ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Jeremáyà 21:7
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 7 “‘Jèhófà sọ pé, “Lẹ́yìn náà, màá fi Sedekáyà ọba Júdà àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ àti àwọn èèyàn ìlú yìí, ìyẹn àwọn tó bọ́ lọ́wọ́ àjàkálẹ̀ àrùn, idà àti ìyàn, lé ọwọ́ Nebukadinésárì* ọba Bábílónì, lé ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn àti lé ọwọ́ àwọn tó fẹ́ gba ẹ̀mí wọn.*+ Á fi idà pa wọ́n. Kò ní bá wọn kẹ́dùn, bẹ́ẹ̀ ni kò ní yọ́nú sí wọn tàbí kó ṣàánú wọn.”’+

  • Jeremáyà 24:8
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 8 “‘Àmọ́ ní ti ọ̀pọ̀tọ́ tó ti bà jẹ́ débi pé kò ṣeé jẹ,+ ohun tí Jèhófà sọ nìyí: “Bákan náà ni màá ṣe sí Sedekáyà+ ọba Júdà àti àwọn ìjòyè rẹ̀ pẹ̀lú àwọn tó ṣẹ́ kù lára àwọn èèyàn Jerúsálẹ́mù tó wà ní ilẹ̀ yìí àti àwọn tó ń gbé ní ilẹ̀ Íjíbítì.+

  • Jeremáyà 34:21
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 21 Màá sì fi Sedekáyà ọba Júdà àti àwọn ìjòyè rẹ̀ lé ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn àti àwọn tó fẹ́ gba ẹ̀mí wọn* àti lé ọwọ́ àwọn ọmọ ogun ọba Bábílónì+ tó ṣígun kúrò lọ́dọ̀ yín.’+

  • Ìsíkíẹ́lì 12:12, 13
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 12 Ìjòyè àárín wọn yóò gbé ẹrù rẹ̀ lé èjìká, yóò sì lọ nínú òkùnkùn. Ó máa dá ògiri lu, yóò sì gbé ẹrù rẹ̀ gba inú ihò náà.+ Ó máa bo ojú rẹ̀ kó má bàa rí ilẹ̀.’ 13 Èmi yóò ju àwọ̀n mi sí i láti fi mú un.+ Màá wá mú un lọ sí Bábílónì, sí ilẹ̀ àwọn ará Kálídíà, àmọ́ kò ní rí i; ibẹ̀ ló sì máa kú sí.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́