32 “‘Torí náà, ohun tí Jèhófà sọ nípa ọba Ásíríà nìyí:+
“Kò ní wọ inú ìlú yìí+
Bẹ́ẹ̀ ni kò ní ta ọfà sí ibẹ̀
Tàbí kó fi apata dojú kọ ọ́
Bẹ́ẹ̀ sì ni kò ní mọ òkìtì láti dó tì í.+
33 Ọ̀nà tó gbà wá ló máa gbà pa dà;
Kò ní wọ inú ìlú yìí,” ni Jèhófà wí.
34 “Màá gbèjà ìlú yìí,+ màá sì gbà á sílẹ̀ nítorí orúkọ mi+
Àti nítorí Dáfídì ìránṣẹ́ mi.”’”+