé Ísírẹ́lì yóò ti sìn mí ní ilẹ̀ náà, gbogbo wọn pátá,’ ni Jèhófà Olúwa Ọba Aláṣẹ wí.+ ‘Inú mi yóò dùn sí wọn níbẹ̀, èmi yóò sì béèrè ọrẹ yín àti àwọn àkọ́so ẹ̀bùn yín, gbogbo ohun mímọ́ yín.+

  • Jóẹ́lì 3:17
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 17 Ẹ ó sì mọ̀ pé èmi ni Jèhófà Ọlọ́run yín, tó ń gbé ní Síónì, òkè mímọ́ mi.+

      Jerúsálẹ́mù yóò di ibi mímọ́,+

      Àwọn àjèjì* kò sì ní gbà á kọjá mọ́.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́