-
Àìsáyà 56:6, 7Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
6 Ní ti àwọn àjèjì tó fara mọ́ Jèhófà láti máa ṣe ìránṣẹ́ fún un,
Láti nífẹ̀ẹ́ orúkọ Jèhófà,+
Kí wọ́n sì di ìránṣẹ́ rẹ̀,
Gbogbo àwọn tó ń pa Sábáàtì mọ́, tí wọn ò sì kẹ́gàn rẹ̀,
Tí wọ́n ń rọ̀ mọ́ májẹ̀mú mi,
7 Màá tún mú wọn wá sí òkè mímọ́ mi,+
Màá sì mú kí wọ́n máa yọ̀ nínú ilé àdúrà mi.
Màá tẹ́wọ́ gba odindi ẹbọ sísun wọn àtàwọn ẹbọ wọn lórí pẹpẹ mi.
Torí a ó máa pe ilé mi ní ilé àdúrà fún gbogbo èèyàn.”+
-
-
Àìsáyà 66:20Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
20 Wọ́n máa kó gbogbo àwọn arákùnrin yín jáde látinú gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè,+ wọ́n á fi wọ́n ṣe ẹ̀bùn fún Jèhófà, lórí ẹṣin, nínú kẹ̀kẹ́ ẹṣin, nínú kẹ̀kẹ́ tí wọ́n bo orí rẹ̀, lórí àwọn ìbaaka àti lórí àwọn ràkúnmí tó ń yára kánkán, wọ́n á kó wọn wá sórí òkè mímọ́ mi, ìyẹn Jerúsálẹ́mù,” ni Jèhófà wí, “bí ìgbà tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì fi ohun èlò tó mọ́ gbé ẹ̀bùn wọn wá sínú ilé Jèhófà.”
-