-
Jeremáyà 21:8-10Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
8 “Kí o sì sọ fún àwọn èèyàn yìí pé, ‘Ohun tí Jèhófà sọ nìyí: “Wò ó, mò ń fi ọ̀nà ìyè àti ọ̀nà ikú síwájú yín. 9 Idà àti ìyàn pẹ̀lú àjàkálẹ̀ àrùn ni yóò pa àwọn tó bá dúró nínú ìlú yìí. Àmọ́ ẹni tó bá jáde, tó sì fi ara rẹ̀ lé ọwọ́ àwọn ará Kálídíà tí wọ́n dó tì yín, á máa wà láàyè, á sì jèrè ẹ̀mí rẹ̀.”’*+
10 “‘“Nítorí mo ti dojú mi kọ ìlú yìí láti mú àjálù bá a, kì í ṣe fún ire,”+ ni Jèhófà wí. “Màá fi lé ọba Bábílónì lọ́wọ́,+ á sì dáná sun ún.”+
-